ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 2 Kíróníkà 30
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé 2 Kíróníkà

      • Hẹsikáyà ṣe Ìrékọjá (1-27)

2 Kíróníkà 30:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 11:14, 16
  • +2Kr 34:1, 6, 7
  • +Ẹk 12:43; Le 23:5; Di 16:2; 2Kr 35:1

2 Kíróníkà 30:2

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “gbogbo ìjọ.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 9:10, 11

2 Kíróníkà 30:3

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 12:18
  • +2Kr 29:34

2 Kíróníkà 30:4

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “gbogbo ìjọ.”

2 Kíróníkà 30:5

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ond 18:29
  • +2Kr 35:18

2 Kíróníkà 30:6

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “àwọn sárésáré.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 15:29; 1Kr 5:26; 2Kr 28:20, 21

2 Kíróníkà 30:7

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 29:8, 9

2 Kíróníkà 30:8

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 32:9
  • +Di 12:5, 6; Sm 132:13
  • +2Kr 29:10

2 Kíróníkà 30:9

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “olóore ọ̀fẹ́.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 8:49, 50
  • +Di 30:1-3
  • +Ẹk 34:6; Sm 86:5; Mik 7:18
  • +2Kr 15:2; Ais 55:7; Jem 4:8

2 Kíróníkà 30:10

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “àwọn sárésáré.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 30:1
  • +2Kr 36:15, 16

2 Kíróníkà 30:11

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 11:14, 16

2 Kíróníkà 30:12

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “láti fún wọn ní ọkàn kan.”

2 Kíróníkà 30:13

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 23:6
  • +Nọ 9:10, 11

2 Kíróníkà 30:14

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 18:22
  • +2Kr 28:24

2 Kíróníkà 30:16

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 1:5

2 Kíróníkà 30:17

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 29:34

2 Kíróníkà 30:18

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 30:1
  • +Sm 86:5

2 Kíróníkà 30:19

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 19:2, 3; Ẹsr 7:10
  • +Nọ 9:6, 10

2 Kíróníkà 30:20

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “wo àwọn èèyàn náà sàn.”

2 Kíróníkà 30:21

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 23:6
  • +Di 12:5, 7; Ne 8:10
  • +2Kr 29:25

2 Kíróníkà 30:22

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “sọ̀rọ̀ sí ọkàn wọn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 23:6
  • +Le 3:1

2 Kíróníkà 30:23

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 8:65

2 Kíróníkà 30:24

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 35:7, 8
  • +2Kr 29:34

2 Kíróníkà 30:25

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 30:11, 18
  • +Ẹk 12:49

2 Kíróníkà 30:26

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 8:65, 66

2 Kíróníkà 30:27

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 6:23-26; Di 10:8

Àwọn míì

2 Kíró. 30:12Kr 11:14, 16
2 Kíró. 30:12Kr 34:1, 6, 7
2 Kíró. 30:1Ẹk 12:43; Le 23:5; Di 16:2; 2Kr 35:1
2 Kíró. 30:2Nọ 9:10, 11
2 Kíró. 30:3Ẹk 12:18
2 Kíró. 30:32Kr 29:34
2 Kíró. 30:5Ond 18:29
2 Kíró. 30:52Kr 35:18
2 Kíró. 30:62Ọb 15:29; 1Kr 5:26; 2Kr 28:20, 21
2 Kíró. 30:72Kr 29:8, 9
2 Kíró. 30:8Ẹk 32:9
2 Kíró. 30:8Di 12:5, 6; Sm 132:13
2 Kíró. 30:82Kr 29:10
2 Kíró. 30:91Ọb 8:49, 50
2 Kíró. 30:9Di 30:1-3
2 Kíró. 30:9Ẹk 34:6; Sm 86:5; Mik 7:18
2 Kíró. 30:92Kr 15:2; Ais 55:7; Jem 4:8
2 Kíró. 30:102Kr 30:1
2 Kíró. 30:102Kr 36:15, 16
2 Kíró. 30:112Kr 11:14, 16
2 Kíró. 30:13Le 23:6
2 Kíró. 30:13Nọ 9:10, 11
2 Kíró. 30:142Ọb 18:22
2 Kíró. 30:142Kr 28:24
2 Kíró. 30:16Le 1:5
2 Kíró. 30:172Kr 29:34
2 Kíró. 30:182Kr 30:1
2 Kíró. 30:18Sm 86:5
2 Kíró. 30:192Kr 19:2, 3; Ẹsr 7:10
2 Kíró. 30:19Nọ 9:6, 10
2 Kíró. 30:21Le 23:6
2 Kíró. 30:21Di 12:5, 7; Ne 8:10
2 Kíró. 30:212Kr 29:25
2 Kíró. 30:22Le 23:6
2 Kíró. 30:22Le 3:1
2 Kíró. 30:231Ọb 8:65
2 Kíró. 30:242Kr 35:7, 8
2 Kíró. 30:242Kr 29:34
2 Kíró. 30:252Kr 30:11, 18
2 Kíró. 30:25Ẹk 12:49
2 Kíró. 30:261Ọb 8:65, 66
2 Kíró. 30:27Nọ 6:23-26; Di 10:8
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
  • 20
  • 21
  • 22
  • 23
  • 24
  • 25
  • 26
  • 27
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
2 Kíróníkà 30:1-27

