ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Sáàmù 107
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Sáàmù

      • Ẹ dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run nítorí àwọn iṣẹ́ àgbàyanu rẹ̀

        • Ó darí wọn gba ọ̀nà tí ó tọ́ (7)

        • Ó tẹ́ ẹni tí òùngbẹ ń gbẹ àti ẹni tí ebi ń pa lọ́rùn (9)

        • Ó mú wọn jáde látinú òkùnkùn (14)

        • Ó fi ọ̀rọ̀ rẹ̀ ránṣẹ́ láti mú wọn lára dá (20)

        • Ó ń dáàbò bo aláìní lọ́wọ́ ìnilára (41)

Sáàmù 107:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Lk 18:19
  • +1Kr 16:34; Sm 103:17

Sáàmù 107:2

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “rà.”

  • *

    Tàbí “gbà kúrò ní ìkáwọ́.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ais 35:10; Jer 15:21; Mik 4:10

Sáàmù 107:3

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “Láti yíyọ oòrùn àti láti wíwọ̀ oòrùn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 106:47; Jer 29:14
  • +Ais 43:5, 6; Jer 31:8

Sáàmù 107:5

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ọkàn wọn.”

Sáàmù 107:6

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ho 5:14, 15
  • +Ais 41:17

Sáàmù 107:7

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ais 30:21
  • +Ne 11:3

Sáàmù 107:8

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Kr 16:8
  • +Sm 40:5

Sáàmù 107:9

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ọkàn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 34:10; Ais 55:2; Lk 1:53

Sáàmù 107:11

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 106:43; Ida 3:42

Sáàmù 107:12

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 26:21

Sáàmù 107:14

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 68:6; 146:7; Ais 49:8, 9; 61:1

Sáàmù 107:15

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ida 3:22

Sáàmù 107:16

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ais 45:1, 2

Sáàmù 107:17

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 2:19
  • +Ida 3:39

Sáàmù 107:18

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “Ọkàn wọn kọ gbogbo oúnjẹ.”

Sáàmù 107:20

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 147:3

Sáàmù 107:22

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 7:12; Sm 50:14

Sáàmù 107:23

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 9:21; Isk 27:9

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    10/15/2005, ojú ìwé 32

Sáàmù 107:24

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 1:21; Sm 104:25

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    10/15/2005, ojú ìwé 32

Sáàmù 107:25

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 135:7; Jer 10:13; Jon 1:4

Sáàmù 107:27

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jon 1:4, 13

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    9/1/2006, ojú ìwé 14

Sáàmù 107:28

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jon 1:14

Sáàmù 107:29

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 65:7; 89:9; Jon 1:15

Sáàmù 107:31

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 105:5

Sáàmù 107:32

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “ní ìjókòó.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 111:1

Sáàmù 107:33

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 17:1, 7; Ais 42:15; Emọ 4:7

Sáàmù 107:34

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 13:10; Di 29:22, 23

Sáàmù 107:35

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ìyẹn, koríko etí omi.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 3:17; Ais 35:7; 41:18

Sáàmù 107:36

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 146:7; Lk 1:53
  • +Sm 107:7

Sáàmù 107:37

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ais 65:21
  • +Iṣe 14:17

Sáàmù 107:38

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 7:13, 14

Sáàmù 107:40

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Job 12:21, 24

Sáàmù 107:41

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ó gbé àwọn aláìní ga,” ìyẹn, kí ọwọ́ má bàa tó wọn.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 2:8

Sáàmù 107:42

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 58:10
  • +Ẹk 11:7; Sm 63:11

Sáàmù 107:43

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 64:9; Ho 14:9
  • +Sm 77:12; 143:5; Jer 9:24

