ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 9/14 ojú ìwé 3
  • Máa Lo Ìkànnì jw.org Lẹ́nu Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Rẹ

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Máa Lo Ìkànnì jw.org Lẹ́nu Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Rẹ
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2014
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ìkànnì Wa Lórí Íńtánẹ́ẹ̀tì—Ó Wúlò Fún Àwa Àtàwọn Ẹlòmíì
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2012
  • Máa Lo Ìkànnì Wa Lẹ́nu Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Rẹ​—⁠“Ohun Tí Bíbélì Sọ”
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2014
  • Ibo La Ti Lè Rí Ìdáhùn sí Àwọn Ìbéèrè Pàtàkì Nípa Ìgbésí Ayé?
    Ibo La Ti Lè Rí Ìdáhùn sí Àwọn Ìbéèrè Pàtàkì Nípa Ìgbésí Ayé?
  • Ohun Tó Lè Ràn Ẹ́ Lọ́wọ́
    Jí!—2020
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2014
km 9/14 ojú ìwé 3

Máa Lo Ìkànnì jw.org Lẹ́nu Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Rẹ

Ohun èlò tó wúlò gan-an ni Ìkànnì wa, ó ń jẹ́ ká lè tan ìhìn rere “dé apá ibi jíjìnnà jù lọ ní ilẹ̀ ayé.” (Ìṣe 1:8) Ọ̀pọ̀ onílé ni kò mọ bí wọ́n ṣe lè lọ sórí ìkànnì jw.org fúnra wọn. Àfi tí àkéde kan bá kọ́ wọn ni wọ́n tó lè mọ̀ ọ́n.

Alábòójútó arìnrìn-àjò kan wa fídíò náà, Kí Nìdí Tó Fi Yẹ Kó O Kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì? jáde lórí ìkànnì, ó gbé e sórí fóònù rẹ̀, ó sì ń fi han àwọn èèyàn ní gbogbo ìgbà tó bá ti láǹfààní láti ṣe bẹ́ẹ̀. Bí àpẹẹrẹ, tó bá ń wàásù láti ilé-dé-ilé, ó máa ń sọ pé: “Mo ń lọ sọ́dọ̀ àwọn èèyàn kí ń lè fi ìdáhùn sí àwọn ìbéèrè pàtàkì mẹ́ta kan hàn wọ́n, àwọn ìbéèrè náà ni: Kí nìdí tí ìṣòro fi pọ̀ gan-an láyé? Báwo ni Ọlọ́run ṣe máa yanjú àwọn ìṣòro yìí? Báwo la ṣe lè máa fara dà á títí dìgbà tí Ọlọ́run á fi yanjú àwọn ìṣòro yìí? Fídíò kékeré yìí dáhùn àwọn ìbéèrè yẹn.” Alábòójútó arìnrìn-àjò yìí á wá tan fídíò náà, yóò sì máa wo onílé láti mọ̀ bóyá ó nífẹ̀ẹ́ sí i. Fídíò náà máa ń gba ọ̀pọ̀ èèyàn lọ́kàn débi pé wọn kì í fẹ́ gbójú kúrò títí tó fi máa parí. Lẹ́yìn tí fídíò yìí bá parí, alábòójútó arìnrìn-àjò náà yóò wá sọ pé: “Ẹ gbọ́ tí wọ́n sọ nínú fídíò yìí pé ẹ lè kọ ọ̀rọ̀ sínú fọ́ọ̀mù tó wà fún bíbéèrè fún ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì lórí ìkànnì. Ọ̀kan lára àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà ni mí, mo sì lè fi bí a ṣe ń ṣe ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì hàn yín nísinsìnyí.” Tí onílé bá nífẹ̀ẹ́ sí i, arákùnrin náà yóò lo ìwé Ìròyìn Ayọ̀ láti fi bí a ṣe ń ṣe ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì hàn án. Bí onílé ò bá ráyè, yóò sọ fún un pé òun á pa dà wá fi bí a ṣe ń ṣe ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì hàn án nígbà míì. Ohun kan náà ló máa ń sọ tó bá dúró sinmi díẹ̀ níbì kan, lẹ́yìn tó bá bá àwọn tó wà níbẹ̀ fọ̀rọ̀ wérọ̀, yóò fi fídíò náà hàn wọ́n. Ǹjẹ́ ìwọ náà máa ń lo ìkànnì jw.org lẹ́nu iṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ?

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́