ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 2 Àwọn Ọba 17
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé 2 Àwọn Ọba

      • Hóṣéà di ọba Ísírẹ́lì (1-4)

      • Wọ́n ṣẹ́gun Ísírẹ́lì (5, 6)

      • Ísírẹ́lì lọ sí ìgbèkùn nítorí pé ó di apẹ̀yìndà (7-23)

      • Wọ́n kó àwọn àjèjì wá sí àwọn ìlú Samáríà (24-26)

      • Àwọn ará Samáríà ń ṣe oríṣiríṣi ẹ̀sìn (27-41)

2 Àwọn Ọba 17:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 15:30

2 Àwọn Ọba 17:3

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “owó òde.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 18:9; Ais 10:5, 6; Ho 10:14, 15
  • +2Ọb 18:14

2 Àwọn Ọba 17:4

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “owó òde.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ais 31:1

2 Àwọn Ọba 17:6

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ho 13:16
  • +Le 26:32, 33; Di 4:27; 28:64; 1Ọb 14:15
  • +1Kr 5:26
  • +2Ọb 18:9-11

2 Àwọn Ọba 17:7

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “bẹ̀rù.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 20:2
  • +Ẹk 20:5

2 Àwọn Ọba 17:9

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ìyẹn, ní ibi gbogbo, ì báà jẹ́ ibi tí èèyàn kéréje ń gbé tàbí ọ̀pọ̀ èèyàn.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ho 12:11

2 Àwọn Ọba 17:10

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 34:13; Di 16:21, 22
  • +Di 12:2; Ais 57:5

2 Àwọn Ọba 17:11

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 20:23

2 Àwọn Ọba 17:12

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ó ṣeé ṣe kí ọ̀rọ̀ Hébérù yìí ní í ṣe pẹ̀lú ọ̀rọ̀ tí wọ́n ń lò fún “ìgbẹ́,” wọ́n sì máa ń lò ó fún ohun tí wọ́n bá kórìíra.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 12:28-30; 21:25, 26
  • +Ẹk 20:3-5; Le 26:1; Di 4:23

2 Àwọn Ọba 17:13

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 24:18, 19; 36:15, 16; Jer 25:4
  • +Ais 55:7

2 Àwọn Ọba 17:14

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “wọ́n mú kí ọrùn wọn le bí ọrùn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 1:32; 31:27

2 Àwọn Ọba 17:15

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 5:2; 29:12
  • +Ho 4:6
  • +Di 32:21; 1Sa 12:21
  • +Sm 115:4-8; Ais 44:9
  • +Di 12:30

2 Àwọn Ọba 17:16

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ère dídà.”

  • *

    Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 12:28-30
  • +1Ọb 14:15; 16:33
  • +Di 4:19; Jer 8:2
  • +1Ọb 16:30, 31; 22:51, 53; 2Ọb 10:21; 23:4, 5

2 Àwọn Ọba 17:17

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “ta ara wọn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 16:1, 3
  • +Di 18:10; Mik 5:12

2 Àwọn Ọba 17:18

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 23:12, 13; Ais 42:24

2 Àwọn Ọba 17:19

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 14:22; Jer 3:8
  • +Isk 23:4, 11

2 Àwọn Ọba 17:21

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 12:20

2 Àwọn Ọba 17:22

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 12:28-30

2 Àwọn Ọba 17:23

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 28:45, 63; 1Ọb 14:16; Ho 1:4; Emọ 5:27; Mik 1:6
  • +2Ọb 18:11

2 Àwọn Ọba 17:24

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 19:11, 13

2 Àwọn Ọba 17:25

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “jọ́sìn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 23:29

2 Àwọn Ọba 17:26

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “àwọn àṣà tó wà nínú ẹ̀sìn.”

2 Àwọn Ọba 17:28

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “jọ́sìn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 28:18, 19; Joṣ 16:1; 1Ọb 12:28, 29
  • +Jo 4:20-22

2 Àwọn Ọba 17:29

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ṣe àwọn ọlọ́run tiwọn.”

2 Àwọn Ọba 17:30

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 17:24

2 Àwọn Ọba 17:31

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 18:34

2 Àwọn Ọba 17:32

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 12:31, 32; 13:33

2 Àwọn Ọba 17:33

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “àwọn àṣà tó wà nínú ẹ̀sìn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 17:24, 41

2 Àwọn Ọba 17:34

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “àwọn àṣà tó wà nínú ẹ̀sìn.”

