ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 2 Kíróníkà 24
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé 2 Kíróníkà

      • Ìjọba Jèhóáṣì (1-3)

      • Jèhóáṣì tún tẹ́ńpìlì ṣe (4-14)

      • Jèhóáṣì di apẹ̀yìndà (15-22)

      • Wọ́n pa Jèhóáṣì (23-27)

2 Kíróníkà 24:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 11:21
  • +Jẹ 21:14; 2Sa 3:10; 2Ọb 12:1

2 Kíróníkà 24:2

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 12:2

2 Kíróníkà 24:4

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 22:3-5

2 Kíróníkà 24:5

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 12:4, 5; 2Kr 29:1, 3; 34:9, 10
  • +2Ọb 12:6

2 Kíróníkà 24:6

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 12:7
  • +Ẹk 30:12-16
  • +Nọ 1:50

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àwọn Ìtẹ̀jáde Tá A Tọ́ka sí Nínú Ìwé Ìpàdé, 9/2020, ojú ìwé 5

2 Kíróníkà 24:7

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 22:2, 3
  • +2Kr 28:24

2 Kíróníkà 24:8

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Mk 12:41
  • +2Ọb 12:9

2 Kíróníkà 24:9

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 30:12-16; Ne 10:32; Mt 17:24

2 Kíróníkà 24:10

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí kó jẹ́, “títí gbogbo wọn fi mú wá.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Kr 29:9

2 Kíróníkà 24:11

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 12:10

2 Kíróníkà 24:12

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 12:11, 12; 2Kr 34:10, 11

2 Kíróníkà 24:14

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 37:16; Nọ 7:84
  • +Nọ 28:3

2 Kíróníkà 24:16

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 2:10
  • +2Kr 23:1

2 Kíróníkà 24:18

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.

  • *

    Ní Héb., “tí ìbínú fi ru.”

2 Kíróníkà 24:19

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “jẹ́rìí láti ta kò wọ́n.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 17:13, 14; 2Kr 36:15, 16; Jer 7:25, 26

2 Kíróníkà 24:20

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “bo.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 23:11
  • +Di 29:24, 25; 1Kr 28:9; 2Kr 15:2

2 Kíróníkà 24:21

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 11:19
  • +Mt 23:35; Lk 11:51

2 Kíróníkà 24:22

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ìyẹn, bàbá Sekaráyà.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 9:5; Sm 94:1; Jer 11:20; Heb 10:30

2 Kíróníkà 24:23

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “Nígbà ìyípo ọdún.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 12:17
  • +2Kr 24:17, 18

2 Kíróníkà 24:24

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ìyẹn, àwọn ará Síríà.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 26:17, 37; Di 32:30

2 Kíróníkà 24:25

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “pẹ̀lú ọ̀pọ̀ àrùn.”

  • *

    Tàbí “ọmọ.” Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ àpọ́nlé ni ọ̀rọ̀ ẹlẹ́ni púpọ̀ yìí.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 24:20, 21
  • +2Ọb 12:20
  • +2Sa 5:9; 1Ọb 2:10
  • +2Kr 21:16, 20; 28:27

2 Kíróníkà 24:26

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 12:21

2 Kíróníkà 24:27

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “ìfilọ́lẹ̀.”

  • *

    Tàbí “àlàyé.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 24:20
  • +2Kr 24:13

