Orin Sólómọ́nì
2 “Bí òdòdó lílì láàárín àwọn ẹ̀gún,
Ni olólùfẹ́ mi rí láàárín àwọn ọmọbìnrin.”
3 “Bí igi ápù láàárín àwọn igi inú igbó,
Ni olólùfẹ́ mi rí láàárín àwọn ọmọkùnrin.
Ó wù mí tọkàntọkàn pé kí n jókòó sábẹ́ ibòji rẹ̀,
Èso rẹ̀ sì ń dùn mọ́ mi lẹ́nu.
4 Ó mú mi wá sínú ilé àsè,*
Ó sì fi ìfẹ́ rẹ̀ bò mí.
5 Ẹ fún mi ní ìṣù àjàrà gbígbẹ+ kí ara lè tù mí;
Ẹ fún mi ní èso ápù kí n lè lókun,
Torí òjòjò ìfẹ́ ń ṣe mí.
7 Mo mú kí ẹ búra, ẹ̀yin ọmọbìnrin Jerúsálẹ́mù,
Kí ẹ fi àwọn egbin+ àti àwọn abo àgbọ̀nrín inú pápá búra:
Pé kí ẹ má ṣe ta ìfẹ́ jí, ẹ má sì ru ìfẹ́ sókè nínú mi, títí á fi wá fúnra rẹ̀.+
8 Mo gbọ́ ìró olólùfẹ́ mi!
Wò ó! Òun ló ń bọ̀ yìí,
Ó ń gun àwọn òkè ńlá, ó ń tọ pọ́n-ún pọ́n-ún lórí àwọn òkè kéékèèké.
9 Olólùfẹ́ mi dà bí egbin, bí akọ ọmọ àgbọ̀nrín.+
Òun nìyẹn, ó dúró sí ẹ̀yìn ògiri wa,
Ó ń yọjú lójú fèrèsé,*
Ó ń yọjú níbi àwọn fèrèsé tó ní asẹ́ onígi.
10 Olólùfẹ́ mi bá mi sọ̀rọ̀, ó sọ fún mi pé:
‘Dìde, ìfẹ́ mi,
Arẹwà mi, tẹ̀ lé mi ká lọ.
11 Wò ó! Ìgbà òtútù* ti kọjá.
Òjò ò rọ̀ mọ́, ó ti dáwọ́ dúró.
12 Òdòdó ti yọ ní ilẹ̀ wa,+
Àkókò ti tó láti rẹ́wọ́ ọ̀gbìn,+
A sì gbọ́ orin tí ẹyẹ oriri ń kọ ní ilẹ̀ wa.+
13 Àwọn èso tó kọ́kọ́ yọ lórí igi ọ̀pọ̀tọ́ ti pọ́n;+
Àwọn àjàrà ti yọ òdòdó, wọ́n sì ń ta sánsán.
Dìde, olólùfẹ́ mi, máa bọ̀.
Arẹwà mi, tẹ̀ lé mi ká lọ.
14 Ìwọ àdàbà mi, tí o wà nínú ihò àpáta,+
Níbi kọ́lọ́fín òkè tó dà gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́,
Jẹ́ kí n rí ọ, kí n sì gbọ́ ohùn rẹ,+
Torí ohùn rẹ dùn, ìrísí rẹ sì dára gan-an.’”+
15 “Bá wa mú àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀,
Àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ kéékèèké tó ń ba àwọn ọgbà àjàrà jẹ́,
Torí àwọn ọgbà àjàrà wa ti yọ òdòdó.”
16 “Èmi ni mo ni olólùfẹ́ mi, òun ló sì ni mí.+