ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • nwt Málákì 1:1-4:6
  • Málákì

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Málákì
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Málákì

MÁLÁKÌ

1 Ìkéde:

Ọ̀rọ̀ tí Jèhófà gbẹnu Málákì* sọ fún Ísírẹ́lì nìyí:

2 Jèhófà sọ pé, “Mo ti fi hàn pé mo nífẹ̀ẹ́ yín.”+

Àmọ́, ẹ sọ pé: “Kí lo ṣe tó fi hàn pé o nífẹ̀ẹ́ wa?”

Jèhófà sọ pé, “Ṣebí ọmọ ìyá ni Jékọ́bù àti Ísọ̀?+ Àmọ́ mo nífẹ̀ẹ́ Jékọ́bù, 3 mo sì kórìíra Ísọ̀;+ mo sọ àwọn òkè rẹ̀ di ahoro,+ màá jẹ́ kí àwọn ajáko* inú aginjù gba ogún rẹ̀.”+

4 “Bó tilẹ̀ jẹ́ pé Édómù sọ pé, ‘Wọ́n ti fọ́ wa túútúú, àmọ́ a máa pa dà, a ó sì tún àwọn àwókù náà kọ́,’ ohun tí Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun sọ nìyí, ‘Wọ́n máa kọ́ ọ; àmọ́ màá ya á lulẹ̀, wọ́n sì máa pè wọ́n ní “ilẹ̀ ìwà burúkú” àti “àwọn èèyàn tí Jèhófà ti ta nù títí láé.”+ 5 Ẹ ó fi ojú yín rí i, ẹ ó sì sọ pé: “Kí wọ́n gbé Jèhófà ga ní ilẹ̀ Ísírẹ́lì.”’”

6 Èmi Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun sọ fún ẹ̀yin àlùfáà tó ń tàbùkù sí orúkọ mi+ pé: “‘Ọmọ máa ń bọlá fún bàbá,+ ìránṣẹ́ sì máa ń bọlá fún ọ̀gá rẹ̀. Torí náà, bí mo bá jẹ́ bàbá,+ ǹjẹ́ kò yẹ kí ẹ bọlá fún mi?+ Bí mo bá sì jẹ́ ọ̀gá,* ǹjẹ́ kò yẹ kí ẹ bẹ̀rù* mi?’

“‘Àmọ́, ẹ sọ pé: “Kí la ṣe tí a fi tàbùkù sí orúkọ rẹ?”’

7 “‘Ẹ̀ ń fi oúnjẹ* ẹlẹ́gbin rúbọ lórí pẹpẹ mi.’

“‘Ẹ sì sọ pé: “Kí la ṣe tí a fi sọ ẹ́ di ẹlẹ́gbin?”’

“‘Ẹ̀ ń sọ pé: “Tábìlì Jèhófà+ kò wúlò.” 8 Nígbà tí ẹ bá ń fi ẹran tó fọ́jú rúbọ, ẹ̀ ń sọ pé: “Kò sí ohun tó burú níbẹ̀.” Tí ẹ bá sì ń mú ẹran tó yarọ tàbí èyí tó ń ṣàìsàn wá, ẹ̀ ń sọ pé: “Kò sí ohun tó burú níbẹ̀.”’”+

“Ẹ jọ̀ọ́, ẹ mú un lọ síwájú gómìnà yín. Ṣé inú rẹ̀ á dùn sí yín, ṣé ẹ sì máa rí ojúure rẹ̀?” ni Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun wí.

9 “Ní báyìí, ẹ jọ̀ọ́, ẹ bẹ Ọlọ́run,* kó lè ṣojúure sí wa. Ṣé irú ọrẹ tí ẹ mú wá yẹn lè mú kó ṣojúure sí ẹnikẹ́ni nínú yín?” ni Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun wí.

10 “Ta ló fẹ́ ti àwọn ilẹ̀kùn* nínú yín?+ Ẹ kì í fẹ́ dá iná pẹpẹ mi láìjẹ́ pé ẹ gba nǹkan kan.+ Inú mi ò dùn sí yín,” ni Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun wí, “inú mi ò sì dùn sí ìkankan nínú ọrẹ tí ẹ mú wá.”+

11 “Torí láti yíyọ oòrùn dé wíwọ̀ rẹ̀,* wọn yóò gbé orúkọ mi ga láàárín àwọn orílẹ̀-èdè.+ Níbi gbogbo, wọ́n á mú kí ẹbọ rú èéfín, wọ́n á sì mú àwọn ọrẹ wá torí orúkọ mi, bí ẹ̀bùn tó mọ́; torí wọn yóò gbé orúkọ mi ga láàárín àwọn orílẹ̀-èdè,”+ ni Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun wí.