Àwọn míì

2 Kíró. 24:12Ọb 11:21
2 Kíró. 24:1Jẹ 21:14; 2Sa 3:10; 2Ọb 12:1
2 Kíró. 24:22Ọb 12:2
2 Kíró. 24:42Ọb 22:3-5
2 Kíró. 24:52Ọb 12:4, 5; 2Kr 29:1, 3; 34:9, 10
2 Kíró. 24:52Ọb 12:6
2 Kíró. 24:62Ọb 12:7
2 Kíró. 24:6Ẹk 30:12-16
2 Kíró. 24:6Nọ 1:50
2 Kíró. 24:72Kr 22:2, 3
2 Kíró. 24:72Kr 28:24
2 Kíró. 24:8Mk 12:41
2 Kíró. 24:82Ọb 12:9
2 Kíró. 24:9Ẹk 30:12-16; Ne 10:32; Mt 17:24
2 Kíró. 24:101Kr 29:9
2 Kíró. 24:112Ọb 12:10
2 Kíró. 24:122Ọb 12:11, 12; 2Kr 34:10, 11
2 Kíró. 24:14Ẹk 37:16; Nọ 7:84
2 Kíró. 24:14Nọ 28:3
2 Kíró. 24:161Ọb 2:10
2 Kíró. 24:162Kr 23:1
2 Kíró. 24:192Ọb 17:13, 14; 2Kr 36:15, 16; Jer 7:25, 26
2 Kíró. 24:202Kr 23:11
2 Kíró. 24:20Di 29:24, 25; 1Kr 28:9; 2Kr 15:2
2 Kíró. 24:21Jer 11:19
2 Kíró. 24:21Mt 23:35; Lk 11:51
2 Kíró. 24:22Jẹ 9:5; Sm 94:1; Jer 11:20; Heb 10:30
2 Kíró. 24:232Ọb 12:17
2 Kíró. 24:232Kr 24:17, 18
2 Kíró. 24:24Le 26:17, 37; Di 32:30
2 Kíró. 24:252Kr 24:20, 21
2 Kíró. 24:252Ọb 12:20
2 Kíró. 24:252Sa 5:9; 1Ọb 2:10
2 Kíró. 24:252Kr 21:16, 20; 28:27
2 Kíró. 24:262Ọb 12:21
2 Kíró. 24:272Kr 24:20
2 Kíró. 24:272Kr 24:13
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
  • 20
  • 21
  • 22
  • 23
  • 24
  • 25
  • 26
  • 27
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
2 Kíróníkà 24:1-27

Kíróníkà Kejì

24 Ọmọ ọdún méje ni Jèhóáṣì nígbà tó jọba,+ ogójì (40) ọdún ló sì fi ṣàkóso ní Jerúsálẹ́mù. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Sibáyà láti Bíá-ṣébà.+ 2 Jèhóáṣì ń ṣe ohun tí ó tọ́ lójú Jèhófà ní gbogbo ọjọ́ ayé àlùfáà Jèhóádà.+ 3 Jèhóádà fẹ́ ìyàwó méjì fún un, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin.

4 Lẹ́yìn náà, ó wà lọ́kàn Jèhóáṣì láti tún ilé Jèhófà ṣe.+ 5 Torí náà, ó kó àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Léfì jọ, ó sì sọ fún wọn pé: “Ẹ lọ sí àwọn ìlú Júdà kí ẹ sì gba owó lọ́wọ́ gbogbo Ísírẹ́lì láti máa fi tún ilé Ọlọ́run yín+ ṣe lọ́dọọdún; kí ẹ sì tètè gbé ìgbésẹ̀ lórí ọ̀rọ̀ náà.” Àmọ́, àwọn ọmọ Léfì kò tètè gbé ìgbésẹ̀.+ 6 Nítorí náà, ọba pe Jèhóádà olórí, ó sì sọ fún un pé:+ “Kí ló dé tí o kò tíì ní kí àwọn ọmọ Léfì mú owó orí mímọ́ tí Mósè+ ìránṣẹ́ Jèhófà pa láṣẹ wá láti Júdà àti Jerúsálẹ́mù, ìyẹn owó orí mímọ́ ti ìjọ Ísírẹ́lì, fún àgọ́ Ẹ̀rí?+ 7 Nítorí àwọn ọmọ Ataláyà,+ obìnrin burúkú yẹn, ti fọ́ ilé Ọlọ́run tòótọ́ wọlé,+ wọ́n sì ti lo gbogbo àwọn ohun mímọ́ ilé Jèhófà fún àwọn Báálì.” 8 Nígbà náà, àwọn èèyàn kan àpótí + kan bí ọba ṣe pa á láṣẹ, wọ́n sì gbé e sí ìta ẹnubodè ilé Jèhófà.+ 9 Lẹ́yìn náà, wọ́n kéde káàkiri Júdà àti Jerúsálẹ́mù pé kí wọ́n mú owó orí mímọ́+ tí Mósè ìránṣẹ́ Ọlọ́run tòótọ́ bù lé Ísírẹ́lì ní aginjù, wá fún Jèhófà. 10 Inú gbogbo àwọn ìjòyè àti àwọn èèyàn náà dùn,+ wọ́n ń mú ọrẹ wá, wọ́n sì ń jù ú sínú àpótí náà títí ó fi kún.*

