ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Jeremáyà 23
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Jeremáyà

      • Àwọn olùṣọ́ àgùntàn rere àti búburú (1-4)

      • Ààbò lábẹ́ “èéhù kan tí ó jẹ́ olódodo” (5-8)

      • Ọlọ́run dá àwọn wòlíì èké lẹ́bi (9-32)

      • “Ẹrù tó wúwo” látọ̀dọ̀ Jèhófà (33-40)

Jeremáyà 23:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 10:21; 50:6; Isk 34:2

Jeremáyà 23:2

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Isk 34:5

Jeremáyà 23:3

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ais 11:11; 35:10; Jer 29:14; 31:8
  • +Jer 50:19; Isk 34:14; Mik 2:12
  • +Di 30:3, 5; Emọ 9:14; Sek 10:8

Jeremáyà 23:4

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 3:15; Jo 21:15; Iṣe 20:28

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Jeremáyà, ojú ìwé 129-130

Jeremáyà 23:5

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ajogún.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ais 11:1; 53:2; Jer 33:15, 16; Sek 3:8; Mt 2:23
  • +Lk 1:32, 33
  • +Ais 9:7; 11:3, 4; 32:1

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Jeremáyà, ojú ìwé 173

Jeremáyà 23:6

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sek 10:6
  • +Di 33:28; Jer 32:37; Sek 14:11
  • +Ais 54:17

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Jeremáyà, ojú ìwé 173

Jeremáyà 23:7

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 16:14, 15

Jeremáyà 23:8

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ais 43:5; Isk 34:13; Sef 3:20

Jeremáyà 23:10

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 3:8, 9; 5:7; 13:27; Isk 22:11
  • +Ais 24:4; Joẹ 1:10
  • +Jer 12:4

Jeremáyà 23:11

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “apẹ̀yìndà.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ais 28:7; Jer 5:31; 6:13; Isk 22:25; Sef 3:4
  • +2Kr 33:1, 5; 36:14; Jer 7:11; Isk 8:10, 11; 23:39

Jeremáyà 23:12

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 13:16

Jeremáyà 23:13

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Isk 16:46

Jeremáyà 23:14

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “Wọ́n ń fún ọwọ́ àwọn aṣebi lókun.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 29:21, 23
  • +Jer 23:26
  • +Ais 3:9
  • +Jẹ 18:20; Di 32:32; Ais 1:10; Jud 7

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé-Ìṣọ́nà,

    3/1/1994, ojú ìwé 8-9

Jeremáyà 23:15

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ìyẹn, igi kan tó korò gan-an.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 8:14; 9:15

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé-Ìṣọ́nà,

    3/1/1994, ojú ìwé 9

Jeremáyà 23:16

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “Ìrètí asán ni wọ́n ń fún yín.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 27:9; 29:8
  • +Ida 2:14
  • +Jer 14:14; Isk 13:3; 22:28

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé-Ìṣọ́nà,

    3/1/1994, ojú ìwé 9

Jeremáyà 23:17

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 4:10; 6:13, 14; 8:11; Isk 13:10
  • +Mik 3:11

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé-Ìṣọ́nà,

    3/1/1994, ojú ìwé 11

Jeremáyà 23:19

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 25:32; 30:23, 24

Jeremáyà 23:21

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 14:14; 27:15; 29:8, 9

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé-Ìṣọ́nà,

    3/1/1994, ojú ìwé 9

Jeremáyà 23:22

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 25:4, 5

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé-Ìṣọ́nà,

    3/1/1994, ojú ìwé 11

Jeremáyà 23:24

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 16:7, 13; Owe 15:3; Emọ 9:2; Heb 4:13
  • +Sm 139:7

Jeremáyà 23:25

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 18:20; Jer 27:9; 29:21, 23

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé-Ìṣọ́nà,

    3/1/1994, ojú ìwé 9-10

Jeremáyà 23:26

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 14:14

Jeremáyà 23:27

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ond 3:7; 2Ọb 21:1, 3

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́),

    6/2019, ojú ìwé 4

    Ilé-Ìṣọ́nà,

    3/1/1994, ojú ìwé 10

Jeremáyà 23:29

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ìyẹn, hámà ńlá tí àwọn alágbẹ̀dẹ máa ń lò.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 5:14
  • +Heb 4:12

Jeremáyà 23:30

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 18:20; Jer 14:15; Isk 13:2, 3

