ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Jeremáyà 26
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Jeremáyà

      • Wọ́n fi ikú halẹ̀ mọ́ Jeremáyà (1-15)

      • Wọ́n dá Jeremáyà sí (16-19)

        • Wọ́n fa ọ̀rọ̀ yọ látinú àsọtẹ́lẹ̀ Míkà (18)

      • Wòlíì Úríjà (20-24)

Jeremáyà 26:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 23:34; 2Kr 36:4; Jer 25:1; 35:1; 36:1

Jeremáyà 26:2

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “nípa.”

  • *

    Tàbí “forí balẹ̀.”

Jeremáyà 26:3

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “yí ìpinnu mi pa dà.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ais 55:7; Jer 18:7, 8; 36:3; Isk 18:27

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Jeremáyà, ojú ìwé 151

Jeremáyà 26:4

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ìtọ́ni.”

Jeremáyà 26:5

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “tí mò ń dìde ní kùtùkùtù, tí mo sì ń rán níṣẹ́.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 17:13, 14; Jer 7:12-14; 25:3

Jeremáyà 26:6

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 78:60
  • +Jer 24:9

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ìwé Ìpàdé Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́,

    4/2017, ojú ìwé 7

Jeremáyà 26:7

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 26:2

Jeremáyà 26:10

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ààfin.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 36:10

Jeremáyà 26:11

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 18:19, 20
  • +Jer 38:4

Jeremáyà 26:12

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 1:17

Jeremáyà 26:13

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “yí ìpinnu rẹ̀ pa dà.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 7:3; 36:3; Isk 18:32; Jon 3:9

Jeremáyà 26:17

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ìjọ.”

Jeremáyà 26:18

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “Òkè tẹ́ńpìlì.”

  • *

    Tàbí “òkè tí igi pọ̀ sí.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Mik 1:1
  • +2Kr 29:1
  • +Sm 79:1; Jer 9:11
  • +Mik 3:12

Jeremáyà 26:19

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “gbìyànjú láti tu Jèhófà lójú.”

  • *

    Tàbí “yí ìpinnu rẹ̀ pa dà.”

  • *

    Tàbí “ọkàn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 32:26

Jeremáyà 26:20

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 15:20, 60; 18:11, 14; 1Sa 7:2

Jeremáyà 26:21

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 23:34; 2Kr 36:5
  • +2Kr 16:10

Jeremáyà 26:22

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 36:11, 12

Jeremáyà 26:23

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 2:30

Jeremáyà 26:24

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 22:12, 13; Jer 39:13, 14; 40:5
  • +2Ọb 22:10
  • +1Ọb 18:4

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Jeremáyà, ojú ìwé 122

Àwọn míì

Jer. 26:12Ọb 23:34; 2Kr 36:4; Jer 25:1; 35:1; 36:1
Jer. 26:3Ais 55:7; Jer 18:7, 8; 36:3; Isk 18:27
Jer. 26:52Ọb 17:13, 14; Jer 7:12-14; 25:3
Jer. 26:6Sm 78:60
Jer. 26:6Jer 24:9
Jer. 26:7Jer 26:2
Jer. 26:10Jer 36:10
Jer. 26:11Jer 18:19, 20
Jer. 26:11Jer 38:4
Jer. 26:12Jer 1:17
Jer. 26:13Jer 7:3; 36:3; Isk 18:32; Jon 3:9
Jer. 26:18Mik 1:1
Jer. 26:182Kr 29:1
Jer. 26:18Sm 79:1; Jer 9:11
Jer. 26:18Mik 3:12
Jer. 26:192Kr 32:26
Jer. 26:20Joṣ 15:20, 60; 18:11, 14; 1Sa 7:2
Jer. 26:212Ọb 23:34; 2Kr 36:5
Jer. 26:212Kr 16:10
Jer. 26:22Jer 36:11, 12
Jer. 26:23Jer 2:30
Jer. 26:242Ọb 22:12, 13; Jer 39:13, 14; 40:5
Jer. 26:242Ọb 22:10
Jer. 26:241Ọb 18:4
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
  • 20
  • 21
  • 22
  • 23
  • 24
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Jeremáyà 26:1-24