11 Nígbàkigbà tí àwọn ọmọ Léfì bá gbé àpótí náà wá kí wọ́n lè kó ohun tó wà nínú rẹ̀ fún ọba, tí wọ́n sì rí i pé owó ti pọ̀ nínú rẹ̀, akọ̀wé ọba àti kọmíṣọ́nnà tó ń ṣojú olórí àlùfáà á wá, wọ́n á kó ohun tó wà nínú àpótí+ náà, wọ́n á sì dá a pa dà sí àyè rẹ̀. Ohun tí wọ́n máa ń ṣe nìyẹn lójoojúmọ́, wọ́n sì rí ọ̀pọ̀ owó kó jọ. 12 Lẹ́yìn náà, ọba àti Jèhóádà á kó o fún àwọn tó ń bójú tó iṣẹ́ ìsìn ilé Jèhófà, wọ́n á sì háyà àwọn agékùúta àti àwọn oníṣẹ́ ọnà láti tún ilé Jèhófà ṣe,+ títí kan àwọn oníṣẹ́ irin àti bàbà láti tún ilé Jèhófà ṣe. 13 Àwọn tó ń bójú tó iṣẹ́ náà sì bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́, iṣẹ́ àtúnṣe náà ń tẹ̀ síwájú lábẹ́ àbójútó wọn, wọ́n mú kí ilé Ọlọ́run tòótọ́ pa dà sí bó ṣe yẹ kó wà, wọ́n sì mú kó lágbára. 14 Gbàrà tí wọ́n ṣe tán, wọ́n kó owó tó ṣẹ́ kù wá fún ọba àti Jèhóádà, wọ́n sì fi ṣe àwọn nǹkan èlò fún ilé Jèhófà, àwọn nǹkan èlò fún iṣẹ́ ìsìn àti fún rírú ẹbọ àti àwọn ife àti àwọn nǹkan èlò wúrà àti ti fàdákà.+ Wọ́n máa ń rú àwọn ẹbọ sísun+ déédéé ní ilé Jèhófà ní gbogbo ọjọ́ ayé Jèhóádà.

15 Nígbà tí Jèhóádà darúgbó, tó sì ti lo ọ̀pọ̀ ọdún, ó kú; ẹni àádóje (130) ọdún ni nígbà tó kú. 16 Nítorí náà, wọ́n sin ín sí Ìlú Dáfídì níbi tí wọ́n ń sin àwọn ọba sí,+ nítorí ó ti ṣe dáadáa ní Ísírẹ́lì+ sí Ọlọ́run tòótọ́ àti sí ilé Rẹ̀.

