ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 1 Sámúẹ́lì 15
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé 1 Sámúẹ́lì

      • Àìgbọ́ràn mú kí Sọ́ọ̀lù dá Ágágì sí (1-9)

      • Sámúẹ́lì bá Sọ́ọ̀lù wí (10-23)

        • “Ṣíṣe ìgbọràn sàn ju ẹbọ” (22)

      • Ọlọ́run kọ Sọ́ọ̀lù lọ́ba (24-29)

      • Sámúẹ́lì pa Ágágì (30-35)

1 Sámúẹ́lì 15:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 9:16; 10:1
  • +1Sa 12:14

1 Sámúẹ́lì 15:2

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 17:8; Nọ 24:20; Di 25:17, 18

1 Sámúẹ́lì 15:3

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ṣàánú wọn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 17:14; Di 25:19; 1Kr 4:43
  • +Le 27:29; 1Sa 15:18
  • +Di 9:1, 3
  • +Di 13:17; Joṣ 6:18

1 Sámúẹ́lì 15:4

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 11:8; 13:15

1 Sámúẹ́lì 15:6

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 10:29, 32; 24:21; Ond 1:16
  • +Jẹ 18:25; 19:12, 13; Joṣ 6:17
  • +Ẹk 18:9, 12

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    3/15/2005, ojú ìwé 23

1 Sámúẹ́lì 15:7

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 25:19; 1Sa 14:47, 48
  • +Jẹ 25:17, 18
  • +1Sa 27:8

1 Sámúẹ́lì 15:8

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 15:33
  • +Le 27:29; 1Sa 15:3

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé-Ìṣọ́nà,

    7/15/1992, ojú ìwé 5

1 Sámúẹ́lì 15:9

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “yọ́nú sí Ágágì.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 7:12

1 Sámúẹ́lì 15:11

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “Mo kẹ́dùn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 13:13; 15:3
  • +1Sa 16:1

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    4/15/1998, ojú ìwé 6-7

1 Sámúẹ́lì 15:12

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 15:20, 55
  • +2Sa 18:18

1 Sámúẹ́lì 15:14

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 15:3

1 Sámúẹ́lì 15:15

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “fi ìyọ́nú hàn sí agbo ẹran àti ọ̀wọ́ ẹran tó dára jù.”

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àwọn Ìtẹ̀jáde Tá A Tọ́ka sí Nínú Ìwé Ìpàdé, 3/2022,

1 Sámúẹ́lì 15:16

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 15:10, 11

1 Sámúẹ́lì 15:17

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 9:21; 10:22
  • +1Sa 9:16; 10:1

1 Sámúẹ́lì 15:18

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 15:3
  • +Di 25:19

1 Sámúẹ́lì 15:19

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 13:17; 1Sa 15:9

1 Sámúẹ́lì 15:20

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 27:29; Di 7:16; 1Sa 15:3, 9

1 Sámúẹ́lì 15:21

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 15:15

1 Sámúẹ́lì 15:22

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ais 1:11
  • +Owe 21:3; Ho 6:6; Mk 12:33
  • +Le 3:16

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    6/15/2007, ojú ìwé 26-28

1 Sámúẹ́lì 15:23

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “ère tẹ́ráfímù,” ìyẹn, àwọn òrìṣà ìdílé; òrìṣà.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 12:15
  • +Le 20:6; Di 18:10, 12; 1Kr 10:13
  • +1Sa 15:3
  • +1Sa 13:14; 16:1; Iṣe 13:22

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àwọn Ìtẹ̀jáde Tá A Tọ́ka sí Nínú Ìwé Ìpàdé, 3/2022,

1 Sámúẹ́lì 15:25

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 15:30

1 Sámúẹ́lì 15:26

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 13:14; 16:1

1 Sámúẹ́lì 15:28

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 13:14; 16:12, 13; Iṣe 13:22

1 Sámúẹ́lì 15:29

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “kábàámọ̀.”

  • *

    Tàbí “kábàámọ̀.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Kr 29:11
  • +Tit 1:2; Heb 6:18
  • +Nọ 23:19

1 Sámúẹ́lì 15:30

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 15:25

1 Sámúẹ́lì 15:32

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí kó jẹ́, “Ágágì bá ń fi ìgboyà.”

  • *

    Ní Héb., “ìkorò ikú.”

