ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Jóṣúà 10
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Jóṣúà

      • Ísírẹ́lì gbèjà Gíbíónì (1-7)

      • Jèhófà jà fún Ísírẹ́lì (8-15)

        • Òkúta yìnyín já bọ́ lu àwọn ọ̀tá tó ń sá lọ (11)

        • Oòrùn dúró sójú kan (12-14)

      • Wọ́n pa ọba márààrún tó gbéjà kò wọ́n (16-28)

      • Wọ́n gba àwọn ìlú tó wà ní gúúsù (29-43)

Jóṣúà 10:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 6:2, 21
  • +Joṣ 8:24, 29
  • +Joṣ 9:9, 15; 11:19

Jóṣúà 10:2

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 2:25; 11:25; Joṣ 2:10, 11; 5:1
  • +Joṣ 8:25

Jóṣúà 10:3

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 23:2; Nọ 13:22
  • +Joṣ 12:7, 10-12

Jóṣúà 10:4

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 9:9, 15; 11:19

Jóṣúà 10:5

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 15:16

Jóṣúà 10:6

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “Má dẹ ọwọ́ rẹ lọ́dọ̀ àwa ẹrú rẹ.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 5:10
  • +Joṣ 9:25, 27

Jóṣúà 10:7

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 8:3

Jóṣúà 10:8

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 3:2; 20:1
  • +Di 7:24; Joṣ 11:6
  • +Joṣ 1:3-5

Jóṣúà 10:10

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 44:3

Jóṣúà 10:12

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “Pẹ̀tẹ́lẹ̀.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 20:10; Sm 135:6; Ais 38:8
  • +Ais 28:21

Jóṣúà 10:13

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 1:17, 18

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    3/15/2009, ojú ìwé 32

    12/1/2004, ojú ìwé 11

Jóṣúà 10:14

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 9:18, 19; 1Ọb 17:22; Jem 5:16
  • +Di 1:30; Joṣ 23:3

Jóṣúà 10:15

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 5:10; 9:6

Jóṣúà 10:16

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 10:10

Jóṣúà 10:17

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 10:28

Jóṣúà 10:19

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 28:7

Jóṣúà 10:21

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “pọ́n ahọ́n rẹ̀.”

Jóṣúà 10:23

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 10:3-5; 12:7, 10-12

Jóṣúà 10:24

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 23:27

Jóṣúà 10:25

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 31:6; Joṣ 1:9
  • +Di 3:21; 7:18, 19

Jóṣúà 10:26

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “igi.”

Jóṣúà 10:27

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 21:22, 23; Joṣ 8:29

Jóṣúà 10:28

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ọkàn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 10:10; 15:20, 41
  • +Di 20:16
  • +Joṣ 12:7, 16

Jóṣúà 10:29

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 15:20, 42; 21:13

Jóṣúà 10:30

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ọkàn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 12:7, 15
  • +Joṣ 6:2, 21

Jóṣúà 10:31

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 10:3, 4; 12:7, 11; 15:20, 39

Jóṣúà 10:32

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ọkàn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 20:16

Jóṣúà 10:33

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 12:7, 12; 16:10; 21:20, 21; 1Ọb 9:16

Jóṣúà 10:34

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 10:3, 4; 12:7, 12; 15:20, 39

Jóṣúà 10:35

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ọkàn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 20:16; Joṣ 10:32

Jóṣúà 10:36

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 13:18; 23:19; Nọ 13:22; Joṣ 10:3, 4; 15:13; 21:13

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àwọn Ìtẹ̀jáde Tá A Tọ́ka sí Nínú Ìwé Ìpàdé, 9/2021,

Jóṣúà 10:37

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ọkàn.”

  • *

    Tàbí “ọkàn.”

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àwọn Ìtẹ̀jáde Tá A Tọ́ka sí Nínú Ìwé Ìpàdé, 9/2021,

Jóṣúà 10:38

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 12:7, 13; 15:15

Jóṣúà 10:39

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ọkàn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 7:2
  • +Joṣ 11:14

Jóṣúà 10:40

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 9:1, 2; Ond 1:9
  • +Le 27:29; Di 20:16; Joṣ 11:14
  • +Di 7:2; 9:5

Jóṣúà 10:41

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 34:2, 4; Di 9:23
  • +Di 2:23
  • +Joṣ 15:20, 51
  • +Joṣ 11:16, 19