12 “Àmọ́ ẹ̀ ń kẹ́gàn rẹ̀,*+ ẹ̀ ń sọ pé, ‘Tábìlì Jèhófà jẹ́ ẹlẹ́gbin, ó sì yẹ ká tẹ́ńbẹ́lú èso àti oúnjẹ rẹ̀.’+ 13 Ẹ tún sọ pé, ‘Ẹ wò ó! Ó ti sú wa o!’ ẹ sì fi í ṣe ẹlẹ́yà,” ni Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun wí. “Ẹran tí ẹ jí, èyí tó yarọ àti èyí tó ń ṣàìsàn lẹ̀ ń mú wá. Àní, irú nǹkan bẹ́ẹ̀ lẹ̀ ń fún mi! Ṣé ó yẹ kí n gbà á lọ́wọ́ yín?”+ ni Jèhófà wí.

14 “Ègún ni fún ẹni tó ń ṣe àrékérekè, tó ní akọ ẹran tí ara rẹ̀ dá ṣáṣá nínú agbo ẹran rẹ̀, tó sì wá fi ẹran tó ní àbùkù* rúbọ sí Jèhófà lẹ́yìn tó jẹ́ ẹ̀jẹ́. Torí Ọba tó ju ọba lọ ni mí,”+ ni Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun wí, “orúkọ mi yóò sì ba àwọn orílẹ̀-èdè lẹ́rù.”+

2 “Ẹ̀yin àlùfáà, ẹ̀yin ni mò ń pa àṣẹ yìí fún.+ 2 Tí ẹ kò bá fetí sílẹ̀, tí ẹ kò sì fi í sọ́kàn, kí ẹ lè yin orúkọ mi lógo,” ni Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun wí, “èmi yóò gégùn-ún fún yín,+ èmi yóò sì sọ ìbùkún yín di ègún.+ Àní, mo ti sọ ìbùkún yín di ègún torí ẹ kò fi í sọ́kàn.”

3 “Ẹ wò ó! Nítorí yín, màá mú kí ohun tí ẹ gbìn pa run,*+ màá sì da ìgbẹ́ ẹran sí yín lójú, ìgbẹ́ àwọn ẹran tí ẹ fi rúbọ níbi àjọyọ̀ yín; wọ́n á sì gbé yín lọ síbẹ̀.* 4 Ẹ ó sì mọ̀ pé mo ti pa àṣẹ yìí fún yín, kí májẹ̀mú tí mo bá Léfì dá má bàa yẹ̀,”+ ni Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun wí.

5 “Májẹ̀mú ìyè àti àlàáfíà ni mo bá a dá, mo sì dá a kó lè bẹ̀rù* mi. Ó bẹ̀rù mi, àní, ó bẹ̀rù orúkọ mi. 6 Òfin* òtítọ́ wà ní ẹnu rẹ̀,+ kò sì sí àìṣòdodo kankan ní ètè rẹ̀. Ó bá mi rìn ní àlàáfíà àti ní òdodo,+ ó sì yí ọ̀pọ̀ pa dà kúrò nínú ìṣìnà. 7 Ó yẹ kí ìmọ̀ máa wà ní ètè àlùfáà, ó sì yẹ kí àwọn èèyàn máa wá òfin* ní ẹnu rẹ̀,+ torí ìránṣẹ́ Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun ni.

8 Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun sọ pé: “Àmọ́ ẹ̀yin fúnra yín ti yà kúrò ní ọ̀nà. Ẹ ti lo òfin* láti mú ọ̀pọ̀ kọsẹ̀.+ Ẹ ti da májẹ̀mú Léfì.+ 9 Torí náà, màá mú kí gbogbo èèyàn tẹ́ńbẹ́lú yín kí wọ́n sì fojú kéré yín, torí ẹ kò pa àwọn ọ̀nà mi mọ́, ẹ sì ń ṣe ojúsàájú dípò kí ẹ tẹ̀ lé òfin.”+

