ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Nehemáyà 9
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Nehemáyà

      • Àwọn èèyàn jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ wọn (1-38)

        • Jèhófà, Ọlọ́run tó ń dárí jini (17)

Nehemáyà 9:1

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “aṣọ àpò ìdọ̀họ.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 7:6; Jon 3:5, 6

Nehemáyà 9:2

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹsr 9:1, 2; Ne 13:3
  • +Le 26:40; Ẹsr 9:6; Sm 106:6; Da 9:8

Nehemáyà 9:3

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “ìdá mẹ́rin ọjọ́.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ne 8:3, 8

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    10/15/2013, ojú ìwé 22

Nehemáyà 9:4

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ne 8:7
  • +Ne 8:4

Nehemáyà 9:5

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “láti ayérayé dé ayérayé.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 33:10, 11

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    10/15/2013, ojú ìwé 21, 23

Nehemáyà 9:6

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 6:4

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    10/15/2013, ojú ìwé 23

Nehemáyà 9:7

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 12:1, 2
  • +Jẹ 11:31
  • +Jẹ 17:5

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    10/15/2013, ojú ìwé 23-24

Nehemáyà 9:8

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “èso.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 22:10-12
  • +Jẹ 15:18

Nehemáyà 9:9

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 2:23-25; 3:7

Nehemáyà 9:10

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 7:3; Di 6:22
  • +Ẹk 5:2
  • +Ẹk 9:16

Nehemáyà 9:11

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 14:21, 22
  • +Ẹk 15:1, 5, 10

Nehemáyà 9:12

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “àwọsánmà tó rí bí òpó.”

  • *

    Tàbí “iná tó rí bí òpó.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 13:21; 14:19, 20

Nehemáyà 9:13

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “àwọn òfin tó ṣeé gbára lé.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 19:11
  • +Di 4:10, 36
  • +Di 4:8

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    10/15/2013, ojú ìwé 24

Nehemáyà 9:14

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 16:29; 20:8-11; Di 5:12-14

Nehemáyà 9:15

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “tí o gbé ọwọ́ rẹ sókè.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 16:4
  • +Ẹk 17:6

Nehemáyà 9:16

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “mú kí ọrùn wọn le.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 14:44
  • +Di 9:6

Nehemáyà 9:17

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “wọ́n mú kí ọrùn wọn le.”

  • *

    Tàbí “Ọlọ́run ìṣe ìdáríjì.”

  • *

    Tàbí “olóore ọ̀fẹ́.”

  • *

    Tàbí “inú rere onífẹ̀ẹ́ rẹ.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 14:11, 41
  • +Nọ 14:1, 4
  • +Ẹk 34:6; Nọ 14:18
  • +Di 4:31

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Jí!,

    No. 1 2021 ojú ìwé 14

Nehemáyà 9:18

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ère dídà.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 32:1, 4

Nehemáyà 9:19

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “àwọsánmà tó rí bí òpó.”

  • *

    Tàbí “iná tó rí bí òpó.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 14:19, 20
  • +Ẹk 40:38; Nọ 9:15

Nehemáyà 9:20

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 11:17, 25
  • +Ẹk 16:14, 15
  • +Nọ 20:8

Nehemáyà 9:21

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 16:35; Nọ 14:33; Di 2:7
  • +Di 29:5

Nehemáyà 9:22

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 11:23
  • +Nọ 21:23, 24; Di 2:31
  • +Nọ 21:26
  • +Nọ 21:33, 35

Nehemáyà 9:23

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 15:1, 5
  • +Jẹ 12:7; 26:3

Nehemáyà 9:24

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 14:29-31; Joṣ 21:43
  • +Joṣ 18:1

Nehemáyà 9:25

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ilẹ̀ dáradára.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 3:4, 5
  • +Di 8:7-9
  • +Joṣ 24:13

Nehemáyà 9:26

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “wọ́n ju Òfin rẹ sí ẹ̀yìn wọn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 31:20; 32:15; Ond 2:12
  • +2Ọb 21:11; Sm 106:38

