ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 2 Kíróníkà 32
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé 2 Kíróníkà

      • Senakérúbù gbógun ti Jerúsálẹ́mù (1-8)

      • Senakérúbù pẹ̀gàn Jèhófà (9-19)

      • Áńgẹ́lì pa àwọn ọmọ ogun Ásíríà (20-23)

      • Àìsàn tó ṣe Hẹsikáyà àti ìgbéraga rẹ̀ (24-26)

      • Àwọn àṣeyọrí Hẹsikáyà àti ikú rẹ̀ (27-33)

2 Kíróníkà 32:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 31:20
  • +2Ọb 18:7, 13; Ais 36:1

2 Kíróníkà 32:3

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 20:20

2 Kíróníkà 32:5

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “Mílò.” Ọ̀rọ̀ Hébérù tó túmọ̀ sí “iyẹ̀pẹ̀ tí a kó jọ gègèrè.”

  • *

    Tàbí “ọṣẹ́.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 5:9; 1Ọb 9:24; 11:27; 2Ọb 12:20

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    6/15/1997, ojú ìwé 11

2 Kíróníkà 32:6

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “ó sì sọ̀rọ̀ sí ọkàn wọn.”

2 Kíróníkà 32:7

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 19:6
  • +Di 31:6, 8; Joṣ 1:6, 9; 2Ọb 6:16, 17; 2Kr 20:15

2 Kíróníkà 32:8

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “Apá tó jẹ́ ẹran ara ló wà pẹ̀lú rẹ̀.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 14:9; Di 20:1, 4; Joṣ 10:42; Jer 17:5
  • +2Kr 20:20

2 Kíróníkà 32:9

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “pẹ̀lú gbogbo àwọn ológun rẹ̀ àti ògo rẹ̀.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ais 37:8
  • +2Ọb 18:17; Ais 36:2

2 Kíróníkà 32:10

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 18:19; Ais 36:4

2 Kíróníkà 32:11

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 18:29, 30; 19:10

2 Kíróníkà 32:12

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “rẹ̀.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 18:1, 4
  • +2Kr 31:1
  • +2Ọb 18:22; Ais 36:7

2 Kíróníkà 32:13

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 15:29; 17:5; Ais 37:12
  • +2Ọb 18:33, 34; 19:17, 18

2 Kíróníkà 32:14

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 14:3; 15:9

2 Kíróníkà 32:15

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 18:29
  • +Ẹk 5:2; Di 32:27; Da 3:14, 15

2 Kíróníkà 32:17

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 19:14
  • +Ais 37:29
  • +2Ọb 17:6; 19:12

2 Kíróníkà 32:18

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 18:26, 28; Ais 36:11, 13

2 Kíróníkà 32:20

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 19:2, 20; Ais 37:2
  • +2Ọb 19:14, 15; 2Kr 14:11

2 Kíróníkà 32:21

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “tẹ́ńpìlì.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 76:5
  • +2Ọb 19:35-37; Ais 37:37, 38

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé-Ìṣọ́nà,

    6/1/1993, ojú ìwé 6

2 Kíróníkà 32:23

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 4:21; 2Kr 17:1, 5

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà, Apá Kìíní, ojú ìwé 396

2 Kíróníkà 32:24

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “fi ohun tó máa ṣẹlẹ̀ hàn án.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 20:1, 2; Ais 38:1, 2
  • +2Ọb 20:5, 9; 2Kr 32:31; Ais 38:8

2 Kíróníkà 32:25

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́),

    3/2017, ojú ìwé 26

    Ilé Ìṣọ́,

    10/15/2005, ojú ìwé 25

2 Kíróníkà 32:26

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 26:18, 19
  • +2Ọb 20:19

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà, Apá Kìíní, ojú ìwé 397

2 Kíróníkà 32:27

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 1:11, 12; 17:1, 5
  • +1Ọb 9:17-19

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà, Apá Kìíní, ojú ìwé 396

2 Kíróníkà 32:30

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 32:4
  • +1Ọb 1:33, 45
  • +2Sa 5:9

