ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 2 Sámúẹ́lì 3
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé 2 Sámúẹ́lì

      • Ilé Dáfídì ń di alágbára sí i (1)

      • Àwọn ọmọkùnrin Dáfídì (2-5)

      • Ábínérì lọ dara pọ̀ mọ́ Dáfídì (6-21)

      • Jóábù pa Ábínérì (22-30)

      • Dáfídì ṣọ̀fọ̀ Ábínérì (31-39)

2 Sámúẹ́lì 3:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 15:27, 28; 24:17, 20; 26:25
  • +2Sa 2:17

2 Sámúẹ́lì 3:2

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Kr 3:1-4
  • +2Sa 13:1
  • +1Sa 25:43

2 Sámúẹ́lì 3:3

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 25:42
  • +2Sa 15:12
  • +2Sa 13:37

2 Sámúẹ́lì 3:4

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 1:5

2 Sámúẹ́lì 3:6

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 2:8

2 Sámúẹ́lì 3:7

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ìyàwó onípò kejì.” Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀, “Wáhàrì.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 21:8-11
  • +2Sa 2:10
  • +2Sa 16:21; 1Ọb 2:22

2 Sámúẹ́lì 3:9

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 15:27, 28; Sm 78:70; 89:20

2 Sámúẹ́lì 3:10

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ond 20:1; 2Sa 24:2

2 Sámúẹ́lì 3:11

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 3:39

2 Sámúẹ́lì 3:12

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “wò ó! ọwọ́ mi wà pẹ̀lú rẹ.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 5:3

2 Sámúẹ́lì 3:13

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 18:20; 19:11; 1Kr 15:29

2 Sámúẹ́lì 3:14

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 2:10
  • +1Sa 18:25, 27

2 Sámúẹ́lì 3:15

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 25:44

2 Sámúẹ́lì 3:16

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 16:5; 1Ọb 2:8

2 Sámúẹ́lì 3:18

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 13:14; 15:27, 28; 16:1, 13; Sm 89:3, 20; 132:17; Iṣe 13:22

2 Sámúẹ́lì 3:19

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 10:20, 21; 1Kr 12:29

2 Sámúẹ́lì 3:21

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ọkàn rẹ.”

2 Sámúẹ́lì 3:23

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 8:16
  • +1Sa 14:50; 2Sa 2:8, 22
  • +1Sa 14:51

2 Sámúẹ́lì 3:27

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “nítorí ẹ̀jẹ̀.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 3:20
  • +1Ọb 2:5
  • +2Sa 2:22, 23

2 Sámúẹ́lì 3:28

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 9:6; Ẹk 21:12; Nọ 35:33; Di 21:9

2 Sámúẹ́lì 3:29

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ó ṣeé ṣe kó máa tọ́ka sí ọkùnrin tó yarọ tí wọ́n ní kó máa ṣe iṣẹ́ obìnrin.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 7:16; 55:23; Owe 5:22
  • +Le 15:2
  • +Le 13:44; Nọ 5:2
  • +Di 27:24; Sm 109:2, 10

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    5/15/2005, ojú ìwé 17

2 Sámúẹ́lì 3:30

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 2:24
  • +2Sa 2:8
  • +2Sa 2:23

2 Sámúẹ́lì 3:31

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “aṣọ àpò ìdọ̀họ.”

2 Sámúẹ́lì 3:34

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “Bàbà.”

