ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 2 Sámúẹ́lì 24
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé 2 Sámúẹ́lì

      • Dáfídì dẹ́ṣẹ̀ torí pé ó ka èèyàn (1-14)

      • Àjàkálẹ̀ àrùn pa 70,000 (15-17)

      • Dáfídì mọ pẹpẹ (18-25)

        • Kò sí ẹbọ tí kì í náni ní nǹkan (24)

2 Sámúẹ́lì 24:1

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “fi sí Dáfídì lọ́kàn láti.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 21:1
  • +1Kr 27:23, 24
  • +1Kr 21:1-3

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    5/15/2005, ojú ìwé 19

    7/15/1992, ojú ìwé 5

2 Sámúẹ́lì 24:2

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 8:16; 20:23
  • +Ond 20:1

2 Sámúẹ́lì 24:4

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 1:2; 1Kr 21:4

2 Sámúẹ́lì 24:5

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “gúúsù.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 2:36; Joṣ 13:8, 9
  • +Nọ 32:34, 35

2 Sámúẹ́lì 24:6

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 32:40
  • +Jẹ 10:15; 49:13; Joṣ 11:8

2 Sámúẹ́lì 24:7

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 19:24, 29
  • +Joṣ 11:19
  • +Joṣ 15:1
  • +Jẹ 21:31; Joṣ 15:21, 28

2 Sámúẹ́lì 24:9

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 2:32; 26:51; 1Kr 21:5, 6; 27:23

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé-Ìṣọ́nà,

    7/15/1992, ojú ìwé 5

2 Sámúẹ́lì 24:10

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ẹ̀rí ọkàn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 24:5; Ro 2:15
  • +2Sa 12:13
  • +Sm 130:3; Ho 14:2; 1Jo 1:9
  • +1Kr 21:8-13

2 Sámúẹ́lì 24:11

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 22:5; 1Kr 29:29

2 Sámúẹ́lì 24:12

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Owe 3:12

2 Sámúẹ́lì 24:13

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 26:18, 20; 2Sa 21:1
  • +Le 26:14, 17
  • +Le 26:16

2 Sámúẹ́lì 24:14

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Heb 12:6
  • +Sm 103:8; 119:156
  • +2Kr 28:1, 5

2 Sámúẹ́lì 24:15

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 16:46; 1Kr 27:24
  • +1Kr 21:14, 15
  • +2Sa 24:2

2 Sámúẹ́lì 24:16

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “kẹ́dùn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 78:38; Jer 26:19; Joẹ 2:13
  • +2Kr 3:1
  • +Jẹ 10:15, 16; Joṣ 15:8

2 Sámúẹ́lì 24:17

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 95:7
  • +1Kr 21:16, 17

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    5/15/2005, ojú ìwé 19

2 Sámúẹ́lì 24:18

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Kr 21:18-23; 2Kr 3:1

2 Sámúẹ́lì 24:21

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 16:46, 47; 25:8; 2Sa 24:15

2 Sámúẹ́lì 24:22

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “ohun tó bá dára lójú rẹ.”

2 Sámúẹ́lì 24:24

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ṣékélì kan jẹ́ gíráàmù 11.4. Wo Àfikún B14.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Kr 21:24-28

2 Sámúẹ́lì 24:25

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 20:25; 1Kr 22:1
  • +2Sa 21:14; 2Kr 33:13

Àwọn míì

2 Sám. 24:12Sa 21:1
2 Sám. 24:11Kr 27:23, 24
2 Sám. 24:11Kr 21:1-3
2 Sám. 24:22Sa 8:16; 20:23
2 Sám. 24:2Ond 20:1
2 Sám. 24:4Nọ 1:2; 1Kr 21:4
2 Sám. 24:5Di 2:36; Joṣ 13:8, 9
2 Sám. 24:5Nọ 32:34, 35
2 Sám. 24:6Nọ 32:40
2 Sám. 24:6Jẹ 10:15; 49:13; Joṣ 11:8
2 Sám. 24:7Joṣ 19:24, 29
2 Sám. 24:7Joṣ 11:19
2 Sám. 24:7Joṣ 15:1
2 Sám. 24:7Jẹ 21:31; Joṣ 15:21, 28
2 Sám. 24:9Nọ 2:32; 26:51; 1Kr 21:5, 6; 27:23
2 Sám. 24:101Sa 24:5; Ro 2:15
2 Sám. 24:102Sa 12:13
2 Sám. 24:10Sm 130:3; Ho 14:2; 1Jo 1:9
2 Sám. 24:101Kr 21:8-13
2 Sám. 24:111Sa 22:5; 1Kr 29:29
2 Sám. 24:12Owe 3:12
2 Sám. 24:13Le 26:18, 20; 2Sa 21:1
2 Sám. 24:13Le 26:14, 17
2 Sám. 24:13Le 26:16
2 Sám. 24:14Heb 12:6
2 Sám. 24:14Sm 103:8; 119:156
2 Sám. 24:142Kr 28:1, 5
2 Sám. 24:15Nọ 16:46; 1Kr 27:24
2 Sám. 24:151Kr 21:14, 15
2 Sám. 24:152Sa 24:2
2 Sám. 24:16Sm 78:38; Jer 26:19; Joẹ 2:13
2 Sám. 24:162Kr 3:1
2 Sám. 24:16Jẹ 10:15, 16; Joṣ 15:8
2 Sám. 24:17Sm 95:7
2 Sám. 24:171Kr 21:16, 17
2 Sám. 24:181Kr 21:18-23; 2Kr 3:1
2 Sám. 24:21Nọ 16:46, 47; 25:8; 2Sa 24:15
2 Sám. 24:241Kr 21:24-28
2 Sám. 24:25Ẹk 20:25; 1Kr 22:1
2 Sám. 24:252Sa 21:14; 2Kr 33:13
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
  • 20
  • 21
  • 22
  • 23
  • 24
  • 25
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
2 Sámúẹ́lì 24:1-25