17 Lẹ́yìn ikú Jèhóádà, àwọn ìjòyè Júdà wọlé wá, wọ́n tẹrí ba fún ọba, ọba sì fetí sí wọn. 18 Wọ́n fi ilé Jèhófà Ọlọ́run àwọn baba ńlá wọn sílẹ̀, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í sin àwọn òpó òrìṣà* àti àwọn òrìṣà, tó fi di pé Ọlọ́run bínú* sí Júdà àti Jerúsálẹ́mù nítorí pé wọ́n ti jẹ̀bi. 19 Ó ń rán àwọn wòlíì sáàárín wọn léraléra láti mú wọn pa dà wá sọ́dọ̀ Jèhófà, wọ́n sì ń kìlọ̀ fún wọn* léraléra, àmọ́ wọn ò gbọ́.+

20 Ẹ̀mí Ọlọ́run bà lé* Sekaráyà ọmọ àlùfáà Jèhóádà,+ ó dúró sórí ibi tó ga láàárín àwọn èèyàn náà, ó sì sọ fún wọn pé: “Ohun tí Ọlọ́run tòótọ́ sọ nìyí, ‘Kí ló dé tí ẹ fi ń tẹ àwọn àṣẹ Jèhófà lójú? Ẹ ò ní ṣàṣeyọrí! Nítorí ẹ ti fi Jèhófà sílẹ̀, òun náà á sì fi yín sílẹ̀.’”+ 21 Àmọ́ wọ́n dìtẹ̀ mọ́ ọn,+ wọ́n sì sọ ọ́ lókùúta gẹ́gẹ́ bí àṣẹ ọba, ní àgbàlá ilé Jèhófà.+ 22 Bí Ọba Jèhóáṣì kò ṣe rántí ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ tí Jèhóádà bàbá rẹ̀* fi hàn sí i nìyẹn, tó sì pa á lọ́mọ. Bí ọmọ náà ṣe ń kú lọ, ó sọ pé: “Kí Jèhófà rí sí i, kí ó sì pè ọ́ wá jíhìn.”+

23 Ní ìbẹ̀rẹ̀ ọdún,* àwọn ọmọ ogun ará Síríà wá gbéjà ko Jèhóáṣì, wọ́n sì ya wọ Júdà àti Jerúsálẹ́mù.+ Lẹ́yìn náà, wọ́n pa gbogbo àwọn ìjòyè+ àwọn èèyàn náà, wọ́n kó gbogbo ẹrù wọn, wọ́n sì fi ránṣẹ́ sí ọba Damásíkù. 24 Bó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ọmọ ogun ará Síríà tó ya wá kò pọ̀, Jèhófà fi ọmọ ogun tó pọ̀ gan-an lé wọn lọ́wọ́,+ nítorí wọ́n ti fi Jèhófà Ọlọ́run àwọn baba ńlá wọn sílẹ̀; torí náà, wọ́n* mú ìdájọ́ ṣẹ sórí Jèhóáṣì. 25 Nígbà tí wọ́n kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ (nítorí wọ́n fi í sílẹ̀ pẹ̀lú ọgbẹ́ yán-na-yàn-na* lára), àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ dìtẹ̀ mọ́ ọn nítorí ó ti ta ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọ* àlùfáà Jèhóádà+ sílẹ̀. Wọ́n pa á lórí ibùsùn rẹ̀.+ Bó ṣe kú nìyẹn, wọ́n sì sin ín sí Ìlú Dáfídì,+ àmọ́ wọn ò sin ín sí ibi tí wọ́n ń sin àwọn ọba sí.+

26 Àwọn tó dìtẹ̀+ mọ́ ọn nìyí: Sábádì ọmọ Ṣíméátì ọmọbìnrin Ámónì àti Jèhósábádì ọmọ Ṣímúrítì ọmọbìnrin Móábù. 27 Ní ti àwọn ọmọ rẹ̀ àti ọ̀pọ̀ ìkéde tí wọ́n ké lé e lórí+ àti àtúnṣe* ilé Ọlọ́run tòótọ́,+ gbogbo nǹkan yìí wà ní àkọsílẹ̀* nínú Ìwé Àwọn Ọba. Amasááyà ọmọ rẹ̀ sì jọba ní ipò rẹ̀.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́