Diutarónómì
33 Bí Mósè èèyàn Ọlọ́run tòótọ́ ṣe súre fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì kó tó kú nìyí.+ 2 Ó sọ pé:
“Jèhófà wá láti Sínáì,+
Ó sì tàn sórí wọn láti Séírì.
Ògo rẹ̀ tàn láti agbègbè olókè Páránì,+
Ọ̀kẹ́ àìmọye* àwọn ẹni mímọ́+ sì wà pẹ̀lú rẹ̀,
Àwọn jagunjagun+ rẹ̀ wà ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀.
7 Ó sì súre fún Júdà+ pé:
“Ìwọ Jèhófà, gbọ́ ohùn Júdà,+
Kí o sì mú un pa dà sọ́dọ̀ àwọn èèyàn rẹ̀.
8 Ó sọ nípa Léfì pé:+
O bẹ̀rẹ̀ sí í bá a fà á lẹ́gbẹ̀ẹ́ omi Mẹ́ríbà,+
9 Ẹni tó sọ nípa bàbá àti ìyá rẹ̀ pé, ‘Mi ò kà wọ́n sí.’
Ó tiẹ̀ tún kọ àwọn arákùnrin rẹ̀,+
Ó sì pa àwọn ọmọ rẹ̀ tì.
Torí wọ́n tẹ̀ lé ọ̀rọ̀ rẹ,
Wọ́n sì pa májẹ̀mú rẹ mọ́.+
11 Bù kún agbára rẹ̀, Jèhófà,
Kí inú rẹ sì dùn sí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.
Fọ́ ẹsẹ̀* àwọn tó dìde sí i,
Kí àwọn tó kórìíra rẹ̀ má bàa dìde mọ́.”
12 Ó sọ nípa Bẹ́ńjámínì pé:+
“Kí ẹni ọ̀wọ́n Jèhófà máa gbé láìséwu lọ́dọ̀ rẹ̀;
Bó ṣe ń dáàbò bò ó ní gbogbo ọjọ́,
Á máa gbé láàárín èjìká rẹ̀.”
13 Ó sọ nípa Jósẹ́fù pé:+
“Kí Jèhófà bù kún ilẹ̀ rẹ̀+
Pẹ̀lú àwọn ohun tó dáa láti ọ̀run,
Pẹ̀lú ìrì àti omi tó ń sun láti ilẹ̀,+
14 Pẹ̀lú àwọn ohun tó dáa tí oòrùn mú jáde,
Àti ohun tó dáa tó ń mú jáde lóṣooṣù,+
15 Pẹ̀lú àwọn ohun tó dáa jù láti àwọn òkè àtijọ́,*+
Àti àwọn ohun tó dáa láti àwọn òkè tó ti wà tipẹ́,
16 Pẹ̀lú àwọn ohun tó dáa ní ayé àti ohun tó kún inú rẹ̀,+
Kí Ẹni tó ń gbé inú igi ẹlẹ́gùn-ún+ sì tẹ́wọ́ gbà á.
Kí wọ́n wá sí orí Jósẹ́fù,
Sí àtàrí ẹni tí a yà sọ́tọ̀ lára àwọn arákùnrin rẹ̀.+
17 Iyì rẹ̀ dà bíi ti àkọ́bí akọ màlúù,
Ìwo akọ màlúù igbó sì ni àwọn ìwo rẹ̀.
Ó máa fi ti* àwọn èèyàn,
Gbogbo wọn pa pọ̀ títí dé àwọn ìkángun ayé.
Ẹgbẹẹgbàárùn-ún Éfúrémù + ni wọ́n,
Ẹgbẹẹgbẹ̀rún Mánásè sì ni wọ́n.”
18 Ó sọ nípa Sébúlúnì pé:+
“Ìwọ Sébúlúnì, máa yọ̀ bí o ṣe ń jáde lọ,
Àti ìwọ Ísákà, nínú àwọn àgọ́ rẹ.+
19 Wọ́n á pe àwọn èèyàn wá sórí òkè.
Ibẹ̀ ni wọ́n á ti rú àwọn ẹbọ òdodo.
20 Ó sọ nípa Gádì pé:+
“Ìbùkún ni fún ẹni tó ń mú kí àwọn ààlà Gádì+ fẹ̀ sí i.
Ó dùbúlẹ̀ síbẹ̀ bíi kìnnìún,
Tó múra tán láti fa apá ya, àní àtàrí.
Àwọn olórí àwọn èèyàn náà máa kóra jọ.
Ó máa mú òdodo Jèhófà ṣẹ
Àti àwọn ìdájọ́ rẹ̀ pẹ̀lú Ísírẹ́lì.”
22 Ó sọ nípa Dánì pé:+
“Ọmọ kìnnìún ni Dánì.+
Ó máa bẹ́ jáde láti Báṣánì.”+
23 Ó sọ nípa Náfútálì pé:+
“Jèhófà ti tẹ́wọ́ gba Náfútálì
Ó sì ti bù kún un lọ́pọ̀lọpọ̀.
Gba ìwọ̀ oòrùn àti gúúsù.”
24 Ó sọ nípa Áṣérì pé:+
“A fi àwọn ọmọ bù kún Áṣérì.
Kó rí ojúure àwọn arákùnrin rẹ̀,
Kó sì ki ẹsẹ̀ rẹ̀ bọ inú òróró.*
25 Irin àti bàbà ni wọ́n fi ṣe ohun tí wọ́n fi ń ti ẹnubodè rẹ,+
O sì máa wà láìséwu ní gbogbo ọjọ́ rẹ.*
Ó máa lé ọ̀tá kúrò níwájú rẹ,+
Ó sì máa sọ pé, ‘Pa wọ́n run!’+
28 Ísírẹ́lì á máa gbé láìséwu,
Orísun Jékọ́bù sì máa wà lọ́tọ̀,
Ní ilẹ̀ tí ọkà àti wáìnì tuntun+ wà,
Tí ìrì á máa sẹ̀ lójú ọ̀run rẹ̀.+
29 Aláyọ̀ ni ọ́, ìwọ Ísírẹ́lì!+