Jóṣúà 10:42

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 14:14; Di 1:30

Jóṣúà 10:43

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 4:19

Àwọn míì

Jóṣ. 10:1Joṣ 6:2, 21
Jóṣ. 10:1Joṣ 8:24, 29
Jóṣ. 10:1Joṣ 9:9, 15; 11:19
Jóṣ. 10:2Di 2:25; 11:25; Joṣ 2:10, 11; 5:1
Jóṣ. 10:2Joṣ 8:25
Jóṣ. 10:3Jẹ 23:2; Nọ 13:22
Jóṣ. 10:3Joṣ 12:7, 10-12
Jóṣ. 10:4Joṣ 9:9, 15; 11:19
Jóṣ. 10:5Jẹ 15:16
Jóṣ. 10:6Joṣ 5:10
Jóṣ. 10:6Joṣ 9:25, 27
Jóṣ. 10:7Joṣ 8:3
Jóṣ. 10:8Di 3:2; 20:1
Jóṣ. 10:8Di 7:24; Joṣ 11:6
Jóṣ. 10:8Joṣ 1:3-5
Jóṣ. 10:10Sm 44:3
Jóṣ. 10:122Ọb 20:10; Sm 135:6; Ais 38:8
Jóṣ. 10:12Ais 28:21
Jóṣ. 10:132Sa 1:17, 18
Jóṣ. 10:14Di 9:18, 19; 1Ọb 17:22; Jem 5:16
Jóṣ. 10:14Di 1:30; Joṣ 23:3
Jóṣ. 10:15Joṣ 5:10; 9:6
Jóṣ. 10:16Joṣ 10:10
Jóṣ. 10:17Joṣ 10:28
Jóṣ. 10:19Di 28:7
Jóṣ. 10:23Joṣ 10:3-5; 12:7, 10-12
Jóṣ. 10:24Ẹk 23:27
Jóṣ. 10:25Di 31:6; Joṣ 1:9
Jóṣ. 10:25Di 3:21; 7:18, 19
Jóṣ. 10:27Di 21:22, 23; Joṣ 8:29
Jóṣ. 10:28Joṣ 10:10; 15:20, 41
Jóṣ. 10:28Di 20:16
Jóṣ. 10:28Joṣ 12:7, 16
Jóṣ. 10:29Joṣ 15:20, 42; 21:13
Jóṣ. 10:30Joṣ 12:7, 15
Jóṣ. 10:30Joṣ 6:2, 21
Jóṣ. 10:31Joṣ 10:3, 4; 12:7, 11; 15:20, 39
Jóṣ. 10:32Di 20:16
Jóṣ. 10:33Joṣ 12:7, 12; 16:10; 21:20, 21; 1Ọb 9:16
Jóṣ. 10:34Joṣ 10:3, 4; 12:7, 12; 15:20, 39
Jóṣ. 10:35Di 20:16; Joṣ 10:32
Jóṣ. 10:36Jẹ 13:18; 23:19; Nọ 13:22; Joṣ 10:3, 4; 15:13; 21:13
Jóṣ. 10:38Joṣ 12:7, 13; 15:15
Jóṣ. 10:39Di 7:2
Jóṣ. 10:39Joṣ 11:14
Jóṣ. 10:40Joṣ 9:1, 2; Ond 1:9
Jóṣ. 10:40Le 27:29; Di 20:16; Joṣ 11:14
Jóṣ. 10:40Di 7:2; 9:5
Jóṣ. 10:41Nọ 34:2, 4; Di 9:23
Jóṣ. 10:41Di 2:23
Jóṣ. 10:41Joṣ 15:20, 51
Jóṣ. 10:41Joṣ 11:16, 19
Jóṣ. 10:42Ẹk 14:14; Di 1:30
Jóṣ. 10:43Joṣ 4:19
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
  • 20
  • 21
  • 22
  • 23
  • 24
  • 25
  • 26
  • 27
  • 28
  • 29
  • 30
  • 31
  • 32
  • 33
  • 34
  • 35
  • 36
  • 37
  • 38
  • 39
  • 40
  • 41
  • 42
  • 43
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Jóṣúà 10:1-43

