ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 2 Àwọn Ọba 4
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé 2 Àwọn Ọba

      • Èlíṣà sọ òróró opó kan di púpọ̀ (1-7)

      • Obìnrin ará Ṣúnémù ṣe àlejò (8-16)

      • Obìnrin kan rí ọmọ bí; ọmọ náà kú (17-31)

      • Èlíṣà jí ọmọ tó kú dìde (32-37)

      • Èlíṣà mú kí ọbẹ̀ kan ṣeé jẹ (38-41)

      • Èlíṣà sọ búrẹ́dì di púpọ̀ (42-44)

2 Àwọn Ọba 4:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 2:3, 5
  • +1Ọb 19:18

2 Àwọn Ọba 4:2

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ìṣà ẹlẹ́nu ṣọọrọ.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 17:9, 12

2 Àwọn Ọba 4:3

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ìkòkò.”

2 Àwọn Ọba 4:5

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Mk 6:41; 8:6-8; Jo 2:7-9

2 Àwọn Ọba 4:6

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Mt 14:19
  • +Joṣ 5:12; 1Ọb 17:14

2 Àwọn Ọba 4:8

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 19:17, 18
  • +Jẹ 19:1-3; Ond 13:15

2 Àwọn Ọba 4:10

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ond 3:20; 1Ọb 17:19
  • +Mt 10:41; Ro 12:13; Heb 13:2

2 Àwọn Ọba 4:11

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    10/1/1997, ojú ìwé 30

2 Àwọn Ọba 4:12

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 5:25-27; 8:4
  • +Joṣ 19:17, 18

2 Àwọn Ọba 4:13

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ro 16:6
  • +2Ọb 4:1, 2; Heb 6:10
  • +2Ọb 8:3

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    10/1/1997, ojú ìwé 30

2 Àwọn Ọba 4:14

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 15:2; 30:1

2 Àwọn Ọba 4:16

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 18:10

2 Àwọn Ọba 4:20

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 17:17

2 Àwọn Ọba 4:21

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 4:9, 10

2 Àwọn Ọba 4:23

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 10:10; 28:11

2 Àwọn Ọba 4:24

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì.”

2 Àwọn Ọba 4:27

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ọkàn rẹ̀ ló gbọgbẹ́.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Mt 28:9

2 Àwọn Ọba 4:28

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 4:16

2 Àwọn Ọba 4:29

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 18:46

2 Àwọn Ọba 4:30

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “tí ọkàn rẹ.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Mt 15:22, 28

2 Àwọn Ọba 4:31

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Mt 17:15, 16; Mk 9:17, 18

2 Àwọn Ọba 4:32

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 4:21

2 Àwọn Ọba 4:33

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 17:19, 20; Jo 11:41; Iṣe 9:40

2 Àwọn Ọba 4:34

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 17:21, 22; Iṣe 20:9, 10

2 Àwọn Ọba 4:35

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 8:1, 5

2 Àwọn Ọba 4:36

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Heb 11:35

2 Àwọn Ọba 4:38

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 28:23, 24; 2Ọb 8:1; Isk 14:13
  • +2Ọb 2:3, 5
  • +2Ọb 4:12

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àwọn Ìtẹ̀jáde Tá A Tọ́ka sí Nínú Ìwé Ìpàdé, 9/2022,

2 Àwọn Ọba 4:41

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 15:23-25; 2Ọb 2:19-21

2 Àwọn Ọba 4:42

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 9:3, 4
  • +Jo 6:9
  • +1Sa 9:6, 7

2 Àwọn Ọba 4:43

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Mt 14:17; Mk 8:4
  • +Mt 14:20; Mk 8:8