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé-Ìṣọ́nà,

    2/1/1992, ojú ìwé 4

Jeremáyà 23:31

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Isk 13:7

Jeremáyà 23:32

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sef 3:4
  • +Jer 7:8; Ida 2:14

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé-Ìṣọ́nà,

    3/1/1994, ojú ìwé 9-10

Jeremáyà 23:33

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ọ̀rọ̀ Hébérù tí wọ́n túmọ̀ níbí yìí sí “ẹrù tó wúwo,” tún lè túmọ̀ sí “ìkéde.” Ńṣe ni wọ́n fi ọ̀rọ̀ yìí dárà ní ẹsẹ 33-38.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 12:7

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    3/15/2007, ojú ìwé 11

    3/1/1994, ojú ìwé 12

Jeremáyà 23:34

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “Ọ̀rọ̀.”

Jeremáyà 23:36

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ọ̀rọ̀.”

  • *

    Tàbí “ọ̀rọ̀.”

Jeremáyà 23:38

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “Ọ̀rọ̀.”

  • *

    Tàbí “ọ̀rọ̀.”

  • *

    Tàbí “Ọ̀rọ̀.”

Jeremáyà 23:40

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 24:9; 42:18; Ida 5:20; Da 9:16

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé-Ìṣọ́nà,

    3/1/1994, ojú ìwé 12-13

Àwọn míì

Jer. 23:1Jer 10:21; 50:6; Isk 34:2
Jer. 23:2Isk 34:5
Jer. 23:3Ais 11:11; 35:10; Jer 29:14; 31:8
Jer. 23:3Jer 50:19; Isk 34:14; Mik 2:12
Jer. 23:3Di 30:3, 5; Emọ 9:14; Sek 10:8
Jer. 23:4Jer 3:15; Jo 21:15; Iṣe 20:28
Jer. 23:5Ais 11:1; 53:2; Jer 33:15, 16; Sek 3:8; Mt 2:23
Jer. 23:5Lk 1:32, 33
Jer. 23:5Ais 9:7; 11:3, 4; 32:1
Jer. 23:6Sek 10:6
Jer. 23:6Di 33:28; Jer 32:37; Sek 14:11
Jer. 23:6Ais 54:17
Jer. 23:7Jer 16:14, 15
Jer. 23:8Ais 43:5; Isk 34:13; Sef 3:20
Jer. 23:10Jer 3:8, 9; 5:7; 13:27; Isk 22:11
Jer. 23:10Ais 24:4; Joẹ 1:10
Jer. 23:10Jer 12:4
Jer. 23:11Ais 28:7; Jer 5:31; 6:13; Isk 22:25; Sef 3:4
Jer. 23:112Kr 33:1, 5; 36:14; Jer 7:11; Isk 8:10, 11; 23:39
Jer. 23:12Jer 13:16
Jer. 23:13Isk 16:46
Jer. 23:14Jer 29:21, 23
Jer. 23:14Jer 23:26
Jer. 23:14Ais 3:9
Jer. 23:14Jẹ 18:20; Di 32:32; Ais 1:10; Jud 7
Jer. 23:15Jer 8:14; 9:15
Jer. 23:16Jer 27:9; 29:8
Jer. 23:16Ida 2:14
Jer. 23:16Jer 14:14; Isk 13:3; 22:28
Jer. 23:17Jer 4:10; 6:13, 14; 8:11; Isk 13:10
Jer. 23:17Mik 3:11
Jer. 23:19Jer 25:32; 30:23, 24
Jer. 23:21Jer 14:14; 27:15; 29:8, 9
Jer. 23:22Jer 25:4, 5
Jer. 23:24Jẹ 16:7, 13; Owe 15:3; Emọ 9:2; Heb 4:13
Jer. 23:24Sm 139:7
Jer. 23:25Di 18:20; Jer 27:9; 29:21, 23
Jer. 23:26Jer 14:14
Jer. 23:27Ond 3:7; 2Ọb 21:1, 3
Jer. 23:29Jer 5:14
Jer. 23:29Heb 4:12
Jer. 23:30Di 18:20; Jer 14:15; Isk 13:2, 3
Jer. 23:31Isk 13:7
Jer. 23:32Sef 3:4
Jer. 23:32Jer 7:8; Ida 2:14
Jer. 23:33Jer 12:7
Jer. 23:40Jer 24:9; 42:18; Ida 5:20; Da 9:16
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
  • 20
  • 21
  • 22
  • 23
  • 24
  • 25
  • 26
  • 27
  • 28
  • 29
  • 30
  • 31
  • 32
  • 33
  • 34
  • 35
  • 36
  • 37
  • 38
  • 39
  • 40
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Jeremáyà 23:1-40