Kíróníkà Kejì

30 Hẹsikáyà ránṣẹ́ sí gbogbo Ísírẹ́lì+ àti Júdà, ó tiẹ̀ tún kọ lẹ́tà sí Éfúrémù àti Mánásè,+ pé kí wọ́n wá sí ilé Jèhófà ní Jerúsálẹ́mù láti wá ṣe Ìrékọjá sí Jèhófà Ọlọ́run Ísírẹ́lì.+ 2 Àmọ́, ọba àti àwọn ìjòyè rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo àwọn èèyàn* ní Jerúsálẹ́mù pinnu láti ṣe Ìrékọjá náà ní oṣù kejì,+ 3 nítorí wọn ò lè ṣe é ní àkókò tó yẹ kí wọ́n ṣe é,+ torí pé àwọn àlùfáà tó ti ya ara wọn sí mímọ́ kò pọ̀ tó  + àti pé àwọn èèyàn náà kò tíì kóra jọ sí Jerúsálẹ́mù. 4 Ètò yìí dára lójú ọba àti lójú gbogbo àwọn èèyàn* náà. 5 Nítorí náà, wọ́n pinnu láti kéde káàkiri gbogbo Ísírẹ́lì, láti Bíá-ṣébà dé Dánì,+ pé kí àwọn èèyàn wá ṣe Ìrékọjá sí Jèhófà Ọlọ́run Ísírẹ́lì ní Jerúsálẹ́mù, torí wọn ò tíì máa ṣe é pa pọ̀ bó ṣe wà lákọsílẹ̀.+

6 Lẹ́yìn náà, àwọn asáréjíṣẹ́* lọ káàkiri gbogbo Ísírẹ́lì àti Júdà pẹ̀lú àwọn lẹ́tà látọ̀dọ̀ ọba àti àwọn ìjòyè rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ọba ti pa á láṣẹ, ó ní: “Ẹ̀yin ọmọ Ísírẹ́lì, ẹ pa dà sọ́dọ̀ Jèhófà Ọlọ́run Ábúráhámù, Ísákì àti Ísírẹ́lì, kí ó lè pa dà sọ́dọ̀ àwọn tó ṣẹ́ kù tí wọ́n sá kúrò lọ́wọ́ àwọn ọba Ásíríà.+ 7 Ẹ má dà bí àwọn baba ńlá yín àti àwọn arákùnrin yín tó hùwà àìṣòótọ́ sí Jèhófà Ọlọ́run àwọn baba ńlá wọn, tí ó fi sọ wọ́n di ohun àríbẹ̀rù, bí ẹ̀yin náà ṣe rí i.+ 8 Ní báyìí, ẹ má ṣorí kunkun bí àwọn baba ńlá yín.+ Ẹ fi ara yín fún Jèhófà, kí ẹ wá sí ibi mímọ́ rẹ̀+ tó ti yà sí mímọ́ títí láé, kí ẹ sì máa sin Jèhófà Ọlọ́run yín, kí ìbínú rẹ̀ tó ń jó fòfò lè kúrò lórí yín.+ 9 Torí ìgbà tí ẹ bá pa dà sọ́dọ̀ Jèhófà ni àwọn arákùnrin yín àti àwọn ọmọ yín máa rí àánú gbà látọ̀dọ̀ àwọn tó mú wọn lẹ́rú,+ wọ́n á sì jẹ́ kí wọ́n pa dà sí ilẹ̀ yìí,+ nítorí Jèhófà Ọlọ́run yín jẹ́ ẹni tó ń gba tẹni rò* àti aláàánú,+ kò sì ní yí ojú rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ yín tí ẹ bá pa dà sọ́dọ̀ rẹ̀.”+

10 Torí náà, àwọn asáréjíṣẹ́* lọ láti ìlú dé ìlú káàkiri ilẹ̀ Éfúrémù àti Mánásè,+ kódà wọ́n dé Sébúlúnì, àmọ́ àwọn èèyàn ń fi wọ́n rẹ́rìn-ín, wọ́n sì ń fi wọ́n ṣe yẹ̀yẹ́.+ 11 Ṣùgbọ́n, àwọn kan láti Áṣérì, Mánásè àti Sébúlúnì rẹ ara wọn sílẹ̀, wọ́n sì wá sí Jerúsálẹ́mù.+ 12 Bákan náà, ọwọ́ Ọlọ́run tòótọ́ wà ní Júdà láti mú wọn ṣọ̀kan* kí wọ́n lè ṣe ohun tí ọba àti àwọn ìjòyè pa láṣẹ, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Jèhófà.