2 Àwọn Ọba 4:44

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Lk 9:17; Jo 6:13

Àwọn míì

2 Ọba 4:12Ọb 2:3, 5
2 Ọba 4:11Ọb 19:18
2 Ọba 4:21Ọb 17:9, 12
2 Ọba 4:5Mk 6:41; 8:6-8; Jo 2:7-9
2 Ọba 4:6Mt 14:19
2 Ọba 4:6Joṣ 5:12; 1Ọb 17:14
2 Ọba 4:8Joṣ 19:17, 18
2 Ọba 4:8Jẹ 19:1-3; Ond 13:15
2 Ọba 4:10Ond 3:20; 1Ọb 17:19
2 Ọba 4:10Mt 10:41; Ro 12:13; Heb 13:2
2 Ọba 4:122Ọb 5:25-27; 8:4
2 Ọba 4:12Joṣ 19:17, 18
2 Ọba 4:13Ro 16:6
2 Ọba 4:132Ọb 4:1, 2; Heb 6:10
2 Ọba 4:132Ọb 8:3
2 Ọba 4:14Jẹ 15:2; 30:1
2 Ọba 4:16Jẹ 18:10
2 Ọba 4:201Ọb 17:17
2 Ọba 4:212Ọb 4:9, 10
2 Ọba 4:23Nọ 10:10; 28:11
2 Ọba 4:27Mt 28:9
2 Ọba 4:282Ọb 4:16
2 Ọba 4:291Ọb 18:46
2 Ọba 4:30Mt 15:22, 28
2 Ọba 4:31Mt 17:15, 16; Mk 9:17, 18
2 Ọba 4:322Ọb 4:21
2 Ọba 4:331Ọb 17:19, 20; Jo 11:41; Iṣe 9:40
2 Ọba 4:341Ọb 17:21, 22; Iṣe 20:9, 10
2 Ọba 4:352Ọb 8:1, 5
2 Ọba 4:36Heb 11:35
2 Ọba 4:38Di 28:23, 24; 2Ọb 8:1; Isk 14:13
2 Ọba 4:382Ọb 2:3, 5
2 Ọba 4:382Ọb 4:12
2 Ọba 4:41Ẹk 15:23-25; 2Ọb 2:19-21
2 Ọba 4:421Sa 9:3, 4
2 Ọba 4:42Jo 6:9
2 Ọba 4:421Sa 9:6, 7
2 Ọba 4:43Mt 14:17; Mk 8:4
2 Ọba 4:43Mt 14:20; Mk 8:8
2 Ọba 4:44Lk 9:17; Jo 6:13
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
  • 20
  • 21
  • 22
  • 23
  • 24
  • 25
  • 26
  • 27
  • 28
  • 29
  • 30
  • 31
  • 32
  • 33
  • 34
  • 35
  • 36
  • 37
  • 38
  • 39
  • 40
  • 41
  • 42
  • 43
  • 44
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
2 Àwọn Ọba 4:1-44

Àwọn Ọba Kejì

4 Nígbà náà, ọ̀kan lára ìyàwó àwọn ọmọ wòlíì+ sunkún lọ bá Èlíṣà, ó ní: “Ìránṣẹ́ rẹ, ọkọ mi, ti kú, o sì mọ̀ pé gbogbo ọjọ́ ayé ìránṣẹ́ rẹ ni ó fi bẹ̀rù Jèhófà.+ Àmọ́ ní báyìí, ẹni tí a jẹ ní gbèsè ti wá láti kó àwọn ọmọ mi méjèèjì kó lè fi wọ́n ṣe ẹrú.” 2 Èlíṣà wá béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé: “Kí ni kí n ṣe fún ọ? Sọ fún mi, kí lo ní sílé?” Ó fèsì pé: “Ìránṣẹ́ rẹ ò ní nǹkan kan nílé àfi ìṣà* òróró kan.”+ 3 Ó wá sọ pé: “Jáde, lọ gba àwọn òfìfo ohun èlò* lọ́wọ́ gbogbo àwọn aládùúgbò rẹ. Jẹ́ kí wọ́n pọ̀. 4 Lẹ́yìn náà kí o wọlé, kí o sì ti ilẹ̀kùn mọ́ ara rẹ àti àwọn ọmọ rẹ. Rọ òróró sínú àwọn ohun èlò náà, kí o sì gbé àwọn tó ti kún sẹ́gbẹ̀ẹ́ kan.” 5 Torí náà, ó kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.