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    “Ilẹ̀ Dáradára,” ojú ìwé 20-21

    Ilé Ìṣọ́,

    6/15/1997, ojú ìwé 9-10

    8/15/1996, ojú ìwé 5-6

    Jí!,

    6/8/1996, ojú ìwé 29

2 Kíróníkà 32:31

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ohun tó máa ṣẹlẹ̀.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 20:8-11; Ais 38:8
  • +2Ọb 20:12; Ais 39:1
  • +Jẹ 22:1
  • +Di 8:2; Sm 7:9; 139:23

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́),

    3/2017, ojú ìwé 26

2 Kíróníkà 32:32

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 31:20, 21
  • +Ais 1:1
  • +2Ọb 20:20

2 Kíróníkà 32:33

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 11:43

Àwọn míì

2 Kíró. 32:12Kr 31:20
2 Kíró. 32:12Ọb 18:7, 13; Ais 36:1
2 Kíró. 32:32Ọb 20:20
2 Kíró. 32:52Sa 5:9; 1Ọb 9:24; 11:27; 2Ọb 12:20
2 Kíró. 32:72Ọb 19:6
2 Kíró. 32:7Di 31:6, 8; Joṣ 1:6, 9; 2Ọb 6:16, 17; 2Kr 20:15
2 Kíró. 32:8Nọ 14:9; Di 20:1, 4; Joṣ 10:42; Jer 17:5
2 Kíró. 32:82Kr 20:20
2 Kíró. 32:9Ais 37:8
2 Kíró. 32:92Ọb 18:17; Ais 36:2
2 Kíró. 32:102Ọb 18:19; Ais 36:4
2 Kíró. 32:112Ọb 18:29, 30; 19:10
2 Kíró. 32:122Ọb 18:1, 4
2 Kíró. 32:122Kr 31:1
2 Kíró. 32:122Ọb 18:22; Ais 36:7
2 Kíró. 32:132Ọb 15:29; 17:5; Ais 37:12
2 Kíró. 32:132Ọb 18:33, 34; 19:17, 18
2 Kíró. 32:14Ẹk 14:3; 15:9
2 Kíró. 32:152Ọb 18:29
2 Kíró. 32:15Ẹk 5:2; Di 32:27; Da 3:14, 15
2 Kíró. 32:172Ọb 19:14
2 Kíró. 32:17Ais 37:29
2 Kíró. 32:172Ọb 17:6; 19:12
2 Kíró. 32:182Ọb 18:26, 28; Ais 36:11, 13
2 Kíró. 32:202Ọb 19:2, 20; Ais 37:2
2 Kíró. 32:202Ọb 19:14, 15; 2Kr 14:11
2 Kíró. 32:21Sm 76:5
2 Kíró. 32:212Ọb 19:35-37; Ais 37:37, 38
2 Kíró. 32:231Ọb 4:21; 2Kr 17:1, 5
2 Kíró. 32:242Ọb 20:1, 2; Ais 38:1, 2
2 Kíró. 32:242Ọb 20:5, 9; 2Kr 32:31; Ais 38:8
2 Kíró. 32:26Jer 26:18, 19
2 Kíró. 32:262Ọb 20:19
2 Kíró. 32:272Kr 1:11, 12; 17:1, 5
2 Kíró. 32:271Ọb 9:17-19
2 Kíró. 32:302Kr 32:4
2 Kíró. 32:301Ọb 1:33, 45
2 Kíró. 32:302Sa 5:9
2 Kíró. 32:312Ọb 20:8-11; Ais 38:8
2 Kíró. 32:312Ọb 20:12; Ais 39:1
2 Kíró. 32:31Jẹ 22:1
2 Kíró. 32:31Di 8:2; Sm 7:9; 139:23
2 Kíró. 32:322Kr 31:20, 21
2 Kíró. 32:32Ais 1:1
2 Kíró. 32:322Ọb 20:20
2 Kíró. 32:331Ọb 11:43
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
  • 20
  • 21
  • 22
  • 23
  • 24
  • 25
  • 26
  • 27
  • 28
  • 29
  • 30
  • 31
  • 32
  • 33
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
2 Kíróníkà 32:1-33