1 Sámúẹ́lì 15:33

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 17:14; Di 25:19; 1Sa 15:3

1 Sámúẹ́lì 15:35

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “Jèhófà sì kẹ́dùn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 16:1
  • +1Sa 15:11

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    4/15/1998, ojú ìwé 6-7

Àwọn míì

1 Sám. 15:11Sa 9:16; 10:1
1 Sám. 15:11Sa 12:14
1 Sám. 15:2Ẹk 17:8; Nọ 24:20; Di 25:17, 18
1 Sám. 15:3Ẹk 17:14; Di 25:19; 1Kr 4:43
1 Sám. 15:3Le 27:29; 1Sa 15:18
1 Sám. 15:3Di 9:1, 3
1 Sám. 15:3Di 13:17; Joṣ 6:18
1 Sám. 15:41Sa 11:8; 13:15
1 Sám. 15:6Nọ 10:29, 32; 24:21; Ond 1:16
1 Sám. 15:6Jẹ 18:25; 19:12, 13; Joṣ 6:17
1 Sám. 15:6Ẹk 18:9, 12
1 Sám. 15:7Di 25:19; 1Sa 14:47, 48
1 Sám. 15:7Jẹ 25:17, 18
1 Sám. 15:71Sa 27:8
1 Sám. 15:81Sa 15:33
1 Sám. 15:8Le 27:29; 1Sa 15:3
1 Sám. 15:9Joṣ 7:12
1 Sám. 15:111Sa 13:13; 15:3
1 Sám. 15:111Sa 16:1
1 Sám. 15:12Joṣ 15:20, 55
1 Sám. 15:122Sa 18:18
1 Sám. 15:141Sa 15:3
1 Sám. 15:161Sa 15:10, 11
1 Sám. 15:171Sa 9:21; 10:22
1 Sám. 15:171Sa 9:16; 10:1
1 Sám. 15:181Sa 15:3
1 Sám. 15:18Di 25:19
1 Sám. 15:19Di 13:17; 1Sa 15:9
1 Sám. 15:20Le 27:29; Di 7:16; 1Sa 15:3, 9
1 Sám. 15:211Sa 15:15
1 Sám. 15:22Ais 1:11
1 Sám. 15:22Owe 21:3; Ho 6:6; Mk 12:33
1 Sám. 15:22Le 3:16
1 Sám. 15:231Sa 12:15
1 Sám. 15:23Le 20:6; Di 18:10, 12; 1Kr 10:13
1 Sám. 15:231Sa 15:3
1 Sám. 15:231Sa 13:14; 16:1; Iṣe 13:22
1 Sám. 15:251Sa 15:30
1 Sám. 15:261Sa 13:14; 16:1
1 Sám. 15:281Sa 13:14; 16:12, 13; Iṣe 13:22
1 Sám. 15:291Kr 29:11
1 Sám. 15:29Tit 1:2; Heb 6:18
1 Sám. 15:29Nọ 23:19
1 Sám. 15:301Sa 15:25
1 Sám. 15:33Ẹk 17:14; Di 25:19; 1Sa 15:3
1 Sám. 15:351Sa 16:1
1 Sám. 15:351Sa 15:11
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
  • 20
  • 21
  • 22
  • 23
  • 24
  • 25
  • 26
  • 27
  • 28
  • 29
  • 30
  • 31
  • 32
  • 33
  • 34
  • 35
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
1 Sámúẹ́lì 15:1-35

Sámúẹ́lì Kìíní

15 Nígbà náà, Sámúẹ́lì sọ fún Sọ́ọ̀lù pé: “Jèhófà rán mi láti fòróró yàn ọ́ ṣe ọba lórí àwọn èèyàn rẹ̀ Ísírẹ́lì;+ ní báyìí, gbọ́ ohun tí Jèhófà fẹ́ sọ.+ 2 Ohun tí Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun sọ nìyí: ‘Màá pe àwọn ọmọ Ámálékì wá jíhìn nítorí ohun tí wọ́n ṣe sí Ísírẹ́lì bí wọ́n ṣe gbéjà kò ó nígbà tó ń jáde bọ̀ láti Íjíbítì.+ 3 Ní báyìí, lọ ṣá àwọn ọmọ Ámálékì+ balẹ̀, kí o sì pa wọ́n run pátápátá+ pẹ̀lú gbogbo ohun tí wọ́n ní. O ò gbọ́dọ̀ dá wọn sí;* ṣe ni kí o pa gbogbo wọn,+ ọkùnrin àti obìnrin, ọmọdé àti ọmọ jòjòló, akọ màlúù àti àgùntàn, ràkúnmí àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.’”+ 4 Sọ́ọ̀lù pe àwọn èèyàn náà jọ, ó sì kà wọ́n ní Téláímù: Wọ́n jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́wàá (200,000) ọmọ ogun tó ń fẹsẹ̀ rìn àti ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá (10,000) ọkùnrin Júdà.+