  • *

    Ní Héb., “àwọn aláìṣòdodo ọmọ.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 2:31, 32

2 Sámúẹ́lì 3:35

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “oúnjẹ ọ̀fọ̀.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ond 20:26

2 Sámúẹ́lì 3:37

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 3:28; 1Ọb 2:5

2 Sámúẹ́lì 3:38

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 14:50; 2Sa 2:8; 3:12

2 Sámúẹ́lì 3:39

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 2:4
  • +1Kr 2:15, 16
  • +2Sa 19:13; 20:10
  • +2Sa 3:29; 1Ọb 2:5, 34

Àwọn míì

2 Sám. 3:11Sa 15:27, 28; 24:17, 20; 26:25
2 Sám. 3:12Sa 2:17
2 Sám. 3:21Kr 3:1-4
2 Sám. 3:22Sa 13:1
2 Sám. 3:21Sa 25:43
2 Sám. 3:31Sa 25:42
2 Sám. 3:32Sa 15:12
2 Sám. 3:32Sa 13:37
2 Sám. 3:41Ọb 1:5
2 Sám. 3:62Sa 2:8
2 Sám. 3:72Sa 21:8-11
2 Sám. 3:72Sa 2:10
2 Sám. 3:72Sa 16:21; 1Ọb 2:22
2 Sám. 3:91Sa 15:27, 28; Sm 78:70; 89:20
2 Sám. 3:10Ond 20:1; 2Sa 24:2
2 Sám. 3:112Sa 3:39
2 Sám. 3:122Sa 5:3
2 Sám. 3:131Sa 18:20; 19:11; 1Kr 15:29
2 Sám. 3:142Sa 2:10
2 Sám. 3:141Sa 18:25, 27
2 Sám. 3:151Sa 25:44
2 Sám. 3:162Sa 16:5; 1Ọb 2:8
2 Sám. 3:181Sa 13:14; 15:27, 28; 16:1, 13; Sm 89:3, 20; 132:17; Iṣe 13:22
2 Sám. 3:191Sa 10:20, 21; 1Kr 12:29
2 Sám. 3:232Sa 8:16
2 Sám. 3:231Sa 14:50; 2Sa 2:8, 22
2 Sám. 3:231Sa 14:51
2 Sám. 3:272Sa 3:20
2 Sám. 3:271Ọb 2:5
2 Sám. 3:272Sa 2:22, 23
2 Sám. 3:28Jẹ 9:6; Ẹk 21:12; Nọ 35:33; Di 21:9
2 Sám. 3:29Sm 7:16; 55:23; Owe 5:22
2 Sám. 3:29Le 15:2
2 Sám. 3:29Le 13:44; Nọ 5:2
2 Sám. 3:29Di 27:24; Sm 109:2, 10
2 Sám. 3:302Sa 2:24
2 Sám. 3:302Sa 2:8
2 Sám. 3:302Sa 2:23
2 Sám. 3:341Ọb 2:31, 32
2 Sám. 3:35Ond 20:26
2 Sám. 3:372Sa 3:28; 1Ọb 2:5
2 Sám. 3:381Sa 14:50; 2Sa 2:8; 3:12
2 Sám. 3:392Sa 19:13; 20:10
2 Sám. 3:392Sa 3:29; 1Ọb 2:5, 34
2 Sám. 3:392Sa 2:4
2 Sám. 3:391Kr 2:15, 16
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
  • 20
  • 21
  • 22
  • 23
  • 24
  • 25
  • 26
  • 27
  • 28
  • 29
  • 30
  • 31
  • 32
  • 33
  • 34
  • 35
  • 36
  • 37
  • 38
  • 39
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
2 Sámúẹ́lì 3:1-39

Sámúẹ́lì Kejì

3 Ogun tí ó wà láàárín ilé Sọ́ọ̀lù àti ilé Dáfídì kò tíì parí; bí Dáfídì ṣe túbọ̀ ń mókè+ ni ilé Sọ́ọ̀lù ń lọ sílẹ̀.+

2 Láàárín àkókò yìí, Dáfídì bí àwọn ọmọkùnrin ní Hébúrónì.+ Ámínónì+ ni àkọ́bí tí Áhínóámù+ ará Jésírẹ́lì bí fún un. 3 Ìkejì ni Kíléábù tí Ábígẹ́lì+ opó Nábálì ará Kámẹ́lì bí; ìkẹta ni Ábúsálómù+ ọmọ Máákà ọmọbìnrin Tálímáì+ ọba Géṣúrì. 4 Ìkẹrin ni Ádóníjà+ ọmọ Hágítì, ìkarùn-ún ni Ṣẹfatáyà ọmọ Ábítálì. 5 Ìkẹfà sì ni Ítíréámù tí Ẹ́gílà ìyàwó Dáfídì bí. Àwọn ọmọ tí wọ́n bí fún Dáfídì nìyẹn ní Hébúrónì.