Sámúẹ́lì Kejì

24 Inú tún bí Jèhófà sí Ísírẹ́lì+ nígbà tí ẹnì kan mú kí Dáfídì* ṣe ohun kan sí wọn, ó ní: “Lọ, ka iye+ àwọn èèyàn Ísírẹ́lì àti Júdà.”+ 2 Nítorí náà, ọba sọ fún Jóábù+ olórí àwọn ọmọ ogun tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ pé: “Jọ̀wọ́, lọ yí ká gbogbo àwọn ẹ̀yà Ísírẹ́lì, láti Dánì títí dé Bíá-ṣébà,+ kí ẹ sì forúkọ àwọn èèyàn náà sílẹ̀, kí n lè mọ iye wọn.” 3 Ṣùgbọ́n Jóábù sọ fún ọba pé: “Kí Jèhófà Ọlọ́run rẹ sọ àwọn èèyàn náà di púpọ̀ ní ìlọ́po ọgọ́rùn-ún (100), kí ó sì ṣojú olúwa mi ọba, àmọ́ kí nìdí tí olúwa mi ọba fi fẹ́ ṣe irú nǹkan yìí?”

4 Àmọ́ ọ̀rọ̀ ọba borí ti Jóábù àti ti àwọn olórí ọmọ ogun. Torí náà, Jóábù àti àwọn olórí ọmọ ogun jáde níwájú ọba láti forúkọ àwọn èèyàn Ísírẹ́lì sílẹ̀.+ 5 Wọ́n sọdá Jọ́dánì, wọ́n sì dó sí Áróérì,+ lápá ọ̀tún* ìlú ní àárín àfonífojì, wọ́n forí lé ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Gádì, wọ́n sì dé Jásérì.+ 6 Lẹ́yìn ìyẹn, wọ́n lọ sí Gílíádì+ àti ilẹ̀ Tatimu-hódíṣì, wọ́n ń lọ títí dé Dani-jáánì, wọ́n sì lọ yí ká dé Sídónì.+ 7 Lẹ́yìn náà, wọ́n lọ sí ibi ààbò Tírè+ àti gbogbo ìlú àwọn Hífì+ àti ti àwọn ọmọ Kénáánì, níkẹyìn wọ́n dé Négébù+ ti Júdà ní Bíá-ṣébà.+ 8 Bí wọ́n ṣe lọ káàkiri gbogbo ilẹ̀ náà nìyẹn, wọ́n sì wá sí Jerúsálẹ́mù ní òpin oṣù mẹ́sàn-án àti ogún (20) ọjọ́. 9 Jóábù wá fún ọba ní iye àwọn èèyàn tó forúkọ wọn sílẹ̀. Ogójì ọ̀kẹ́ (800,000) jagunjagun tó ní idà ló wà ní Ísírẹ́lì, àwọn ọkùnrin Júdà sì jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n (500,000).+

10 Àmọ́ ọkàn* Dáfídì dá a lẹ́bi+ lẹ́yìn tó ti ka iye àwọn èèyàn náà. Dáfídì wá sọ fún Jèhófà pé: “Mo ti dá ẹ̀ṣẹ̀+ ńlá nítorí ohun tí mo ṣe yìí. Ní báyìí, Jèhófà, jọ̀wọ́ dárí ẹ̀ṣẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ jì í,+ nítorí mo ti hùwà òmùgọ̀ gan-an.”+ 11 Nígbà tí Dáfídì dìde ní àárọ̀, Jèhófà bá wòlíì Gádì+ tó jẹ́ aríran Dáfídì sọ̀rọ̀, ó ní: 12 “Lọ sọ fún Dáfídì pé, ‘Ohun tí Jèhófà sọ nìyí: “Ohun mẹ́ta ni màá fi síwájú rẹ. Mú ọ̀kan tí o fẹ́ kí n ṣe sí ọ.”’”+ 13 Torí náà, Gádì wá sọ́dọ̀ Dáfídì, ó sì sọ fún un pé: “Ṣé kí ìyàn ọdún méje mú ní ilẹ̀ rẹ?+ Tàbí kí o fi oṣù mẹ́ta máa sá fún àwọn ọ̀tá rẹ nígbà tí wọ́n bá ń lépa rẹ?+ Tàbí kí àjàkálẹ̀ àrùn fi ọjọ́ mẹ́ta jà ní ilẹ̀ rẹ?+ Ní báyìí, fara balẹ̀, kí o ro ohun tí o fẹ́ kí n sọ fún Ẹni tó rán mi.” 14 Nítorí náà, Dáfídì sọ fún Gádì pé: “Ọ̀rọ̀ yìí kó ìdààmú bá mi gan-an. Jọ̀wọ́, jẹ́ kí a ṣubú sí ọwọ́ Jèhófà,+ nítorí àánú rẹ̀ pọ̀;+ ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí n ṣubú sí ọwọ́ èèyàn.”+

