ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Nehemáyà 7
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Nehemáyà

      • Àwọn ẹnubodè ìlú àti àwọn aṣọ́bodè (1-4)

      • Orúkọ àwọn tó dé láti ìgbèkùn (5-69)

        • Àwọn ìránṣẹ́ tẹ́ńpìlì (46-56)

        • Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Sólómọ́nì (57-60)

      • Ọrẹ tí wọ́n ṣe fún iṣẹ́ náà (70-73)

Nehemáyà 7:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ne 2:17; 6:15; Da 9:25
  • +Ne 3:1, 6, 13
  • +1Kr 26:1; Ẹsr 2:1, 42
  • +1Kr 9:33; Ẹsr 2:1, 41
  • +Ẹsr 3:8

Nehemáyà 7:2

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ne 1:2
  • +Ne 2:8
  • +Ne 5:15

Nehemáyà 7:4

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ne 11:1

Nehemáyà 7:5

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Kr 9:1; Ẹsr 2:59, 62

Nehemáyà 7:6

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “agbègbè abẹ́ àṣẹ.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 25:1; Da 3:1
  • +2Ọb 24:12, 14; 2Kr 36:17, 20; Jer 39:9; 52:15, 28
  • +Ẹsr 2:1

Nehemáyà 7:7

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹsr 1:8, 11; Sek 4:9; Mt 1:12
  • +Ẹsr 3:8; 5:2; Hag 1:14; Sek 3:1
  • +Ẹsr 2:2-35

Nehemáyà 7:10

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ne 6:17, 18

Nehemáyà 7:11

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹsr 10:30, 44
  • +Ẹsr 8:1, 9

Nehemáyà 7:12

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹsr 10:26, 44

Nehemáyà 7:25

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 11:19; 2Sa 21:2; Ne 3:7

Nehemáyà 7:26

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    “Ete aiyeraiye,” ojú ìwé 131-132

Nehemáyà 7:27

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 21:8, 18; Jer 1:1

Nehemáyà 7:29

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 7:2
  • +Joṣ 18:25, 28

Nehemáyà 7:30

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 18:21, 24

Nehemáyà 7:31

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 13:5

Nehemáyà 7:32

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 12:32
  • +Joṣ 7:2

Nehemáyà 7:37

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ne 6:2; 11:31, 35

Nehemáyà 7:39

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹsr 2:36-39

Nehemáyà 7:41

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹsr 10:22, 44

Nehemáyà 7:42

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Kr 24:3, 8

Nehemáyà 7:43

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹsr 2:40
  • +Ẹsr 3:9

Nehemáyà 7:44

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Kr 25:7; Ẹsr 2:41
  • +1Kr 6:31, 39

Nehemáyà 7:45

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹsr 2:42; Ne 7:1
  • +1Kr 9:2, 17; Ne 11:19; 12:25

Nehemáyà 7:46

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “Nétínímù.” Ní Héb., “Àwọn tí a fi fúnni.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 9:3, 27; 1Kr 9:2; Ẹsr 2:43-54, 58

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé-Ìṣọ́nà,

    4/15/1992, ojú ìwé 13-17

Nehemáyà 7:57

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹsr 2:55-58; Ne 11:3

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé-Ìṣọ́nà,

    4/15/1992, ojú ìwé 13-17

Nehemáyà 7:60

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “Nétínímù.” Ní Héb., “àwọn tí a fi fúnni.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 9:3, 27; Ne 3:26

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé-Ìṣọ́nà,

    4/15/1992, ojú ìwé 13-17

Nehemáyà 7:61

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹsr 2:59-63

Nehemáyà 7:63

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Kr 24:3, 10; Ne 3:21
  • +2Sa 17:27-29; 19:31; 1Ọb 2:7

Nehemáyà 7:64

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “wọ́n yọ wọ́n ní ipò àlùfáà torí wọ́n kà wọ́n sí aláìmọ́.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 18:7

Nehemáyà 7:65

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “Tíṣátà,” orúkọ oyè tí àwọn ará Páṣíà fún gómìnà ìpínlẹ̀.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ne 8:9; 10:1
  • +Le 2:3; Nọ 18:8, 9
  • +Ẹk 28:30; 1Sa 28:6

Nehemáyà 7:66

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹsr 2:64-67

Nehemáyà 7:67

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 25:44
  • +Ẹk 15:21; 1Sa 18:6

Nehemáyà 7:70

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “Tíṣátà,” orúkọ oyè tí àwọn ará Páṣíà fún gómìnà ìpínlẹ̀.