10 “Ṣebí bàbá kan ni gbogbo wa ní?+ Àbí Ọlọ́run kan náà kọ́ ló dá wa? Kí ló wá dé tí a fi ń dalẹ̀ ara wa,+ tí a sì ń pẹ̀gàn májẹ̀mú àwọn baba ńlá wa? 11 Júdà ti dalẹ̀, wọ́n sì ti ṣe ohun tó ń ríni lára ní Ísírẹ́lì àti Jerúsálẹ́mù; torí Júdà ti kẹ́gàn ìjẹ́mímọ́* Jèhófà,+ èyí tí Òun nífẹ̀ẹ́, ó sì ti fi ọmọ ọlọ́run àjèjì ṣe ìyàwó.+ 12 Bí ẹnikẹ́ni nínú àgọ́ Jékọ́bù, tó bá ń ṣe nǹkan yìí bá tiẹ̀ mú ọrẹ wá fún Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun, Jèhófà yóò pa á run, ẹni yòówù kó jẹ́.”*+

13 “Ohun míì* wà tí ẹ ṣe, tó mú kí wọ́n fi omijé àti ẹkún sísun pẹ̀lú ẹ̀dùn ọkàn bo pẹpẹ Jèhófà, tí kò fi fiyè sí ọrẹ tí ẹ̀ ń mú wá mọ́, tí kò sì gba ohunkóhun lọ́wọ́ yín.+ 14 Ẹ sì sọ pé, ‘Kí nìdí?’ Ìdí ni pé Jèhófà ti ṣe ẹlẹ́rìí láàárín ìwọ àti aya ìgbà èwe rẹ tí o hùwà àìṣòótọ́ sí, bó tilẹ̀ jẹ́ pé òun ni ẹnì kejì rẹ, òun sì ni ìyàwó rẹ tí o bá dá májẹ̀mú.*+ 15 Àmọ́ ẹnì kan wà tí kò ṣe bẹ́ẹ̀ torí èyí tó ṣẹ́ kù lára ẹ̀mí náà wà lára rẹ̀. Kí sì ni ẹni yẹn ń wá? Ọmọ* Ọlọ́run. Torí náà, ẹ ṣọ́ ẹ̀mí tó ń darí yín, ẹ má sì hùwà àìṣòótọ́ sí aya ìgbà èwe yín. 16 Torí mo kórìíra* ìkọ̀sílẹ̀,”+ ni Jèhófà Ọlọ́run Ísírẹ́lì wí, “mo sì kórìíra ẹni tí ìwà ipá ti wọ̀ lẹ́wù,”* ni Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun wí. “Ẹ ṣọ́ ẹ̀mí tó ń darí yín, ẹ má sì hùwà àìṣòótọ́.+

17 “Ẹ ti jẹ́ kí ọ̀rọ̀ yín sú Jèhófà.+ Àmọ́ ẹ̀ ń sọ pé, ‘Kí la ṣe tó jẹ́ kí ọ̀rọ̀ wa sú u?’ Torí bí ẹ ṣe ń sọ pé, ‘Gbogbo ẹni tó ń ṣe ohun búburú jẹ́ ẹni rere lójú Jèhófà, inú rẹ̀ sì dùn sí wọn,’+ tàbí bí ẹ ṣe ń sọ pé, ‘Ibo ni Ọlọ́run tó ń ṣe ìdájọ́ òdodo wà?’”

3 Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun sọ pé: “Wò ó! Màá rán ìránṣẹ́ mi, á sì tún ọ̀nà ṣe* dè mí.+ Lójijì, Olúwa tòótọ́, ẹni tí ẹ̀ ń wá yóò wá sí tẹ́ńpìlì rẹ̀;+ ìránṣẹ́ májẹ̀mú yóò sì wá, ẹni tí inú yín dùn sí. Wò ó! Ó dájú pé ó máa wá.

2 “Àmọ́ ta ló máa lè fara da ọjọ́ tó máa wá, ta ló sì máa lè dúró nígbà tó bá fara hàn? Torí òun yóò dà bí iná ẹni tó ń yọ́ nǹkan mọ́ àti bí ọṣẹ+ alágbàfọ̀. 3 Ó máa jókòó bí ẹni tó ń yọ́ fàdákà, tó sì ń fọ̀ ọ́ mọ́,+ ó sì máa fọ àwọn ọmọ Léfì mọ́; á sì yọ́ wọn mọ́* bíi wúrà àti fàdákà, ó sì dájú pé wọ́n á fi ọkàn òdodo mú ọrẹ wá fún Jèhófà. 4 Ní tòótọ́, ọrẹ tí Júdà àti Jerúsálẹ́mù bá mú wá yóò mú inú Jèhófà dùn,* bíi ti àtijọ́ àti àwọn ọdún láéláé.+

5 “Èmi yóò sún mọ́ yín láti dá yín lẹ́jọ́, èmi yóò sì ta ko àwọn oníṣẹ́ oṣó láìjáfara,+ èmi yóò ta ko àwọn alágbèrè, àwọn tó ń búra èké,+ àwọn tó ń lu òṣìṣẹ́ àti opó àti ọmọ aláìníbaba* ní jìbìtì,+ títí kan àwọn tó kọ̀ láti ran àwọn àjèjì lọ́wọ́.*+ Wọn ò bẹ̀rù mi,” ni Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun wí.