6 Bí ogun tó wà láàárín ilé Sọ́ọ̀lù àti ilé Dáfídì ṣe ń bá a lọ, agbára tí Ábínérì+ ní nílé Sọ́ọ̀lù ń pọ̀ sí i. 7 Sọ́ọ̀lù ní wáhàrì* kan tó ń jẹ́ Rísípà,+ ọmọ Áyà. Lẹ́yìn náà, Íṣí-bóṣétì  + sọ fún Ábínérì pé: “Kí ló dé tí o fi bá wáhàrì bàbá mi lò pọ̀?”+ 8 Inú bí Ábínérì gan-an lórí ọ̀rọ̀ Íṣí-bóṣétì, ó sì sọ pé: “Ṣé ajá Júdà lo fi mí pè ni? Títí di òní yìí, mo ti fi ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ hàn sí ilé Sọ́ọ̀lù bàbá rẹ àti sí àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀, mi ò sì gbẹ̀yìn lọ fi ọ́ lé Dáfídì lọ́wọ́; síbẹ̀ lónìí, o pè mí wá jíhìn ẹ̀ṣẹ̀ nítorí obìnrin. 9 Kí Ọlọ́run fìyà jẹ èmi Ábínérì gan-an, tí mi ò bá ṣe gẹ́gẹ́ bí Jèhófà ti búra fún Dáfídì+ pé: 10 Ìjọba náà máa kúrò ní ilé Sọ́ọ̀lù, a ó sì fìdí ìtẹ́ Dáfídì múlẹ̀ lórí Ísírẹ́lì àti lórí Júdà, láti Dánì dé Bíá-ṣébà.”+ 11 Íṣí-bóṣétì kò sì lè fèsì kankan nítorí ẹ̀rù Ábínérì bà á.+

12 Lójú ẹsẹ̀, Ábínérì rán àwọn òjíṣẹ́ sí Dáfídì pé: “Ta ló ni ilẹ̀ náà?” Ó tún sọ pé: “Bá mi dá májẹ̀mú, màá sì ṣe gbogbo ohun tí mo lè ṣe* láti yí gbogbo Ísírẹ́lì sọ́dọ̀ rẹ.”+ 13 Ó fèsì pé: “Ó dáa! Màá bá ọ dá májẹ̀mú. Ohun kan ṣoṣo tí màá béèrè lọ́wọ́ rẹ ni pé, o ò gbọ́dọ̀ fojú kàn mí, àfi tí o bá mú Míkálì,+ ọmọ Sọ́ọ̀lù dání, nígbà tí o bá ń bọ̀ wá rí mi.” 14 Lẹ́yìn náà, Dáfídì rán àwọn òjíṣẹ́ sí Íṣí-bóṣétì,+ ọmọ Sọ́ọ̀lù, pé: “Fún mi ní Míkálì ìyàwó mi, ẹni tí mo fi ọgọ́rùn-ún (100) adọ̀dọ́ àwọn Filísínì+ fẹ́.” 15 Nítorí náà, Íṣí-bóṣétì ní kí wọ́n lọ mú un wá lọ́dọ̀ ọkọ rẹ̀, Pálítíélì+ ọmọ Láíṣì. 16 Ṣùgbọ́n ọkọ rẹ̀ ń bá a rìn lọ, ó ń sunkún bí ó ṣe ń tẹ̀ lé e títí dé Báhúrímù.+ Ábínérì bá sọ fún un pé: “Ó yá, pa dà!” Nígbà náà, ó pa dà.

