ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 1 Sámúẹ́lì 25
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé 1 Sámúẹ́lì

      • Ikú Sámúẹ́lì (1)

      • Nábálì kan àwọn ọkùnrin Dáfídì lábùkù (2-13)

      • Ábígẹ́lì hùwà ọgbọ́n (14-35)

        • ‘Àpò ìwàláàyè lọ́dọ̀ Jèhófà’ (29)

      • Jèhófà kọ lu Nábálì tó jẹ́ òmùgọ̀ (36-38)

      • Ábígẹ́lì di ìyàwó Dáfídì (39-44)

1 Sámúẹ́lì 25:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 1:20; 2:18; 3:20; Sm 99:6
  • +1Sa 7:15, 17

1 Sámúẹ́lì 25:2

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ìlú kan ní Júdà; ó yàtọ̀ sí Òkè Kámẹ́lì.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 23:24
  • +Joṣ 15:20, 55

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ, ojú ìwé 77-78

    Ilé Ìṣọ́,

    7/1/2009, ojú ìwé 19

1 Sámúẹ́lì 25:3

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 25:25
  • +1Sa 27:3
  • +Nọ 13:6; 32:11, 12
  • +1Sa 25:17, 21

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ, ojú ìwé 76-77

    Ilé Ìṣọ́,

    7/1/2009, ojú ìwé 18-19

1 Sámúẹ́lì 25:6

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “Kí o ní àlàáfíà.”

1 Sámúẹ́lì 25:7

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 25:14-16

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ, ojú ìwé 78

    Ilé Ìṣọ́,

    7/1/2009, ojú ìwé 19

1 Sámúẹ́lì 25:8

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “ọjọ́ rere.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 15:7

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ, ojú ìwé 78

    Ilé Ìṣọ́,

    7/1/2009, ojú ìwé 19

1 Sámúẹ́lì 25:10

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 22:2

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àwọn Ìtẹ̀jáde Tá A Tọ́ka sí Nínú Ìwé Ìpàdé, 6/2020, ojú ìwé 7

    Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ, ojú ìwé 78-79

    Ilé Ìṣọ́,

    7/1/2009, ojú ìwé 19-20

1 Sámúẹ́lì 25:11

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ, ojú ìwé 78-79

    Ilé Ìṣọ́,

    7/1/2009, ojú ìwé 19-20

1 Sámúẹ́lì 25:13

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 37:8; Owe 15:1; Onw 7:9

1 Sámúẹ́lì 25:14

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 25:10

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ, ojú ìwé 76-77, 78-79

    Ilé Ìṣọ́,

    7/1/2009, ojú ìwé 18-20

1 Sámúẹ́lì 25:15

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 25:7

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ, ojú ìwé 78

    Ilé Ìṣọ́,

    7/1/2009, ojú ìwé 19

1 Sámúẹ́lì 25:16

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ, ojú ìwé 78

    Ilé Ìṣọ́,

    7/1/2009, ojú ìwé 19

1 Sámúẹ́lì 25:17

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “aláìdára fún ohunkóhun.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 25:13
  • +1Sa 25:3

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ, ojú ìwé 79

    Ilé Ìṣọ́,

    7/1/2009, ojú ìwé 20

1 Sámúẹ́lì 25:18

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Síà kan jẹ́ Lítà 7.33. Wo Àfikún B14.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 25:3
  • +2Sa 16:1; 17:27-29

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ, ojú ìwé 79-80

    Ilé Ìṣọ́,

    7/1/2009, ojú ìwé 20

1 Sámúẹ́lì 25:19

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    7/1/2009, ojú ìwé 20

1 Sámúẹ́lì 25:21

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 25:7
  • +1Sa 25:10; Sm 35:12

1 Sámúẹ́lì 25:22

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí kó jẹ́, “lára Dáfídì.”

  • *

    Ní Héb., “ẹnikẹ́ni tó ń tọ̀ sára ògiri.” Ọ̀rọ̀ Hébérù tí wọ́n fi ń pẹ̀gàn àwọn ọkùnrin.

1 Sámúẹ́lì 25:24

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    11/1/2002, ojú ìwé 4-5

1 Sámúẹ́lì 25:25

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ó túmọ̀ sí “Òmùgọ̀; Òpònú.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 25:17

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ, ojú ìwé 80

    Ilé Ìṣọ́,

    7/1/2009, ojú ìwé 20-21

1 Sámúẹ́lì 25:26

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ọkàn rẹ.”

