ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ẹ́kísódù 32
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Ẹ́kísódù

      • Wọ́n jọ́sìn ère ọmọ màlúù (1-35)

        • Mósè gbọ́ orin tó ṣàjèjì (17, 18)

        • Mósè fọ́ àwọn wàláà òfin túútúú (19)

        • Àwọn ọmọ Léfì ò fi Jèhófà sílẹ̀ (26-29)

Ẹ́kísódù 32:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 24:18; Di 9:9
  • +Iṣe 7:40

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    5/15/2009, ojú ìwé 11

Ẹ́kísódù 32:2

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 12:35, 36

Ẹ́kísódù 32:4

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ère dídà.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 9:16; Ais 46:6; Iṣe 7:41
  • +Ẹk 20:4; Ne 9:18; Sm 106:19, 20

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!, ẹ̀kọ́ 44

Ẹ́kísódù 32:6

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Kọ 10:7

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé-Ìṣọ́nà,

    3/1/1995, ojú ìwé 16

Ẹ́kísódù 32:7

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 4:15-18

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!, ẹ̀kọ́ 44

Ẹ́kísódù 32:8

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ère dídà.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 18:20; 20:3

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!, ẹ̀kọ́ 44

Ẹ́kísódù 32:9

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “ọlọ́rùn líle.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 34:9; Di 9:6; Iṣe 7:51

Ẹ́kísódù 32:10

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 14:12; Di 9:14

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    10/15/2010, ojú ìwé 5-6

Ẹ́kísódù 32:11

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “tu Jèhófà Ọlọ́run rẹ̀ lójú.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 106:23
  • +Di 9:18, 19

Ẹ́kísódù 32:12

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “yí ìpinnu rẹ pa dà.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 9:28

Ẹ́kísódù 32:13

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “èso.”

  • *

    Ní Héb., “èso.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 22:15-17; 35:10, 11; Heb 6:13, 14
  • +Jẹ 13:14, 15; 26:3, 4

Ẹ́kísódù 32:14

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “yí ìpinnu rẹ̀ pa dà.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 106:45

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́),

    9/2018, ojú ìwé 6

    Ilé Ìṣọ́,

    10/15/2010, ojú ìwé 5-6

Ẹ́kísódù 32:15

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 40:20; Di 5:22
  • +Di 9:15

Ẹ́kísódù 32:16

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 31:18; Di 9:10

Ẹ́kísódù 32:18

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “iṣẹ́ àgbàyanu.”

Ẹ́kísódù 32:19

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ne 9:18; Sm 106:19, 20; Iṣe 7:41
  • +Di 9:16, 17

Ẹ́kísódù 32:20

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 7:25
  • +Di 9:21

Ẹ́kísódù 32:22

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 15:24; 16:2; 17:2; Di 9:7; 31:27

Ẹ́kísódù 32:23

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 32:1; Iṣe 7:40

Ẹ́kísódù 32:26

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 24:15; 2Ọb 10:15

Ẹ́kísódù 32:27

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 25:5

Ẹ́kísódù 32:29

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “Ẹ fi kún ọwọ́ yín.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 25:11; Di 13:6-9
  • +Di 33:8, 9

Ẹ́kísódù 32:30

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 16:47; 21:7; Di 9:18

Ẹ́kísódù 32:31

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 20:23

Ẹ́kísódù 32:32

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 14:19
  • +Flp 4:3; Ifi 3:5

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    11/1/2012, ojú ìwé 15

    10/2020, ojú ìwé 2

Ẹ́kísódù 32:33

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àwọn Ìtẹ̀jáde Tá A Tọ́ka sí Nínú Ìwé Ìpàdé,

    10/2020, ojú ìwé 2

Ẹ́kísódù 32:34

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 23:20; 33:2

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àsọtẹ́lẹ̀ Dáníẹ́lì, ojú ìwé 204-205