5 Sọ́ọ̀lù lọ títí dé ìlú Ámálékì, ó sì lúgọ sẹ́gbẹ̀ẹ́ àfonífojì. 6 Sọ́ọ̀lù wá sọ fún àwọn Kénì pé:+ “Ẹ jáde kúrò láàárín àwọn ọmọ Ámálékì, kí n má bàa gbá yín lọ pẹ̀lú wọn.+ Nítorí ẹ fi ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ hàn sí gbogbo ọmọ Ísírẹ́lì+ nígbà tí wọ́n jáde kúrò ní Íjíbítì.” Torí náà, àwọn Kénì kúrò ní àárín àwọn ọmọ Ámálékì. 7 Lẹ́yìn ìyẹn, Sọ́ọ̀lù pa àwọn ọmọ Ámálékì+ láti Háfílà+ títí dé Ṣúrì,+ tó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ Íjíbítì. 8 Ó mú Ágágì+ ọba Ámálékì láàyè, àmọ́ ó fi idà pa gbogbo àwọn èèyàn tó ṣẹ́ kù run.+ 9 Ṣùgbọ́n Sọ́ọ̀lù àti àwọn ọmọ ogun rẹ̀ dá Ágágì sí* àti agbo ẹran tó dára jù, títí kan ọ̀wọ́ ẹran, àwọn ẹran àbọ́sanra, àwọn àgbò àti gbogbo ohun tó dára.+ Wọn ò fẹ́ pa wọ́n run. Àmọ́ wọ́n pa gbogbo nǹkan tí kò ní láárí, tí kò sì wúlò run.

10 Ìgbà náà ni Jèhófà bá Sámúẹ́lì sọ̀rọ̀, ó ní: 11 “Ó dùn mí* pé mo fi Sọ́ọ̀lù jọba, torí ó ti pa dà lẹ́yìn mi, kò sì ṣe ohun tí mo sọ.”+ Inú Sámúẹ́lì bà jẹ́ gan-an, ó sì ń ké pe Jèhófà láti òru mọ́jú.+ 12 Nígbà tí Sámúẹ́lì dìde ní àárọ̀ kùtù láti lọ bá Sọ́ọ̀lù, wọ́n sọ fún Sámúẹ́lì pé: “Sọ́ọ̀lù ti lọ sí Kámẹ́lì,+ ó sì gbé ohun tí wọ́n á máa fi rántí rẹ̀ dúró síbẹ̀.+ Ó wá pa dà, ó sì gba Gílígálì lọ.” 13 Níkẹyìn, Sámúẹ́lì dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, Sọ́ọ̀lù sì sọ fún un pé: “Kí Jèhófà bù kún ọ. Mo ti ṣe ohun tí Jèhófà sọ.” 14 Àmọ́ Sámúẹ́lì sọ pé: “Kí wá ni ohùn agbo ẹran tó ń dún yìí àti ohùn ọ̀wọ́ ẹran tí mò ń gbọ́ yìí?”+ 15 Ni Sọ́ọ̀lù bá sọ pé: “Ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Ámálékì ni wọ́n ti mú wọn wá, nítorí àwọn èèyàn náà dá agbo ẹran àti ọ̀wọ́ ẹran tó dára jù sí,* láti fi wọ́n rúbọ sí Jèhófà Ọlọ́run rẹ; àmọ́ a ti pa àwọn ohun tó ṣẹ́ kù run.” 16 Sámúẹ́lì bá sọ fún Sọ́ọ̀lù pé: “Ó tó! Jẹ́ kí n sọ ohun tí Jèhófà sọ fún mi lóru àná fún ọ.”+ Torí náà, ó sọ fún un pé: “Sọ ọ́!”

17 Sámúẹ́lì ń bá ọ̀rọ̀ rẹ̀ lọ, ó ní: “Ṣebí o ò já mọ́ nǹkan lójú ara rẹ+ nígbà tí a fi ọ́ ṣe olórí àwọn ẹ̀yà Ísírẹ́lì, tí Jèhófà sì fòróró yàn ọ́ ṣe ọba lórí Ísírẹ́lì?+ 18 Ẹ̀yìn náà ni Jèhófà rán ọ níṣẹ́, ó sọ pé, ‘Lọ pa àwọn ọmọ Ámálékì tó jẹ́ ẹlẹ́ṣẹ̀ run pátápátá.+ Bá wọn jà títí wàá fi pa wọ́n run.’+ 19 Kí ló dé tí o ò ṣègbọràn sí ohùn Jèhófà? Kàkà bẹ́ẹ̀, ńṣe lo fi ojúkòkòrò kó nǹkan wọn,+ tí o sì ṣe ohun tó burú ní ojú Jèhófà!”