17 Láàárín àkókò yìí, Ábínérì ránṣẹ́ sí àwọn àgbààgbà Ísírẹ́lì pé: “Ó ti pẹ́ díẹ̀ tí ẹ ti fẹ́ kí Dáfídì jọba lórí yín. 18 Ní báyìí, ẹ gbé ìgbésẹ̀, nítorí Jèhófà ti sọ fún Dáfídì pé: ‘Nípasẹ̀ Dáfídì+ ìránṣẹ́ mi ni màá fi gba àwọn èèyàn mi Ísírẹ́lì kúrò lọ́wọ́ àwọn Filísínì àti gbogbo àwọn ọ̀tá wọn.’” 19 Nígbà náà, Ábínérì bá àwọn èèyàn Bẹ́ńjámínì+ sọ̀rọ̀. Ábínérì sì tún lọ bá Dáfídì sọ̀rọ̀ ní Hébúrónì ní ìdákọ́ńkọ́ kí ó lè mọ ohun tí Ísírẹ́lì àti gbogbo ilé Bẹ́ńjámínì fohùn ṣọ̀kan láti ṣe.

20 Nígbà tí Ábínérì àti ogún (20) ọkùnrin tó wà pẹ̀lú rẹ̀ dé ọ̀dọ̀ Dáfídì ní Hébúrónì, Dáfídì se àsè fún Ábínérì àti àwọn ọkùnrin rẹ̀. 21 Ni Ábínérì bá sọ fún Dáfídì pé: “Jẹ́ kí n lọ kó gbogbo Ísírẹ́lì jọ sọ́dọ̀ olúwa mi ọba, kí wọ́n lè bá ọ dá májẹ̀mú, wàá sì di ọba lórí gbogbo àwọn tí o* fẹ́.” Nítorí náà, Dáfídì rán Ábínérì lọ, ó sì lọ ní àlàáfíà.

22 Kété lẹ́yìn náà, àwọn ìránṣẹ́ Dáfídì àti Jóábù dé láti ibi tí wọ́n ti lọ fi ogun kó ẹrù àwọn èèyàn, ohun tí wọ́n kó dé sì pọ̀ gan-an. Ábínérì kò sí lọ́dọ̀ Dáfídì ní Hébúrónì mọ́, nítorí ó ti rán an lọ ní àlàáfíà. 23 Nígbà tí Jóábù+ àti gbogbo ọmọ ogun tó wà pẹ̀lú rẹ̀ dé, wọ́n ròyìn fún Jóábù pé: “Ábínérì+ ọmọ Nérì+ wá sọ́dọ̀ ọba, ó rán an lọ, ó sì lọ ní àlàáfíà.” 24 Nítorí náà, Jóábù wọlé lọ bá ọba, ó sì sọ pé: “Kí lo ṣe yìí? Ábínérì wá sọ́dọ̀ rẹ. Kí ló dé tí o fi rán an lọ, tí o sì jẹ́ kí ó lọ bẹ́ẹ̀? 25 Ṣebí o mọ Ábínérì ọmọ Nérì dáadáa! Torí kí ó lè tàn ọ́ ni ó ṣe wá, kí ó sì mọ gbogbo ìrìn rẹ àti gbogbo ohun tí ò ń ṣe.”