Jóṣúà

10 Gbàrà tí Adoni-sédékì ọba Jerúsálẹ́mù gbọ́ pé Jóṣúà ti gba Áì, tó sì ti pa á run, tó ṣe ohun tó ṣe fún Jẹ́ríkò àti ọba rẹ̀+ gẹ́lẹ́ sí Áì àti ọba rẹ̀+ àti bí àwọn tó ń gbé Gíbíónì ṣe bá Ísírẹ́lì ṣàdéhùn+ àlàáfíà, tí wọ́n sì wá ń gbé ní àárín wọn, 2 ẹ̀rù bà á gidigidi,+ torí pé ìlú ńlá ni Gíbíónì, ó dà bí ọ̀kan lára àwọn ìlú ọba. Ó tóbi ju ìlú Áì lọ,+ jagunjagun sì ni gbogbo àwọn ọkùnrin ibẹ̀. 3 Adoni-sédékì ọba Jerúsálẹ́mù wá ránṣẹ́ sí Hóhámù ọba Hébúrónì,+ Pírámù ọba Jámútì, Jáfíà ọba Lákíṣì àti Débírì ọba Ẹ́gílónì+ pé: 4 “Ẹ wá ràn mí lọ́wọ́, ká lè jọ gbógun ja Gíbíónì, torí ó ti bá Jóṣúà àti àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ṣe àdéhùn àlàáfíà.”+ 5 Ni àwọn ọba Ámórì+ márààrún bá kóra jọ pẹ̀lú àwọn ọmọ ogun wọn, ìyẹn ọba Jerúsálẹ́mù, ọba Hébúrónì, ọba Jámútì, ọba Lákíṣì àti ọba Ẹ́gílónì, wọ́n sì lọ pàgọ́ ti Gíbíónì láti bá a jà.

6 Àwọn ará Gíbíónì wá ránṣẹ́ sí Jóṣúà ní ibùdó tó wà ní Gílígálì+ pé: “Má fi àwa ẹrú rẹ sílẹ̀.*+ Tètè máa bọ̀! Wá gbà wá, kí o sì ràn wá lọ́wọ́! Gbogbo àwọn ọba Ámórì láti agbègbè olókè ti kóra jọ láti bá wa jà.” 7 Jóṣúà bá gbéra láti Gílígálì, òun àti gbogbo ọkùnrin ogun pẹ̀lú àwọn jagunjagun tó lákíkanjú.+

8 Jèhófà sì sọ fún Jóṣúà pé: “Má bẹ̀rù wọn,+ torí mo ti fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́.+ Ìkankan nínú wọn ò ní lè dojú kọ ọ́.”+ 9 Òjijì ni Jóṣúà dé láti bá wọn jà lẹ́yìn tó ti fi gbogbo òru rìn wá láti Gílígálì. 10 Jèhófà da àárín wọn rú níwájú Ísírẹ́lì,+ wọ́n sì pa wọ́n lọ rẹpẹtẹ ní Gíbíónì, wọ́n lé wọn gba ọ̀nà tí wọ́n ń gbà gòkè lọ sí Bẹti-hórónì, wọ́n sì ń pa wọ́n títí lọ dé Ásékà àti Mákédà. 11 Bí wọ́n ṣe ń sá fún Ísírẹ́lì, tí wọ́n sì wà níbi gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Bẹti-hórónì, Jèhófà rọ̀jò òkúta yìnyín ńláńlá lé wọn lórí láti ọ̀run, ó ń rọ̀ lé wọn lórí títí dé Ásékà, wọ́n sì ṣègbé. Kódà, àwọn tí yìnyín náà pa pọ̀ ju àwọn tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì fi idà pa lọ.

12 Lọ́jọ́ tí Jèhófà ṣẹ́gun àwọn Ámórì níṣojú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, ìgbà yẹn ni Jóṣúà sọ fún Jèhófà níṣojú Ísírẹ́lì pé:

“Oòrùn, dúró sójú kan+ lórí Gíbíónì,+

Àti òṣùpá, lórí Àfonífojì* Áíjálónì!”

13 Bí oòrùn ṣe dúró sójú kan nìyẹn, òṣùpá ò sì kúrò títí orílẹ̀-èdè náà fi gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá rẹ̀. Ṣebí wọ́n kọ ọ́ sínú ìwé Jáṣárì?+ Oòrùn dúró sójú kan ní àárín ojú ọ̀run, kò sì tètè wọ̀ fún nǹkan bí odindi ọjọ́ kan. 14 Kò tíì sí ọjọ́ kankan bí ọjọ́ yìí, ṣáájú rẹ̀ tàbí lẹ́yìn rẹ̀, tí Jèhófà fetí sí ohùn èèyàn,+ torí Jèhófà ń jà fún Ísírẹ́lì.+