  • *

    Tàbí “bẹ̀rù.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 32:28

2 Àwọn Ọba 17:35

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 19:5; 24:7; Di 29:1
  • +Ẹk 20:3-5; 23:24; 34:14; Di 5:9

2 Àwọn Ọba 17:36

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 6:6
  • +Di 6:12, 13

2 Àwọn Ọba 17:37

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 31:9

2 Àwọn Ọba 17:38

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 4:23

2 Àwọn Ọba 17:40

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “àwọn àṣà tó wà nínú ẹ̀sìn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 17:34

2 Àwọn Ọba 17:41

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹsr 4:1, 2

Àwọn míì

2 Ọba 17:12Ọb 15:30
2 Ọba 17:32Ọb 18:9; Ais 10:5, 6; Ho 10:14, 15
2 Ọba 17:32Ọb 18:14
2 Ọba 17:4Ais 31:1
2 Ọba 17:6Ho 13:16
2 Ọba 17:6Le 26:32, 33; Di 4:27; 28:64; 1Ọb 14:15
2 Ọba 17:61Kr 5:26
2 Ọba 17:62Ọb 18:9-11
2 Ọba 17:7Ẹk 20:2
2 Ọba 17:7Ẹk 20:5
2 Ọba 17:9Ho 12:11
2 Ọba 17:10Ẹk 34:13; Di 16:21, 22
2 Ọba 17:10Di 12:2; Ais 57:5
2 Ọba 17:11Le 20:23
2 Ọba 17:121Ọb 12:28-30; 21:25, 26
2 Ọba 17:12Ẹk 20:3-5; Le 26:1; Di 4:23
2 Ọba 17:132Kr 24:18, 19; 36:15, 16; Jer 25:4
2 Ọba 17:13Ais 55:7
2 Ọba 17:14Di 1:32; 31:27
2 Ọba 17:15Di 5:2; 29:12
2 Ọba 17:15Ho 4:6
2 Ọba 17:15Di 32:21; 1Sa 12:21
2 Ọba 17:15Sm 115:4-8; Ais 44:9
2 Ọba 17:15Di 12:30
2 Ọba 17:161Ọb 12:28-30
2 Ọba 17:161Ọb 14:15; 16:33
2 Ọba 17:16Di 4:19; Jer 8:2
2 Ọba 17:161Ọb 16:30, 31; 22:51, 53; 2Ọb 10:21; 23:4, 5
2 Ọba 17:172Ọb 16:1, 3
2 Ọba 17:17Di 18:10; Mik 5:12
2 Ọba 17:18Joṣ 23:12, 13; Ais 42:24
2 Ọba 17:191Ọb 14:22; Jer 3:8
2 Ọba 17:19Isk 23:4, 11
2 Ọba 17:211Ọb 12:20
2 Ọba 17:221Ọb 12:28-30
2 Ọba 17:23Di 28:45, 63; 1Ọb 14:16; Ho 1:4; Emọ 5:27; Mik 1:6
2 Ọba 17:232Ọb 18:11
2 Ọba 17:242Ọb 19:11, 13
2 Ọba 17:25Ẹk 23:29
2 Ọba 17:28Jẹ 28:18, 19; Joṣ 16:1; 1Ọb 12:28, 29
2 Ọba 17:28Jo 4:20-22
2 Ọba 17:302Ọb 17:24
2 Ọba 17:312Ọb 18:34
2 Ọba 17:321Ọb 12:31, 32; 13:33
2 Ọba 17:332Ọb 17:24, 41
2 Ọba 17:34Jẹ 32:28
2 Ọba 17:35Ẹk 19:5; 24:7; Di 29:1
2 Ọba 17:35Ẹk 20:3-5; 23:24; 34:14; Di 5:9
2 Ọba 17:36Ẹk 6:6
2 Ọba 17:36Di 6:12, 13
2 Ọba 17:37Di 31:9
2 Ọba 17:38Di 4:23
2 Ọba 17:402Ọb 17:34
2 Ọba 17:41Ẹsr 4:1, 2
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
  • 20
  • 21
  • 22
  • 23
  • 24
  • 25
  • 26
  • 27
  • 28
  • 29
  • 30
  • 31
  • 32
  • 33
  • 34
  • 35
  • 36
  • 37
  • 38
  • 39
  • 40
  • 41
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
2 Àwọn Ọba 17:1-41

