ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb20 January ojú ìwé 8
  • Bá A Ṣe Lè Fi Àṣàrò Kúkúrú Bẹ̀rẹ̀ Ìjíròrò

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Bá A Ṣe Lè Fi Àṣàrò Kúkúrú Bẹ̀rẹ̀ Ìjíròrò
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2020
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Àwọn Ìwé Àṣàrò Kúkúrú Wa Tuntun Ṣàrà Ọ̀tọ̀!
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2014
  • Bá A Ṣe Lè Lo Ohun Tá A Lè Bá Àwọn Èèyàn Sọ
    Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2020
  • Máa Lo Ìwé Àṣàrò Kúkúrú Láti Wàásù Ìhìn Rere
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2012
  • Lo Ìwé Àṣàrò Kúkúrú Láti Bẹ̀rẹ̀ Ìjíròrò
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2000
Àwọn Míì
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2020
mwb20 January ojú ìwé 8
Arábìnrin kan wàásù lọ́nà àìjẹ́-bí-àṣà fún obìnrin kan níbi tí wọ́n ti fẹ́ wọkọ̀, ó ń lo ìwé àṣàrò kúkúrú náà ‘Ǹjẹ́ Ìyà Lè Dópin?’

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Bá A Ṣe Lè Fi Àṣàrò Kúkúrú Bẹ̀rẹ̀ Ìjíròrò

Láti January 2018 la ti bẹ̀rẹ̀ sí í gbé apá tá a pè ní ohun tá a lè bá àwọn èèyàn sọ sí iwájú Ìwé Ìpàdé Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́. Àtìgbà yẹn la ti ń pọkàn pọ̀ sí bíba àwọn èèyàn sọ̀rọ̀ dípò ká kàn máa fún wọn láwọn ìwé wa. A tún ṣe àwọn fídíò ohun tá a lè bá àwọn èèyàn sọ kó lè rọrùn fún wa láti mọ bá a ṣe lè fi Bíbélì nìkan wàásù. Ṣé ìyẹn wá túmọ̀ sí pé a ò fẹ́ ká máa lo àwọn ìtẹ̀jáde wa lẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù ilé dé ilé mọ́ ni? Rárá o! Bí àpẹẹrẹ, àwọn ìwé àṣàrò kúkúrú wa gbéṣẹ́ gan-an láti fi bẹ̀rẹ̀ ìjíròrò. A lè gbìyànjú àwọn àbá yìí tá a bá fẹ́ lo èyíkéyìí nínú àwọn àṣàrò kúkúrú náà:

  1. Béèrè ìbéèrè tó wà níwájú àṣàrò kúkúrú náà, kó o sì ní kẹ́ni náà yan ìdáhùn tó rò pé ó tọ́.

  2. Fi ìdáhùn Bíbélì tó wà ní ojú ìwé kejì hàn onílé náà. Tí àkókò bá wà, o lè ka àwọn àlàyé díẹ̀ fún un látinú àṣàrò kúkúrú náà.

  3. Fún un ní àṣàrò kúkúrú náà kó o sì ní kó ka àwọn àlàyé tó kù láyè ara ẹ̀.

  4. Fi àwọn ìbéèrè tó wà lábẹ́ “Rò Ó Wò Ná” han onílé náà kó o sì ṣètò láti pa dà wá jíròrò ẹ̀ nígbà míì.

Ìwé àṣàrò kúkúrú náà, ‘Kí Ló Máa Ṣẹlẹ̀ Lọ́jọ́ Ọ̀la?’ A sì fi nọ́ńbà kìíní sí kẹrin tọ́ka sí àwọn apá tí ìwé náà ní.

Nígbà tó o bá pa dà lọ, jíròrò ìbéèrè tó o fi sílẹ̀ kó o sì tún fi ìbéèrè míì sílẹ̀ fún un. O lè yan ọ̀kan lára àwọn ìbéèrè tó wà lórí ìkànnì wa tàbí lára èyí tó wà nínú ìtẹ̀jáde tá a tọ́ka sí lẹ́yìn àṣàrò kúkúrú náà. O lè fún onílé náà ní ìwé Ìròyìn Ayọ̀ Látọ̀dọ̀ Ọlọ́run! tàbí èyíkéyìí nínú àwọn ìtẹ̀jáde tó wà nínú Àpótí Ìkọ́nilẹ́kọ̀ọ́ nígbà tó o bá rí i pé ó yẹ bẹ́ẹ̀.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́