  • *

    Wọ́n gbà pé ó jẹ́ iye kan náà pẹ̀lú owó dáríkì wúrà ilẹ̀ Páṣíà tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ gíráàmù 8.4. Kì í ṣe dírákímà inú Ìwé Mímọ́ Lédè Gíríìkì. Wo Àfikún B14.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹsr 2:68, 69
  • +Le 6:10

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Bíbélì Ìtumọ̀ Ayé Tuntun, ojú ìwé 1697

Nehemáyà 7:71

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Mínà kan nínú Ìwé Mímọ́ Lédè Hébérù jẹ́ gíráàmù 570. Wo Àfikún B14.

Nehemáyà 7:73

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “Nétínímù.” Ní Héb., “àwọn tí a fi fúnni.”

  • *

    Ní Héb., “gbogbo Ísírẹ́lì.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ne 7:1
  • +Ne 11:20
  • +Le 23:24, 27; 1Ọb 8:2; Ẹsr 3:1
  • +Ẹsr 2:70

Àwọn míì

Neh. 7:1Ne 2:17; 6:15; Da 9:25
Neh. 7:1Ne 3:1, 6, 13
Neh. 7:11Kr 26:1; Ẹsr 2:1, 42
Neh. 7:11Kr 9:33; Ẹsr 2:1, 41
Neh. 7:1Ẹsr 3:8
Neh. 7:2Ne 1:2
Neh. 7:2Ne 2:8
Neh. 7:2Ne 5:15
Neh. 7:4Ne 11:1
Neh. 7:51Kr 9:1; Ẹsr 2:59, 62
Neh. 7:62Ọb 25:1; Da 3:1
Neh. 7:62Ọb 24:12, 14; 2Kr 36:17, 20; Jer 39:9; 52:15, 28
Neh. 7:6Ẹsr 2:1
Neh. 7:7Ẹsr 1:8, 11; Sek 4:9; Mt 1:12
Neh. 7:7Ẹsr 3:8; 5:2; Hag 1:14; Sek 3:1
Neh. 7:7Ẹsr 2:2-35
Neh. 7:10Ne 6:17, 18
Neh. 7:11Ẹsr 10:30, 44
Neh. 7:11Ẹsr 8:1, 9
Neh. 7:12Ẹsr 10:26, 44
Neh. 7:25Joṣ 11:19; 2Sa 21:2; Ne 3:7
Neh. 7:27Joṣ 21:8, 18; Jer 1:1
Neh. 7:291Sa 7:2
Neh. 7:29Joṣ 18:25, 28
Neh. 7:30Joṣ 18:21, 24
Neh. 7:311Sa 13:5
Neh. 7:321Ọb 12:32
Neh. 7:32Joṣ 7:2
Neh. 7:37Ne 6:2; 11:31, 35
Neh. 7:39Ẹsr 2:36-39
Neh. 7:41Ẹsr 10:22, 44
Neh. 7:421Kr 24:3, 8
Neh. 7:43Ẹsr 2:40
Neh. 7:43Ẹsr 3:9
Neh. 7:441Kr 25:7; Ẹsr 2:41
Neh. 7:441Kr 6:31, 39
Neh. 7:45Ẹsr 2:42; Ne 7:1
Neh. 7:451Kr 9:2, 17; Ne 11:19; 12:25
Neh. 7:46Joṣ 9:3, 27; 1Kr 9:2; Ẹsr 2:43-54, 58
Neh. 7:57Ẹsr 2:55-58; Ne 11:3
Neh. 7:60Joṣ 9:3, 27; Ne 3:26
Neh. 7:61Ẹsr 2:59-63
Neh. 7:631Kr 24:3, 10; Ne 3:21
Neh. 7:632Sa 17:27-29; 19:31; 1Ọb 2:7
Neh. 7:64Nọ 18:7
Neh. 7:65Ne 8:9; 10:1
Neh. 7:65Le 2:3; Nọ 18:8, 9
Neh. 7:65Ẹk 28:30; 1Sa 28:6
Neh. 7:66Ẹsr 2:64-67
Neh. 7:67Le 25:44
Neh. 7:67Ẹk 15:21; 1Sa 18:6
Neh. 7:70Ẹsr 2:68, 69
Neh. 7:70Le 6:10
Neh. 7:73Ne 7:1
Neh. 7:73Ne 11:20
Neh. 7:73Le 23:24, 27; 1Ọb 8:2; Ẹsr 3:1
Neh. 7:73Ẹsr 2:70
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
  • 20
  • 21
  • 22
  • 23
  • 24
  • 25
  • 26
  • 27
  • 28
  • 29
  • 30
  • 31
  • 32
  • 33
  • 34
  • 35
  • 36
  • 37
  • 38
  • 39
  • 40
  • 41
  • 42
  • 43
  • 44
  • 45
  • 46
  • 47
  • 48
  • 49
  • 50
  • 51
  • 52
  • 53
  • 54
  • 55
  • 56
  • 57
  • 58
  • 59
  • 60
  • 61
  • 62
  • 63
  • 64
  • 65
  • 66
  • 67
  • 68
  • 69
  • 70
  • 71
  • 72
  • 73
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Nehemáyà 7:1-73