15 Nígbà náà, Jèhófà rán àjàkálẹ̀ àrùn+ sí Ísírẹ́lì láti àárọ̀ títí di àkókò tó dá, tí ọ̀kẹ́ mẹ́ta ààbọ̀ (70,000) fi kú+ lára àwọn èèyàn náà láti Dánì títí dé Bíá-ṣébà.+ 16 Nígbà tí áńgẹ́lì náà na ọwọ́ rẹ̀ sí Jerúsálẹ́mù láti pa á run, Jèhófà pèrò dà* lórí àjálù+ náà, ó sì sọ fún áńgẹ́lì tó ń pa àwọn èèyàn náà pé: “Ó tó gẹ́ẹ́! Gbé ọwọ́ rẹ wálẹ̀.” Áńgẹ́lì Jèhófà wà nítòsí ibi ìpakà Áráúnà+ ará Jébúsì.+

17 Nígbà tí Dáfídì rí áńgẹ́lì tó ń pa àwọn èèyàn náà, ó sọ fún Jèhófà pé: “Èmi ni mo ṣẹ̀, èmi ni mo sì ṣe ohun tí kò dáa; àmọ́ kí ni àwọn àgùntàn+ yìí ṣe? Jọ̀ọ́, èmi àti ilé bàbá mi+ ni kí o gbé ọwọ́ rẹ sókè sí.”

18 Torí náà, Gádì wọlé wá bá Dáfídì ní ọjọ́ yẹn, ó sì sọ fún un pé: “Lọ, kí o ṣe pẹpẹ kan fún Jèhófà ní ibi ìpakà Áráúnà ará Jébúsì.”+ 19 Dáfídì wá lọ bí Gádì ṣe sọ, gẹ́gẹ́ bí Jèhófà ti pàṣẹ fún un. 20 Nígbà tí Áráúnà wo ìsàlẹ̀, tí ó sì rí ọba àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tí wọ́n ń bọ̀ lọ́dọ̀ rẹ̀, lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, Áráúnà jáde wá, ó tẹrí ba fún ọba, ó sì dojú bolẹ̀. 21 Áráúnà béèrè pé: “Kí nìdí tí olúwa mi ọba fi wá sọ́dọ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀?” Dáfídì dáhùn pé: “Láti ra ibi ìpakà yìí lọ́wọ́ rẹ ni, kí n lè mọ pẹpẹ kan fún Jèhófà, kí àjàkálẹ̀ àrùn tó ń pa àwọn èèyàn yìí lè dáwọ́ dúró.”+ 22 Ṣùgbọ́n Áráúnà sọ fún Dáfídì pé: “Kí olúwa mi ọba mú un, kó sì fi ohun tó bá rí pé ó dára* rúbọ. Màlúù rèé fún ẹbọ sísun, ohun èlò ìpakà àti igi àjàgà sì rèé fún iná dídá. 23 Gbogbo nǹkan yìí ni èmi Áráúnà fún ọba.” Lẹ́yìn náà, Áráúnà sọ fún ọba pé: “Kí Jèhófà Ọlọ́run rẹ ṣojú rere sí ọ.”

24 Àmọ́ ọba sọ fún Áráúnà pé: “Rárá o, mo gbọ́dọ̀ rà á lọ́wọ́ rẹ ní iye kan. Mi ò ní rú ẹbọ sísun tí kò ná mi ní nǹkan kan sí Jèhófà Ọlọ́run mi.” Ni Dáfídì bá ra ibi ìpakà náà àti màlúù náà ní àádọ́ta (50) ṣékélì fàdákà.*+ 25 Dáfídì mọ pẹpẹ+ kan síbẹ̀ fún Jèhófà, ó sì rú àwọn ẹbọ sísun àti àwọn ẹbọ ìrẹ́pọ̀. Lẹ́yìn náà, Jèhófà gbọ́ ẹ̀bẹ̀ ilẹ̀ náà,+ àjàkálẹ̀ àrùn tó ń pa àwọn èèyàn Ísírẹ́lì sì dáwọ́ dúró.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́