ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Sáàmù 109
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Sáàmù

      • Àdúrà ẹni tí ìdààmú bá

        • ‘Kí ẹlòmíì gba ipò rẹ̀’ (8)

        • Ọlọ́run dúró ti aláìní (31)

Sáàmù 109:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 33:1

Sáàmù 109:2

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 15:2, 3; Sm 31:18

Sáàmù 109:3

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 15:12; 16:5-7; Sm 69:4

Sáàmù 109:4

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 13:39

Sáàmù 109:5

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 35:11, 12; 38:19, 20
  • +Sm 55:12-14

Sáàmù 109:6

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “afinisùn.”

Sáàmù 109:7

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “kí wọ́n pè é ní ẹni burúkú.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ais 1:15; Mik 3:4

Sáàmù 109:8

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 55:23; Mt 27:5
  • +Iṣe 1:16-20

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àwọn Ìtẹ̀jáde Tá A Tọ́ka sí Nínú Ìwé Ìpàdé, 8/2016,

    Jíjẹ́rìí Kúnnákúnná, ojú ìwé 18-19

Sáàmù 109:9

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “àwọn ọmọkùnrin.”

Sáàmù 109:10

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “àwọn ọmọkùnrin.”

Sáàmù 109:11

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ẹni tó ń gba èlé gọbọi dẹ pańpẹ́ mú.”

Sáàmù 109:12

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ìfẹ́ tí kì í yẹ̀.”

Sáàmù 109:13

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ìran àtẹ̀lé.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 37:28

Sáàmù 109:14

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 3:28, 29; 21:1

Sáàmù 109:15

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 34:16

Sáàmù 109:16

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “fi ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ hàn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jem 2:13
  • +Sm 10:2
  • +2Sa 16:11; 17:1, 2; Sm 37:32

Sáàmù 109:19

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 109:29

Sáàmù 109:20

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ọkàn mi.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 17:23

Sáàmù 109:21

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 25:11; 31:3
  • +Sm 36:7; 69:16; 86:5

Sáàmù 109:22

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 40:17
  • +Sm 102:4

Sáàmù 109:23

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    9/1/2006, ojú ìwé 13

Sáàmù 109:24

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “Ara mi ti rù, láìní ọ̀rá (òróró).”

Sáàmù 109:25

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 31:11
  • +Sm 22:7; Mt 27:39

Sáàmù 109:29

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “aṣọ àwọ̀lékè tí kò lápá.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 35:26

Sáàmù 109:30

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 22:22

Sáàmù 109:31

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ọkàn rẹ̀.”

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    9/1/2006, ojú ìwé 14

Àwọn míì

Sm 109:1Sm 33:1
Sm 109:22Sa 15:2, 3; Sm 31:18
Sm 109:32Sa 15:12; 16:5-7; Sm 69:4
Sm 109:42Sa 13:39
Sm 109:5Sm 35:11, 12; 38:19, 20
Sm 109:5Sm 55:12-14
Sm 109:7Ais 1:15; Mik 3:4
Sm 109:8Sm 55:23; Mt 27:5
Sm 109:8Iṣe 1:16-20
Sm 109:13Sm 37:28
Sm 109:142Sa 3:28, 29; 21:1
Sm 109:15Sm 34:16
Sm 109:16Jem 2:13
Sm 109:16Sm 10:2
Sm 109:162Sa 16:11; 17:1, 2; Sm 37:32
Sm 109:19Sm 109:29
Sm 109:202Sa 17:23
Sm 109:21Sm 25:11; 31:3
Sm 109:21Sm 36:7; 69:16; 86:5
Sm 109:22Sm 40:17
Sm 109:22Sm 102:4
Sm 109:25Sm 31:11
Sm 109:25Sm 22:7; Mt 27:39
Sm 109:29Sm 35:26
Sm 109:30Sm 22:22
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
  • 20
  • 21
  • 22
  • 23
  • 24
  • 25
  • 26
  • 27
  • 28
  • 29
  • 30
  • 31
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Sáàmù 109:1-31

Sáàmù

Sí olùdarí. Ti Dáfídì. Orin.

109 Ìwọ Ọlọ́run tí mò ń yìn,+ má ṣe dákẹ́.

 2 Nítorí àwọn ẹni burúkú àti àwọn ẹlẹ́tàn ń la ẹnu wọn sí mi.

Wọ́n ń fi ahọ́n èké sọ̀rọ̀ nípa mi;+

 3 Wọ́n yí mi ká, wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ ìkórìíra sí mi,

Wọ́n ń bá mi jà láìnídìí.+

 4 Mo nífẹ̀ẹ́ wọn, àmọ́ ńṣe ni wọ́n ń ta kò mí;+

Síbẹ̀ mi ò dákẹ́ àdúrà.