Nehemáyà 9:27

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ond 2:14
  • +Di 31:17
  • +Ond 2:18; 3:9, 15; 1Sa 12:11; 2Ọb 13:4, 5

Nehemáyà 9:28

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ond 2:19
  • +Ond 4:1, 2; 6:1
  • +Ond 6:6
  • +Sm 106:43-45

Nehemáyà 9:29

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 17:13, 14; 2Kr 24:19
  • +Le 18:5

Nehemáyà 9:30

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ro 10:21
  • +2Kr 36:15, 16; Ais 42:24; Jer 40:2, 3

Nehemáyà 9:31

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “olóore ọ̀fẹ́.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Isk 14:22
  • +Ẹk 34:6; Di 4:31

Nehemáyà 9:32

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 7:9; Da 9:4
  • +2Ọb 24:12, 14
  • +Jer 34:18-20
  • +Ida 4:13, 14
  • +2Ọb 17:6

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    10/15/2013, ojú ìwé 23

Nehemáyà 9:33

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Da 9:5

Nehemáyà 9:34

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ìkìlọ̀.”

Nehemáyà 9:35

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ilẹ̀ dáradára.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 28:47; 32:15

Nehemáyà 9:36

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 28:48; Ẹsr 9:9

Nehemáyà 9:37

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “ara wa.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 28:15, 33; Ne 5:4

Nehemáyà 9:38

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 23:3; 2Kr 15:12; Ẹsr 10:3
  • +Ne 10:28, 29

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    10/15/1998, ojú ìwé 21

Àwọn míì

Neh. 9:1Joṣ 7:6; Jon 3:5, 6
Neh. 9:2Ẹsr 9:1, 2; Ne 13:3
Neh. 9:2Le 26:40; Ẹsr 9:6; Sm 106:6; Da 9:8
Neh. 9:3Ne 8:3, 8
Neh. 9:4Ne 8:7
Neh. 9:4Ne 8:4
Neh. 9:5Jer 33:10, 11
Neh. 9:6Di 6:4
Neh. 9:7Jẹ 12:1, 2
Neh. 9:7Jẹ 11:31
Neh. 9:7Jẹ 17:5
Neh. 9:8Jẹ 22:10-12
Neh. 9:8Jẹ 15:18
Neh. 9:9Ẹk 2:23-25; 3:7
Neh. 9:10Ẹk 7:3; Di 6:22
Neh. 9:10Ẹk 5:2
Neh. 9:10Ẹk 9:16
Neh. 9:11Ẹk 14:21, 22
Neh. 9:11Ẹk 15:1, 5, 10
Neh. 9:12Ẹk 13:21; 14:19, 20
Neh. 9:13Ẹk 19:11
Neh. 9:13Di 4:10, 36
Neh. 9:13Di 4:8
Neh. 9:14Ẹk 16:29; 20:8-11; Di 5:12-14
Neh. 9:15Ẹk 16:4
Neh. 9:15Ẹk 17:6
Neh. 9:16Nọ 14:44
Neh. 9:16Di 9:6
Neh. 9:17Nọ 14:11, 41
Neh. 9:17Nọ 14:1, 4
Neh. 9:17Ẹk 34:6; Nọ 14:18
Neh. 9:17Di 4:31
Neh. 9:18Ẹk 32:1, 4
Neh. 9:19Nọ 14:19, 20
Neh. 9:19Ẹk 40:38; Nọ 9:15
Neh. 9:20Nọ 11:17, 25
Neh. 9:20Ẹk 16:14, 15
Neh. 9:20Nọ 20:8
Neh. 9:21Ẹk 16:35; Nọ 14:33; Di 2:7
Neh. 9:21Di 29:5
Neh. 9:22Joṣ 11:23
Neh. 9:22Nọ 21:23, 24; Di 2:31
Neh. 9:22Nọ 21:26
Neh. 9:22Nọ 21:33, 35
Neh. 9:23Jẹ 15:1, 5
Neh. 9:23Jẹ 12:7; 26:3
Neh. 9:24Nọ 14:29-31; Joṣ 21:43
Neh. 9:24Joṣ 18:1
Neh. 9:25Di 3:4, 5
Neh. 9:25Di 8:7-9
Neh. 9:25Joṣ 24:13
Neh. 9:26Di 31:20; 32:15; Ond 2:12
Neh. 9:262Ọb 21:11; Sm 106:38
Neh. 9:27Ond 2:14
Neh. 9:27Di 31:17
Neh. 9:27Ond 2:18; 3:9, 15; 1Sa 12:11; 2Ọb 13:4, 5
Neh. 9:28Ond 2:19
Neh. 9:28Ond 4:1, 2; 6:1
Neh. 9:28Ond 6:6
Neh. 9:28Sm 106:43-45
Neh. 9:292Ọb 17:13, 14; 2Kr 24:19
Neh. 9:29Le 18:5
Neh. 9:30Ro 10:21
Neh. 9:302Kr 36:15, 16; Ais 42:24; Jer 40:2, 3
Neh. 9:31Isk 14:22
Neh. 9:31Ẹk 34:6; Di 4:31
Neh. 9:32Di 7:9; Da 9:4
Neh. 9:322Ọb 24:12, 14
Neh. 9:32Jer 34:18-20
Neh. 9:32Ida 4:13, 14
Neh. 9:322Ọb 17:6
Neh. 9:33Da 9:5
Neh. 9:35Di 28:47; 32:15
Neh. 9:36Di 28:48; Ẹsr 9:9
Neh. 9:37Di 28:15, 33; Ne 5:4
Neh. 9:382Ọb 23:3; 2Kr 15:12; Ẹsr 10:3
Neh. 9:38Ne 10:28, 29
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
  • 20
  • 21
  • 22
  • 23
  • 24
  • 25
  • 26
  • 27
  • 28
  • 29
  • 30
  • 31
  • 32
  • 33
  • 34
  • 35
  • 36
  • 37
  • 38
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Nehemáyà 9:1-38