Kíróníkà Kejì

32 Lẹ́yìn tí Hẹsikáyà ti fi òtítọ́ ṣe àwọn nǹkan yìí,+ Senakérúbù ọba Ásíríà wá, ó sì ya wọ Júdà. Ó dó ti àwọn ìlú olódi, ó fẹ́ wọlé kí ó sì gbà wọ́n.+

2 Nígbà tí Hẹsikáyà rí i pé Senakérúbù ti dé, tó sì fẹ́ gbéjà ko Jerúsálẹ́mù, 3 lẹ́yìn tó fọ̀rọ̀ lọ àwọn ìjòyè rẹ̀ àti àwọn jagunjagun rẹ̀, ó pinnu láti dí àwọn ìsun omi tó wà lóde ìlú náà pa,+ wọ́n sì ràn án lọ́wọ́. 4 Ọ̀pọ̀ èèyàn kóra jọ, wọ́n sì dí gbogbo ìsun omi pa àti odò tó ń ṣàn gba ilẹ̀ náà kọjá, wọ́n sọ pé: “A ò fẹ́ kí àwọn ọba Ásíríà rí omi lò nígbà tí wọ́n bá wá.”

5 Yàtọ̀ síyẹn, ó rí i dájú pé òun tún gbogbo ògiri tó wó lulẹ̀ mọ, ó sì kọ́ àwọn ilé gogoro lé e lórí, ó tún mọ ògiri míì síta. Bákan náà, ó ṣàtúnṣe Òkìtì*+ tó wà ní Ìlú Dáfídì, ó sì ṣe ohun ìjà* tó pọ̀ gan-an àti àwọn apata. 6 Lẹ́yìn náà, ó yan àwọn olórí ogun lé àwọn èèyàn náà lórí, ó kó wọn jọ sí ojúde ẹnubodè ìlú, ó sì fún wọn níṣìírí,* ó sọ pé: 7 “Ẹ jẹ́ onígboyà àti alágbára. Ẹ má bẹ̀rù, ẹ má sì jáyà nítorí ọba Ásíríà+ àti gbogbo ọ̀pọ̀ èèyàn tó wà pẹ̀lú rẹ̀, torí àwọn tó wà pẹ̀lú wa pọ̀ ju àwọn tó wà pẹ̀lú rẹ̀.+ 8 Agbára èèyàn ló gbẹ́kẹ̀ lé,* àmọ́ Jèhófà Ọlọ́run wa ló wà pẹ̀lú wa láti ràn wá lọ́wọ́, kó sì jà fún wa.”+ Ọ̀rọ̀ Hẹsikáyà ọba Júdà sì fún àwọn èèyàn náà lókun.+

9 Lẹ́yìn náà, nígbà tí Senakérúbù ọba Ásíríà wà ní Lákíṣì+ pẹ̀lú gbogbo ogun rẹ̀,* ó rán àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sí Jerúsálẹ́mù, sí Hẹsikáyà ọba Júdà àti sí gbogbo àwọn ará Jùdíà tó wà ní Jerúsálẹ́mù,+ ó sọ pé:

10 “Ohun tí Senakérúbù ọba Ásíríà sọ nìyí, ‘Kí lẹ gbẹ́kẹ̀ lé tí ẹ fi dúró sí Jerúsálẹ́mù nígbà tí a dó tì í?+ 11 Ṣé ẹ ò mọ̀ pé Hẹsikáyà ń ṣì yín lọ́nà ni, tó fẹ́ kí ìyàn àti òùngbẹ pa yín kú, bó ṣe ń sọ pé: “Jèhófà Ọlọ́run wa yóò gbà wá lọ́wọ́ ọba Ásíríà”?+ 12 Ṣé kì í ṣe Hẹsikáyà yìí ló mú àwọn ibi gíga+ Ọlọ́run yín* àti àwọn pẹpẹ Rẹ̀ + kúrò, tó wá sọ fún Júdà àti Jerúsálẹ́mù pé: “Iwájú pẹpẹ kan ṣoṣo ni kí ẹ ti máa forí balẹ̀, orí rẹ̀ sì ni kí ẹ ti máa mú àwọn ẹbọ yín rú èéfín”?+ 13 Ṣé ẹ kò mọ ohun tí èmi àti àwọn baba ńlá mi ṣe sí gbogbo àwọn èèyàn ilẹ̀ míì ni?+ Ṣé àwọn ọlọ́run àwọn orílẹ̀-èdè gba orílẹ̀-èdè wọn lọ́wọ́ mi ni?+ 14 Èwo nínú gbogbo ọlọ́run àwọn orílẹ̀-èdè tí àwọn baba ńlá mi pa run ló gba àwọn èèyàn rẹ̀ lọ́wọ́ mi, tí Ọlọ́run yín á fi lè gbà yín lọ́wọ́ mi?+ 15 Torí náà, ẹ má ṣe jẹ́ kí Hẹsikáyà fi èyí tàn yín jẹ tàbí kó ṣì yín lọ́nà!+ Ẹ má gbà á gbọ́, nítorí kò sí ọlọ́run orílẹ̀-èdè kankan tàbí ìjọba èyíkéyìí tó gba àwọn èèyàn rẹ̀ lọ́wọ́ mi àti lọ́wọ́ àwọn baba ńlá mi. Ká má ṣẹ̀ṣẹ̀ wá sọ ti Ọlọ́run yín pé á gbà yín lọ́wọ́ mi!’”+

16 Àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tiẹ̀ sọ ohun tó jù bẹ́ẹ̀ lọ sí Jèhófà Ọlọ́run tòótọ́ àti sí Hẹsikáyà ìránṣẹ́ rẹ̀. 17 Ó tún kọ àwọn lẹ́tà+ láti fi pẹ̀gàn Jèhófà Ọlọ́run Ísírẹ́lì+ àti láti fi sọ̀rọ̀ òdì sí i, ó ní: “Bí àwọn ọlọ́run àwọn orílẹ̀-èdè kò ṣe gba àwọn èèyàn wọn lọ́wọ́ mi,+ bẹ́ẹ̀ ni Ọlọ́run Hẹsikáyà kò ní gba àwọn èèyàn rẹ̀ lọ́wọ́ mi.” 18 Wọ́n gbóhùn sókè, wọ́n ń sọ̀rọ̀ ní èdè àwọn Júù sí àwọn èèyàn Jerúsálẹ́mù tó wà lórí ògiri, láti dẹ́rù bà wọ́n kí wọ́n sì kó jìnnìjìnnì bá wọn, kí wọ́n lè gba ìlú náà.+ 19 Wọ́n sọ̀rọ̀ sí Ọlọ́run Jerúsálẹ́mù bí wọ́n ṣe sọ̀rọ̀ sí àwọn ọlọ́run ará ayé, tí wọ́n jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ èèyàn. 20 Àmọ́ Ọba Hẹsikáyà àti wòlíì Àìsáyà+ ọmọ Émọ́ọ̀sì kò dákẹ́ àdúrà lórí ọ̀rọ̀ yìí, wọ́n sì ń ké pe Ọlọ́run lókè ọ̀run pé kó ran àwọn lọ́wọ́.+

21 Lẹ́yìn náà, Jèhófà rán áńgẹ́lì kan, ó sì pa gbogbo jagunjagun tó lákíkanjú + àti àwọn aṣáájú pẹ̀lú àwọn olórí nínú ibùdó ọba Ásíríà, tó fi di pé ìtìjú ló fi pa dà lọ sí ilẹ̀ rẹ̀. Nígbà tó yá, ó wọ ilé* ọlọ́run rẹ̀, ibẹ̀ ni àwọn kan lára àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì ti fi idà pa á.+ 22 Bí Jèhófà ṣe gba Hẹsikáyà àti àwọn tó ń gbé Jerúsálẹ́mù lọ́wọ́ Senakérúbù ọba Ásíríà nìyẹn àti lọ́wọ́ gbogbo àwọn yòókù, ó sì fún wọn ní ìsinmi kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá tó yí wọn ká. 23 Ọ̀pọ̀ èèyàn mú ẹ̀bùn wá fún Jèhófà ní Jerúsálẹ́mù, wọ́n sì mú àwọn ohun iyebíye wá fún Hẹsikáyà ọba Júdà,+ gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè sì ń bọ̀wọ̀ fún un gidigidi lẹ́yìn náà.