 5 Wọ́n ń fi ibi san ire fún mi,+

Wọ́n sì ń fi ìkórìíra san ìfẹ́ tí mo ní sí wọn.+

 6 Yan ẹni burúkú lé e lórí;

Kí alátakò* dúró sí ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀.

 7 Nígbà tí wọ́n bá ṣèdájọ́ rẹ̀, kí ó jẹ̀bi;*

Kí á ka àdúrà rẹ̀ pàápàá sí ẹ̀ṣẹ̀.+

 8 Kí ẹ̀mí rẹ̀ má ṣe gùn;+

Kí ẹlòmíì gba iṣẹ́ àbójútó rẹ̀.+

 9 Kí àwọn ọmọ* rẹ̀ di aláìníbaba,

Kí ìyàwó rẹ̀ sì di opó.

10 Kí àwọn ọmọ* rẹ̀ máa tọrọ nǹkan kiri,

Kí wọ́n sì máa jáde látinú ilé wọn tó ti di ahoro lọ wá oúnjẹ.

11 Kí ẹni tó jẹ ní gbèsè gbẹ́sẹ̀ lé* gbogbo ohun tó ní,

Kí àwọn àjèjì sì kó ohun ìní rẹ̀.

12 Kí ẹnikẹ́ni má ṣe nawọ́ oore* sí i,

Kí ẹnikẹ́ni má sì ṣojú rere sí àwọn ọmọ rẹ̀ tí kò ní bàbá.

13 Kí àtọmọdọ́mọ* rẹ̀ pa rẹ́;+

Kí orúkọ wọn pa rẹ́ kí ìran tó ń bọ̀ tó dé.

14 Kí Jèhófà rántí àṣìṣe àwọn baba ńlá rẹ̀,+

Kí ẹ̀ṣẹ̀ ìyá rẹ̀ má sì pa rẹ́.

15 Kí Jèhófà máa rántí gbogbo ohun tí wọ́n ṣe;

Kí ó sì pa ìrántí wọn rẹ́ kúrò ní ayé.+

16 Nítorí kò rántí ṣe oore,*+

Àmọ́, ó ń lé ẹni tí ìyà ń jẹ+ àti aláìní pẹ̀lú ẹni tó ní ọgbẹ́ ọkàn

Láti pa wọ́n.+

17 Ó fẹ́ràn kó máa gégùn-ún, ohun tó sì dà lé e lórí nìyẹn;

Kì í fẹ́ súre, torí náà, kò rí ìbùkún kankan gbà.

18 Ó gbé ègún wọ̀ bí aṣọ.

Ó dà sínú ara rẹ̀ bí omi,

Ó sì wọnú egungun rẹ̀ bí òróró.

19 Kí ègún wé mọ́ ọn bí aṣọ tó ń wọ̀+

Àti bí àmùrè tó ń dè nígbà gbogbo.

20 Ohun tí Jèhófà máa san fún ẹni tó ń ta kò mí nìyí+

Àti fún àwọn tó ń sọ̀rọ̀ burúkú sí mi.*

21 Àmọ́ ìwọ, Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ,

Gbèjà mi nítorí orúkọ rẹ.+

Gbà mí sílẹ̀, nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ dára.+

22 Mi ò lè ṣe nǹkan kan, mo jẹ́ aláìní,+

Ọkàn mi sì ti gbọgbẹ́.+

23 Mò ń kọjá lọ bí òjìji tó ń pa rẹ́ lọ;

Wọ́n ti gbọ̀n mí dà nù bí eéṣú.

24 Àwọn eékún mi ti yẹ̀ nítorí ààwẹ̀ gbígbà;

Mo ti rù, mo sì ń kú lọ.*

25 Mo ti di ohun tí wọ́n fi ń ṣe yẹ̀yẹ́.+

Tí wọ́n bá rí mi, ṣe ni wọ́n ń mi orí.+

26 Ràn mí lọ́wọ́, Jèhófà Ọlọ́run mi;

Fi ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ gbà mí.

27 Kí wọ́n mọ̀ pé ọwọ́ rẹ ló ṣe èyí;

Pé ìwọ, Jèhófà, ló ṣe é.

28 Kí wọ́n gégùn-ún, àmọ́ ṣe ni kí o súre fún mi.

Tí wọ́n bá dìde sí mi, jẹ́ kí ojú tì wọ́n,

Àmọ́ kí ìránṣẹ́ rẹ máa yọ̀.

29 Kí ẹ̀tẹ́ bo àwọn tó ń ta kò mí;

Kí wọ́n gbé ìtìjú wọ̀ bí aṣọ.*+

30 Ẹnu mi á máa yin Jèhófà gidigidi;

Màá máa yìn ín níwájú ọ̀pọ̀ èèyàn.+

31 Nítorí á dúró ní ọwọ́ ọ̀tún aláìní

Láti gbà á lọ́wọ́ àwọn tó ń dá a* lẹ́bi.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́