Nehemáyà

9 Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù yìí, àwọn ọmọ Ísírẹ́lì kóra jọ; wọ́n gbààwẹ̀, wọ́n wọ aṣọ ọ̀fọ̀,* wọ́n sì da iyẹ̀pẹ̀ sórí.+ 2 Àwọn àtọmọdọ́mọ Ísírẹ́lì wá ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò lára gbogbo àwọn àjèjì,+ wọ́n dìde dúró, wọ́n sì jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ wọn àti àṣìṣe àwọn bàbá wọn.+ 3 Lẹ́yìn náà, wọ́n dìde dúró ní àyè wọn, wọ́n sì fi wákàtí mẹ́ta* ka ìwé Òfin+ Jèhófà Ọlọ́run wọn sókè; wọ́n fi wákàtí mẹ́ta míì jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ wọn, wọ́n sì ń wólẹ̀ fún Jèhófà Ọlọ́run wọn.

4 Jéṣúà, Bánì, Kádímíélì, Ṣebanáyà, Búnì, Ṣerebáyà,+ Bánì àti Kénánì dúró lórí pèpéle+ àwọn ọmọ Léfì, wọ́n gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì ń sunkún sí Jèhófà Ọlọ́run wọn. 5 Àwọn ọmọ Léfì, ìyẹn Jéṣúà, Kádímíélì, Bánì, Haṣabanéáyà, Ṣerebáyà, Hodáyà, Ṣebanáyà àti Petaháyà sọ pé: “Ẹ dìde, kí ẹ yin Jèhófà Ọlọ́run yín títí láé àti láéláé.*+ Kí wọ́n yin orúkọ rẹ ológo, èyí tí a gbé ga ju gbogbo ìbùkún àti ìyìn lọ.