Jeremáyà

23 “Ẹ gbé, ẹ̀yin olùṣọ́ àgùntàn tó ń pa àwọn àgùntàn ibi ìjẹko mi run, tí ẹ sì ń tú wọn ká!” ni Jèhófà wí.+

2 Torí náà, ohun tí Jèhófà Ọlọ́run Ísírẹ́lì sọ sí àwọn olùṣọ́ àgùntàn tó ń bójú tó àwọn èèyàn mi nìyí: “Ẹ ti tú àwọn àgùntàn mi ká, ẹ sì ń fọ́n wọn ká ṣáá, ẹ kò sì tọ́jú wọn.”+

“Torí náà màá fìyà jẹ yín nítorí ìwà ibi yín,” ni Jèhófà wí.

3 “Ìgbà náà ni màá kó àwọn tó ṣẹ́ kù lára àgùntàn mi jọ láti gbogbo ilẹ̀ tí mo fọ́n wọn ká sí,+ màá sì mú wọn pa dà wá sí ibi ìjẹko wọn,+ wọ́n á máa bímọ, wọ́n á sì di púpọ̀.+ 4 Màá sì gbé àwọn olùṣọ́ àgùntàn dìde lórí wọn tí á máa bójú tó wọn dáadáa.+ Ẹ̀rù ò ní bà wọ́n mọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn ò ní jáyà, kò sì sí ìkankan nínú wọn tó máa sọ nù,” ni Jèhófà wí.

5 “Wò ó! Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Jèhófà wí, “tí màá gbé èéhù* kan tó jẹ́ olódodo dìde fún Dáfídì.+ Ọba kan máa jẹ,+ á sì fi ìjìnlẹ̀ òye hùwà, á dá ẹjọ́ bó ṣe tọ́, á sì ṣe òdodo ní ilẹ̀ náà.+ 6 Júdà máa rí ìgbàlà ní ìgbà ayé rẹ̀,+ Ísírẹ́lì sì máa wà ní ààbò.+ Orúkọ tí a ó sì máa pè é ni, Jèhófà Ni Òdodo Wa.”+

7 “Síbẹ̀, ìgbà kan ń bọ̀,” ni Jèhófà wí, “tí wọn ò ní máa sọ pé: ‘Bí Jèhófà ti wà láàyè, ẹni tó mú àwọn èèyàn Ísírẹ́lì jáde kúrò ní ilẹ̀ Íjíbítì!’+ 8 kàkà bẹ́ẹ̀, wọ́n á máa sọ pé: ‘Bí Jèhófà ti wà láàyè, ẹni tó mú àwọn ọmọ ilé Ísírẹ́lì jáde kúrò, tó sì mú wọn wọlé wá láti ilẹ̀ àríwá àti gbogbo ilẹ̀ tó tú wọn ká sí!’ wọ́n á sì máa gbé lórí ilẹ̀ tiwọn.”+

9 Ní ti àwọn wòlíì:

Ọkàn mi bà jẹ́ nínú mi.

Gbogbo egungun mi ń gbọ̀n.

Mo dà bí ọkùnrin tó ti mutí yó

Àti bí ọkùnrin tí wáìnì ń pa,

Nítorí Jèhófà àti nítorí àwọn ọ̀rọ̀ mímọ́ rẹ̀.

10 Nítorí àwọn alágbèrè ló kún ilẹ̀ náà;+

Nítorí ègún, ilẹ̀ náà ti bẹ̀rẹ̀ sí í ṣọ̀fọ̀+

Àwọn ibi ìjẹko inú aginjù ti gbẹ.+

Ọ̀nà wọn jẹ́ ibi, wọ́n sì ń ṣi agbára wọn lò.

11 “Nítorí pé wòlíì àti àlùfáà ti di eléèérí.*+

Kódà, mo ti rí ìwà búburú wọn nínú ilé mi,”+ ni Jèhófà wí.

12 “Nítorí náà, ọ̀nà wọn á di ibi tó ń yọ̀, tó sì ṣókùnkùn;+

A ó tì wọ́n, wọ́n á sì ṣubú.

Torí pé màá mú àjálù bá wọn

Ní ọdún ìbẹ̀wò,” ni Jèhófà wí.