  • *

    Tàbí “gba ara rẹ là.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 20:6
  • +Jẹ 9:6

1 Sámúẹ́lì 25:27

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “ìbùkún.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 22:2; 25:13
  • +1Sa 25:18

1 Sámúẹ́lì 25:28

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 15:28; 2Sa 7:8, 11; 1Ọb 9:5
  • +1Sa 17:45; 18:17
  • +1Sa 24:11; 1Ọb 15:5

1 Sámúẹ́lì 25:29

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ọkàn.”

  • *

    Tàbí “ọkàn.”

  • *

    Tàbí “ọkàn.”

  • *

    Tàbí “ta òkúta láti inú kànnàkànnà.”

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé-Ìṣọ́nà,

    6/15/1991, ojú ìwé 14

1 Sámúẹ́lì 25:30

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 13:13, 14; 23:17; 2Sa 6:21; 7:8; Sm 89:20

1 Sámúẹ́lì 25:31

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “ta gọ̀ọ́gọ̀ọ́ tàbí kọsẹ̀.”

  • *

    Tàbí “gba ara rẹ là.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 32:35; 1Sa 24:15

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ, ojú ìwé 80

    Ilé Ìṣọ́,

    7/1/2009, ojú ìwé 20-21

1 Sámúẹ́lì 25:33

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “gba ara mi là.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 19:10; 1Sa 25:26

1 Sámúẹ́lì 25:34

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “ẹnikẹ́ni tó ń tọ̀ sára ògiri.” Ọ̀rọ̀ Hébérù tí wọ́n fi ń pẹ̀gàn àwọn ọkùnrin.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 25:24
  • +1Sa 25:18
  • +1Sa 25:22

1 Sámúẹ́lì 25:36

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “ọkàn Nábálì.”

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ, ojú ìwé 80-82

    Ilé Ìṣọ́,

    7/1/2009, ojú ìwé 21

1 Sámúẹ́lì 25:37

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ, ojú ìwé 82

    Ilé Ìṣọ́,

    7/1/2009, ojú ìwé 21

1 Sámúẹ́lì 25:38

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ, ojú ìwé 82

    Ilé Ìṣọ́,

    7/1/2009, ojú ìwé 21

1 Sámúẹ́lì 25:39

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 24:15; Sm 35:1
  • +1Sa 25:10, 14
  • +1Sa 25:34

1 Sámúẹ́lì 25:41

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 18:3, 4; Lk 7:44

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ, ojú ìwé 82

    Ilé Ìṣọ́,

    7/1/2009, ojú ìwé 21

1 Sámúẹ́lì 25:42

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 25:3

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ, ojú ìwé 82-83

    Ilé Ìṣọ́,

    7/1/2009, ojú ìwé 21

1 Sámúẹ́lì 25:43

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 27:3; 2Sa 3:2; 1Kr 3:1
  • +Joṣ 15:20, 56
  • +1Sa 30:5; 2Sa 5:13