Àwọn míì

Ẹ́kís. 32:1Ẹk 24:18; Di 9:9
Ẹ́kís. 32:1Iṣe 7:40
Ẹ́kís. 32:2Ẹk 12:35, 36
Ẹ́kís. 32:4Di 9:16; Ais 46:6; Iṣe 7:41
Ẹ́kís. 32:4Ẹk 20:4; Ne 9:18; Sm 106:19, 20
Ẹ́kís. 32:61Kọ 10:7
Ẹ́kís. 32:7Di 4:15-18
Ẹ́kís. 32:8Ẹk 18:20; 20:3
Ẹ́kís. 32:9Ẹk 34:9; Di 9:6; Iṣe 7:51
Ẹ́kís. 32:10Nọ 14:12; Di 9:14
Ẹ́kís. 32:11Sm 106:23
Ẹ́kís. 32:11Di 9:18, 19
Ẹ́kís. 32:12Di 9:28
Ẹ́kís. 32:13Jẹ 22:15-17; 35:10, 11; Heb 6:13, 14
Ẹ́kís. 32:13Jẹ 13:14, 15; 26:3, 4
Ẹ́kís. 32:14Sm 106:45
Ẹ́kís. 32:15Ẹk 40:20; Di 5:22
Ẹ́kís. 32:15Di 9:15
Ẹ́kís. 32:16Ẹk 31:18; Di 9:10
Ẹ́kís. 32:19Ne 9:18; Sm 106:19, 20; Iṣe 7:41
Ẹ́kís. 32:19Di 9:16, 17
Ẹ́kís. 32:20Di 7:25
Ẹ́kís. 32:20Di 9:21
Ẹ́kís. 32:22Ẹk 15:24; 16:2; 17:2; Di 9:7; 31:27
Ẹ́kís. 32:23Ẹk 32:1; Iṣe 7:40
Ẹ́kís. 32:26Joṣ 24:15; 2Ọb 10:15
Ẹ́kís. 32:27Nọ 25:5
Ẹ́kís. 32:29Nọ 25:11; Di 13:6-9
Ẹ́kís. 32:29Di 33:8, 9
Ẹ́kís. 32:30Nọ 16:47; 21:7; Di 9:18
Ẹ́kís. 32:31Ẹk 20:23
Ẹ́kís. 32:32Nọ 14:19
Ẹ́kís. 32:32Flp 4:3; Ifi 3:5
Ẹ́kís. 32:34Ẹk 23:20; 33:2
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
  • 20
  • 21
  • 22
  • 23
  • 24
  • 25
  • 26
  • 27
  • 28
  • 29
  • 30
  • 31
  • 32
  • 33
  • 34
  • 35
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Ẹ́kísódù 32:1-35

Ẹ́kísódù

32 Ní gbogbo àkókò yẹn, àwọn èèyàn náà rí i pé Mósè ń pẹ́ lórí òkè náà.+ Àwọn èèyàn náà wá yí Áárónì ká, wọ́n sì sọ fún un pé: “Ó yá, ṣe ọlọ́run kan fún wa tó máa ṣáájú wa,+ torí a ò mọ ohun tó ti ṣẹlẹ̀ sí Mósè yìí, ẹni tó kó wa kúrò ní ilẹ̀ Íjíbítì.” 2 Ni Áárónì bá sọ fún wọn pé: “Ẹ gba yẹtí wúrà+ tó wà ní etí àwọn ìyàwó yín, àwọn ọmọ yín lọ́kùnrin àti lóbìnrin, kí ẹ sì kó o wá fún mi.” 3 Gbogbo àwọn èèyàn náà wá bẹ̀rẹ̀ sí í bọ́ yẹtí wúrà tó wà ní etí wọn, wọ́n sì ń kó o wá fún Áárónì. 4 Ó gba wúrà náà lọ́wọ́ wọn, ó lo irinṣẹ́ àwọn tó ń fín nǹkan láti fi mọ ọ́n, ó sì fi ṣe ère* ọmọ màlúù.+ Wọ́n wá ń sọ pé: “Ìwọ Ísírẹ́lì, Ọlọ́run rẹ nìyí, òun ló mú ọ kúrò ní ilẹ̀ Íjíbítì.”+

5 Nígbà tí Áárónì rí èyí, ó mọ pẹpẹ kan síwájú rẹ̀. Áárónì wá kéde pé: “Àjọyọ̀ wà fún Jèhófà lọ́la.” 6 Ni wọ́n bá tètè dìde ní ọjọ́ kejì, wọ́n wá bẹ̀rẹ̀ sí í rú ẹbọ sísun, wọ́n sì ń mú àwọn ẹbọ ìrẹ́pọ̀ wá. Lẹ́yìn náà, àwọn èèyàn náà jókòó láti jẹ àti láti mu. Wọ́n sì dìde láti gbádùn ara wọn.+

