ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Sáàmù 140
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Sáàmù

      • Jèhófà, Olùgbàlà tó lágbára

        • Àwọn aṣebi dà bí ejò (3)

        • Àwọn oníwà ipá yóò ṣubú (11)

Sáàmù 140:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 18:48; 59:1

Sáàmù 140:2

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 64:2, 6

Sáàmù 140:3

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 52:1, 2; 58:3, 4
  • +Ro 3:13; Jem 3:8

Sáàmù 140:4

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 17:8; 36:11; 71:4

Sáàmù 140:5

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 10:9
  • +Jer 18:22

Sáàmù 140:6

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 28:2; 55:1

Sáàmù 140:7

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 17:37

Sáàmù 140:8

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 15:31; Sm 27:12

Sáàmù 140:9

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 7:16; Owe 12:13

Sáàmù 140:10

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “kòtò olómi.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 11:5, 6
  • +Sm 55:23

Sáàmù 140:11

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “lórí ilẹ̀.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 12:3

Sáàmù 140:12

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 10:17, 18; 22:24

Sáàmù 140:13

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “lọ́dọ̀.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 23:6

Àwọn míì

Sm 140:1Sm 18:48; 59:1
Sm 140:2Sm 64:2, 6
Sm 140:3Sm 52:1, 2; 58:3, 4
Sm 140:3Ro 3:13; Jem 3:8
Sm 140:4Sm 17:8; 36:11; 71:4
Sm 140:5Sm 10:9
Sm 140:5Jer 18:22
Sm 140:6Sm 28:2; 55:1
Sm 140:71Sa 17:37
Sm 140:82Sa 15:31; Sm 27:12
Sm 140:9Sm 7:16; Owe 12:13
Sm 140:10Sm 11:5, 6
Sm 140:10Sm 55:23
Sm 140:11Sm 12:3
Sm 140:12Sm 10:17, 18; 22:24
Sm 140:13Sm 23:6
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Sáàmù 140:1-13

Sáàmù

Fún olùdarí. Orin Dáfídì.

140 Jèhófà, gbà mí lọ́wọ́ àwọn aṣebi;

Dáàbò bò mí lọ́wọ́ àwọn oníwà ipá,+

2 Àwọn tó ń gbèrò ibi nínú ọkàn wọn,+

Tí wọ́n sì ń dá ìjà sílẹ̀ látàárọ̀ ṣúlẹ̀.

3 Wọ́n pọ́n ahọ́n wọn bíi ti ejò;+

Oró paramọ́lẹ̀ wà lábẹ́ ètè wọn.+ (Sélà)

4 Jèhófà, dáàbò bò mí lọ́wọ́ ẹni burúkú;+

Máa ṣọ́ mi lọ́wọ́ àwọn oníwà ipá,

Àwọn tó ń gbèrò láti mú kí n yọ̀ ṣubú.

5 Àwọn agbéraga dẹ pańpẹ́ pa mọ́ dè mí;

Wọ́n fi okùn ta àwọ̀n sẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀nà.+

Wọ́n dẹkùn fún mi.+ (Sélà)

6 Mo sọ fún Jèhófà pé: “Ìwọ ni Ọlọ́run mi.

Jèhófà, jọ̀wọ́ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi fún ìrànlọ́wọ́.”+

7 Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ, Olùgbàlà mi tó lágbára,

O dáàbò bo orí mi ní ọjọ́ ogun.+

8 Jèhófà, má ṣe fún àwọn ẹni burúkú ní ohun tí ọkàn wọn fẹ́.

Má ṣe jẹ́ kí ohun tí wọ́n gbèrò bọ́ sí i, kí wọ́n má bàa gbé ara wọn ga.+ (Sélà)

9 Kí ọ̀rọ̀ ibi tí àwọn tó yí mi ká ń fẹnu wọn sọ+

Dà lé wọn lórí.

10 Kí òjò ẹyin iná rọ̀ lé wọn lórí.+

Ká jù wọ́n sínú iná,

Sínú àwọn kòtò jíjìn,*+ kí wọ́n má ṣe gbérí mọ́.

11 Kí àwọn abanijẹ́ má ṣe ríbi gbé nínú ayé.*+

Kí ibi máa lépa àwọn oníwà ipá, kó sì mú wọn balẹ̀.

12 Mo mọ̀ pé Jèhófà máa gbèjà àwọn aláìní

Á sì ṣèdájọ́ òdodo fún àwọn tálákà.+

13 Ó dájú pé àwọn olódodo yóò máa fi ọpẹ́ fún orúkọ rẹ;

Àwọn adúróṣinṣin yóò máa gbé níwájú* rẹ.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́