ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb17 March ojú ìwé 8
  • Bá A Ṣe Lè Lo Ìwé Àwọn Wo Ló Ń ṣe Ìfẹ́ Jèhófà Lóde Òní?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Bá A Ṣe Lè Lo Ìwé Àwọn Wo Ló Ń ṣe Ìfẹ́ Jèhófà Lóde Òní?
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Àwa Kristẹni​—Ìwé Ìpàdé (2017)
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Bá A Ṣe Lè Lo Ìwé Àwọn Wo Ló Ń Ṣe Ìfẹ́ Jèhófà Lóde Òní?
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2013
  • Bá A Ṣe Lè Lo Ìwé Ìròyìn Ayọ̀ Látọ̀dọ̀ Ọlọ́run!
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2013
  • Ohun Tó O Kọ́ Ní Apá 2
    Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
  • Àwọn Wo Ló Ń Ṣe Ìfẹ́ Jèhófà Lóde Òní?
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2013
Àwọn Míì
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Àwa Kristẹni​—Ìwé Ìpàdé (2017)
mwb17 March ojú ìwé 8
Arábìnrin kan ń fi ìwé pẹlẹbẹ Àwọn Wo Ló Ń ṣe Ìfẹ́ Jèhófà Lóde Òní? kọ́ ẹnì kan lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Bá A Ṣe Lè Lo Ìwé Àwọn Wo Ló Ń ṣe Ìfẹ́ Jèhófà Lóde Òní?

Ohun tó wà nínú ìwé Àwọn Wo Ló Ń ṣe Ìfẹ́ Jèhófà Lóde Òní

A ṣe ìwé pẹlẹbẹ Àwọn Wo Ló Ń ṣe Ìfẹ́ Jèhófà Lóde Òní? ká lè jíròrò rẹ̀ pẹ̀lú akẹ́kọ́ọ̀ ṣáájú tàbí lẹ́yìn ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì kọ̀ọ̀kan.a Ẹ̀kọ́ 1 sí 4 máa jẹ́ kí akẹ́kọ̀ọ́ mọ irú èèyàn tá a jẹ́, ẹ̀kọ́ 5 sí 14 máa jẹ́ kí wọ́n mọ àwọn nǹkan tí à ń ṣe, ẹ̀kọ́ 15 sí 28 sì máa ṣàlàyé ohun tí ètò wa ń gbéṣe fún wọn. Ó máa dáa ká jíròrò àwọn ẹ̀kọ́ yìí ní ṣísẹ̀-n-tẹ̀lé, àyàfi tó bá gba pé ká jíròrò apá kan ní kíá. Ojú ìwé kan ni ẹ̀kọ́ kọ̀ọ̀kan wà, a sì lè lo ìṣẹ́jú márùn-ún sí mẹ́wàá láti jíròrò ẹ̀kọ́ kan.

  • Ẹ̀kọ́ 8 nínú ìwé Àwọn Wo Ló Ń ṣe Ìfẹ́ Jèhófà Lóde Òní

    Pe àfíyèsí akẹ́kọ́ọ̀ sí ìbéèrè àkọ́kọ́ tó jẹ́ àkórí ẹ̀kọ́ náà

  • Ẹ jọ ka ẹ̀kọ́ náà papọ̀, ẹ lè kà á látòkè-délẹ̀ lẹ́ẹ̀kan náà, ẹ sì lè ṣàlàyé ìpínrọ̀ kan kí ẹ tó ka ìpínrọ̀ tó tẹ̀lé e

  • Ẹ jọ jíròrò ohun tí ẹ kà. Béèrè àwọn ìbẹ́èrè tó wà nísàlẹ̀ ìwé, kí ẹ sì sọ̀rọ̀ lórí àwọn àwòrán tó wà níbẹ̀. Àwa la máa pinnu èyí tá a máa kà nínú àwọn ẹsẹ Bíbélì tí wọ́n tọ́ka sí, tá a sì máa ṣàlàyé. Sọ bí àwọn ìsọ̀rí tí wọ́n kọ lọ́nà tó dúdú yàtọ̀ ṣe dáhùn ìbéèrè tó jẹ́ àkórí ẹ̀kọ́ náà

  • Tí àpótí “Ṣe Ìwádìí Sí I” bá wà nínú ẹ̀kọ́ náà, ẹ jọ́ kà á, kó o sì gba akẹ́kọ̀ọ́ náà níyànjú pé kó tẹ̀lé àbá tó wà níbẹ̀

a A ti ṣe àwọn àtúnṣe díẹ̀ sí ẹ̀dà ìwé yìí tó wà lórí ìkànnì.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́