13 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ èèyàn kóra jọ sí Jerúsálẹ́mù láti ṣe Àjọyọ̀ Búrẹ́dì Aláìwú+ ní oṣù kejì;+ àwọn èèyàn náà jẹ́ ìjọ ńlá. 14 Wọ́n dìde, wọ́n sì mú àwọn pẹpẹ tó wà ní Jerúsálẹ́mù kúrò,+ wọ́n kó gbogbo àwọn pẹpẹ tùràrí kúrò,+ wọ́n sì kó wọn dà sí Àfonífojì Kídírónì. 15 Lẹ́yìn náà, wọ́n pa ẹran ẹbọ Ìrékọjá ní ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kejì. Ìtìjú bá àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Léfì, torí náà, wọ́n ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n sì mú àwọn ẹbọ sísun wá sí ilé Jèhófà. 16 Wọ́n dúró sí àyè wọn, bí Òfin Mósè èèyàn Ọlọ́run tòótọ́ ṣe sọ; lẹ́yìn náà, àwọn àlùfáà wọ́n ẹ̀jẹ̀+ tí wọ́n gbà lọ́wọ́ àwọn ọmọ Léfì. 17 Ọ̀pọ̀ lára àwọn tó wà ní ìjọ náà ni kò tíì ya ara wọn sí mímọ́, àwọn ọmọ Léfì ló sì ń bójú tó pípa àwọn ẹran ẹbọ Ìrékọjá fún gbogbo àwọn tí kò mọ́,+ láti yà wọ́n sí mímọ́ fún Jèhófà. 18 Nítorí ọ̀pọ̀ lára àwọn èèyàn náà, pàápàá àwọn tó wá láti Éfúrémù, Mánásè,+ Ísákà àti Sébúlúnì ni kò tíì wẹ ara wọn mọ́, síbẹ̀ wọ́n jẹ Ìrékọjá, èyí sì ta ko ohun tó wà lákọsílẹ̀. Àmọ́ Hẹsikáyà gbàdúrà fún wọn pé: “Kí Jèhófà, ẹni rere,+ dárí ji 19 gbogbo ẹni tó ti múra ọkàn rẹ̀ sílẹ̀ láti wá Jèhófà Ọlọ́run tòótọ́,+ ìyẹn Ọlọ́run àwọn baba ńlá rẹ̀, bó tilẹ̀ jẹ́ pé a ò tíì wẹ̀ ẹ́ mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìlànà ìjẹ́mímọ́.”+ 20 Jèhófà fetí sí Hẹsikáyà, ó sì dárí ji àwọn èèyàn náà.*

21 Nítorí náà, àwọn ọmọ Ísírẹ́lì tó wà ní Jerúsálẹ́mù fi ọjọ́ méje ṣe Àjọyọ̀ Búrẹ́dì Aláìwú+ tìdùnnútìdùnnú,+ àwọn ọmọ Léfì àti àwọn àlùfáà sì ń yin Jèhófà lójoojúmọ́, wọ́n ń fi àwọn ohun èlò orin wọn kọrin sókè sí Jèhófà.+ 22 Yàtọ̀ síyẹn, Hẹsikáyà bá gbogbo àwọn ọmọ Léfì tó ń fi ìjìnlẹ̀ òye sin Jèhófà sọ̀rọ̀, ó sì fún wọn níṣìírí.* Ọjọ́ méje ni wọ́n fi jẹun ní àjọyọ̀ náà,+ wọ́n ń rú àwọn ẹbọ ìrẹ́pọ̀,+ wọ́n sì ń dúpẹ́ lọ́wọ́ Jèhófà Ọlọ́run àwọn baba ńlá wọn.

23 Lẹ́yìn náà, gbogbo ìjọ náà pinnu láti fi ọjọ́ méje míì ṣe àjọyọ̀ náà, torí náà, wọ́n fi ọjọ́ méje tó tẹ̀ lé e ṣe é tìdùnnútìdùnnú.+ 24 Hẹsikáyà ọba Júdà wá fi ẹgbẹ̀rún kan (1,000) akọ màlúù àti ẹgbẹ̀rún méje (7,000) àgùntàn ṣe ọrẹ fún ìjọ náà, àwọn ìjòyè sì fi ẹgbẹ̀rún kan (1,000) akọ màlúù àti ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá (10,000) àgùntàn ṣe ọrẹ fún ìjọ náà;+ ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn àlùfáà sì ń ya ara wọn sí mímọ́.+ 25 Gbogbo ìjọ Júdà àti àwọn àlùfáà pẹ̀lú àwọn ọmọ Léfì àti gbogbo ìjọ tó wá láti Ísírẹ́lì+ pẹ̀lú àwọn àjèjì+ tó wá láti ilẹ̀ Ísírẹ́lì àti àwọn tó ń gbé ní Júdà sì ń yọ̀. 26 Ìdùnnú ṣubú layọ̀ ní Jerúsálẹ́mù, torí pé láti ìgbà ayé Sólómọ́nì ọmọ Dáfídì ọba Ísírẹ́lì, irú èyí ò ṣẹlẹ̀ ní Jerúsálẹ́mù.+ 27 Níkẹyìn, àwọn ọmọ Léfì tó jẹ́ àlùfáà dìde dúró, wọ́n sì súre fún àwọn èèyàn náà;+ Ọlọ́run gbọ́ ohùn wọn, àdúrà wọn sì dé ibi mímọ́ tó ń gbé ní ọ̀run.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́