15 Lẹ́yìn náà, Jóṣúà àti gbogbo Ísírẹ́lì pa dà sí Gílígálì tí wọ́n pàgọ́ sí.+

16 Àmọ́ àwọn ọba márààrún sá lọ, wọ́n sì lọ fara pa mọ́ sí inú ihò àpáta ní Mákédà.+ 17 Àwọn kan wá sọ fún Jóṣúà pé: “A ti rí àwọn ọba márààrún tí wọ́n fara pa mọ́ sí inú ihò àpáta ní Mákédà.”+ 18 Jóṣúà wá sọ pé: “Ẹ yí àwọn òkúta ńlá sí ẹnu ihò náà, kí ẹ sì yan àwọn ọkùnrin tí á máa ṣọ́ wọn. 19 Àmọ́ ẹ̀yin tó kù ò gbọ́dọ̀ dáwọ́ dúró. Ẹ lé àwọn ọ̀tá yín, kí ẹ sì máa ṣá wọn balẹ̀ láti ẹ̀yìn.+ Ẹ má ṣe jẹ́ kí wọ́n wọnú àwọn ìlú wọn, torí Jèhófà Ọlọ́run yín ti fi wọ́n lé yín lọ́wọ́.”

20 Lẹ́yìn tí Jóṣúà àti àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ti pa wọ́n lọ rẹpẹtẹ, débi pé wọ́n pa wọ́n run, àfi àwọn kan tó sá lọ sí àwọn ìlú olódi, 21 gbogbo àwọn èèyàn náà pa dà sọ́dọ̀ Jóṣúà ní ibùdó tó wà ní Mákédà, ohunkóhun ò sì ṣe wọ́n. Kò sẹ́ni tó gbójúgbóyà láti sọ̀rọ̀ kankan* sí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì. 22 Jóṣúà wá sọ pé: “Ẹ ṣí ihò náà, kí ẹ sì mú àwọn ọba márààrún jáde látinú ihò wá bá mi.” 23 Wọ́n mú àwọn ọba márààrún yìí jáde wá bá a látinú ihò náà: ọba Jerúsálẹ́mù, ọba Hébúrónì, ọba Jámútì, ọba Lákíṣì àti ọba Ẹ́gílónì.+ 24 Nígbà tí wọ́n mú àwọn ọba yìí dé ọ̀dọ̀ Jóṣúà, ó pe gbogbo ọkùnrin Ísírẹ́lì, ó sì sọ fún àwọn ọ̀gágun nínú àwọn ọkùnrin ogun tó bá a lọ pé: “Ẹ bọ́ síwájú. Ẹ gbé ẹsẹ̀ yín lé ẹ̀yìn ọrùn àwọn ọba yìí.” Wọ́n wá bọ́ síwájú, wọ́n sì gbé ẹsẹ̀ wọn lé ẹ̀yìn ọrùn wọn.+ 25 Lẹ́yìn náà, Jóṣúà sọ fún wọn pé: “Ẹ má bẹ̀rù, ẹ má sì jáyà.+ Ẹ jẹ́ onígboyà àti alágbára, torí ohun tí Jèhófà máa ṣe sí gbogbo àwọn ọ̀tá yín tí ẹ̀ ń bá jà nìyí.”+

26 Jóṣúà wá ṣá wọn balẹ̀, ó sì pa wọ́n, ó gbé wọn kọ́ sórí òpó* márùn-ún, wọ́n sì wà lórí òpó náà títí di ìrọ̀lẹ́. 27 Nígbà tí oòrùn wọ̀, Jóṣúà pàṣẹ pé kí wọ́n gbé wọn kúrò lórí òpó+ kí wọ́n sì jù wọ́n sí inú ihò àpáta tí wọ́n fara pa mọ́ sí. Wọ́n wá yí àwọn òkúta ńlá sí ẹnu ihò náà, ó sì wà bẹ́ẹ̀ títí di òní olónìí.