1 Sámúẹ́lì 25:44

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 18:20
  • +2Sa 3:14, 15

Àwọn míì

1 Sám. 25:11Sa 1:20; 2:18; 3:20; Sm 99:6
1 Sám. 25:11Sa 7:15, 17
1 Sám. 25:21Sa 23:24
1 Sám. 25:2Joṣ 15:20, 55
1 Sám. 25:31Sa 25:25
1 Sám. 25:31Sa 27:3
1 Sám. 25:3Nọ 13:6; 32:11, 12
1 Sám. 25:31Sa 25:17, 21
1 Sám. 25:71Sa 25:14-16
1 Sám. 25:8Di 15:7
1 Sám. 25:101Sa 22:2
1 Sám. 25:13Sm 37:8; Owe 15:1; Onw 7:9
1 Sám. 25:141Sa 25:10
1 Sám. 25:151Sa 25:7
1 Sám. 25:171Sa 25:13
1 Sám. 25:171Sa 25:3
1 Sám. 25:181Sa 25:3
1 Sám. 25:182Sa 16:1; 17:27-29
1 Sám. 25:211Sa 25:7
1 Sám. 25:211Sa 25:10; Sm 35:12
1 Sám. 25:251Sa 25:17
1 Sám. 25:26Jẹ 20:6
1 Sám. 25:26Jẹ 9:6
1 Sám. 25:271Sa 22:2; 25:13
1 Sám. 25:271Sa 25:18
1 Sám. 25:281Sa 15:28; 2Sa 7:8, 11; 1Ọb 9:5
1 Sám. 25:281Sa 17:45; 18:17
1 Sám. 25:281Sa 24:11; 1Ọb 15:5
1 Sám. 25:301Sa 13:13, 14; 23:17; 2Sa 6:21; 7:8; Sm 89:20
1 Sám. 25:31Di 32:35; 1Sa 24:15
1 Sám. 25:33Di 19:10; 1Sa 25:26
1 Sám. 25:341Sa 25:24
1 Sám. 25:341Sa 25:18
1 Sám. 25:341Sa 25:22
1 Sám. 25:391Sa 24:15; Sm 35:1
1 Sám. 25:391Sa 25:10, 14
1 Sám. 25:391Sa 25:34
1 Sám. 25:41Jẹ 18:3, 4; Lk 7:44
1 Sám. 25:421Sa 25:3
1 Sám. 25:431Sa 27:3; 2Sa 3:2; 1Kr 3:1
1 Sám. 25:43Joṣ 15:20, 56
1 Sám. 25:431Sa 30:5; 2Sa 5:13
1 Sám. 25:441Sa 18:20
1 Sám. 25:442Sa 3:14, 15
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
  • 20
  • 21
  • 22
  • 23
  • 24
  • 25
  • 26
  • 27
  • 28
  • 29
  • 30
  • 31
  • 32
  • 33
  • 34
  • 35
  • 36
  • 37
  • 38
  • 39
  • 40
  • 41
  • 42
  • 43
  • 44
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
1 Sámúẹ́lì 25:1-44

Sámúẹ́lì Kìíní

25 Nígbà tó yá, Sámúẹ́lì+ kú; gbogbo Ísírẹ́lì kóra jọ kí wọ́n lè ṣọ̀fọ̀ rẹ̀, kí wọ́n sì sin ín sí ilé rẹ̀ ní Rámà.+ Ìgbà náà ni Dáfídì gbéra, ó sì lọ sí aginjù Páránì.

2 Ọkùnrin kan wà ní Máónì+ tó ń ṣiṣẹ́ ní Kámẹ́lì.*+ Ọkùnrin náà ní ọrọ̀ gan-an; ó ní ẹgbẹ̀rún mẹ́ta (3,000) àgùntàn àti ẹgbẹ̀rún kan (1,000) ewúrẹ́, ó sì ń rẹ́ irun àgùntàn rẹ̀ ní Kámẹ́lì. 3 Orúkọ ọkùnrin náà ni Nábálì,+ ìyàwó rẹ̀ sì ń jẹ́ Ábígẹ́lì.+ Ìyàwó yìí ní òye, ó sì rẹwà, ṣùgbọ́n ọkọ rẹ̀ tó jẹ́ ọmọ Kélẹ́bù+ le, ìwà rẹ̀ sì burú.+ 4 Dáfídì gbọ́ ní aginjù pé Nábálì ń rẹ́ irun àgùntàn rẹ̀. 5 Torí náà, Dáfídì rán ọ̀dọ́kùnrin mẹ́wàá sí i, Dáfídì sì sọ fún àwọn ọ̀dọ́kùnrin náà pé: “Ẹ lọ sí Kámẹ́lì, tí ẹ bá ti dé ọ̀dọ̀ Nábálì, kí ẹ sọ pé mo ní, ṣé àlàáfíà ni ó wà? 6 Lẹ́yìn náà, ẹ sọ pé, ‘Kí ẹ̀mí rẹ gùn,* kí àlàáfíà máa bá ìwọ àti agbo ilé rẹ gbé, kí gbogbo ohun tí o ní sì wà ní àlàáfíà. 7 Mo gbọ́ pé ò ń rẹ́ irun àwọn àgùntàn rẹ. Nígbà tí àwọn olùṣọ́ àgùntàn rẹ wà lọ́dọ̀ wa, a ò pa wọ́n lára,+ kò sì sí nǹkan wọn tó sọ nù ní gbogbo ìgbà tí wọ́n fi wà ní Kámẹ́lì. 8 Béèrè lọ́wọ́ àwọn ọ̀dọ́kùnrin rẹ, wọ́n á sì sọ fún ọ. Kí àwọn ọ̀dọ́kùnrin mi rí ojú rere rẹ, nítorí pé àkókò ayọ̀* ni a wá. Jọ̀wọ́ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ àti Dáfídì ọmọ rẹ ní ohunkóhun tí o bá lè yọ̀ǹda.’”+