13 “Mo ti rí ohun ìríra nínú àwọn wòlíì Samáríà.+

Báálì ló ń mú kí wọ́n lè sọ àsọtẹ́lẹ̀,

Wọ́n sì ń kó àwọn èèyàn mi Ísírẹ́lì ṣìnà.

14 Mo ti rí àwọn ohun tó burú nínú àwọn wòlíì Jerúsálẹ́mù.

Wọ́n ń ṣe àgbèrè,+ wọ́n sì ń rìn nínú èké;+

Wọ́n ń ti àwọn aṣebi lẹ́yìn,*

Wọn ò sì jáwọ́ nínú ìwà burúkú wọn.

Lójú mi, gbogbo wọn dà bíi Sódómù,+

Àwọn tó ń gbé inú rẹ̀ sì dà bíi Gòmórà.”+

15 Nítorí náà, ohun tí Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun sọ sí àwọn wòlíì náà nìyí:

“Wò ó, màá mú kí wọ́n jẹ iwọ*

Màá sì fún wọn ní omi tó ní májèlé mu.+

Nítorí láti ọ̀dọ̀ àwọn wòlíì Jerúsálẹ́mù ni ìpẹ̀yìndà ti tàn káàkiri ilẹ̀ náà.”

16 Ohun tí Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun sọ nìyí:

“Ẹ má fetí sí ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì tó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún yín.+

Wọ́n ń tàn yín ni.*

Ìran tó wá láti inú ọkàn wọn ni wọ́n ń sọ,+

Kì í ṣe láti ẹnu Jèhófà.+

17 Léraléra ni wọ́n ń sọ fún àwọn tí kò bọ̀wọ̀ fún mi pé,

‘Jèhófà ti sọ pé: “Ẹ máa ní àlàáfíà.”’+

Wọ́n sì ń sọ fún gbogbo ẹni tó ní agídí ọkàn pé,

‘Àjálù kankan kò ní bá yín.’+

18 Ta ló ti dúró láàárín àwọn èèyàn tó sún mọ́ Jèhófà

Kí ó lè rí, kí ó sì gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀?

Ta ló ti fiyè sí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kí ó lè gbọ́ ọ?

19 Wò ó! Ìjì Jèhófà máa fi ìbínú tú jáde;

Bí ìjì líle tó ń fẹ́ yí ká, á tú jáde sí orí àwọn ẹni burúkú.+

20 Ìbínú Jèhófà kò ní dáwọ́ dúró

Títí á fi ṣe ohun tó wà lọ́kàn rẹ̀, tí á sì mú èrò rẹ̀ ṣẹ.

Ní àkókò òpin, ọ̀rọ̀ yìí á yé yín dáadáa.

21 Mi ò rán àwọn wòlíì náà, síbẹ̀ wọ́n sáré.

Mi ò bá wọn sọ̀rọ̀, síbẹ̀ wọ́n sọ tẹ́lẹ̀.+

22 Àmọ́ tó bá jẹ́ pé wọ́n wà láàárín àwọn èèyàn tó sún mọ́ mi,

Wọ́n á ti jẹ́ kí àwọn èèyàn mi gbọ́ ọ̀rọ̀ mi

Wọ́n á sì ti mú kí wọ́n yí pa dà kúrò ní ọ̀nà búburú wọn àti kúrò nínú ìwà ibi wọn.”+

23 “Ṣé tòsí nìkan ni mo ti jẹ́ Ọlọ́run,” ni Jèhófà wí, “ṣé mi kì í ṣe Ọlọ́run láti ọ̀nà jíjìn ni?”

24 “Ṣé ibì kan wà téèyàn lè sá pa mọ́ sí tí mi ò ní lè rí i?”+ ni Jèhófà wí.

“Ǹjẹ́ ohunkóhun wà láyé tàbí lọ́run tí ojú mi ò tó?”+ ni Jèhófà wí.

25 “Mo ti gbọ́ ohun tí àwọn wòlíì tó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké ní orúkọ mi sọ, pé, ‘Mo lá àlá! Mo lá àlá!’+ 26 Ìgbà wo ni àwọn wòlíì ò ní yéé sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké tó wà lọ́kàn wọn? Wọ́n jẹ́ àwọn wòlíì tó ń sọ ẹ̀tàn inú ọkàn wọn.+ 27 Wọ́n fẹ́ kí àwọn èèyàn mi gbàgbé orúkọ mi nípasẹ̀ àwọn àlá tí wọ́n ń rọ́ fún ọmọnìkejì wọn, gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wọn ti gbàgbé orúkọ mi nítorí Báálì.+ 28 Ẹ jẹ́ kí wòlíì tó bá lá àlá rọ́ àlá náà, ṣùgbọ́n kí ẹni tí ó ní ọ̀rọ̀ mi sọ ọ́ pẹ̀lú òtítọ́.”