6 “Torí èmi ni Jèhófà; èmi kì í yí pa dà.*+ Ẹ̀yin sì ni ọmọ Jékọ́bù; ẹ kò tíì pa run. 7 Láti ọjọ́ àwọn baba ńlá yín ni ẹ ti kẹ̀yìn sí àwọn ìlànà mi, ẹ kò sì tẹ̀ lé wọn.+ Ẹ pa dà sọ́dọ̀ mi, èmi yóò sì pa dà sọ́dọ̀ yín,”+ ni Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun wí.

Àmọ́, ẹ sọ pé: “Báwo la ṣe máa pa dà?”

8 “Ṣé èèyàn lásán lè ja Ọlọ́run lólè? Àmọ́ ẹ̀ ń jà mí lólè.”

Ẹ sì sọ pé: “Ọ̀nà wo ni a gbà jà ọ́ lólè?”

“Nínú ìdá mẹ́wàá àti ọrẹ ni. 9 Ó dájú pé ègún wà lórí yín* torí ẹ̀ ń jà mí lólè, àní gbogbo orílẹ̀-èdè yìí ló ń ṣe bẹ́ẹ̀. 10 Ẹ mú gbogbo ìdá mẹ́wàá wá sínú ilé ìkẹ́rùsí,+ kí oúnjẹ lè wà nínú ilé mi.+ Ẹ jọ̀ọ́, ẹ fi èyí dán mi wò,” ni Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun wí, “kí ẹ lè rí i bóyá mi ò ní ṣí ibú omi ọ̀run,+ kí n sì tú* ìbùkún sórí yín títí ẹ kò fi ní ṣaláìní ohunkóhun.”+

11 “Èmi yóò sì bá ẹni tó ń jẹ nǹkan run* wí torí yín, kò ní run èso ilẹ̀ yín, àjàrà inú oko yín yóò sì so èso,”+ ni Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun wí.

12 “Gbogbo orílẹ̀-èdè yóò pè yín ní aláyọ̀,+ torí ẹ ó di ilẹ̀ tó ń múnú ẹni dùn,” ni Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun wí.

13 Jèhófà sọ pé: “Ọ̀rọ̀ líle lẹ sọ sí mi.”

Ẹ sì sọ pé: “Ọ̀rọ̀ líle wo la sọ sí ọ?”+

14 “Ẹ sọ pé, ‘Kò sí àǹfààní kankan nínú sísin Ọlọ́run.+ Èrè wo la rí gbà bí a ti ń ṣe ojúṣe wa sí i, tí a sì ń kárí sọ níwájú Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun? 15 Ní báyìí, àwọn agbéraga* ni à ń pè ní aláyọ̀. Bákan náà, àwọn tó ń hùwà burúkú ń ṣàṣeyọrí.+ Àyà kò wọ́n láti dán Ọlọ́run wò, wọ́n sì ń mú un jẹ.’”

16 Ní àkókò yẹn, àwọn tó bẹ̀rù Jèhófà bá ara wọn sọ̀rọ̀, kálukú pẹ̀lú ẹnì kejì rẹ̀, Jèhófà sì ń fiyè sí i, ó sì ń fetí sílẹ̀. Wọ́n sì kọ ìwé ìrántí kan níwájú rẹ̀+ torí àwọn tó ń bẹ̀rù Jèhófà àti àwọn tó ń ṣe àṣàrò lórí orúkọ rẹ̀.*+

17 Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun sọ pé: “Wọn yóò di tèmi+ ní ọjọ́ tí mo bá sọ wọ́n di ohun ìní mi pàtàkì.*+ Èmi yóò ṣàánú wọn, bí èèyàn ṣe máa ń ṣàánú ọmọ rẹ̀ tó ń gbọ́ràn sí i lẹ́nu.+ 18 Ẹ ó sì tún rí ìyàtọ̀ láàárín olódodo àti ẹni burúkú,+ láàárín ẹni tó ń sin Ọlọ́run àti ẹni tí kò sìn ín.”