9 Ni àwọn ọ̀dọ́kùnrin Dáfídì bá lọ sọ gbogbo ọ̀rọ̀ yìí fún Nábálì ní orúkọ Dáfídì. Nígbà tí wọ́n parí ọ̀rọ̀ wọn, 10 Nábálì dá àwọn ìránṣẹ́ Dáfídì lóhùn pé: “Ta ni Dáfídì, ta sì ni ọmọ Jésè? Lóde òní, ọ̀pọ̀ àwọn ìránṣẹ́ ló ń sá kúrò lọ́dọ̀ ọ̀gá wọn.+ 11 Ṣé oúnjẹ mi àti omi mi àti ẹran tí mo pa fún àwọn tó ń bá mi rẹ́ irun àgùntàn ni kí n wá fún àwọn ọkùnrin tí mi ò mọ ibi tí wọ́n ti wá?”

12 Àwọn ọ̀dọ́kùnrin Dáfídì bá pa dà, wọ́n sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ yìí fún un. 13 Lójú ẹsẹ̀, Dáfídì sọ fún àwọn ọkùnrin rẹ̀ pé: “Kí kálukú yín sán idà rẹ̀!”+ Nítorí náà, gbogbo wọn sán idà wọn, Dáfídì náà sán idà rẹ̀, nǹkan bí ọgọ́rùn-ún mẹ́rin (400) ọkùnrin sì tẹ̀ lé Dáfídì, nígbà tí igba (200) ọkùnrin jókòó ti ẹrù wọn.

14 Ní àkókò yìí, ọ̀kan lára àwọn ìránṣẹ́ Nábálì ròyìn fún Ábígẹ́lì, ìyàwó Nábálì pé: “Wò ó! Dáfídì rán àwọn òjíṣẹ́ láti aginjù kí wọ́n wá wo àlàáfíà ọ̀gá wa, àmọ́ ṣe ló fi ìbínú sọ̀rọ̀ burúkú sí wọn.+ 15 Àwọn ọkùnrin náà ṣe dáadáa sí wa. Wọn ò pa wá lára rí, bẹ́ẹ̀ ni kò sí nǹkan wa kankan tó sọ nù ní gbogbo ìgbà tí a fi wà lọ́dọ̀ wọn ní pápá.+ 16 Wọ́n dà bí ògiri yí wa ká, ní ọ̀sán àti ní òru, ní gbogbo ìgbà tí a fi wà lọ́dọ̀ wọn, tí à ń tọ́jú àwọn àgùntàn. 17 Ní báyìí, pinnu ohun tí o máa ṣe, torí àjálù máa tó dé bá ọ̀gá wa àti gbogbo ilé rẹ̀,+ aláìníláárí*+ ni, kò sì sí ẹni tó lè bá a sọ̀rọ̀.”

18 Ni Ábígẹ́lì+ bá sáré mú igba (200) búrẹ́dì àti wáìnì ìṣà ńlá méjì àti àgùntàn márùn-ún tí wọ́n ti pa, tí wọ́n sì ti ṣètò rẹ̀ àti òṣùwọ̀n síà* márùn-ún àyangbẹ ọkà àti ọgọ́rùn-ún (100) ìṣù èso àjàrà gbígbẹ àti igba (200) ìṣù èso ọ̀pọ̀tọ́, ó sì kó gbogbo wọn sórí àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.+ 19 Ó wá sọ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé: “Ẹ máa lọ níwájú mi; màá tẹ̀ lé yín.” Ṣùgbọ́n kò sọ nǹkan kan fún Nábálì ọkọ rẹ̀.