Nehemáyà

7 Nígbà tí a tún ògiri náà mọ tán,+ mo gbé àwọn ilẹ̀kùn sí i;+ lẹ́yìn náà, a yan àwọn aṣọ́bodè,+ àwọn akọrin+ àti àwọn ọmọ Léfì.+ 2 Mo wá ní kí Hánáánì+ arákùnrin mi máa bójú tó Jerúsálẹ́mù pẹ̀lú Hananáyà olórí Ibi Ààbò,+ torí òun ló ṣe é fọkàn tán jù lọ, ó sì bẹ̀rù Ọlọ́run tòótọ́+ ju ọ̀pọ̀ àwọn míì lọ. 3 Torí náà, mo sọ fún wọn pé: “Àwọn aṣọ́bodè kò gbọ́dọ̀ ṣí àwọn ẹnubodè Jerúsálẹ́mù títí ọ̀sán á fi pọ́n. Kí wọ́n tó kúrò lẹ́nu iṣẹ́, kí wọ́n ti àwọn ilẹ̀kùn, kí wọ́n sì fi ìkọ́ há wọn. Kí wọ́n yan àwọn ẹ̀ṣọ́ lára àwọn tó ń gbé Jerúsálẹ́mù, kálukú sí ibi ìṣọ́ tí wọ́n yàn án sí, kí kálukú sì wà níwájú ilé rẹ̀.” 4 Ìlú náà tóbi, ó sì fẹ̀, àmọ́ àwọn tó wà nínú rẹ̀ kò pọ̀,+ wọn ò sì tíì tún àwọn ilé tó wà nínú rẹ̀ kọ́.

5 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run mi fi sí mi lọ́kàn pé kí n kó àwọn èèyàn pàtàkì àti àwọn alábòójútó pẹ̀lú àwọn èèyàn náà jọ láti kọ orúkọ wọn sílẹ̀ bí wọ́n ṣe wà nínú ìdílé wọn.+ Nígbà náà, mo rí ìwé àkọsílẹ̀ ìdílé àwọn tó kọ́kọ́ jáde wá, mo sì rí i pé a kọ ọ́ sínú rẹ̀ pé:

6 Àwọn yìí ni àwọn èèyàn ìpínlẹ̀* tí wọ́n pa dà lára àwọn tó wà nígbèkùn, àwọn tí Nebukadinésárì+ ọba Bábílónì kó lọ sí ìgbèkùn,+ àmọ́ tí wọ́n pa dà sí Jerúsálẹ́mù àti Júdà nígbà tó yá, kálukú pa dà sí ìlú rẹ̀,+ 7 àwọn tí wọ́n tẹ̀ lé ni Serubábélì,+ Jéṣúà,+ Nehemáyà, Asaráyà, Raamáyà, Náhámánì, Módékáì, Bílíṣánì, Mísípérétì, Bígífáì, Néhúmù àti Báánà.