6 “Ìwọ nìkan ṣoṣo ni Jèhófà;+ ìwọ lo dá ọ̀run, àní ọ̀run àwọn ọ̀run àti gbogbo ọmọ ogun wọn, ayé àti gbogbo ohun tó wà lórí rẹ̀, àwọn òkun àti gbogbo ohun tó wà nínú wọn. O pa gbogbo wọn mọ́, àwọn ọmọ ogun ọ̀run sì ń forí balẹ̀ fún ọ. 7 Ìwọ ni Jèhófà Ọlọ́run tòótọ́, tó yan Ábúrámù,+ tó mú un jáde kúrò ní Úrì,+ ìlú àwọn ará Kálídíà, tó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Ábúráhámù.+ 8 O rí i pé ó jẹ́ olóòótọ́ níwájú rẹ,+ torí náà, o bá a dá májẹ̀mú láti fún un ní ilẹ̀ àwọn ọmọ Kénáánì, àwọn ọmọ Hétì, àwọn Ámórì, àwọn Pérísì, àwọn ará Jébúsì àti àwọn Gẹ́gáṣì, pé kó fún àwọn ọmọ* rẹ̀;+ o sì mú ìlérí rẹ ṣẹ nítorí pé olódodo ni ọ́.

9 “O rí ìpọ́njú àwọn baba ńlá wa ní Íjíbítì,+ o sì gbọ́ igbe ẹkún wọn ní Òkun Pupa. 10 O wá ṣe àwọn iṣẹ́ àmì àti àwọn iṣẹ́ ìyanu láti fìyà jẹ Fáráò àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo àwọn èèyàn ilẹ̀ rẹ̀,+ torí o mọ̀ pé wọ́n ti kọjá àyè wọn+ sí àwọn èèyàn rẹ. O ṣe orúkọ fún ara rẹ, orúkọ náà sì wà títí dòní.+ 11 O pín òkun sí méjì níwájú wọn, kí wọ́n lè gba àárín òkun kọjá lórí ilẹ̀ gbígbẹ,+ o fi àwọn tó ń lépa wọn sọ̀kò sínú ibú bí òkúta tí a jù sínú omi tó ń ru gùdù.+ 12 O fi ọwọ̀n ìkùukùu* darí wọn ní ọ̀sán, o sì fi ọwọ̀n iná* darí wọn ní òru, láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ ní ọ̀nà tí wọ́n máa gbà.+ 13 O sọ̀ kalẹ̀ sórí Òkè Sínáì,+ o bá wọn sọ̀rọ̀ láti ọ̀run,+ o sì fún wọn ní àwọn ìdájọ́ òdodo, àwọn òfin òtítọ́,* àwọn ìlànà àti àwọn àṣẹ tó dáa.+ 14 O jẹ́ kí wọ́n mọ Sábáàtì mímọ́+ rẹ, o sì fún wọn ní àṣẹ, ìlànà àti òfin nípasẹ̀ Mósè ìránṣẹ́ rẹ. 15 O fún wọn ní oúnjẹ láti ọ̀run nígbà tí ebi ń pa wọ́n,+ o fún wọn ní omi látinú àpáta nígbà tí òùngbẹ ń gbẹ wọ́n,+ o sì ní kí wọ́n wọ ilẹ̀ tí o búra* pé wàá fún wọn, kí wọ́n sì gbà á.

16 “Àmọ́, àwọn baba ńlá wa kọjá àyè wọn,+ wọ́n sì ya alágídí,*+ wọn kò fetí sí àwọn àṣẹ rẹ. 17 Wọn ò fetí sílẹ̀,+ wọn ò sì rántí àwọn ohun àgbàyanu tí o ṣe láàárín wọn, àmọ́ wọ́n ya alágídí,* wọ́n sì yan olórí láti kó wọn pa dà sí ipò ẹrú wọn ní Íjíbítì.+ Ṣùgbọ́n Ọlọ́run tó ṣe tán láti dárí jini* ni ọ́, o jẹ́ ẹni tó ń gba tẹni rò* àti aláàánú, o kì í tètè bínú, ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀* sì pọ̀ gidigidi,+ o ò pa wọ́n tì.+ 18 Kódà nígbà tí wọ́n ṣe ère onírin* ọmọ màlúù fún ara wọn, tí wọ́n sì ń sọ pé, ‘Ọlọ́run rẹ nìyí tó mú ọ jáde kúrò ní Íjíbítì,’+ tí wọ́n hu ìwà àìlọ́wọ̀ tó bùáyà, 19 síbẹ̀ ìwọ, nínú àánú ńlá rẹ, o ò kọ̀ wọ́n sílẹ̀ nínú aginjù.+ Ọwọ̀n ìkùukùu* kò kúrò lórí wọn ní ọ̀sán láti máa darí wọn ní ọ̀nà wọn, ọwọ̀n iná* kò sì kúrò ní òru láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ ní ọ̀nà tí wọ́n máa gbà.+ 20 O fún wọn ní ẹ̀mí rere rẹ láti jẹ́ kí wọ́n ní ìjìnlẹ̀ òye,+ o ò fawọ́ mánà rẹ sẹ́yìn kúrò ní ẹnu wọn,+ o sì fún wọn ní omi nígbà tí òùngbẹ ń gbẹ wọ́n.+ 21 Ogójì (40) ọdún lo fi pèsè oúnjẹ fún wọn ní aginjù.+ Wọn ò ṣaláìní nǹkan kan. Aṣọ wọn ò gbó,+ ẹsẹ̀ wọn ò sì wú.