Jeremáyà

26 Ní ìbẹ̀rẹ̀ ìjọba Jèhóákímù+ ọmọ Jòsáyà, ọba Júdà, ọ̀rọ̀ yìí wá láti ọ̀dọ̀ Jèhófà, pé: 2 “Ohun tí Jèhófà sọ nìyí, ‘Dúró sí àgbàlá ilé Jèhófà, kí o sì sọ̀rọ̀ fún* gbogbo àwọn ará ìlú Júdà tó wá ń jọ́sìn* ní ilé Jèhófà. Gbogbo ohun tí mo pa láṣẹ fún ọ ni kí o sọ fún wọn, má ṣe yọ ọ̀rọ̀ kankan kúrò. 3 Bóyá wọ́n á fetí sílẹ̀, tí kálukú wọn á yí pa dà kúrò ní ọ̀nà búburú wọn, tí màá sì pèrò dà* lórí àjálù tí mo fẹ́ mú bá wọn nítorí ìwà ibi wọn.+ 4 Sọ fún wọn pé: “Ohun tí Jèhófà sọ nìyí, ‘Bí ẹ kò bá fetí sí mi láti máa tẹ̀ lé òfin* mi tí mo fún yín, 5 láti máa fetí sí ọ̀rọ̀ àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì, tí mò ń rán sí yín léraléra,* àwọn tí ẹ kì í fetí sí,+ 6 nígbà náà, ńṣe ni màá ṣe ilé yìí bíi Ṣílò,+ màá sì sọ ìlú yìí di ibi ègún lójú gbogbo orílẹ̀-èdè tó wà láyé.’”’”+

7 Àwọn àlùfáà àti àwọn wòlíì àti gbogbo èèyàn náà sì gbọ́ tí Jeremáyà ń sọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ní ilé Jèhófà.+ 8 Nígbà tí Jeremáyà parí gbogbo ohun tí Jèhófà pàṣẹ fún un pé kó sọ fún gbogbo àwọn èèyàn náà, ńṣe ni àwọn àlùfáà àti àwọn wòlíì pẹ̀lú gbogbo àwọn èèyàn náà gbá a mú, wọ́n sì sọ pé: “Ó dájú pé o máa kú. 9 Kí nìdí tí o fi sọ tẹ́lẹ̀ ní orúkọ Jèhófà, pé, ‘Ilé yìí máa dà bíi Ṣílò, ìlú yìí á sì di ahoro tí kò ní sí ẹnì kankan tí á máa gbé ibẹ̀’?” Gbogbo àwọn èèyàn náà sì pé jọ yí Jeremáyà ká ní ilé Jèhófà.

10 Nígbà tí àwọn ìjòyè Júdà gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, wọ́n wá láti ilé* ọba sí ilé Jèhófà, wọ́n sì jókòó sí ibi àtiwọ ẹnubodè tuntun ti Jèhófà.+ 11 Àwọn àlùfáà àti àwọn wòlíì sì sọ fún àwọn ìjòyè àti gbogbo àwọn èèyàn náà pé: “Ikú tọ́ sí ọkùnrin yìí,+ nítorí ó sọ tẹ́lẹ̀ nípa ìlú yìí, gẹ́gẹ́ bí ẹ ti fi etí ara yín gbọ́ ọ.”+