28 Jóṣúà gba Mákédà+ ní ọjọ́ yẹn, ó sì fi idà pa á run. Ó pa ọba rẹ̀ àti gbogbo àwọn* tó ń gbé ibẹ̀ run, kò ṣẹ́ ẹnì kankan kù.+ Ohun tó ṣe sí ọba Jẹ́ríkò gẹ́lẹ́ ló ṣe sí ọba Mákédà.+

29 Jóṣúà àti gbogbo Ísírẹ́lì wá kúrò ní Mákédà lọ sí Líbínà, wọ́n sì bá Líbínà+ jà. 30 Jèhófà tún fi ìlú náà àti ọba rẹ̀+ lé Ísírẹ́lì lọ́wọ́, wọ́n sì fi idà pa ìlú náà run àti gbogbo àwọn* tó ń gbé ibẹ̀, wọn ò ṣẹ́ ẹnì kankan kù níbẹ̀. Ohun tí wọ́n ṣe sí ọba Jẹ́ríkò+ gẹ́lẹ́ ni wọ́n ṣe sí ọba ìlú náà.

31 Lẹ́yìn náà, Jóṣúà àti gbogbo Ísírẹ́lì kúrò ní Líbínà lọ sí Lákíṣì,+ wọ́n pàgọ́ tì í, wọ́n sì bá a jà. 32 Jèhófà fi Lákíṣì lé Ísírẹ́lì lọ́wọ́, wọ́n sì gbà á ní ọjọ́ kejì. Wọ́n fi idà pa ìlú náà run àti gbogbo àwọn* tó ń gbé ibẹ̀,+ bí wọ́n ṣe ṣe sí Líbínà gẹ́lẹ́.

33 Hórámù ọba Gésérì+ wá lọ ran Lákíṣì lọ́wọ́, àmọ́ Jóṣúà pa òun àtàwọn èèyàn rẹ̀ láìku ẹnì kan.

34 Lẹ́yìn náà, Jóṣúà àti gbogbo Ísírẹ́lì kúrò ní Lákíṣì lọ sí Ẹ́gílónì,+ wọ́n pàgọ́ tì í, wọ́n sì bá a jà. 35 Wọ́n gbà á ní ọjọ́ yẹn, wọ́n sì fi idà pa á run. Wọ́n pa gbogbo àwọn* tó ń gbé ibẹ̀ run lọ́jọ́ yẹn, bí wọ́n ṣe ṣe sí Lákíṣì gẹ́lẹ́.+

36 Lẹ́yìn náà, Jóṣúà àti gbogbo Ísírẹ́lì kúrò ní Ẹ́gílónì lọ sí Hébúrónì,+ wọ́n sì bá a jà. 37 Wọ́n gbà á, wọ́n sì fi idà pa á run, pẹ̀lú ọba rẹ̀, àwọn ìlú rẹ̀ àti gbogbo àwọn* tó ń gbé ibẹ̀, wọn ò ṣẹ́ ẹnì kankan kù. Ó pa Hébúrónì àti gbogbo àwọn* tó ń gbé ibẹ̀ run bó ṣe ṣe sí Ẹ́gílónì gẹ́lẹ́.

38 Níkẹyìn, Jóṣúà àti gbogbo Ísírẹ́lì ṣẹ́rí pa dà, wọ́n sì lọ bá Débírì+ jà. 39 Ó gba ibẹ̀, ọba rẹ̀ àti gbogbo ìlú rẹ̀, wọ́n sì fi idà pa wọ́n, wọ́n pa gbogbo àwọn* tó ń gbé ibẹ̀ run,+ wọn ò ṣẹ́ ẹnì kankan kù.+ Ohun tó ṣe sí Hébúrónì àti Líbínà àti ọba rẹ̀ náà ló ṣe sí Débírì àti ọba rẹ̀.

40 Jóṣúà ṣẹ́gun gbogbo ilẹ̀ tó wà ní agbègbè olókè, Négébù, Ṣẹ́fẹ́là,+ àwọn gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ àti gbogbo ọba wọn, kò ṣẹ́ ẹnì kankan kù; ó pa gbogbo ohun eléèémí run,+ bí Jèhófà Ọlọ́run Ísírẹ́lì ṣe pa á láṣẹ gẹ́lẹ́.+ 41 Jóṣúà ṣẹ́gun wọn láti Kadeṣi-báníà+ títí dé Gásà+ àti gbogbo ilẹ̀ Góṣénì+ títí dé Gíbíónì.+ 42 Ìgbà kan náà ni Jóṣúà ṣẹ́gun àwọn ọba yìí àti gbogbo ilẹ̀ wọn, torí Jèhófà Ọlọ́run Ísírẹ́lì ló ń jà fún Ísírẹ́lì.+ 43 Lẹ́yìn náà, Jóṣúà àti gbogbo Ísírẹ́lì pa dà sí ibùdó ní Gílígálì.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́