Iye àwọn ọkùnrin tí wọ́n jẹ́ ọmọ Ísírẹ́lì nìyí:+ 8 àwọn ọmọ Páróṣì jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì ó lé méjìléláàádọ́sàn-án (2,172); 9 àwọn ọmọ Ṣẹfatáyà jẹ́ ọgọ́rùn-ún mẹ́ta ó lé méjìléláàádọ́rin (372); 10 àwọn ọmọ Áráhì+ jẹ́ ọgọ́rùn-ún mẹ́fà ó lé méjìléláàádọ́ta (652); 11 àwọn ọmọ Pahati-móábù,+ látinú àwọn ọmọ Jéṣúà àti Jóábù+ jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì ó lé ọgọ́rùn-ún mẹ́jọ àti méjìdínlógún (2,818); 12 àwọn ọmọ Élámù+ jẹ́ ẹgbẹ̀rún kan ó lé igba àti mẹ́rìnléláàádọ́ta (1,254); 13 àwọn ọmọ Sátù jẹ́ ọgọ́rùn-ún mẹ́jọ ó lé márùnlélógójì (845); 14 àwọn ọmọ Sákáì jẹ́ ọgọ́rùn-ún méje ó lé ọgọ́ta (760); 15 àwọn ọmọ Bínúì jẹ́ ọgọ́rùn-ún mẹ́fà ó lé méjìdínláàádọ́ta (648); 16 àwọn ọmọ Bébáì jẹ́ ọgọ́rùn-ún mẹ́fà ó lé méjìdínlọ́gbọ̀n (628); 17 àwọn ọmọ Ásígádì jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì ó lé ọgọ́rùn-ún mẹ́ta àti méjìlélógún (2,322); 18 àwọn ọmọ Ádóníkámù jẹ́ ọgọ́rùn-ún mẹ́fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́rin (667); 19 àwọn ọmọ Bígífáì jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì ó lé mẹ́tàdínláàádọ́rin (2,067); 20 àwọn ọmọ Ádínì jẹ́ ọgọ́rùn-ún mẹ́fà ó lé márùndínlọ́gọ́ta (655); 21 àwọn ọmọ Átérì láti ilé Hẹsikáyà jẹ́ méjìdínlọ́gọ́rùn-ún (98); 22 àwọn ọmọ Háṣúmù jẹ́ ọgọ́rùn-ún mẹ́ta ó lé méjìdínlọ́gbọ̀n (328); 23 àwọn ọmọ Bísáì jẹ́ ọgọ́rùn-ún mẹ́ta ó lé mẹ́rìnlélógún (324); 24 àwọn ọmọ Hárífù jẹ́ méjìléláàádọ́fà (112); 25 àwọn ọmọ Gíbíónì+ jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn-ún (95); 26 àwọn ọkùnrin Bẹ́tílẹ́hẹ́mù àti Nétófà jẹ́ ọgọ́sàn-án ó lé mẹ́jọ (188); 27 àwọn ọkùnrin Ánátótì+ jẹ́ méjìdínláàádóje (128); 28 àwọn ọkùnrin Bẹti-ásímáfẹ́tì jẹ́ méjìlélógójì (42); 29 àwọn ọkùnrin Kiriati-jéárímù,+ Kéfírà àti Béérótì+ jẹ́ ọgọ́rùn-ún méje ó lé mẹ́tàlélógójì (743); 30 àwọn ọkùnrin Rámà àti Gébà+ jẹ́ ọgọ́rùn-ún mẹ́fà ó lé mọ́kànlélógún (621); 31 àwọn ọkùnrin Míkímásì+ jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà (122); 32 àwọn ọkùnrin Bẹ́tẹ́lì+ àti Áì+ jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà (123); 33 àwọn ọkùnrin Nébò kejì jẹ́ méjìléláàádọ́ta (52); 34 àwọn ọmọ Élámù kejì jẹ́ ẹgbẹ̀rún kan ó lé igba àti mẹ́rìnléláàádọ́ta (1,254); 35 àwọn ọmọ Hárímù jẹ́ ọgọ́rùn-ún mẹ́ta ó lé ogún (320); 36 àwọn ọmọ Jẹ́ríkò jẹ́ ọgọ́rùn-ún mẹ́ta ó lé márùnlélógójì (345); 37 àwọn ọmọ Lódì, Hádídì àti Ónò+ jẹ́ ọgọ́rùn-ún méje ó lé mọ́kànlélógún (721); 38 àwọn ọmọ Sénáà jẹ́ ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ó lé ọgọ́rùn-ún mẹ́sàn-án àti ọgbọ̀n (3,930).