20 Bí ó ṣe ń lọ lórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, òkè kan wà tí kò jẹ́ kó rí Dáfídì àti àwọn ọkùnrin rẹ̀ tí wọ́n ń bọ̀ lápá ọ̀dọ̀ rẹ̀, ló bá ṣe kòńgẹ́ wọn. 21 Dáfídì ti ń sọ pé: “Lásán ni mo ṣọ́ gbogbo nǹkan tí ọ̀gbẹ́ni yìí ní nínú aginjù. Kò sí ìkankan lára gbogbo ohun tó jẹ́ tirẹ̀ tó sọ nù,+ síbẹ̀ ibi ló fi san ire pa dà fún mi.+ 22 Kí Ọlọ́run gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá Dáfídì,* kó sì fìyà jẹ wọ́n gan-an tí mo bá jẹ́ kí ìkankan lára àwọn ọkùnrin* rẹ̀ ṣẹ́ kù títí di àárọ̀ ọ̀la.”

23 Nígbà tí Ábígẹ́lì tajú kán rí Dáfídì, ní kíá ó sọ̀ kalẹ̀ lórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó kúnlẹ̀, ó sì dojú bolẹ̀ níwájú Dáfídì. 24 Ó kúnlẹ̀ síbi ẹsẹ̀ rẹ̀, ó sì sọ pé: “Olúwa mi, jẹ́ kí ẹ̀bi náà wà lórí mi; jẹ́ kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ bá ọ sọ̀rọ̀, kí o sì fetí sí ọ̀rọ̀ tí ìránṣẹ́bìnrin rẹ fẹ́ sọ. 25 Kí olúwa mi jọ̀wọ́ má fiyè sí Nábálì ọkùnrin aláìníláárí+ yìí, nítorí bí orúkọ rẹ̀ ti jẹ́, ni òun náà jẹ́. Nábálì* ni orúkọ rẹ̀, ìwà òmùgọ̀ ló sì ń hù. Àmọ́ èmi ìránṣẹ́bìnrin rẹ kò rí àwọn ọ̀dọ́kùnrin tí olúwa mi rán. 26 Ní báyìí, olúwa mi, bí Jèhófà ti wà láàyè, tí ìwọ* náà sì wà láàyè, Jèhófà ni kò jẹ́ kí o+ jẹ̀bi ẹ̀jẹ̀,+ tí kò sì jẹ́ kí o fi ọwọ́ ara rẹ gbẹ̀san.* Kí àwọn ọ̀tá rẹ àti àwọn tí ó fẹ́ ṣe olúwa mi ní jàǹbá dà bíi Nábálì. 27 Jọ̀wọ́ jẹ́ kí a fún àwọn ọ̀dọ́kùnrin tó ń tẹ̀ lé olúwa mi+ ní ẹ̀bùn*+ tí ìránṣẹ́bìnrin rẹ mú wá fún olúwa mi. 28 Jọ̀wọ́, dárí ìṣìnà ìránṣẹ́bìnrin rẹ jì í, nítorí ó dájú pé Jèhófà máa ṣe ilé tó máa wà títí láé fún olúwa mi,+ nítorí àwọn ogun Jèhófà ni olúwa mi ń jà+ àti pé kò sí ìwà ibi kankan tí a rí lọ́wọ́ rẹ ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ.+ 29 Tí ẹnì kan bá dìde láti lépa rẹ, tí ó sì fẹ́ gba ẹ̀mí* rẹ, Jèhófà Ọlọ́run rẹ yóò fi ẹ̀mí* olúwa mi pa mọ́ sínú àpò ìwàláàyè lọ́dọ̀ rẹ̀. Ṣùgbọ́n, ní ti ẹ̀mí* àwọn ọ̀tá rẹ, òun yóò ta á jáde bí ìgbà tí èèyàn fi kànnàkànnà ta òkúta.* 30 Tí Jèhófà bá ti ṣe gbogbo ohun rere tí ó ṣèlérí fún olúwa mi, tí ó sì fi ọ́ ṣe olórí Ísírẹ́lì,+ 31 o ò ní banú jẹ́ tàbí kí o kábàámọ̀* nínú ọkàn rẹ pé o ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ láìnídìí tàbí pé olúwa mi fi ọwọ́ ara rẹ̀ gbẹ̀san.*+ Nígbà tí Jèhófà bá bù kún olúwa mi, kí o rántí ìránṣẹ́bìnrin rẹ.”