22 “O fún wọn ní àwọn ìjọba àti àwọn èèyàn, o sì pín wọn ní ẹyọ-ẹyọ fún wọn,+ kí wọ́n lè gba ilẹ̀ Síhónì,+ ìyẹn ilẹ̀ ọba Hẹ́ṣíbónì+ àti ilẹ̀ Ógù+ ọba Báṣánì. 23 O mú kí àwọn ọmọ wọn pọ̀ bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run.+ Lẹ́yìn náà, o mú wọn wá sí ilẹ̀ tí o ṣèlérí fún àwọn baba ńlá wọn pé kí wọ́n wọ̀, kí wọ́n sì gbà.+ 24 Torí náà, àwọn ọmọ wọn wọlé, wọ́n sì gba ilẹ̀ náà,+ o ṣẹ́gun àwọn ọmọ Kénáánì tó ń gbé ilẹ̀ náà níwájú wọn,+ o sì fi wọ́n lé wọn lọ́wọ́, látorí àwọn ọba wọn dórí àwọn èèyàn ilẹ̀ náà, kí wọ́n lè ṣe wọ́n bí wọ́n ṣe fẹ́. 25 Wọ́n gba àwọn ìlú olódi+ àti ilẹ̀ ọlọ́ràá,*+ wọ́n gba àwọn ilé tí oríṣiríṣi ohun rere kún inú rẹ̀, wọ́n gba àwọn kòtò omi tí wọ́n ti gbẹ́ síbẹ̀, àwọn ọgbà àjàrà, àwọn oko ólífì+ àti àwọn igi eléso tó pọ̀ rẹpẹtẹ. Torí náà, wọ́n jẹ, wọ́n yó, wọ́n sì sanra, wọ́n gbádùn oore ńlá rẹ.

26 “Àmọ́, wọ́n ya aláìgbọràn, wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí ọ,+ wọ́n sì kẹ̀yìn sí Òfin rẹ.* Wọ́n pa àwọn wòlíì rẹ tó kìlọ̀ fún wọn láti mú wọn pa dà sọ́dọ̀ rẹ, wọ́n sì hu ìwà àìlọ́wọ̀ tó bùáyà.+ 27 Nítorí èyí, o fi wọ́n lé ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn,+ wọ́n sì ń kó wàhálà bá wọn.+ Àmọ́, wọ́n á ké pè ọ́ ní àkókò wàhálà wọn, ìwọ náà á sì gbọ́ láti ọ̀run; nítorí àánú ńlá rẹ, wàá fún wọn ní olùgbàlà láti gbà wọ́n lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn.+

