ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 2 Kíróníkà 21
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé 2 Kíróníkà

      • Jèhórámù di ọba Júdà (1-11)

      • Èlíjà kọ̀wé ránṣẹ́ (12-15)

      • Ìgbẹ̀yìn Jèhórámù kò dáa (16-20)

2 Kíróníkà 21:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 22:50

2 Kíróníkà 21:3

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 11:5, 23
  • +2Ọb 8:16

2 Kíróníkà 21:4

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ond 9:5, 6

2 Kíróníkà 21:5

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 8:17-19

2 Kíróníkà 21:6

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 14:7, 9; Ho 4:1
  • +2Kr 22:2; Ne 13:26

2 Kíróníkà 21:7

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “òun á fún Dáfídì àti àwọn ọmọ rẹ̀ ní fìtílà.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 23:5; Sm 89:20, 28; Jer 33:20, 21
  • +2Sa 7:12, 16; 1Ọb 11:36; Sm 132:11

2 Kíróníkà 21:8

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 27:40
  • +1Ọb 22:47; 2Ọb 8:20-22

2 Kíróníkà 21:10

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 21:13; 2Ọb 19:8
  • +2Kr 15:2; Jer 2:13

2 Kíróníkà 21:11

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 12:2

2 Kíróníkà 21:12

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 2:1, 11
  • +2Kr 17:3
  • +1Ọb 15:11; 2Kr 14:2, 5

2 Kíróníkà 21:13

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 16:25, 33
  • +Ẹk 34:15; Jer 3:8
  • +2Ọb 9:22
  • +2Kr 21:4

2 Kíróníkà 21:16

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “ẹ̀mí àwọn Filísínì.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 11:14; 2Kr 33:11; Ais 10:5
  • +Joṣ 13:1, 2; 2Sa 8:1
  • +2Kr 17:11

2 Kíróníkà 21:17

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ààfin.”

  • *

    Wọ́n tún ń pè é ní Ahasáyà.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 14:25, 26
  • +2Kr 22:1

2 Kíróníkà 21:18

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Iṣe 12:21-23

2 Kíróníkà 21:19

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 16:13, 14; Jer 34:4, 5

2 Kíróníkà 21:20

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 2:10
  • +2Kr 24:24, 25; 28:27

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    11/15/1998, ojú ìwé 32

Àwọn míì

2 Kíró. 21:11Ọb 22:50
2 Kíró. 21:32Kr 11:5, 23
2 Kíró. 21:32Ọb 8:16
2 Kíró. 21:4Ond 9:5, 6
2 Kíró. 21:52Ọb 8:17-19
2 Kíró. 21:61Ọb 14:7, 9; Ho 4:1
2 Kíró. 21:62Kr 22:2; Ne 13:26
2 Kíró. 21:72Sa 23:5; Sm 89:20, 28; Jer 33:20, 21
2 Kíró. 21:72Sa 7:12, 16; 1Ọb 11:36; Sm 132:11
2 Kíró. 21:8Jẹ 27:40
2 Kíró. 21:81Ọb 22:47; 2Ọb 8:20-22
2 Kíró. 21:10Joṣ 21:13; 2Ọb 19:8
2 Kíró. 21:102Kr 15:2; Jer 2:13
2 Kíró. 21:11Di 12:2
2 Kíró. 21:122Ọb 2:1, 11
2 Kíró. 21:122Kr 17:3
2 Kíró. 21:121Ọb 15:11; 2Kr 14:2, 5
2 Kíró. 21:131Ọb 16:25, 33
2 Kíró. 21:13Ẹk 34:15; Jer 3:8
2 Kíró. 21:132Ọb 9:22
2 Kíró. 21:132Kr 21:4
2 Kíró. 21:161Ọb 11:14; 2Kr 33:11; Ais 10:5
2 Kíró. 21:16Joṣ 13:1, 2; 2Sa 8:1
2 Kíró. 21:162Kr 17:11
2 Kíró. 21:171Ọb 14:25, 26
2 Kíró. 21:172Kr 22:1
2 Kíró. 21:18Iṣe 12:21-23
2 Kíró. 21:192Kr 16:13, 14; Jer 34:4, 5
2 Kíró. 21:201Ọb 2:10
2 Kíró. 21:202Kr 24:24, 25; 28:27
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
  • 20
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
2 Kíróníkà 21:1-20

Kíróníkà Kejì

21 Níkẹyìn, Jèhóṣáfátì sinmi pẹ̀lú àwọn baba ńlá rẹ̀, wọ́n sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba ńlá rẹ̀ sí Ìlú Dáfídì; Jèhórámù ọmọ rẹ̀ sì jọba ní ipò rẹ̀.+ 2 Àwọn arákùnrin rẹ̀, ìyẹn àwọn ọmọ Jèhóṣáfátì ni Asaráyà, Jéhíélì, Sekaráyà, Asaráyà, Máíkẹ́lì àti Ṣẹfatáyà; gbogbo wọn jẹ́ ọmọ Jèhóṣáfátì ọba Ísírẹ́lì. 3 Bàbá wọn fún wọn ní ẹ̀bùn púpọ̀ tó jẹ́ fàdákà àti wúrà pẹ̀lú àwọn nǹkan iyebíye, títí kan àwọn ìlú olódi ní Júdà;+ àmọ́ ó fún Jèhórámù ní ìjọba,+ torí pé òun ni àkọ́bí.