Nígbà tó ti ilẹ̀kùn mọ́ ara rẹ̀ àti àwọn ọmọ rẹ̀, wọ́n ń kó àwọn ohun èlò náà wá fún un, ó sì ń rọ ọ́ sínú wọn.+ 6 Nígbà tí àwọn ohun èlò náà kún, ó sọ fún ọ̀kan lára àwọn ọmọ rẹ̀ pé: “Gbé ohun èlò míì wá fún mi.”+ Àmọ́, ó sọ fún un pé: “Kò sí ohun èlò míì mọ́.” Bí òróró náà ṣe dá nìyẹn.+ 7 Nítorí náà, ó wọlé, ó sì sọ fún èèyàn Ọlọ́run tòótọ́ náà. Èlíṣà wá sọ pé: “Lọ ta òróró náà, kí o fi san gbèsè rẹ, kí ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ sì máa fi ohun tó kù tọ́jú ara yín.”

8 Lọ́jọ́ kan, Èlíṣà lọ sí Ṣúnémù,+ níbi tí gbajúmọ̀ obìnrin kan wà, obìnrin náà sì rọ̀ ọ́ pé kó jẹun níbẹ̀.+ Nígbàkigbà tó bá kọjá, ó máa ń dúró jẹun níbẹ̀. 9 Obìnrin náà wá sọ fún ọkọ rẹ̀ pé: “Mo mọ̀ pé èèyàn mímọ́ Ọlọ́run ni ọkùnrin tó máa ń gba ibí kọjá déédéé. 10 Jọ̀ọ́, jẹ́ kí a ṣe yàrá kékeré kan sórí òrùlé,+ kí a sì gbé ibùsùn, tábìlì, àga àti ọ̀pá fìtílà kan síbẹ̀ fún un. Nígbàkigbà tó bá wá sọ́dọ̀ wa, á lè dúró síbẹ̀.”+

11 Lọ́jọ́ kan, ó wá síbẹ̀, ó sì lọ sínú yàrá tó wà lórí òrùlé láti sùn. 12 Ó wá sọ fún Géhásì,+ ìránṣẹ́ rẹ̀ pé: “Pe obìnrin ará Ṣúnémù+ yìí wá.” Torí náà, ó pè é, obìnrin náà sì dúró níwájú rẹ̀. 13 Lẹ́yìn náà, ó sọ fún Géhásì pé: “Jọ̀ọ́, sọ fún un pé, ‘O ti ṣe wàhálà gan-an nítorí wa.+ Kí ni kí n ṣe fún ọ?+ Ṣé ohun kan wà tí o fẹ́ kí n bá ọ sọ fún ọba+ tàbí fún olórí àwọn ọmọ ogun?’” Àmọ́, obìnrin náà fèsì pé: “Àárín àwọn èèyàn mi ni mò ń gbé.” 14 Torí náà, Èlíṣà sọ pé: “Kí wá ni a lè ṣe fún un?” Géhásì bá sọ pé: “Mo rí i pé kò ní ọmọ kankan,+ ọkọ rẹ̀ sì ti darúgbó.” 15 Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, ó sọ pé: “Pè é wá.” Torí náà, ó pè é, obìnrin náà sì dúró lẹ́nu ọ̀nà. 16 Ó wá sọ pé: “Ní ìwòyí ọdún tó ń bọ̀, wàá fi ọwọ́ rẹ gbé ọmọkùnrin.”+ Àmọ́, obìnrin náà sọ pé: “Rárá, ọ̀gá mi, èèyàn Ọlọ́run tòótọ́! Má parọ́ fún ìránṣẹ́ rẹ.”