“Kí ni pòròpórò ní í ṣe pẹ̀lú ọkà?” ni Jèhófà wí.

29 “Ǹjẹ́ kì í ṣe bí iná ni ọ̀rọ̀ mi rí,”+ ni Jèhófà wí “àti bí òòlù irin* tó ń fọ́ àpáta sí wẹ́wẹ́?”+

30 “Nítorí náà, mo dojú ìjà kọ àwọn wòlíì, àwọn tó ń jí ọ̀rọ̀ mi gbé lọ lọ́dọ̀ ọmọnìkejì wọn,” ni Jèhófà wí.+

31 “Wò ó, mo dojú ìjà kọ àwọn wòlíì,” ni Jèhófà wí, “àwọn tó ń fi ahọ́n wọn sọ pé, ‘Ó wí pé!’”+

32 “Wò ó, mo dojú ìjà kọ àwọn wòlíì tó ń lá àlá èké,” ni Jèhófà wí, “àwọn tó ń rọ́ àlá, tí wọ́n sì ń kó àwọn èèyàn mi ṣìnà nítorí irọ́ wọn àti bí wọ́n ṣe ń fọ́nnu.”+

“Ṣùgbọ́n mi ò rán wọn, bẹ́ẹ̀ ni mi ò pàṣẹ fún wọn. Nítorí náà, wọn ò ní ṣe àwọn èèyàn yìí láǹfààní kankan,”+ ni Jèhófà wí.

33 “Nígbà tí àwọn èèyàn yìí tàbí wòlíì tàbí àlùfáà kan bá béèrè lọ́wọ́ rẹ pé, ‘Kí ni ẹrù tó wúwo* látọ̀dọ̀ Jèhófà?’ kí o sọ fún wọn pé, ‘“Ẹ̀yin gan-an ni ẹrù tó wúwo náà! Màá sì lé yín dà nù,”+ ni Jèhófà wí.’ 34 Ní ti wòlíì tàbí àlùfáà tàbí àwọn èèyàn tó bá sọ pé, ‘Ẹrù* tó wúwo látọ̀dọ̀ Jèhófà nìyí!’ Ńṣe ni màá dojú kọ ọkùnrin yẹn àti agbo ilé rẹ̀. 35 Ohun tí ẹnì kọ̀ọ̀kan yín ń sọ fún ẹnì kejì rẹ̀ àti fún arákùnrin rẹ̀ ni pé, ‘Kí ni ìdáhùn Jèhófà? Kí sì ni ohun tí Jèhófà sọ?’ 36 Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe mẹ́nu kan ẹrù* tó wúwo látọ̀dọ̀ Jèhófà mọ́, nítorí ẹrù* tó wúwo náà jẹ́ ọ̀rọ̀ ẹnì kọ̀ọ̀kan yín, ẹ sì ti yí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run alààyè pa dà, ọ̀rọ̀ Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun, Ọlọ́run wa.

37 “Ohun tí wàá béèrè lọ́wọ́ wòlíì náà nìyí, ‘Kí ni Jèhófà fi dá ọ lóhùn? Kí sì ni Jèhófà sọ? 38 Bí o bá ṣì ń sọ pé “Ẹrù* tó wúwo látọ̀dọ̀ Jèhófà!” ohun tí Jèhófà sọ nìyí: “Nítorí ẹ̀ ń sọ pé, ‘Ọ̀rọ̀ yìí jẹ́ ẹrù* tó wúwo látọ̀dọ̀ Jèhófà,’ lẹ́yìn tí mo ti sọ fún ọ pé, ‘Ẹ kò gbọ́dọ̀ sọ pé: “Ẹrù* tó wúwo látọ̀dọ̀ Jèhófà!”’ 39 wò ó! Màá gbé yín sókè, màá sì sọ yín nù kúrò níwájú mi, ẹ̀yin àti ìlú tí mo fún ẹ̀yin àti àwọn baba ńlá yín. 40 Ńṣe ni màá mú ìtìjú tí kò lópin àti ẹ̀tẹ́ ayérayé bá yín, èyí tí kò ní ṣeé gbàgbé.”’”+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́