39 Àwọn àlùfáà nìyí:+ àwọn ọmọ Jedáyà láti ilé Jéṣúà jẹ́ ọgọ́rùn-ún mẹ́sàn-án ó lé mẹ́tàléláàádọ́rin (973); 40 àwọn ọmọ Ímérì jẹ́ ẹgbẹ̀rún kan ó lé méjìléláàádọ́ta (1,052); 41 àwọn ọmọ Páṣúrì+ jẹ́ ẹgbẹ̀rún kan ó lé igba àti mẹ́tàdínláàádọ́ta (1,247); 42 àwọn ọmọ Hárímù+ jẹ́ ẹgbẹ̀rún kan ó lé mẹ́tàdínlógún (1,017).

43 Àwọn ọmọ Léfì nìyí:+ àwọn ọmọ Jéṣúà, ti Kádímíélì,+ ti àwọn ọmọ Hódéfà jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin (74); 44 Àwọn akọrin nìyí:+ àwọn ọmọ Ásáfù,+ wọ́n jẹ́ méjìdínláàádọ́jọ (148). 45 Àwọn aṣọ́bodè nìyí:+ àwọn ọmọ Ṣálúmù, àwọn ọmọ Átérì, àwọn ọmọ Tálímónì, àwọn ọmọ Ákúbù,+ àwọn ọmọ Hátítà, àwọn ọmọ Ṣóbáì, gbogbo wọn jẹ́ méjìdínlógóje (138).

46 Àwọn ìránṣẹ́ tẹ́ńpìlì* nìyí:+ àwọn ọmọ Síhà, àwọn ọmọ Hásúfà, àwọn ọmọ Tábáótì, 47 àwọn ọmọ Kérósì, àwọn ọmọ Síà, àwọn ọmọ Pádónì, 48 àwọn ọmọ Lébánà, àwọn ọmọ Hágábà, àwọn ọmọ Sálímáì, 49 àwọn ọmọ Hánánì, àwọn ọmọ Gídélì, àwọn ọmọ Gáhárì, 50 àwọn ọmọ Reáyà, àwọn ọmọ Résínì, àwọn ọmọ Nékódà, 51 àwọn ọmọ Gásámù, àwọn ọmọ Úúsà, àwọn ọmọ Páséà, 52 àwọn ọmọ Bésáì, àwọn ọmọ Méúnímù, àwọn ọmọ Néfúṣésímù, 53 àwọn ọmọ Bákíbúkì, àwọn ọmọ Hákúfà, àwọn ọmọ Háhúrì, 54 àwọn ọmọ Básílítì, àwọn ọmọ Méhídà, àwọn ọmọ Háṣà, 55 àwọn ọmọ Bákósì, àwọn ọmọ Sísérà, àwọn ọmọ Téémà, 56 àwọn ọmọ Nesáyà àti àwọn ọmọ Hátífà.

57 Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Sólómọ́nì nìyí:+ àwọn ọmọ Sótáì, àwọn ọmọ Sóférétì, àwọn ọmọ Pérídà, 58 àwọn ọmọ Jáálà, àwọn ọmọ Dákónì, àwọn ọmọ Gídélì, 59 àwọn ọmọ Ṣẹfatáyà, àwọn ọmọ Hátílì, àwọn ọmọ Pokereti-hásébáímù, àwọn ọmọ Ámọ́nì. 60 Gbogbo àwọn ìránṣẹ́ tẹ́ńpìlì*+ àti ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Sólómọ́nì jẹ́ ọgọ́rùn-ún mẹ́ta ó lé àádọ́rùn-ún àti méjì (392).