17 Ṣùgbọ́n, obìnrin náà lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan ní àkókò kan náà ní ọdún tó tẹ̀ lé e, gẹ́gẹ́ bí Èlíṣà ṣe sọ fún un. 18 Ọmọ náà ń dàgbà, lọ́jọ́ kan, ó jáde lọ bá bàbá rẹ̀ lọ́dọ̀ àwọn olùkórè. 19 Ó ṣáà ń sọ fún bàbá rẹ̀ pé: “Orí mi o, orí mi o!” Lẹ́yìn náà, bàbá rẹ̀ sọ fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé: “Gbé e lọ fún ìyá rẹ̀.” 20 Torí náà, ó gbé e lọ fún ìyá rẹ̀, ọmọ náà jókòó sórí ẹsẹ̀ ìyá rẹ̀ títí di ọ̀sán, lẹ́yìn náà ó kú.+ 21 Ni obìnrin náà bá gbé e lọ sókè, ó tẹ́ ẹ sórí ibùsùn èèyàn Ọlọ́run tòótọ́,+ ó ti ilẹ̀kùn mọ́ ọn, ó sì jáde lọ. 22 Ó wá ránṣẹ́ sí ọkọ rẹ̀ pé: “Jọ̀ọ́, fi ìránṣẹ́ kan àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan ránṣẹ́ sí mi, kí n lè sáré dé ọ̀dọ̀ èèyàn Ọlọ́run tòótọ́ kí n sì pa dà.” 23 Ṣùgbọ́n ọkọ rẹ̀ sọ pé: “Kí lo fẹ́ lọ rí i fún lónìí? Òní kọ́ ni òṣùpá tuntun+ tàbí sábáàtì.” Síbẹ̀, ó sọ pé: “Kò séwu.” 24 Nítorí náà, ó di ohun tí wọ́n fi ń jókòó mọ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,* ó sì sọ fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé: “Ó yá, gbéra. Má ṣe tẹ̀ ẹ́ jẹ́ẹ́jẹ́ẹ́ nítorí mi àfi tí mo bá ní kí o ṣe bẹ́ẹ̀.”

25 Torí náà, ó lọ sọ́dọ̀ èèyàn Ọlọ́run tòótọ́ ní Òkè Kámẹ́lì. Bí èèyàn Ọlọ́run tòótọ́ ṣe rí i lọ́ọ̀ọ́kán, ó sọ fún Géhásì, ìránṣẹ́ rẹ̀ pé: “Wò ó! Obìnrin ará Ṣúnémù yẹn ló ń bọ̀ yìí. 26 Jọ̀ọ́, sáré pàdé rẹ̀, kí o sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, ‘Ṣé àlàáfíà ni? Ṣé àlàáfíà ni ọkọ rẹ wà? Ṣé àlàáfíà ni ọmọ rẹ wà?’” Ó fèsì pé: “Àlàáfíà ni.” 27 Nígbà tó dé ọ̀dọ̀ èèyàn Ọlọ́run tòótọ́ ní òkè náà, ní kíá, ó di ẹsẹ̀ rẹ̀ mú.+ Ni Géhásì bá sún mọ́ ọn láti tì í kúrò, àmọ́ èèyàn Ọlọ́run tòótọ́ sọ pé: “Fi sílẹ̀, ẹ̀dùn ọkàn ló bá a,* Jèhófà ò sì jẹ́ kí n mọ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sọ fún mi.” 28 Obìnrin náà wá sọ pé: “Ṣé mo ní kí olúwa mi fún mi lọ́mọ ni? Ṣé mi ò sọ pé, ‘Kí o má ṣe fún mi ní ìrètí asán’?”+

29 Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, ó sọ fún Géhásì pé: “Ká aṣọ rẹ mọ́ra,+ kí o mú ọ̀pá mi dání, kí o sì lọ. Tí o bá pàdé èèyàn, má kí i; tí ẹnikẹ́ni bá sì kí ọ, má ṣe dá a lóhùn. Kí o lọ gbé ọ̀pá mi lé ojú ọmọ náà.” 30 Ni ìyá ọmọ náà bá sọ pé: “Bí Jèhófà ti wà láàyè, tí ìwọ náà* sì wà láàyè, mi ò ní fi ọ́ sílẹ̀.”+ Torí náà, ó dìde, ó sì bá a lọ. 31 Géhásì lọ ṣáájú wọn, ó gbé ọ̀pá náà lé ojú ọmọ náà, àmọ́ kò fọhùn, kò sì mira.+ Ó pa dà lọ bá Èlíṣà, ó sì sọ fún un pé: “Ọmọ náà ò jí o.”