4 Nígbà tí Jèhórámù gorí ìtẹ́ ìjọba bàbá rẹ̀, ó fi idà pa gbogbo àwọn àbúrò rẹ̀+ àti àwọn kan lára àwọn ìjòyè Ísírẹ́lì, ó sì tipa bẹ́ẹ̀ mú kí ipò rẹ̀ fìdí múlẹ̀. 5 Ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n (32) ni Jèhórámù nígbà tó jọba, ọdún mẹ́jọ ló sì fi ṣàkóso ní Jerúsálẹ́mù.+ 6 Ó rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Ísírẹ́lì,+ bí àwọn ọba tó wá láti ilé Áhábù ti ṣe, nítorí ọmọ Áhábù ló fi ṣe aya;+ ó sì ń ṣe ohun tó burú ní ojú Jèhófà. 7 Àmọ́ Jèhófà ò fẹ́ pa ilé Dáfídì run, nítorí májẹ̀mú tó bá Dáfídì dá,+ torí ó ti ṣèlérí pé Dáfídì àti àwọn ọmọ rẹ̀ lá máa ṣàkóso* títí lọ.+

8 Nígbà ayé rẹ̀, Édómù ṣọ̀tẹ̀ sí Júdà,+ wọ́n sì fi ọba jẹ lórí ara wọn.+ 9 Nítorí náà, Jèhórámù àti àwọn olórí tó yàn sọdá pẹ̀lú gbogbo kẹ̀kẹ́ ẹṣin rẹ̀, ó dìde ní òru, ó sì ṣẹ́gun àwọn ọmọ Édómù tí wọ́n yí i ká àti àwọn olórí kẹ̀kẹ́ ẹṣin. 10 Àmọ́ Édómù ṣì ń ṣọ̀tẹ̀ sí Júdà títí di òní yìí. Líbínà+ pẹ̀lú ṣọ̀tẹ̀ sí i ní àkókò yẹn, nítorí ó ti fi Jèhófà Ọlọ́run àwọn baba ńlá rẹ̀ sílẹ̀.+ 11 Òun náà ṣe àwọn ibi gíga + lórí àwọn òkè Júdà, kí ó lè mú àwọn tó ń gbé Jerúsálẹ́mù ṣe àgbèrè ẹ̀sìn, ó sì kó Júdà ṣìnà.

12 Níkẹyìn, wòlíì Èlíjà kọ ìwé kan sí i,+ ó ní: “Ohun tí Jèhófà Ọlọ́run Dáfídì baba ńlá rẹ sọ nìyí, ‘Ìwọ kò rìn ní ọ̀nà Jèhóṣáfátì+ bàbá rẹ tàbí ní ọ̀nà Ásà+ ọba Júdà. 13 Àmọ́, ò ń rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Ísírẹ́lì,+ o sì mú kí Júdà àti àwọn tó ń gbé Jerúsálẹ́mù ṣe àgbèrè ẹ̀sìn+ bí àgbèrè tí ilé Áhábù ṣe,+ kódà o pa àwọn arákùnrin rẹ,+ agbo ilé bàbá rẹ, àwọn tó sàn jù ọ́ lọ. 14 Torí náà, Jèhófà yóò mú àjálù ńlá bá àwọn èèyàn rẹ, àwọn ọmọ rẹ, àwọn ìyàwó rẹ àti gbogbo ohun ìní rẹ. 15 Oríṣiríṣi àìsàn máa ṣe ọ́ pẹ̀lú àrùn tó máa mú ọ ní ìfun, títí àwọn ìfun rẹ á fi tú jáde nítorí àìsàn tí á máa ṣe ọ́ lójoojúmọ́.’”

16 Lẹ́yìn náà, Jèhófà gbé+ àwọn Filísínì*+ àti àwọn ará Arébíà+ tó wà nítòsí àwọn ará Etiópíà dìde sí Jèhórámù. 17 Nítorí náà, wọ́n ya bo Júdà, wọ́n sì fi ipá wọ inú rẹ̀, wọ́n kó gbogbo ohun ìní tó wà nínú ilé* ọba,+ wọ́n tún kó àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn ìyàwó rẹ̀; ọmọ kan ṣoṣo tó ṣẹ́ kù fún un ni Jèhóáhásì,*+ àbíkẹ́yìn rẹ̀. 18 Lẹ́yìn gbogbo èyí, Jèhófà fi àìsàn kan tí kò ṣeé wò sàn kọ lù ú ní ìfun rẹ̀.+ 19 Nígbà tó yá, tí ọdún méjì gbáko ti kọjá, ìfun rẹ̀ tú jáde nítorí àìsàn tó ń ṣe é, ó sì kú nínú ìrora ńlá tí àìsàn náà mú bá a; àwọn èèyàn rẹ̀ kò ṣe ìfinásun nítorí rẹ̀ bí wọ́n ti ṣe ìfinásun nítorí àwọn baba ńlá rẹ̀.+ 20 Ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n (32) ni nígbà tó jọba, ọdún mẹ́jọ ló sì fi ṣàkóso ní Jerúsálẹ́mù. Kò sẹ́ni tí ikú rẹ̀ dùn. Torí náà, wọ́n sin ín sí Ìlú Dáfídì,+ àmọ́ kì í ṣe ní ibi tí wọ́n sin àwọn ọba sí.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́