12 Jeremáyà wá sọ fún gbogbo àwọn ìjòyè àti gbogbo àwọn èèyàn náà pé: “Jèhófà ló rán mi láti sọ gbogbo àsọtẹ́lẹ̀ tí ẹ ti gbọ́ nípa ilé yìí àti nípa ìlú yìí.+ 13 Torí náà, ẹ tún ọ̀nà àti ìwà yín ṣe, ẹ sì ṣègbọràn sí ohùn Jèhófà Ọlọ́run yín, Jèhófà sì máa pèrò dà* lórí àjálù tó ti sọ pé òun máa mú bá yín.+ 14 Àmọ́ ní tèmi, èmi rèé lọ́wọ́ yín. Ẹ ṣe ohunkóhun tó bá dáa, tó sì tọ́ lójú yín sí mi. 15 Àmọ́, kó dá yín lójú pé, bí ẹ bá pa mí, ẹ ó mú ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ wá sórí ara yín àti sórí ìlú yìí àti sórí àwọn tó ń gbé ibẹ̀, torí pé òótọ́ ni Jèhófà rán mi sí yín pé kí n sọ gbogbo ọ̀rọ̀ yìí létí yín.”

16 Ìgbà náà ni àwọn ìjòyè àti gbogbo àwọn èèyàn náà sọ fún àwọn àlùfáà àti àwọn wòlíì pé: “Ikú kò tọ́ sí ọkùnrin yìí, torí ó bá wa sọ̀rọ̀ ní orúkọ Jèhófà Ọlọ́run wa.”

17 Yàtọ̀ síyẹn, àwọn kan lára àwọn àgbààgbà ilẹ̀ náà dìde, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í sọ fún àwùjọ* àwọn èèyàn náà pé: 18 “Míkà+ ti Móréṣétì sọ tẹ́lẹ̀ nígbà ayé Hẹsikáyà+ ọba Júdà, ó sì sọ fún gbogbo èèyàn Júdà pé, ‘Ohun tí Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun sọ nìyí:

“Wọ́n á túlẹ̀ Síónì bíi pápá,

Jerúsálẹ́mù á di àwókù,+

Òkè Ilé* náà á sì dà bí àwọn ibi gíga nínú igbó.”’*+

19 “Ṣé Ọba Hẹsikáyà ti Júdà àti gbogbo àwọn èèyàn Júdà wá pa á ni? Ǹjẹ́ kò bẹ̀rù Jèhófà, tó sì bẹ Jèhófà pé kó ṣojú rere sí òun,* tí Jèhófà fi pèrò dà* lórí àjálù tó sọ pé òun máa mú bá wọn?+ Nítorí náà, àjálù ńlá ni a fẹ́ fà wá bá ara* wa yìí o.

20 “Ọkùnrin kan tún wà tó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní orúkọ Jèhófà, Úríjà ọmọ Ṣemáyà láti Kiriati-jéárímù,+ tí ọ̀rọ̀ tó sọ tẹ́lẹ̀ nípa ìlú yìí àti ilẹ̀ yìí dà bíi ti Jeremáyà. 21 Ọba Jèhóákímù+ àti gbogbo àwọn ọkùnrin rẹ̀ alágbára àti gbogbo ìjòyè sì gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀, ọba sì wá ọ̀nà láti pa á.+ Nígbà tí Úríjà gbọ́ nípa rẹ̀, lójú ẹsẹ̀, ẹ̀rù bà á, ó sì sá lọ sí Íjíbítì. 22 Ni Ọba Jèhóákímù bá rán Élínátánì+ ọmọ Ákíbórì àti àwọn ọkùnrin míì pẹ̀lú rẹ̀ lọ sí Íjíbítì. 23 Wọ́n mú Úríjà wá láti Íjíbítì, wọ́n sì mú un lọ sọ́dọ̀ Ọba Jèhóákímù, ó fi idà pa á,+ ó sì ju òkú rẹ̀ sí ibi tí wọ́n ń sin àwọn èèyàn lásán sí.”

24 Àmọ́ Áhíkámù+ ọmọ Ṣáfánì+ ran Jeremáyà lọ́wọ́, kí wọ́n má bàa fi í lé àwọn èèyàn náà lọ́wọ́ láti pa á.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́