ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w07 4/15 ojú ìwé 31
  • Aláàbọ̀ Ara Ni Síbẹ̀ Ó Fẹ́ Láti Ṣiṣẹ́ Ọlọ́run

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Aláàbọ̀ Ara Ni Síbẹ̀ Ó Fẹ́ Láti Ṣiṣẹ́ Ọlọ́run
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2007
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ṣé O Lè Lo Àkókò àti Okun Rẹ?
    Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2020
  • Ètò Kíkọ́ Gbọ̀ngàn Ìjọba—Ọ̀kan Pàtàkì Lára Iṣẹ́ Ìsìn Mímọ́
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2006
  • Ojúṣe Rẹ Nínú Kíkọ́lé fún Ọjọ́ Ọ̀la
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1996
  • Bó O Ṣe Lè Borí Ẹ̀dùn Ọkàn Tí Ikú Fà
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2008
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2007
w07 4/15 ojú ìwé 31

Aláàbọ̀ Ara Ni Síbẹ̀ Ó Fẹ́ Láti Ṣiṣẹ́ Ọlọ́run

TÉÈYÀN bá kọ́kọ́ rí Leonardo, kò jọ irú ẹni tó lè ṣiṣẹ́ ìkọ́lé. Ohun tó mú kó rí bẹ́ẹ̀ ni pé ó ti pàdánù ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì nígbà tí jàǹbá kan ṣẹlẹ̀ sí i lẹ́nu iṣẹ́ rẹ̀ nígbà kan sẹ́yìn. Àmọ́, pẹ̀lú bó ṣe jẹ́ aláàbọ̀ ara yẹn, ó fi ìtara ṣiṣẹ́ níbi iṣẹ́ ìkọ́lé kan nílùú Acajutla, lórílẹ̀-èdè El Salvador. Àwòrán ibi tó ti ń bá wọn ṣiṣẹ́ ìkọ́lé náà ló wà lójú ewé yìí.

Ó ní kí wọ́n bá òun ṣe ohun èlò ìṣiṣẹ́ tó máa jẹ́ kóun lè kópa nínú iṣẹ́ ìkọ́lé náà. Wọ́n wá bá a jó irin oníhò mọ́ ìdí ṣọ́bìrì. Á wá ki apá rẹ̀ ọ̀tún sáàárín irin oníhò tí wọ́n jó mọ́ ìdí ṣọ́bìrì yìí, á sì fọgbọ́n fi ṣọ́bìrì náà kó ilẹ̀ sínú bárò kan. Torí pé kò ní ọwọ́ tó máa fi di bárò náà mú, wọ́n bá a ṣe irin oníhò mọ́ ọwọ́ bárò náà kó lè máa ki apá rẹ̀ bọ̀ ọ́ láti fi tì í. Ṣùgbọ́n, kí ló sún un láti kópa nínú iṣẹ́ ìkọ́lé náà?

Ó jẹ́ ìfẹ́ ọkàn Leonardo pé kó wà lára àwọn tó máa kọ́ Gbọ̀ngàn Ìjọba kan, ìyẹn orúkọ táwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ń pe ibi tá a ti máa ń ṣe ìjọsìn. Ọ̀pọ̀ ìdí wà tó fi lè sọ pé òun ò ní lè ṣe nínú iṣẹ́ náà. Lára ẹ̀ ni pé, ó ní iṣẹ́ oúnjẹ òòjọ́ tó ń ṣe látàárọ̀ ṣúlẹ̀, ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì ti gé, ìránṣẹ́ iṣẹ́ òjíṣẹ́ tún ni nínú ìjọ wọn. Àmọ́, ó fẹ́ ṣe gbogbo ohun tó bá lè ṣe níbi iṣẹ́ ìkọ́lé náà láti ṣiṣẹ́ fún Ọlọ́run.

Ǹjẹ́ o ní irú ẹ̀mí tí arákùnrin yìí ní láti ṣiṣẹ́ Ọlọ́run? Kò fi jíjẹ́ tó jẹ́ aláàbọ̀ ara kẹ́wọ́, dípò ìyẹn, ńṣe ló ronú ọ̀nà tí wọ́n lè gbà bá a ṣe ohun èlò ìṣiṣẹ́ tirẹ̀ fúnra rẹ̀ kó bàa lè ṣeé ṣe fún un láti ṣiṣẹ́ tí kì bá má lè ṣe. ‘Gbogbo èrò inú rẹ̀’ ló fi ń sin Ọlọ́run. (Mátíù 22:37) Kò sí àní-àní pé ńṣe làwọn tó ń kópa nínú iṣẹ́ kíkọ́ Gbọ̀ngàn Ìjọba àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà jákèjádò ayé yọ̀ǹda ara wọn tọkàntọkàn, yálà wọ́n jẹ́ aláàbọ̀ ara tàbí wọn kì í ṣe aláàbọ̀ ara. Ẹnikẹ́ni ló lè wá síbi ìpàdé àwa Ẹlẹ́rìí. Torí náà, máa bọ̀.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́