28 “Àmọ́, nígbà tí ara bá ti tù wọ́n, wọ́n á tún ṣe ohun tó burú níwájú rẹ,+ wàá sì fi wọ́n sílẹ̀ sọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn, wọ́n á sì jọba lé wọn lórí.*+ Lẹ́yìn náà, wọ́n á pa dà, wọ́n á sì ké pè ọ́ pé kí o ran àwọn lọ́wọ́,+ wàá gbọ́ láti ọ̀run, léraléra lo sì ń gbà wọ́n nítorí àánú ńlá rẹ.+ 29 O máa ń kìlọ̀ fún wọn kí o lè mú wọn pa dà wá sínú Òfin rẹ, síbẹ̀ ṣe ni wọ́n ń kọjá àyè wọn, wọn ò sì fetí sí àwọn àṣẹ rẹ;+ wọ́n ń ṣe ohun tó ta ko ìlànà rẹ, èyí tó máa jẹ́ kẹ́ni tó ba ń pa á mọ́ lè wà láàyè.+ Agídí wọn mú kí wọ́n kẹ̀yìn sí ọ, wọ́n mú kí ọrùn wọn le, wọn ò sì fetí sílẹ̀. 30 Ọ̀pọ̀ ọdún lo fi mú sùúrù fún wọn,+ o sì ń fi ẹ̀mí rẹ kìlọ̀ fún wọn nípasẹ̀ àwọn wòlíì rẹ, àmọ́ wọn ò gbọ́. Níkẹyìn, o fi wọ́n lé àwọn èèyàn ilẹ̀ tó yí wọn ká lọ́wọ́.+ 31 Nínú àánú ńlá rẹ, o ò pa wọ́n run,+ o ò sì fi wọ́n sílẹ̀, nítorí Ọlọ́run tó ń gba tẹni rò* àti aláàánú ni ọ́.+

32 “Ní báyìí, ìwọ Ọlọ́run wa, Ọlọ́run títóbi, alágbára ńlá, tó sì yẹ lẹ́ni tí à ń bẹ̀rù, tó ń pa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́, tí ó sì ń fi ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ hàn,+ má fojú kékeré wo gbogbo ìnira tó bá àwa, àwọn ọba wa, àwọn ìjòyè wa,+ àwọn àlùfáà wa,+ àwọn wòlíì wa,+ àwọn baba ńlá wa àti gbogbo àwọn èèyàn rẹ láti ìgbà àwọn ọba Ásíríà+ títí di òní yìí. 33 O ò lẹ́bi kankan nínú gbogbo ohun tó dé bá wa, nítorí òótọ́ lo fi bá wa lò; àwa la hùwà burúkú.+ 34 Ní ti àwọn ọba wa, àwọn ìjòyè wa, àwọn àlùfáà wa àti àwọn baba ńlá wa, wọn ò pa Òfin rẹ mọ́, wọn ò sì fiyè sí àwọn àṣẹ rẹ tàbí àwọn ìránnilétí* rẹ tí o fi kìlọ̀ fún wọn. 35 Kódà nígbà tí wọ́n wà lábẹ́ ìjọba ti ara wọn, tí wọ́n sì ń gbádùn ọ̀pọ̀ ohun rere tí o fún wọn, tí wọ́n ń gbé lórí ilẹ̀ tó fẹ̀, tó sì lọ́ràá* tí o fi jíǹkí wọn, wọn ò sìn ọ́,+ wọn ò sì jáwọ́ nínú ìwà búburú tí wọ́n ń hù. 36 Àwa rèé lónìí, àwa ẹrú,+ bẹ́ẹ̀ ni, ẹrú lórí ilẹ̀ tí o fún àwọn baba ńlá wa pé kí wọ́n máa jẹ èso rẹ̀ àti ohun rere rẹ̀. 37 Ọ̀pọ̀ àwọn ohun rere tí ilẹ̀ náà ń mú jáde jẹ́ ti àwọn ọba tí o fi ṣe olórí wa nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa.+ Wọ́n ń ṣàkóso àwa* àti àwọn ẹran ọ̀sìn wa bó ṣe wù wọ́n, a sì wà nínú wàhálà ńlá.

38 “Pẹ̀lú gbogbo èyí, a wọnú àdéhùn kan, a sì kọ àdéhùn+ náà sílẹ̀, àwọn ìjòyè wa, àwọn ọmọ Léfì wa àti àwọn àlùfáà wa ti fọwọ́ sí i, wọ́n sì gbé èdìdì lé e.”+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́