Kíróníkà Kìíní
5 Àwọn ọmọ Jáfẹ́tì ni Gómérì, Mágọ́gù, Mádáì, Jáfánì, Túbálì,+ Méṣékì+ àti Tírásì.+
6 Àwọn ọmọ Gómérì ni Áṣíkénásì, Rífátì àti Tógámà.+
7 Àwọn ọmọ Jáfánì ni Élíṣáhì, Táṣíṣì, Kítímù àti Ródánímù.
8 Àwọn ọmọ Hámù ni Kúṣì,+ Mísíráímù, Pútì àti Kénáánì.+
9 Àwọn ọmọ Kúṣì ni Sébà,+ Háfílà, Sábítà, Ráámà+ àti Sábítékà.
Àwọn ọmọ Ráámà sì ni Ṣébà àti Dédánì.+
10 Kúṣì bí Nímírọ́dù.+ Òun ló kọ́kọ́ di alágbára ní ayé.
11 Mísíráímù bí Lúdímù,+ Ánámímù, Léhábímù, Náfútúhímù,+ 12 Pátírúsímù,+ Kásílúhímù (ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni àwọn Filísínì+ ti wá) àti Káfítórímù.+
13 Kénáánì bí Sídónì+ àkọ́bí rẹ̀ àti Hétì+ 14 àti àwọn ará Jébúsì,+ àwọn Ámórì,+ àwọn Gẹ́gáṣì,+ 15 àwọn Hífì,+ àwọn Ákì, àwọn Sáínì, 16 àwọn ọmọ Áfádì,+ àwọn Sémárì àti àwọn ará Hámátì.
18 Ápákíṣádì bí Ṣélà, Ṣélà+ sì bí Ébérì.
19 Ọmọ méjì ni Ébérì bí. Ọ̀kan ń jẹ́ Pélégì,*+ torí pé ìgbà ayé rẹ̀ ni ayé* pín sọ́tọ̀ọ̀tọ̀. Orúkọ arákùnrin rẹ̀ ni Jókítánì.
20 Jókítánì bí Álímódádì, Ṣéléfì, Hasamáfétì, Jérà,+ 21 Hádórámù, Úsálì, Díkílà, 22 Óbálì, Ábímáélì, Ṣébà, 23 Ófírì,+ Háfílà+ àti Jóbábù; gbogbo wọn jẹ́ ọmọ Jókítánì.
28 Àwọn ọmọ Ábúráhámù ni Ísákì+ àti Íṣímáẹ́lì.+
29 Ibi tí ìdílé wọn ti wá nìyí: Àkọ́bí Íṣímáẹ́lì ni Nébáótì,+ lẹ́yìn náà ó bí Kídárì,+ Ádíbéélì, Míbúsámù,+ 30 Míṣímà, Dúmà, Máásà, Hádádì, Témà, 31 Jétúrì, Náfíṣì àti Kédémà. Àwọn yìí ni ọmọ Íṣímáẹ́lì.
32 Àwọn ọmọ tí Kétúrà,+ wáhàrì* Ábúráhámù bí ni Símíránì, Jókíṣánì, Médánì, Mídíánì,+ Íṣíbákì àti Ṣúáhì.+
Àwọn ọmọ Jókíṣánì ni Ṣébà àti Dédánì.+
33 Àwọn ọmọ Mídíánì ni Eéfà,+ Éférì, Hánókù, Ábíídà àti Élídáà.
Ọmọ Kétúrà ni gbogbo wọn.
34 Ábúráhámù bí Ísákì. Àwọn ọmọ Ísákì+ ni Ísọ̀+ àti Ísírẹ́lì.+
35 Àwọn ọmọ Ísọ̀ ni Élífásì, Réúẹ́lì, Jéúṣì, Jálámù àti Kórà.+
36 Àwọn ọmọ Élífásì ni Témánì,+ Ómárì, Séfò, Gátámù, Kénásì, Tímínà àti Ámálékì.+
37 Àwọn ọmọ Réúẹ́lì ni Náhátì, Síírà, Ṣámà àti Mísà.+
38 Àwọn ọmọ Séírì+ ni Lótánì, Ṣóbálì, Síbéónì, Ánáhì, Díṣónì, Ésérì àti Díṣánì.+
39 Àwọn ọmọ Lótánì ni Hórì àti Hómámù. Arábìnrin Lótánì sì ni Tímínà.+
40 Àwọn ọmọ Ṣóbálì ni Álífánì, Mánáhátì, Ébálì, Ṣéfò àti Ónámù.
Àwọn ọmọ Síbéónì sì ni Áyà àti Ánáhì.+
41 Ọmọ* Ánáhì ni Díṣónì.
Àwọn ọmọ Díṣónì sì ni Hémúdánì, Éṣíbánì, Ítíránì àti Kéránì.+
42 Àwọn ọmọ Ésérì+ ni Bílíhánì, Sááfánì àti Ékánì.
Àwọn ọmọ Díṣánì ni Úsì àti Áránì.+
43 Àwọn ọba tó jẹ ní ilẹ̀ Édómù+ kí ọba kankan tó jẹ lórí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì+ nìyí: Bélà ọmọ Béórì; orúkọ ìlú rẹ̀ ni Dínhábà. 44 Nígbà tí Bélà kú, Jóbábù ọmọ Síírà láti Bósírà+ bẹ̀rẹ̀ sí í jọba ní ipò rẹ̀. 45 Nígbà tí Jóbábù kú, Húṣámù láti ilẹ̀ àwọn ará Témánì bẹ̀rẹ̀ sí í jọba ní ipò rẹ̀. 46 Nígbà tí Húṣámù kú, Hádádì ọmọ Bédádì, ẹni tó ṣẹ́gun Mídíánì ní agbègbè* Móábù bẹ̀rẹ̀ sí í jọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Áfítì. 47 Nígbà tí Hádádì kú, Sámúlà láti Másírékà bẹ̀rẹ̀ sí í jọba ní ipò rẹ̀. 48 Nígbà tí Sámúlà kú, Ṣéọ́lù láti Réhóbótì lẹ́gbẹ̀ẹ́ Odò bẹ̀rẹ̀ sí í jọba ní ipò rẹ̀. 49 Nígbà tí Ṣéọ́lù kú, Baali-hánánì ọmọ Ákíbórì bẹ̀rẹ̀ sí í jọba ní ipò rẹ̀. 50 Nígbà tí Baali-hánánì kú, Hádádì bẹ̀rẹ̀ sí í jọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Páù, orúkọ ìyàwó rẹ̀ sì ni Méhétábélì ọmọ Mátírédì, ọmọbìnrin Mésáhábù. 51 Lẹ́yìn náà, Hádádì kú.
Àwọn séríkí* Édómù ni Séríkí Tímínà, Séríkí Álíífà, Séríkí Jététì,+ 52 Séríkí Oholibámà, Séríkí Élà, Séríkí Pínónì, 53 Séríkí Kénásì, Séríkí Témánì, Séríkí Míbúsárì, 54 Séríkí Mágídíélì, Séríkí Írámù. Àwọn yìí ni séríkí Édómù.