20 Sọ́ọ̀lù wá sọ fún Sámúẹ́lì pé: “Ṣebí mo ti ṣègbọràn sí ohùn Jèhófà! Mo lọ jíṣẹ́ tí Jèhófà rán mi, mo mú Ágágì ọba Ámálékì wá, mo sì pa àwọn ọmọ Ámálékì run pátápátá.+ 21 Àmọ́ àwọn èèyàn náà kó àgùntàn àti màlúù látinú ẹrù ogun, èyí tó dára jù nínú ohun tí wọ́n fẹ́ pa run, láti fi rúbọ sí Jèhófà Ọlọ́run rẹ ní Gílígálì.”+

22 Sámúẹ́lì wá sọ pé: “Ṣé àwọn ẹbọ sísun àti ẹbọ+ máa ń múnú Jèhófà dùn tó kéèyàn ṣègbọràn sí ohùn Jèhófà? Wò ó! Ṣíṣe ìgbọràn sàn ju ẹbọ,+ fífi etí sílẹ̀ sì sàn ju ọ̀rá+ àgbò; 23 nítorí ẹ̀ṣẹ̀ kan náà ni ìṣọ̀tẹ̀+ àti iṣẹ́ wíwò+ jẹ́, ọ̀kan náà sì ni kíkọjá àyè jẹ́ pẹ̀lú lílo agbára abàmì àti ìbọ̀rìṣà.* Nítorí o ti kọ ọ̀rọ̀ Jèhófà,+ òun náà ti kọ̀ ọ́ ní ọba.”+

24 Ìgbà náà ni Sọ́ọ̀lù sọ fún Sámúẹ́lì pé: “Mo ti ṣẹ̀, torí mo ti tẹ àṣẹ Jèhófà àti ọ̀rọ̀ rẹ lójú, nítorí mo bẹ̀rù àwọn èèyàn, mo sì fetí sí ohun tí wọ́n sọ. 25 Ní báyìí, jọ̀wọ́, dárí ẹ̀ṣẹ̀ mi jì mí, kí o sì bá mi pa dà kí n lè forí balẹ̀ fún Jèhófà.”+ 26 Àmọ́ Sámúẹ́lì sọ fún Sọ́ọ̀lù pé: “Mi ò ní bá ọ pa dà, nítorí o ti kọ ọ̀rọ̀ Jèhófà, Jèhófà sì ti kọ̀ ọ́ pé kí o má ṣe jẹ́ ọba lórí Ísírẹ́lì mọ́.”+ 27 Bí Sámúẹ́lì ṣe ń yíjú pa dà láti lọ, Sọ́ọ̀lù gbá etí aṣọ àwọ̀lékè rẹ̀ tí kò lápá mú, aṣọ náà bá fà ya. 28 Sámúẹ́lì wá sọ fún un pé: “Jèhófà ti fa ìṣàkóso Ísírẹ́lì ya kúrò lọ́wọ́ rẹ lónìí, yóò sì fún ọmọnìkejì rẹ tó sàn jù ọ́ lọ.+ 29 Yàtọ̀ síyẹn, Atóbilọ́lá Ísírẹ́lì+ kò ní jẹ́ parọ́+ tàbí kó yí ìpinnu rẹ̀ pa dà,* nítorí Òun kì í ṣe èèyàn tí á fi yí ìpinnu rẹ̀ pa dà.”*+

30 Ó wá sọ pé: “Mo ti ṣẹ̀. Àmọ́, jọ̀ọ́ bọlá fún mi níwájú àgbààgbà àwọn èèyàn mi àti níwájú Ísírẹ́lì. Bá mi pa dà, màá sì forí balẹ̀ fún Jèhófà Ọlọ́run rẹ.”+ 31 Torí náà, Sámúẹ́lì tẹ̀ lé Sọ́ọ̀lù pa dà, Sọ́ọ̀lù sì forí balẹ̀ fún Jèhófà. 32 Sámúẹ́lì wá sọ pé: “Ẹ mú Ágágì ọba Ámálékì sún mọ́ mi.” Ni ara bá ń ti Ágágì láti* lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ nítorí Ágágì ń sọ lọ́kàn ara rẹ̀ pé: ‘Ó dájú pé ikú* ti yẹ̀ lórí mi.’ 33 Àmọ́ Sámúẹ́lì sọ pé: “Bí idà rẹ ṣe mú àwọn obìnrin ṣòfò ọmọ, bẹ́ẹ̀ ni ìyá rẹ á ṣe di ẹni tó ṣòfò ọmọ jù láàárín àwọn obìnrin.” Ni Sámúẹ́lì bá ṣá Ágágì sí wẹ́wẹ́ níwájú Jèhófà ní Gílígálì.+

34 Sámúẹ́lì gba Rámà lọ, Sọ́ọ̀lù sì lọ sí ilé rẹ̀ ní Gíbíà ìlú rẹ̀. 35 Títí Sámúẹ́lì fi kú, kò rí Sọ́ọ̀lù mọ́, ńṣe ni Sámúẹ́lì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣọ̀fọ̀ nítorí Sọ́ọ̀lù.+ Ó sì dun Jèhófà* pé ó fi Sọ́ọ̀lù jẹ ọba lórí Ísírẹ́lì.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́