Àwọn Ọba Kejì

17 Ní ọdún kejìlá Áhásì ọba Júdà, Hóṣéà+ ọmọ Élà di ọba ní Samáríà lórí Ísírẹ́lì; ọdún mẹ́sàn-án ló sì fi ṣàkóso. 2 Ó ń ṣe ohun tó burú ní ojú Jèhófà, kìkì pé kò ṣe tó ti àwọn ọba Ísírẹ́lì tó ṣáájú rẹ̀. 3 Ṣálímánésà ọba Ásíríà wá gbéjà ko Hóṣéà,+ Hóṣéà sì di ìránṣẹ́ rẹ̀, ó wá bẹ̀rẹ̀ sí í san ìṣákọ́lẹ̀* fún Ṣálímánésà.+ 4 Àmọ́, ọba Ásíríà rí i pé Hóṣéà ti ń lọ́wọ́ nínú ọ̀tẹ̀, nítorí ó rán àwọn òjíṣẹ́ sí Sóò ọba Íjíbítì,+ kò sì mú ìṣákọ́lẹ̀* wá fún ọba Ásíríà bíi ti àwọn ọdún àtẹ̀yìnwá. Nítorí náà, ọba Ásíríà tì í mọ́ inú ẹ̀wọ̀n, ó sì fi ṣẹkẹ́ṣẹkẹ̀ dè é.

5 Ọba Ásíríà ya wọ gbogbo ilẹ̀ náà, ó wá sí Samáríà, ọdún mẹ́ta ló sì fi dó tì í. 6 Ní ọdún kẹsàn-án Hóṣéà, ọba Ásíríà gba Samáríà.+ Ó wá kó àwọn èèyàn Ísírẹ́lì ní ìgbèkùn+ lọ sí Ásíríà, ó sì mú kí wọ́n máa gbé ní Hálà àti ní Hábórì níbi odò Gósánì+ àti ní àwọn ìlú àwọn ará Mídíà.+

7 Ohun tó fa èyí ni pé àwọn èèyàn Ísírẹ́lì ṣẹ̀ sí Jèhófà Ọlọ́run wọn, ẹni tó mú wọn jáde kúrò ní ilẹ̀ Íjíbítì, kúrò lábẹ́ àṣẹ Fáráò ọba Íjíbítì.+ Wọ́n sin* àwọn ọlọ́run míì,+ 8 wọ́n tẹ̀ lé àṣà àwọn orílẹ̀-èdè tí Jèhófà lé kúrò níwájú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, wọ́n sì tẹ̀ lé àṣà tí àwọn ọba Ísírẹ́lì dá sílẹ̀.

9 Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ń ṣe àwọn nǹkan tí Jèhófà Ọlọ́run wọn sọ pé kò tọ́. Wọ́n ń kọ́ àwọn ibi gíga ní gbogbo àwọn ìlú wọn,+ láti ilé ìṣọ́ títí dé ìlú olódi.* 10 Wọ́n ń gbé àwọn ọwọ̀n òrìṣà àti àwọn òpó òrìṣà*+ kalẹ̀ fún ara wọn lórí gbogbo òkè àti lábẹ́ gbogbo igi tó gbẹ̀rẹ̀gẹ̀jigẹ̀;+ 11 orí gbogbo ibi gíga wọ̀nyí ni wọ́n ti ń mú ẹbọ rú èéfín bí àwọn orílẹ̀-èdè tí Jèhófà lé kúrò níwájú wọn lọ sí ìgbèkùn.+ Wọ́n ń fi ohun búburú tí wọ́n ṣe mú Jèhófà bínú.

12 Wọ́n ń sin àwọn òrìṣà ẹ̀gbin,*+ èyí tí Jèhófà sọ fún wọn pé: “Ẹ kò gbọ́dọ̀ ṣe nǹkan yìí!”+ 13 Jèhófà lo gbogbo wòlíì rẹ̀ àti gbogbo aríran+ rẹ̀ láti máa kìlọ̀ fún Ísírẹ́lì àti Júdà pé: “Ẹ kúrò nínú àwọn ọ̀nà búburú yín!+ Kí ẹ máa pa àwọn àṣẹ mi àti àwọn ìlànà mi mọ́, bó ṣe wà nínú gbogbo òfin tí mo pa láṣẹ fún àwọn baba ńlá yín, tí mo sì fi rán àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì sí yín.” 14 Àmọ́ wọn ò gbọ́, wọ́n sì ya alágídí bí* àwọn baba ńlá wọn tí kò ní ìgbàgbọ́ nínú Jèhófà Ọlọ́run wọn.+ 15 Wọ́n ń pa àwọn ìlànà rẹ̀ tì àti májẹ̀mú+ rẹ̀ tó bá àwọn baba ńlá wọn dá àti àwọn ìránnilétí rẹ̀ tó fi kìlọ̀ fún wọn,+ wọ́n ń sin àwọn òrìṣà asán,+ àwọn fúnra wọn sì di asán,+ torí wọ́n ń fara wé àwọn orílẹ̀-èdè tó yí wọn ká tí Jèhófà pàṣẹ fún wọn pé kí wọ́n má ṣe fara wé.+