32 Nígbà tí Èlíṣà wọnú ilé náà, òkú ọmọ náà wà lórí ibùsùn rẹ̀.+ 33 Lẹ́yìn tó wọlé, ó ti ilẹ̀kùn, àwọn méjèèjì sì wà nínú ilé, ó wá bẹ̀rẹ̀ sí í gbàdúrà sí Jèhófà.+ 34 Ó gorí ibùsùn, ó nà lé ọmọ náà, ó sì gbé ẹnu rẹ̀ lé ẹnu ọmọ náà àti ojú rẹ̀ lé ojú ọmọ náà, ó tún gbé àtẹ́lẹwọ́ rẹ̀ lé àtẹ́lẹwọ́ ọmọ náà, ó sì nà lé e lórí síbẹ̀, ara ọmọ náà wá bẹ̀rẹ̀ sí í móoru.+ 35 Ó lọ síwájú, ó lọ sẹ́yìn nínú ilé náà, ó gorí ibùsùn náà, ó sì nà lé e lórí lẹ́ẹ̀kan sí i. Ọmọ náà bá sín nígbà méje, lẹ́yìn náà ó lajú.+ 36 Èlíṣà wá pe Géhásì, ó sì sọ pé: “Pe obìnrin ará Ṣúnémù náà wá.” Torí náà, ó pè é, ó sì wọlé wá bá a. Lẹ́yìn náà, ó sọ pé: “Gbé ọmọ rẹ.”+ 37 Lẹ́yìn tí obìnrin náà wọlé, ó kúnlẹ̀ níbi ẹsẹ̀ rẹ̀, ó tẹrí ba mọ́lẹ̀ níwájú rẹ̀, ó gbé ọmọ rẹ̀, ó sì jáde lọ.

38 Nígbà tí Èlíṣà pa dà sí Gílígálì, ìyàn mú ní ilẹ̀ náà.+ Àwọn ọmọ wòlíì+ jókòó níwájú rẹ̀, ó sì sọ fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé:+ “Gbé ìkòkò ńlá kaná, kí o sì se ọbẹ̀ fún àwọn ọmọ wòlíì.” 39 Ni ọ̀kan lára wọn bá jáde lọ sínú oko láti já ewéko málò, ó rí àjàrà inú igbó, ó sì ká tàgíìrì lórí rẹ̀, ó wá kó o sínú aṣọ rẹ̀. Lẹ́yìn náà, ó pa dà sílé, ó sì rẹ́ wọn sínú ìkòkò ọbẹ̀ náà, láìmọ ohun tó jẹ́. 40 Lẹ́yìn náà, wọ́n bù ú fún àwọn ọkùnrin náà láti jẹ, àmọ́ bí wọ́n ṣe fi kan ẹnu báyìí, wọ́n figbe ta pé: “Èèyàn Ọlọ́run tòótọ́, ikú wà nínú ìkòkò náà.” Wọn ò sì lè jẹ ẹ́. 41 Torí náà, ó sọ pé: “Ẹ bu ìyẹ̀fun wá.” Lẹ́yìn tó bù ú sínú ìkòkò náà, ó sọ pé: “Ẹ bù ú fún àwọn èèyàn náà.” Kò sì sí ohun eléwu nínú ìkòkò náà mọ́.+

42 Ọkùnrin kan wá láti Baali-ṣálíṣà,+ ó sì kó ogún (20) búrẹ́dì ọkà bálì+ tí wọ́n fi àkọ́so èso ṣe àti àpò ọkà+ tuntun wá. Ìgbà náà ni Èlíṣà sọ pé: “Kó wọn fún àwọn èèyàn náà kí wọ́n lè jẹun.” 43 Síbẹ̀, ìránṣẹ́ rẹ̀ sọ pé: “Báwo ni màá ṣe gbé nǹkan yìí síwájú ọgọ́rùn-ún (100) èèyàn?”+ Ó fèsì pé: “Kó wọn fún àwọn èèyàn náà kí wọ́n lè jẹun, nítorí ohun tí Jèhófà sọ nìyí, ‘Wọ́n á jẹ, á sì tún ṣẹ́ kù.’”+ 44 Ni ó bá gbé e síwájú wọn, wọ́n jẹ, ó sì tún ṣẹ́ kù+ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Jèhófà.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́