7 Jèhófà wá sọ fún Mósè pé: “Máa lọ, sọ̀ kalẹ̀, torí pé àwọn èèyàn rẹ tí o mú kúrò ní ilẹ̀ Íjíbítì ti ba ara wọn jẹ́.+ 8 Wọ́n ti yára kúrò ní ọ̀nà tí mo pa láṣẹ fún wọn pé kí wọ́n máa rìn.+ Wọ́n ti ṣe ère* ọmọ màlúù fún ara wọn, wọ́n ń tẹrí ba fún un, wọ́n sì ń rúbọ sí i, wọ́n ń sọ pé, ‘Ìwọ Ísírẹ́lì, Ọlọ́run rẹ nìyí, òun ló mú ọ kúrò ní ilẹ̀ Íjíbítì.’” 9 Jèhófà ń bá ọ̀rọ̀ tó ń sọ fún Mósè lọ pé: “Mo ti rí i pé alágídí* ni àwọn èèyàn yìí.+ 10 Ní báyìí, fi mí sílẹ̀, màá fi ìbínú mi tó ń jó bí iná pa wọ́n run, kí o sì jẹ́ kí n sọ ìwọ di orílẹ̀-èdè ńlá dípò wọn.”+

11 Mósè wá bẹ Jèhófà Ọlọ́run rẹ̀,*+ ó sọ pé: “Jèhófà, kí ló dé tí wàá fi bínú gidigidi sí àwọn èèyàn rẹ, lẹ́yìn tí o fi agbára ńlá àti ọwọ́ agbára mú wọn kúrò ní ilẹ̀ Íjíbítì?+ 12 Ṣé kí àwọn ará Íjíbítì wá máa sọ pé, ‘Èrò ibi ló wà lọ́kàn rẹ̀ nígbà tó mú wọn kúrò ní ilẹ̀ wa. Ṣe ló fẹ́ pa wọ́n síbi àwọn òkè, kó sì run wọ́n kúrò lórí ilẹ̀’?+ Má ṣe jẹ́ kínú bí ọ sí wọn, jọ̀ọ́ pèrò dà nípa ìpinnu tí o ṣe* láti mú àjálù yìí bá àwọn èèyàn rẹ. 13 Rántí Ábúráhámù, Ísákì àti Ísírẹ́lì, àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí o fi ara rẹ búra fún pé, ‘Màá mú kí ọmọ* rẹ pọ̀ bí àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run,+ màá sì fún ọmọ* rẹ ní gbogbo ilẹ̀ tí mo yàn yìí, kó lè di ohun ìní wọn títí láé.’”+

14 Jèhófà wá bẹ̀rẹ̀ sí í pèrò dà* lórí àjálù tó sọ pé òun máa mú bá àwọn èèyàn òun.+

15 Lẹ́yìn náà, Mósè yíjú pa dà, ó sì sọ̀ kalẹ̀ lórí òkè náà, ó gbé wàláà Ẹ̀rí méjì+ náà dání.+ Ọ̀rọ̀ tí a kọ wà lára wàláà náà ní ojú méjèèjì, ní iwájú àti ní ẹ̀yìn. 16 Iṣẹ́ ọnà Ọlọ́run ni àwọn wàláà náà, Ọlọ́run ló sì kọ ọ̀rọ̀ sára rẹ̀.+ 17 Nígbà tí Jóṣúà bẹ̀rẹ̀ sí í gbọ́ bí àwọn èèyàn náà ṣe ń pariwo, ó sọ fún Mósè pé: “Ariwo ogun wà nínú àgọ́.” 18 Àmọ́ Mósè sọ pé:

“Kì í ṣe orin ìṣẹ́gun,*

Kì í sì í ṣe ìró àwọn tó ń pohùn réré ẹkún torí pé wọ́n ṣẹ́gun wọn;

Ìró orin míì ni mò ń gbọ́.”