16 Wọ́n ń pa gbogbo àṣẹ Jèhófà Ọlọ́run wọn tì, wọ́n sì ṣe ère onírin* ọmọ màlúù méjì,+ wọ́n ṣe òpó òrìṣà,*+ wọ́n ń forí balẹ̀ fún gbogbo ọmọ ogun ọ̀run,+ wọ́n sì ń sin Báálì.+ 17 Wọ́n tún ń sun àwọn ọmọkùnrin wọn àti àwọn ọmọbìnrin wọn nínú iná,+ wọ́n ń woṣẹ́,+ wọ́n ń wá àwọn àmì ìṣẹ̀lẹ̀, wọ́n pinnu* láti máa ṣe ohun tó burú ní ojú Jèhófà, wọ́n sì tipa bẹ́ẹ̀ mú un bínú.

18 Nítorí náà, inú bí Jèhófà gidigidi sí Ísírẹ́lì, tí ó fi mú wọn kúrò níwájú rẹ̀.+ Kò jẹ́ kí èyíkéyìí ṣẹ́ kù lára wọn àfi ẹ̀yà Júdà nìkan.

19 Àwọn èèyàn Júdà pàápàá kò pa àwọn àṣẹ Jèhófà Ọlọ́run wọn mọ́;+ àwọn náà ń tẹ̀ lé àṣà tí Ísírẹ́lì tẹ̀ lé.+ 20 Jèhófà kọ gbogbo àtọmọdọ́mọ Ísírẹ́lì sílẹ̀, ó dójú tì wọ́n, ó sì fi wọ́n lé ọwọ́ àwọn tó ń kóni lẹ́rù, títí ó fi lé wọn kúrò níwájú rẹ̀. 21 Ó fa Ísírẹ́lì ya kúrò ní ilé Dáfídì, wọ́n sì fi Jèróbóámù ọmọ Nébátì jọba.+ Àmọ́ Jèróbóámù mú kí Ísírẹ́lì yà kúrò lẹ́yìn Jèhófà, ó sì mú kí wọ́n dá ẹ̀ṣẹ̀ ńlá. 22 Àwọn èèyàn Ísírẹ́lì ń dá gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí Jèróbóámù dá.+ Wọn kò jáwọ́ nínú wọn 23 títí Jèhófà fi mú Ísírẹ́lì kúrò níwájú rẹ̀, bó ṣe sọ látẹnu gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wòlíì.+ Bí wọ́n ṣe kó Ísírẹ́lì nígbèkùn láti ilẹ̀ rẹ̀ lọ sí Ásíríà+ nìyẹn, wọ́n sì wà níbẹ̀ títí di òní yìí.

24 Lẹ́yìn náà, ọba Ásíríà kó àwọn èèyàn wá láti Bábílónì, Kútà, Áfà, Hámátì àti Séfáfáímù,+ ó sì ní kí wọ́n máa gbé inú àwọn ìlú Samáríà níbi tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ń gbé tẹ́lẹ̀; wọ́n gba Samáríà, wọ́n sì ń gbé inú àwọn ìlú rẹ̀. 25 Nígbà tí wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í gbé ibẹ̀, wọn kò bẹ̀rù* Jèhófà. Nítorí náà, Jèhófà rán àwọn kìnnìún sáàárín wọn,+ wọ́n sì pa lára àwọn èèyàn náà. 26 Wọ́n ròyìn fún ọba Ásíríà pé: “Àwọn orílẹ̀-èdè tí o kó lọ sí ìgbèkùn, tí o ní kí wọ́n máa gbé àwọn ìlú Samáríà kò mọ ẹ̀sìn* Ọlọ́run ilẹ̀ náà. Torí náà, ó ń rán àwọn kìnnìún sáàárín wọn, àwọn kìnnìún náà sì ń pa wọ́n, torí pé kò sí ìkankan nínú wọn tó mọ ẹ̀sìn Ọlọ́run ilẹ̀ náà.”