26 Jóábù bá jáde kúrò lọ́dọ̀ Dáfídì, ó sì rán àwọn òjíṣẹ́ tẹ̀ lé Ábínérì, wọ́n mú un pa dà láti ibi kòtò omi Sáírà; ṣùgbọ́n Dáfídì kò mọ nǹkan kan nípa rẹ̀. 27 Nígbà tí Ábínérì pa dà sí Hébúrónì,+ Jóábù mú un wọnú ibì kan lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹnubodè láti bá a sọ̀rọ̀ ní ìdákọ́ńkọ́. Àmọ́, ibẹ̀ ni ó ti gún un ní ikùn, ó sì kú;+ èyí jẹ́ nítorí pé ó pa* Ásáhélì+ arákùnrin rẹ̀. 28 Nígbà tí Dáfídì wá gbọ́ nípa rẹ̀, ó ní: “Ọrùn èmi àti ìjọba mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀+ Ábínérì ọmọ Nérì níwájú Jèhófà títí láé. 29 Kí ó yí dà sórí Jóábù+ àti gbogbo ilé bàbá rẹ̀. Kí ọkùnrin tí nǹkan ń dà lára rẹ̀+ tàbí tí ó jẹ́ adẹ́tẹ̀  + tàbí tí ó yarọ* tàbí ẹni tí idà pa tàbí ẹni tí kò ní oúnjẹ+ má sì tán nílé Jóábù!” 30 Bí Jóábù àti Ábíṣáì+ ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ṣe pa Ábínérì+ nítorí pé ó pa Ásáhélì àbúrò wọn ní Gíbíónì lójú ogun+ nìyẹn.

31 Nígbà náà, Dáfídì sọ fún Jóábù àti gbogbo àwọn èèyàn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ pé: “Ẹ fa aṣọ yín ya, ẹ wọ aṣọ ọ̀fọ̀,* kí ẹ sì pohùn réré ẹkún nítorí Ábínérì.” Ọba Dáfídì sì ń rìn bọ̀ lẹ́yìn àga ìgbókùú náà. 32 Wọ́n sin Ábínérì sí Hébúrónì; ọba sunkún kíkankíkan ní ibojì Ábínérì, gbogbo àwọn èèyàn náà sì sunkún. 33 Ọba sun rárà nítorí Ábínérì, ó sì sọ pé:

“Ṣé ó yẹ kí Ábínérì kú ikú òpònú?

34 Wọn ò de ọwọ́ rẹ,

Ṣẹkẹ́ṣẹkẹ̀* ò sì sí ní ẹsẹ̀ rẹ.

O ṣubú bí ẹni ṣubú níwájú ọ̀daràn.”*+

Gbogbo àwọn èèyàn náà bá tún bú sẹ́kún nítorí rẹ̀.

35 Lẹ́yìn náà, gbogbo àwọn èèyàn náà wá fún Dáfídì ní oúnjẹ láti tù ú nínú* nígbà tí ilẹ̀ kò tíì ṣú, àmọ́ Dáfídì búra pé: “Kí Ọlọ́run fìyà jẹ mí gan-an, tí mo bá fi oúnjẹ tàbí ohunkóhun kan ẹnu+ kí oòrùn tó wọ̀!” 36 Gbogbo àwọn èèyàn náà fiyè sí i, ó sì dára lójú wọn. Bí gbogbo nǹkan tí ọba ti ń ṣe tẹ́lẹ̀ ṣe dára lójú wọn, bẹ́ẹ̀ ni èyí náà dára lójú gbogbo àwọn èèyàn náà. 37 Gbogbo àwọn èèyàn náà àti gbogbo Ísírẹ́lì sì wá mọ̀ lọ́jọ́ yẹn pé ọba kọ́ ló ní kí wọ́n pa+ Ábínérì ọmọ Nérì. 38 Ìgbà náà ni ọba sọ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé: “Ṣé ẹ ò mọ̀ pé olórí àti èèyàn ńlá ni ẹni tó ṣubú lónìí yìí ní Ísírẹ́lì?+ 39 Ó rẹ̀ mí lónìí yìí, bó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n fòróró yàn mí ṣe ọba,+ ìwà àwọn ọkùnrin yìí, àwọn ọmọ Seruáyà,+ ti le jù fún mi.+ Kí Jèhófà san ibi pa dà fún ẹni tó ń hùwà ibi.”+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́