61 Àwọn tó lọ láti Tẹli-mélà, Tẹli-háṣà, Kérúbù, Ádónì àti Ímérì, àmọ́ tí wọn kò lè sọ agbo ilé bàbá wọn àti ibi tí wọ́n ti ṣẹ̀ wá láti fi hàn pé ọmọ Ísírẹ́lì ni wọ́n nìyí:+ 62 àwọn ọmọ Deláyà, àwọn ọmọ Tòbáyà àti àwọn ọmọ Nékódà, wọ́n jẹ́ ọgọ́rùn-ún mẹ́fà ó lé méjìlélógójì (642). 63 Látinú àwọn àlùfáà: àwọn ọmọ Habáyà, àwọn ọmọ Hákósì,+ àwọn ọmọ Básíláì tó fẹ́ ọ̀kan lára àwọn ọmọbìnrin Básíláì+ ọmọ Gílíádì, tó sì wá ń jẹ́ orúkọ wọn. 64 Wọ́n wá àkọsílẹ̀ wọn láti mọ ìdílé tí wọ́n ti wá, àmọ́ wọn kò rí i, torí náà, wọn ò gbà kí wọ́n ṣiṣẹ́ àlùfáà.*+ 65 Gómìnà*+ sọ fún wọn pé wọn ò gbọ́dọ̀ jẹ lára àwọn ohun mímọ́ jù lọ,+ títí wọ́n á fi rí àlùfáà tó máa bá wọn fi Úrímù àti Túmímù+ wádìí.

66 Iye gbogbo ìjọ náà jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjìlélógójì ó lé ọgọ́rùn-ún mẹ́ta àti ọgọ́ta (42,360),+ 67 yàtọ̀ sí àwọn ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin wọn,+ tí iye wọn jẹ́ ẹgbẹ̀rún méje ó lé ọgọ́rùn-ún mẹ́ta àti mẹ́tàdínlógójì (7,337); wọ́n tún ní àwọn akọrin lọ́kùnrin àti lóbìnrin+ tí wọ́n jẹ́ igba ó lé márùnlélógójì (245). 68 Ẹṣin wọn jẹ́ ọgọ́rùn-ún méje ó lé mẹ́rìndínlógójì (736), ìbaaka wọn jẹ́ igba ó lé márùnlélógójì (245), 69 ràkúnmí wọn jẹ́ ọgọ́rùn-ún mẹ́rin ó lé márùndínlógójì (435), kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn jẹ́ ẹgbẹ̀rún mẹ́fà ó lé ọgọ́rùn-ún méje àti ogún (6,720).

70 Lára àwọn olórí agbo ilé mú ọrẹ wá fún iṣẹ́ náà.+ Gómìnà* mú ẹgbẹ̀rún kan (1,000) owó dírákímà* wúrà, àádọ́ta (50) abọ́ àti ọgọ́rùn-ún márùn-ún ó lé ọgbọ̀n (530) aṣọ àwọn àlùfáà+ wá sí ibi ìṣúra. 71 Lára àwọn olórí agbo ilé mú ọ̀kẹ́ kan (20,000) owó dírákímà wúrà àti ẹgbẹ̀rún méjì ó lé igba (2,200) mínà* fàdákà wá sí ibi ìṣúra iṣẹ́ ilé náà. 72 Àwọn èèyàn yòókù sì mú ọ̀kẹ́ kan (20,000) owó dírákímà wúrà àti ẹgbẹ̀rún méjì (2,000) mínà fàdákà àti àádọ́rin dín mẹ́ta (67) aṣọ àwọn àlùfáà wá.

73 Àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Léfì, àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin,+ àwọn kan lára àwọn èèyàn náà àti àwọn ìránṣẹ́ tẹ́ńpìlì* pẹ̀lú gbogbo ọmọ Ísírẹ́lì yòókù* bẹ̀rẹ̀ sí í gbé inú àwọn ìlú wọn.+ Nígbà tó fi máa di oṣù keje,+ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ti wà nínú àwọn ìlú wọn.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́