32 Ni Dáfídì bá sọ fún Ábígẹ́lì pé: “Ìyìn ni fún Jèhófà Ọlọ́run Ísírẹ́lì, tí ó rán ọ wá pàdé mi lónìí yìí! 33 Ìbùkún sì ni fún làákàyè rẹ! Kí Ọlọ́run bù kún ọ torí o ò jẹ́ kí n jẹ̀bi ẹ̀jẹ̀+ lónìí, o ò sì jẹ́ kí n fi ọwọ́ ara mi gbẹ̀san.* 34 Àìjẹ́ bẹ́ẹ̀, bí Jèhófà Ọlọ́run Ísírẹ́lì tí ó dá mi dúró kí n má bàa ṣe ọ́ léṣe+ ti wà láàyè, ká ní o ò tètè wá pàdé mi+ ni, tó bá fi máa di àárọ̀ ọ̀la, kò ní sí ìkankan lára àwọn ọkùnrin* Nábálì tó máa ṣẹ́ kù.”+ 35 Ni Dáfídì bá gba ohun tó mú wá fún un, ó sì sọ fún un pé: “Máa lọ sí ilé rẹ ní àlàáfíà. Wò ó, mo ti gbọ́ ohun tí o sọ, màá sì ṣe ohun tí o béèrè.”

36 Lẹ́yìn náà, Ábígẹ́lì pa dà sọ́dọ̀ Nábálì, ó ń jẹ àsè lọ́wọ́ nínú ilé rẹ̀ bí ọba, inú Nábálì* ń dùn, ó sì ti mutí yó bìnàkò. Àmọ́ obìnrin náà kò sọ nǹkan kan fún un títí ilẹ̀ fi mọ́. 37 Ní àárọ̀ ọjọ́ kejì tí wáìnì ti dá lójú Nábálì, ìyàwó rẹ̀ sọ ohun tó ṣẹlẹ̀ fún un. Ọkàn rẹ̀ kú tipiri, ó sì sùn sílẹ̀ bí òkúta. 38 Ní nǹkan bí ọjọ́ mẹ́wàá lẹ́yìn náà, Jèhófà kọ lu Nábálì, ó sì kú.

39 Nígbà tí Dáfídì gbọ́ pé Nábálì ti kú, ó sọ pé: “Ẹ yin Jèhófà, ẹni tí ó bá mi dá ẹjọ́ mi+ nítorí àbùkù tí Nábálì fi kàn mí,+ tí kò sì jẹ́ kí ìránṣẹ́ rẹ̀ ṣe ohun búburú,+ Jèhófà sì ti mú kí ibi Nábálì dà lé e lórí!” Dáfídì wá ránṣẹ́ sí Ábígẹ́lì pé kó wá di ìyàwó òun. 40 Torí náà, àwọn ìránṣẹ́ Dáfídì wá sọ́dọ̀ Ábígẹ́lì ní Kámẹ́lì, wọ́n sì sọ fún un pé: “Dáfídì rán wa sí ọ pé kí o wá di ìyàwó òun.” 41 Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, ó dìde, ó dojú bolẹ̀, ó sì sọ pé: “Ẹrú rẹ obìnrin ṣe tán láti di ìránṣẹ́ tí á máa fọ ẹsẹ̀+ àwọn ìránṣẹ́ olúwa mi.” 42 Ìgbà náà ni Ábígẹ́lì+ yára dìde, ó gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, márùn-ún lára àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin sì ń rìn bọ̀ lẹ́yìn rẹ̀; ó bá àwọn òjíṣẹ́ Dáfídì lọ, ó sì di ìyàwó rẹ̀.

43 Dáfídì ti fẹ́ Áhínóámù+ láti Jésírẹ́lì,+ àwọn obìnrin méjèèjì sì di ìyàwó rẹ̀.+

44 Àmọ́ Sọ́ọ̀lù ti fi Míkálì+ ọmọ rẹ̀ tó jẹ́ ìyàwó Dáfídì fún Pálítì+ ọmọ Láíṣì, tó wá láti Gálímù.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́