Nọ́ńbà
33 Bí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ṣe rìnrìn àjò wọn ní àwùjọ-àwùjọ*+ nìyí láti ibì kan sí ibòmíì nígbà tí wọ́n kúrò ní ilẹ̀ Íjíbítì,+ tí Mósè àti Áárónì+ sì ń darí wọn. 2 Bí wọ́n ṣe ń lọ láti ibì kan sí ibòmíì lẹ́nu ìrìn àjò wọn ni Mósè ń kọ àwọn ibi tí wọ́n ti ń gbéra sílẹ̀, bí Jèhófà ṣe pa á láṣẹ. Bí wọ́n ṣe gbéra láti ibì kan sí ibòmíì+ nìyí: 3 Wọ́n kúrò ní Rámésésì+ ní ọjọ́ kẹẹ̀ẹ́dógún oṣù+ kìíní. Ọjọ́ tó tẹ̀ lé Ìrékọjá+ gangan ni àwọn ọmọ Ísírẹ́lì fi ìgboyà* jáde níṣojú gbogbo àwọn ará Íjíbítì. 4 Ìgbà yẹn ni àwọn ará Íjíbítì ń sin àwọn àkọ́bí wọn+ tí Jèhófà pa torí Jèhófà ti dá àwọn ọlọ́run+ wọn lẹ́jọ́.
5 Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì kúrò ní Rámésésì, wọ́n sì pàgọ́ sí Súkótù.+ 6 Lẹ́yìn náà, wọ́n kúrò ní Súkótù, wọ́n sì pàgọ́ sí Étámù+ tó wà létí aginjù. 7 Wọ́n tún kúrò ní Étámù, wọ́n sì ṣẹ́rí pa dà gba Píháhírótì, níbi tí wọ́n á ti máa wo Baali-séfónì+ lọ́ọ̀ọ́kán, wọ́n sì pàgọ́ síwájú Mígídólì.+ 8 Lẹ́yìn náà, wọ́n kúrò ní Píháhírótì, wọ́n sì gba àárín òkun+ kọjá lọ sí aginjù, wọ́n wá rin ìrìn ọjọ́ mẹ́ta ní aginjù+ Étámù,+ wọ́n sì pàgọ́ sí Márà.+
9 Lẹ́yìn náà, wọ́n kúrò ní Márà, wọ́n sì lọ sí Élímù. Ìsun omi méjìlá (12) àti àádọ́rin (70) igi ọ̀pẹ wà ní Élímù, wọ́n sì pàgọ́ síbẹ̀.+ 10 Wọ́n wá kúrò ní Élímù, wọ́n sì pàgọ́ sẹ́gbẹ̀ẹ́ Òkun Pupa. 11 Lẹ́yìn náà, wọ́n kúrò ní Òkun Pupa, wọ́n sì pàgọ́ sí aginjù Sínì.+ 12 Wọ́n kúrò ní aginjù Sínì, wọ́n sì pàgọ́ sí Dófíkà. 13 Lẹ́yìn náà, wọ́n kúrò ní Dófíkà, wọ́n sì pàgọ́ sí Álúṣì. 14 Wọ́n wá kúrò ní Álúṣì, wọ́n sì pàgọ́ sí Réfídímù,+ níbi tí àwọn èèyàn náà ò ti rí omi mu. 15 Lẹ́yìn tí wọ́n kúrò ní Réfídímù, wọ́n pàgọ́ sí aginjù Sínáì.+
16 Wọ́n kúrò ní aginjù Sínáì, wọ́n sì pàgọ́ sí Kiburoti-hátááfà.+ 17 Wọ́n wá kúrò ní Kiburoti-hátááfà, wọ́n sì pàgọ́ sí Hásérótì.+ 18 Lẹ́yìn náà, wọ́n kúrò ní Hásérótì, wọ́n sì pàgọ́ sí Rítímà. 19 Lẹ́yìn náà, wọ́n kúrò ní Rítímà, wọ́n sì pàgọ́ sí Rimoni-pérésì. 20 Wọ́n wá kúrò ní Rimoni-pérésì, wọ́n sì pàgọ́ sí Líbínà. 21 Wọ́n kúrò ní Líbínà, wọ́n sì pàgọ́ sí Rísà. 22 Lẹ́yìn tí wọ́n kúrò ní Rísà, wọ́n pàgọ́ sí Kéhélátà. 23 Wọ́n wá kúrò ní Kéhélátà, wọ́n sì pàgọ́ sí Òkè Ṣéférì.
24 Lẹ́yìn náà, wọ́n kúrò ní Òkè Ṣéférì, wọ́n sì pàgọ́ sí Hárádà. 25 Wọ́n wá kúrò ní Hárádà, wọ́n sì pàgọ́ sí Mákélótì. 26 Lẹ́yìn tí wọ́n kúrò+ ní Mákélótì, wọ́n pàgọ́ sí Táhátì. 27 Wọ́n wá kúrò ní Táhátì, wọ́n sì pàgọ́ sí Térà. 28 Lẹ́yìn náà, wọ́n kúrò ní Térà, wọ́n sì pàgọ́ sí Mítíkà. 29 Wọ́n wá kúrò ní Mítíkà, wọ́n sì pàgọ́ sí Háṣímónà. 30 Lẹ́yìn tí wọ́n kúrò ní Háṣímónà, wọ́n pàgọ́ sí Mósérótì. 31 Wọ́n wá kúrò ní Mósérótì, wọ́n sì pàgọ́ sí Bẹne-jáákánì.+ 32 Lẹ́yìn náà, wọ́n kúrò ní Bẹne-jáákánì, wọ́n sì pàgọ́ sí Hoori-hágígádì. 33 Wọ́n wá kúrò ní Hoori-hágígádì, wọ́n sì pàgọ́ sí Jótíbátà.+ 34 Lẹ́yìn tí wọ́n kúrò ní Jótíbátà, wọ́n pàgọ́ sí Ábúrónà. 35 Wọ́n wá kúrò ní Ábúrónà, wọ́n sì pàgọ́ sí Esioni-gébérì.+ 36 Lẹ́yìn tí wọ́n kúrò ní Esioni-gébérì, wọ́n pàgọ́ sí aginjù Síínì,+ ìyẹn Kádéṣì.
