ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb20 February ojú ìwé 7
  • Bó O Ṣe Lè Jàǹfààní Látinú Ṣíṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Bó O Ṣe Lè Jàǹfààní Látinú Ṣíṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́?
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2020
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ìtòlẹ́sẹẹsẹ Ìdílé—Ẹ̀kọ́ Ojoojúmọ́
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2005
  • Ẹ̀yin Olórí Ìdílé—Ẹ Jẹ́ Kí Ìtòlẹ́sẹẹsẹ Àwọn Nǹkan Tẹ̀mí Máa Bá A Lọ Láìdáwọ́dúró Nínú Ìdílé Yín
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2002
  • Ṣe Ìtòlẹ́sẹẹsẹ Ìdílé Tá Á Ṣeé Tẹ̀ Lé
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2005
  • Nínasẹ̀ Ìwé Mímọ́ Lọ́nà Tó Gbéṣẹ́
    Jàǹfààní Nínú Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run
Àwọn Míì
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2020
mwb20 February ojú ìwé 7

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Bó O Ṣe Lè Jàǹfààní Látinú Ṣíṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́

Ṣé o máa ń ka ìwé Ṣíṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́? Ṣé ó wà lára ohun tó o máa ń ṣe lójoojúmọ́ láti túbọ̀ sún mọ́ Jèhófà? Tí o kì í bá ráyè ṣe bẹ́ẹ̀, ṣé o lè fi kún ohun tó o máa ń ṣe? Àwọn kan máa ń kà á ní ìdájí kí wọ́n lè máa ronú lé e lórí jálẹ̀ ọjọ́ yẹn. (Joṣ 1:8; Sm 119:97) Báwo ló ṣe lè túbọ̀ jàǹfààní nínú ẹsẹ Bíbélì ọjọ́ kọ̀ọ̀kan? Ka àwọn ẹsẹ Bíbélì tó ṣáájú àti èyí tó tẹ̀ lé èyí tí wọ́n tọ́ka sí, kó o lè mọ ibi tí wọ́n ti ń bọ́rọ̀ bọ̀ àti ibi tí wọ́n ń bọ́rọ̀ lọ. Ronú nípa àpẹẹrẹ kan nínú Bíbélì tó ṣàlàyé ìlànà tó wà nínú ẹsẹ Bíbélì náà. Lẹ́yìn ìyẹn, wo bó o ṣe lè fi ìlànà náà sílò. Ó dájú pé tó o bá ń ronú nípa àwọn ìlànà Bíbélì kó o tó ṣèpinnu, ìgbésí ayé rẹ máa nítumọ̀, á sì ṣe ẹ́ láǹfààní.​—Sm 119:105.

Àsìkò oúnjẹ àárọ̀ làwọn ìdílé Bẹ́tẹ́lì kárí ayé máa ń ka ẹsẹ ojúmọ́. Àtọdún díẹ̀ sẹ́yìn la ti ń gbé àwọn ìjíròrò yìí sórí JW Broadcasting® ìyẹn ètò Tẹlifíṣọ̀n JW. Wàá rí àwọn fídíò yìí ní abala ÀWỌN ÈTÒ ÀTI ÌṢẸ̀LẸ̀ PÀTÀKÌ. Ìgbà wo lo lọ síbẹ̀ kẹ́yìn, bóyá tó o wo ọ̀kan tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ nínú wọn? Ó ṣeé ṣe kó o gbọ́ ọ̀rọ̀ tó máa bá ipò rẹ mu. Bí àpẹẹrẹ, báwo lohun tó ṣẹlẹ̀ sí Lọ́ọ̀tì ṣe lè mú kó o ṣe ìpinnu tó tọ́?

WO FÍDÍÒ NÁÀ Ẹ MÁ ṢE MÁA NÍFẸ̀Ẹ́ AYÉ (1JO 2:15), KÓ O SÌ DÁHÙN ÀWỌN ÌBÉÈRÈ YÌÍ:

  • Ìlànà Bíbélì wo ni wọ́n gbé Ìjọsìn Òwúrọ̀ yìí kà?

  • Báwo ni ìtàn Lọ́ọ̀tì ṣe jẹ́ ká rí ewu tó wà nínú kéèyàn nífẹ̀ẹ́ ayé tàbí àwọn nǹkan tó wà nínú rẹ̀?​—Jẹ 13:12; 14:12; 19:3, 12, 13, 24-26

  • Báwo la ṣe lè fi hàn pé Jèhófà la nífẹ̀ẹ́ dípò ayé tàbí àwọn nǹkan tó wà nínú rẹ̀?

Àwọn àwòrán: Arákùnrin kan ń ronú lórí ẹsẹ ojúmọ́ ọjọ́ kan jálẹ̀ gbogbo ọjọ́ náà. 1. Nígbà tó ń ka ẹsẹ ojúmọ́ náà, ó ronú nípa bí àwọn áńgẹ́lì ṣe mú Lọ́ọ̀tì àti ìdílé rẹ̀ jáde kúrò nínú ìlú Sódómù. 2. Nígbà tó ń jẹun ọ̀sán níbi iṣẹ́, ó tún ń ronú nípa ohun tó ti kà. 3. Nígbà tó pa dà dé ilé lálẹ́, ó túbọ̀ ṣàṣàrò lórí ohun tó ti kà nínú ẹsẹ ojúmọ́ ọjọ́ náà bó ṣe ń ká àwọn aṣọ tó fọ̀.

Báwo ni mo ṣe lè fi hàn jálẹ̀ ọjọ́ kan pé mo mọyì Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run?

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́