4 “Wò ó! ọjọ́ náà ń bọ̀, ó ń jó bí iná ìléru,+ nígbà tí gbogbo àwọn agbéraga àti gbogbo àwọn tó ń hùwà burúkú yóò dà bí àgékù pòròpórò. Ọjọ́ tó ń bọ̀ náà yóò jẹ wọ́n run,” ni Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun wí, “kò sì ní fi gbòǹgbò tàbí ẹ̀ka sílẹ̀ fún wọn. 2 Àmọ́ oòrùn òdodo yóò ràn sórí ẹ̀yin tó bọlá fún* orúkọ mi, ìtànṣán* rẹ̀ yóò mú yín lára dá; ẹ ó sì máa tọ pọ́n-ún pọ́n-ún kiri bí àwọn ọmọ màlúù tí wọ́n bọ́ sanra.”

3 Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun sọ pé: “Ẹ ó tẹ àwọn ẹni burúkú mọ́lẹ̀, torí wọ́n á dà bí eruku lábẹ́ ẹsẹ̀ yín, ní ọjọ́ tí mo bá ṣe ohun tí mo sọ.”

4 “Ẹ rántí Òfin Mósè ìránṣẹ́ mi, àwọn ìlànà àti àṣẹ tí mo pa fún gbogbo Ísírẹ́lì ní Hórébù pé kí wọ́n tẹ̀ lé.+

5 “Wò ó! Èmi yóò rán wòlíì Èlíjà sí yín+ kí ọjọ́ ńlá Jèhófà tó ń bani lẹ́rù tó dé.+ 6 Ó sì máa yí ọkàn àwọn bàbá pa dà sọ́dọ̀ àwọn ọmọ+ àti ọkàn àwọn ọmọ pa dà sọ́dọ̀ àwọn bàbá, kí n má bàa fìyà jẹ ayé, kí n sì pa á run.”

(Ìtumọ̀ Ìwé Mímọ́ Lédè Hébérù àti Árámáíkì parí, Ìwé Mímọ́ Kristẹni Lédè Gíríìkì ló kàn báyìí)

Ó túmọ̀ sí “Ìránṣẹ́ Mi.”

Tàbí “akátá.”

Tàbí “ọ̀gá àgbà.”

Tàbí “bọ̀wọ̀ fún.”

Ní Héb., “búrẹ́dì.”

Tàbí “tu Ọlọ́run lójú.”

Ó ṣe kedere pé, iṣẹ́ títi àwọn ilẹ̀kùn tẹ́ńpìlì ló ń sọ.

Tàbí “láti ìlà oòrùn dé ìwọ̀ oòrùn.”

Tàbí kó jẹ́, “pẹ̀gàn mi.”

Tàbí “àbààwọ́n.”

Ní Héb., “màá bá ohun tí ẹ gbìn wí.”

Ìyẹn, ibi tí wọ́n ń da ìgbẹ́ àwọn ẹran tí wọ́n fi rúbọ sí.

Tàbí “bọ̀wọ̀ fún; ní ọ̀wọ̀ tó jinlẹ̀ fún.”

Tàbí “Ẹ̀kọ́.”

Tàbí “ẹ̀kọ́.”

Tàbí kó jẹ́, “ẹ̀kọ́ yín.”

Tàbí kó jẹ́, “ibi mímọ́.”

Ní Héb., “ẹni tí kò sùn àti ẹni tó ń dáhùn.”

Ní Héb., “kejì.”

Tàbí “ìyàwó alárédè.”

Ní Héb., “èso.”

Ní Héb., “ó kórìíra.”

Tàbí “tó ń hùwà ipá.”

Tàbí “palẹ̀ ọ̀nà mọ́.”

Tàbí “mú kí wọ́n mọ́ kedere.”

Tàbí “yóò tẹ́ Jèhófà lọ́rùn.”

Tàbí “ọmọ aláìlóbìí.”

Tàbí “tó ń fi ẹ̀tọ́ àwọn àjèjì dù wọ́n.”

Tàbí “èmi kò yí pa dà.”

Tàbí kó jẹ́, “Ẹ̀ ń gégùn-ún fún mi.”

Ní Héb., “da.”

Ó lè jẹ́ àwọn kòkòrò tó ń ba nǹkan jẹ́ ló ń sọ.

Lédè Hébérù, ó tún túmọ̀ sí “ìgbójú” tàbí “ìkọjá àyè.”

Tàbí “ronú lórí orúkọ rẹ̀.” Tàbí kó jẹ́, “ka orúkọ rẹ̀ sí pàtàkì.”

Tàbí “tó ṣeyebíye.”

Ní Héb., “bẹ̀rù.”

Ní Héb., “àwọn ìyẹ́.”

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́