37 Wọ́n wá kúrò ní Kádéṣì, wọ́n sì pàgọ́ sí Òkè Hóórì,+ ní ààlà ilẹ̀ Édómù. 38 Àlùfáà Áárónì wá gun Òkè Hóórì lọ bí Jèhófà ṣe pa á láṣẹ, ó sì kú síbẹ̀ ní ọjọ́ kìíní, oṣù+ karùn-ún, ọdún ogójì tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì kúrò ní ilẹ̀ Íjíbítì. 39 Ẹni ọdún mẹ́tàlélọ́gọ́fà (123) ni Áárónì nígbà tó kú lórí Òkè Hóórì.
40 Ó ṣẹlẹ̀ pé ọba Árádì,+ ọmọ Kénáánì tó ń gbé ní Négébù, ní ilẹ̀ Kénáánì gbọ́ pé àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ti ń bọ̀.
41 Nígbà tó yá, wọ́n kúrò ní Òkè Hóórì,+ wọ́n sì pàgọ́ sí Sálímónà. 42 Lẹ́yìn náà, wọ́n kúrò ní Sálímónà, wọ́n sì pàgọ́ sí Púnónì. 43 Wọ́n wá kúrò ní Púnónì, wọ́n sì pàgọ́ sí Óbótì.+ 44 Lẹ́yìn náà, wọ́n kúrò ní Óbótì, wọ́n sì pàgọ́ sí Iye-ábárímù ní ààlà Móábù.+ 45 Wọ́n wá kúrò ní Íyímù, wọ́n sì pàgọ́ sí Diboni-gádì.+ 46 Lẹ́yìn náà, wọ́n kúrò ní Diboni-gádì, wọ́n sì pàgọ́ sí Alimoni-díbílátáímù. 47 Wọ́n wá kúrò ní Alimoni-díbílátáímù, wọ́n sì pàgọ́ sí àwọn òkè Ábárímù+ níwájú Nébò.+ 48 Níkẹyìn, wọ́n kúrò ní àwọn òkè Ábárímù, wọ́n sì pàgọ́ sí aṣálẹ̀ tó tẹ́jú ní Móábù, lẹ́gbẹ̀ẹ́ Jọ́dánì ní Jẹ́ríkò.+ 49 Wọ́n wá ń pàgọ́ sẹ́gbẹ̀ẹ́ Jọ́dánì láti Bẹti-jẹ́ṣímótì títí lọ dé Ebẹli-ṣítímù,+ ní aṣálẹ̀ tó tẹ́jú ní Móábù.
50 Jèhófà sọ fún Mósè ní aṣálẹ̀ tó tẹ́jú ní Móábù, lẹ́gbẹ̀ẹ́ Jọ́dánì ní Jẹ́ríkò pé: 51 “Sọ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pé, ‘Ẹ máa sọdá Jọ́dánì sí ilẹ̀ Kénáánì.+ 52 Kí ẹ lé gbogbo àwọn tó ń gbé ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín, kí ẹ run gbogbo ère tí wọ́n fi òkúta+ ṣe àti gbogbo ère onírin*+ wọn, kí ẹ sì wó gbogbo ibi gíga+ tí wọ́n ti ń jọ́sìn àwọn òrìṣà. 53 Ẹ ó gba ilẹ̀ náà, ẹ ó sì máa gbé níbẹ̀, torí ó dájú pé màá fún yín ní ilẹ̀ náà kó lè di tiyín.+ 54 Kí ẹ fi kèké+ pín ilẹ̀ náà bí ohun ìní láàárín àwọn ìdílé yín. Kí ẹ fi kún ogún tí ẹ máa pín fún àwùjọ tó bá pọ̀, kí ẹ sì dín ogún+ tí ẹ máa pín fún àwùjọ tó bá kéré kù. Ibi tí kèké kálukú bá bọ́ sí ni ohun ìní rẹ̀ máa wà. Ẹ̀yà àwọn bàbá+ yín la máa fi pín ogún fún yín.
55 “‘Àmọ́ tí ẹ ò bá lé àwọn tó ń gbé ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín,+ àwọn tí ẹ bá fi sílẹ̀ lára wọn máa dà bí ohun ìríra lójú yín, wọ́n á dà bí ẹ̀gún tó ń gún yín lẹ́gbẹ̀ẹ́, wọ́n á sì máa yọ yín lẹ́nu ní ilẹ̀ tí ẹ máa gbé.+ 56 Ohun tí mo sì fẹ́ ṣe sí wọn ni màá ṣe sí yín.’”+