ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Sáàmù 22:16-18
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 16 Nítorí àwọn ajá yí mi ká;+

      Wọ́n ká mi mọ́ bí ìgbà tí àwọn aṣebi bá káni mọ́,+

      Wọ́n wà níbi ọwọ́ àti ẹsẹ̀ mi bíi kìnnìún.+

      17 Mo lè ka gbogbo egungun mi.+

      Wọ́n ń wò mí, wọ́n sì tẹjú mọ́ mi.

      18 Wọ́n pín ẹ̀wù mi láàárín ara wọn,

      Wọ́n sì ṣẹ́ kèké nítorí aṣọ mi.+

  • Àìsáyà 53:1-12
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 53 Ta ló ti nígbàgbọ́ nínú ohun tó gbọ́ lọ́dọ̀ wa?*+

      Ní ti apá Jèhófà,+ ta la ti fi hàn?+

       2 Ó máa jáde wá bí ẹ̀ka igi+ níwájú rẹ̀,* bíi gbòǹgbò látinú ilẹ̀ tó gbẹ táútáú.

      Ìrísí rẹ̀ kò buyì kún un, kò sì rẹwà rárá;+

      Tí a bá sì rí i, ìrísí rẹ̀ kò fà wá sún mọ́ ọn.*

       3 Àwọn èèyàn kórìíra rẹ̀, wọ́n sì yẹra fún un,+

      Ọkùnrin tó mọ bí ìrora ṣe ń rí,* tó sì mọ àìsàn dunjú.

      Ó dà bí ẹni pé ojú rẹ̀ pa mọ́ fún wa.*

      Wọ́n kórìíra rẹ̀, a sì kà á sí ẹni tí kò já mọ́ nǹkan kan.+

       4 Lóòótọ́, òun fúnra rẹ̀ gbé àwọn àìsàn wa,+

      Ó sì ru àwọn ìrora wa.+

      Àmọ́ a kà á sí ẹni tí ìyọnu bá, ẹni tí Ọlọ́run kọ lù, tó sì ń jìyà.

       5 Wọ́n gún un+ torí àṣìṣe wa;+

      Wọ́n tẹ̀ ẹ́ rẹ́ torí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa.+

      Ó jìyà ká lè ní àlàáfíà,+

      A sì rí ìwòsàn nítorí àwọn ọgbẹ́ rẹ̀.+

       6 Gbogbo wa ti rìn gbéregbère bí àgùntàn,+

      Kálukú ti yíjú sí ọ̀nà tirẹ̀,

      Jèhófà sì ti mú kó ru ẹ̀ṣẹ̀ gbogbo wa.+

       7 Wọ́n ni ín lára,+ ó sì jẹ́ kí wọ́n fìyà jẹ òun,+

      Àmọ́ kò la ẹnu rẹ̀.

      Wọ́n mú un wá bí àgùntàn sí ibi tí wọ́n ti fẹ́ pa á,+

      Bí abo àgùntàn tó dákẹ́ níwájú àwọn tó ń rẹ́ irun rẹ̀,

      Kò sì la ẹnu rẹ̀.+

       8 Wọ́n mú un lọ torí àìṣẹ̀tọ́* àti ìdájọ́;

      Ta ló sì máa da ara rẹ̀ láàmú nípa kúlẹ̀kúlẹ̀ ìran rẹ̀?*

      Torí wọ́n mú un kúrò lórí ilẹ̀ alààyè;+

      Ó jẹ ìyà* torí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn èèyàn mi.+

       9 Wọ́n sin ín* pẹ̀lú àwọn ẹni burúkú+

      Àti àwọn ọlọ́rọ̀,* nígbà tó kú,+

      Bó tilẹ̀ jẹ́ pé kò ṣe ohunkóhun tí kò dáa,*

      Kò sì sí ẹ̀tàn kankan lẹ́nu rẹ̀.+

      10 Àmọ́ ó wu Jèhófà* láti tẹ̀ ẹ́ rẹ́, ó sì jẹ́ kó ṣàìsàn.

      Tí o bá máa fi ẹ̀mí* rẹ̀ rú ẹbọ ẹ̀bi,+

      Ó máa rí ọmọ* rẹ̀, ó máa mú kí àwọn ọjọ́ rẹ̀ gùn,+

      Ohun tí inú Jèhófà dùn sí* sì máa yọrí sí rere nípasẹ̀ rẹ̀.+

      11 Torí ìrora* rẹ̀, ó máa rí i, ó sì máa tẹ́ ẹ lọ́rùn.

      Nípasẹ̀ ìmọ̀ rẹ̀, ìránṣẹ́ mi+ tó jẹ́ olódodo

      Máa mú kí a ka ọ̀pọ̀lọpọ̀ èèyàn sí olódodo,+

      Ó sì máa ru àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wọn.+

      12 Torí ìyẹn, màá fún un ní ìpín láàárín ọ̀pọ̀lọpọ̀,

      Ó sì máa pín ẹrù ogun pẹ̀lú àwọn alágbára,

      Torí ó tú ẹ̀mí* rẹ̀ jáde, àní títí dé ikú,+

      Wọ́n sì kà á mọ́ àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀;+

      Ó ru ẹ̀ṣẹ̀ ọ̀pọ̀ èèyàn,+

      Ó sì bá àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ bẹ̀bẹ̀.+

  • Dáníẹ́lì 9:26
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 26 “Lẹ́yìn ọ̀sẹ̀ méjìlélọ́gọ́ta (62) náà, wọ́n máa pa Mèsáyà,*+ láìṣẹ́ ohunkóhun kù fún ara rẹ̀.+

      “Àwọn èèyàn aṣáájú tó ń bọ̀ máa pa ìlú náà àti ibi mímọ́ náà run.+ Àkúnya omi ló sì máa fòpin sí i. Ogun á sì máa jà títí dé òpin; a ti pinnu pé ó máa di ahoro.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́