27 Ni ọba Ásíríà bá pàṣẹ pé: “Ẹ dá ọ̀kan lára àwọn àlùfáà tí ẹ kó láti ibẹ̀ lọ sí ìgbèkùn pa dà, kó lè máa gbé ibẹ̀, kó sì máa kọ́ wọn ní ẹ̀sìn Ọlọ́run ilẹ̀ náà.” 28 Torí náà, ọ̀kan lára àwọn àlùfáà tí wọ́n kó lọ sí ìgbèkùn láti Samáríà pa dà wá, ó sì ń gbé Bẹ́tẹ́lì,+ ó wá bẹ̀rẹ̀ sí í kọ́ wọn bí wọ́n á ṣe máa bẹ̀rù* Jèhófà.+

29 Àmọ́, orílẹ̀-èdè kọ̀ọ̀kan ṣe ọlọ́run tirẹ̀,* wọ́n gbé wọn sínú àwọn ilé ìjọsìn ní àwọn ibi gíga tí àwọn ará Samáríà ṣe; orílẹ̀-èdè kọ̀ọ̀kan ṣe bẹ́ẹ̀ ní ìlú wọn tí wọ́n ń gbé. 30 Àwọn èèyàn Bábílónì ṣe Sukotu-bénótì, àwọn èèyàn Kútì ṣe Nẹ́gálì, àwọn èèyàn Hámátì+ ṣe Áṣímà, 31 àwọn ará Áfà sì ṣe Níbúhásì àti Tátákì. Àwọn ará Séfáfáímù máa ń sun àwọn ọmọ wọn nínú iná sí Adiramélékì àti Anamélékì, àwọn ọlọ́run Séfáfáímù.+ 32 Bó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n bẹ̀rù Jèhófà, wọ́n yan àwọn àlùfáà sí àwọn ibi gíga látinú àwọn èèyàn wọn, àwọn yìí ló ń bá wọn ṣiṣẹ́ ní àwọn ilé ìjọsìn ní àwọn ibi gíga.+ 33 Nípa bẹ́ẹ̀, wọ́n ń bẹ̀rù Jèhófà, àmọ́ àwọn ọlọ́run wọn ni wọ́n ń sìn bí wọ́n ti ń ṣe nínú ẹ̀sìn* àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti kó wọn wá.+

34 Títí di òní yìí, ẹ̀sìn* wọn àtẹ̀yìnwá ni wọ́n ń ṣe. Kò sí ìkankan lára wọn tó sin* Jèhófà, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ìkankan lára wọn tó tẹ̀ lé ìlànà rẹ̀ àti ìdájọ́ rẹ̀, wọn ò sì pa Òfin àti àṣẹ tí Jèhófà fún àwọn ọmọ Jékọ́bù mọ́, ẹni tí Ó yí orúkọ rẹ̀ pa dà sí Ísírẹ́lì.+ 35 Nígbà tí Jèhófà bá wọn dá májẹ̀mú,+ ó pàṣẹ fún wọn pé: “Ẹ kò gbọ́dọ̀ bẹ̀rù àwọn ọlọ́run míì, ẹ kò sì gbọ́dọ̀ forí balẹ̀ fún wọn tàbí kí ẹ sìn wọ́n tàbí kí ẹ rúbọ sí wọn.+ 36 Ṣùgbọ́n Jèhófà, ẹni tó mú yín jáde kúrò ní ilẹ̀ Íjíbítì pẹ̀lú agbára ńlá àti apá tó nà jáde,+ ni Ẹni tí ẹ ó máa bẹ̀rù,+ òun ni kí ẹ máa forí balẹ̀ fún, òun sì ni kí ẹ máa rúbọ sí. 37 Àwọn ìlànà, àwọn ìdájọ́ àti Òfin pẹ̀lú àṣẹ tó kọ fún yín,+ ni kí ẹ máa pa mọ́ délẹ̀délẹ̀, ẹ ò sì gbọ́dọ̀ sin àwọn ọlọ́run míì. 38 Ẹ ò gbọ́dọ̀ gbàgbé májẹ̀mú tí mo bá yín dá,+ ẹ ò sì gbọ́dọ̀ sin àwọn ọlọ́run míì. 39 Àmọ́ Jèhófà Ọlọ́run yín ni kí ẹ máa sìn, nítorí òun ni ẹni tó máa gbà yín lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá yín.”

40 Àmọ́ wọn ò ṣègbọràn, wọ́n sì ń ṣe ẹ̀sìn* wọn àtẹ̀yìnwá.+ 41 Torí náà, àwọn orílẹ̀-èdè yìí ń bẹ̀rù Jèhófà,+ àmọ́ wọ́n tún ń sin àwọn ère gbígbẹ́ wọn. Àwọn ọmọ wọn àti àwọn ọmọ ọmọ wọn ń ṣe bí àwọn baba ńlá wọn ti ṣe, títí di òní yìí.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́