24 Ní àkókò náà, Hẹsikáyà ṣàìsàn dé ojú ikú, ó sì gbàdúrà sí Jèhófà.+ Ọlọ́run dá a lóhùn, ó sì fún un ní àmì kan.*+ 25 Àmọ́ Hẹsikáyà kò fi hàn pé òun mọyì ohun rere tó rí gbà, nítorí ìgbéraga ti wọ̀ ọ́ lẹ́wù, èyí sì fa ìbínú Ọlọ́run wá sórí rẹ̀ àti sórí Júdà àti Jerúsálẹ́mù. 26 Àmọ́, Hẹsikáyà rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀, ó sì mú ìgbéraga ọkàn rẹ̀ kúrò,+ òun àti àwọn tó ń gbé Jerúsálẹ́mù, ìbínú Jèhófà kò sì wá sórí wọn ní ìgbà ayé Hẹsikáyà.+

27 Hẹsikáyà wá ní ọrọ̀ tó pọ̀ gan-an àti ògo;+ ó ṣe àwọn ilé ìkẹ́rùsí+ fún ara rẹ̀ láti máa kó fàdákà sí àti wúrà pẹ̀lú àwọn òkúta iyebíye, òróró básámù, àwọn apata àti gbogbo àwọn ohun èlò tó ṣeyebíye. 28 Ó tún kọ́ àwọn ibi tó ń kó nǹkan pa mọ́ sí láti máa kó ọkà àti wáìnì tuntun pẹ̀lú òróró sínú wọn, bákan náà ó kọ́ àwọn ilé ẹran fún onírúurú ẹran ọ̀sìn àti fún àwọn agbo ẹran. 29 Ó tún kọ́ àwọn ìlú fún ara rẹ̀, ó sì ní ọ̀pọ̀ ẹran ọ̀sìn àti agbo ẹran pẹ̀lú ọ̀wọ́ ẹran, nítorí Ọlọ́run fún un ní ohun ìní tó pọ̀ gan-an. 30 Hẹsikáyà ló dí orísun omi+ Gíhónì+ tó wà lápá òkè pa, ó sì darí rẹ̀ tààràtà lọ sí ìwọ̀ oòrùn Ìlú Dáfídì.+ Hẹsikáyà ṣàṣeyọrí nínú gbogbo iṣẹ́ rẹ̀. 31 Àmọ́ nígbà tí wọ́n rán àwọn agbẹnusọ àwọn olórí Bábílónì sí i láti béèrè àmì*+ tó wáyé ní ilẹ̀ náà,+ Ọlọ́run tòótọ́ fi í sílẹ̀ láti dán an wò,+ kó lè mọ gbogbo ohun tó wà lọ́kàn rẹ̀.+

32 Ní ti ìyókù ìtàn Hẹsikáyà àti ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ tó fi hàn,+ wọ́n wà lákọsílẹ̀ nínú ìran wòlíì Àìsáyà,+ ọmọ Émọ́ọ̀sì, nínú Ìwé Àwọn Ọba Júdà àti Ísírẹ́lì.+ 33 Níkẹyìn, Hẹsikáyà sinmi pẹ̀lú àwọn baba ńlá rẹ̀, wọ́n sì sin ín síbi ìgòkè tó wà níbi tí wọ́n sin àwọn ọmọ Dáfídì sí;+ gbogbo Júdà àti àwọn tó ń gbé Jerúsálẹ́mù sì yẹ́ ẹ sí nígbà ìsìnkú rẹ̀. Mánásè ọmọ rẹ̀ sì jọba ní ipò rẹ̀.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́