19 Gbàrà tí Mósè sún mọ́ àgọ́ náà, tó sì rí ère ọmọ màlúù+ àtàwọn tó ń jó, inú bí Mósè gan-an, ó ju àwọn wàláà náà sílẹ̀, ó sì fọ́ wọn túútúú sí ẹsẹ̀ òkè náà.+ 20 Ó mú ère ọmọ màlúù tí wọ́n ṣe, ó fi iná sun ún, ó sì fọ́ ọ túútúú tó fi di lẹ́búlẹ́bú;+ ó wá fọ́n ọn sójú omi, ó sì mú kí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì mu ún.+ 21 Mósè bi Áárónì pé: “Kí ni àwọn èèyàn yìí ṣe sí ọ tí o fi mú kí wọ́n dá ẹ̀ṣẹ̀ ńlá?” 22 Áárónì fèsì pé: “Má bínú, olúwa mi. O mọ̀ dáadáa pé èrò ibi ló wà lọ́kàn àwọn èèyàn náà.+ 23 Wọ́n sọ fún mi pé, ‘Ṣe ọlọ́run kan fún wa tó máa ṣáájú wa, torí a ò mọ ohun tó ti ṣẹlẹ̀ sí Mósè yìí, ẹni tó kó wa kúrò ní ilẹ̀ Íjíbítì.’+ 24 Mo wá sọ fún wọn pé, ‘Kí ẹnikẹ́ni tó bá ní wúrà yọ ọ́ wá, kó sì fún mi.’ Mo jù ú sínú iná, òun sì ni mo fi ṣe ọmọ màlúù yìí.”

25 Mósè rí i pé apá ò ká àwọn èèyàn náà mọ́, torí Áárónì ti fàyè gbà wọ́n, wọ́n sì ti di ẹni ìtìjú lójú àwọn alátakò wọn. 26 Lẹ́yìn náà, Mósè dúró ní ẹnubodè àgọ́ náà, ó sì sọ pé: “Ta ló fara mọ́ Jèhófà? Kó máa bọ̀ lọ́dọ̀ mi!”+ Gbogbo àwọn ọmọ Léfì sì kóra jọ sọ́dọ̀ rẹ̀. 27 Ó wá sọ fún wọn pé: “Ohun tí Jèhófà Ọlọ́run Ísírẹ́lì sọ nìyí, ‘Kí kálukú yín sán idà rẹ̀ mọ́ ẹ̀gbẹ́, kí ẹ sì lọ káàkiri àgọ́ náà láti ẹnubodè sí ẹnubodè, kí kálukú pa arákùnrin rẹ̀, aládùúgbò rẹ̀ àti ọ̀rẹ́ rẹ̀ tímọ́tímọ́.’”+ 28 Àwọn ọmọ Léfì ṣe ohun tí Mósè sọ. Nǹkan bí ẹgbẹ̀rún mẹ́ta (3,000) èèyàn ni wọ́n pa lọ́jọ́ yẹn. 29 Mósè wá sọ pé: “Ẹ ya ara yín sọ́tọ̀* fún Jèhófà lónìí, torí kálukú yín ti kẹ̀yìn sí ọmọ rẹ̀ àti arákùnrin rẹ̀;+ òun yóò bù kún yín lónìí.”+

30 Ní ọjọ́ kejì, Mósè sọ fún àwọn èèyàn náà pé: “Ẹ̀ṣẹ̀ ńlá lẹ dá, màá sì gòkè tọ Jèhófà lọ báyìí, kí n wò ó bóyá mo lè bá yín wá nǹkan ṣe sí ẹ̀ṣẹ̀ tí ẹ dá.”+ 31 Mósè wá pa dà sọ́dọ̀ Jèhófà, ó sì sọ pé: “Ẹ̀ṣẹ̀ tí àwọn èèyàn yìí dá mà burú o! Wọ́n fi wúrà ṣe ọlọ́run fún ara wọn!+ 32 Àmọ́, tí o bá fẹ́, dárí jì wọ́n;+ bí bẹ́ẹ̀ kọ́, jọ̀ọ́, pa mí rẹ́ kúrò nínú ìwé rẹ tí o kọ.”+ 33 Àmọ́ Jèhófà sọ fún Mósè pé: “Màá pa ẹnikẹ́ni tó bá ṣẹ̀ mí rẹ́ kúrò nínú ìwé mi. 34 Máa lọ báyìí, darí àwọn èèyàn náà lọ síbi tí mo bá ọ sọ. Wò ó! Áńgẹ́lì mi yóò ṣáájú rẹ.+ Lọ́jọ́ tí mo bá sì fẹ́ ṣèdájọ́, èmi yóò fi ìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn jẹ wọ́n.” 35 Jèhófà wá bẹ̀rẹ̀ sí í mú ìyọnu bá àwọn èèyàn náà torí wọ́n ṣe ère ọmọ màlúù, èyí tí Áárónì ṣe.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́