Àwọn míì

Sm 107:1Lk 18:19
Sm 107:11Kr 16:34; Sm 103:17
Sm 107:2Ais 35:10; Jer 15:21; Mik 4:10
Sm 107:3Sm 106:47; Jer 29:14
Sm 107:3Ais 43:5, 6; Jer 31:8
Sm 107:6Ho 5:14, 15
Sm 107:6Ais 41:17
Sm 107:7Ais 30:21
Sm 107:7Ne 11:3
Sm 107:81Kr 16:8
Sm 107:8Sm 40:5
Sm 107:9Sm 34:10; Ais 55:2; Lk 1:53
Sm 107:11Sm 106:43; Ida 3:42
Sm 107:12Le 26:21
Sm 107:14Sm 68:6; 146:7; Ais 49:8, 9; 61:1
Sm 107:15Ida 3:22
Sm 107:16Ais 45:1, 2
Sm 107:17Jer 2:19
Sm 107:17Ida 3:39
Sm 107:20Sm 147:3
Sm 107:22Le 7:12; Sm 50:14
Sm 107:232Kr 9:21; Isk 27:9
Sm 107:24Jẹ 1:21; Sm 104:25
Sm 107:25Sm 135:7; Jer 10:13; Jon 1:4
Sm 107:27Jon 1:4, 13
Sm 107:28Jon 1:14
Sm 107:29Sm 65:7; 89:9; Jon 1:15
Sm 107:31Sm 105:5
Sm 107:32Sm 111:1
Sm 107:331Ọb 17:1, 7; Ais 42:15; Emọ 4:7
Sm 107:34Jẹ 13:10; Di 29:22, 23
Sm 107:352Ọb 3:17; Ais 35:7; 41:18
Sm 107:36Sm 146:7; Lk 1:53
Sm 107:36Sm 107:7
Sm 107:37Ais 65:21
Sm 107:37Iṣe 14:17
Sm 107:38Di 7:13, 14
Sm 107:40Job 12:21, 24
Sm 107:411Sa 2:8
Sm 107:42Sm 58:10
Sm 107:42Ẹk 11:7; Sm 63:11
Sm 107:43Sm 64:9; Ho 14:9
Sm 107:43Sm 77:12; 143:5; Jer 9:24
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
  • 20
  • 21
  • 22
  • 23
  • 24
  • 25
  • 26
  • 27
  • 28
  • 29
  • 30
  • 31
  • 32
  • 33
  • 34
  • 35
  • 36
  • 37
  • 38
  • 39
  • 40
  • 41
  • 42
  • 43
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Sáàmù 107:1-43

Sáàmù

ÌWÉ KARÙN-ÚN

(Sáàmù 107-150)

107 Ẹ fi ọpẹ́ fún Jèhófà, nítorí ó jẹ́ ẹni rere;+

Ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí láé.+

 2 Kí àwọn tí Jèhófà gbà* pa dà sọ bẹ́ẹ̀,

Àwọn tó gbà pa dà lọ́wọ́* ọ̀tá,+

 3 Àwọn tó kó jọ láti àwọn ilẹ̀,+

Láti ìlà oòrùn àti láti ìwọ̀ oòrùn,*

Láti àríwá àti láti gúúsù.+

 4 Wọ́n rìn kiri ní aginjù, ní aṣálẹ̀;

Wọn ò rí ọ̀nà tí wọ́n lè gbà dé ìlú tí wọ́n lè máa gbé.

 5 Ebi pa wọ́n, òùngbẹ sì gbẹ wọ́n;

Àárẹ̀ mú wọn* torí wọn ò lókun mọ́.

 6 Wọ́n ń ké pe Jèhófà nínú wàhálà tó bá wọn,+

Ó sì gbà wọ́n nínú ìnira wọn.+

 7 Ó mú wọn gba ọ̀nà tí ó tọ́+

Kí wọ́n lè dé ìlú tí wọ́n á lè máa gbé.+

 8 Kí àwọn èèyàn máa dúpẹ́ lọ́wọ́ Jèhófà+ nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀

Àti nítorí àwọn iṣẹ́ àgbàyanu rẹ̀ lórí àwọn ọmọ èèyàn.+

 9 Nítorí ó mú kí àwọn tí òùngbẹ ń gbẹ mu àmutẹ́rùn,

Ó sì mú kí àwọn* tí ebi ń pa jẹ ohun rere ní àjẹtẹ́rùn.+

10 Àwọn kan ń gbé inú òkùnkùn biribiri,

Àwọn ẹlẹ́wọ̀n tí ìyà ń jẹ, tí ṣẹkẹ́ṣẹkẹ̀ sì wà lọ́wọ́ wọn.

11 Nítorí wọ́n ta ko ọ̀rọ̀ Ọlọ́run;

Wọn ò ka ìmọ̀ràn Ẹni Gíga Jù Lọ sí.+

12 Torí náà, ó fi ìnira rẹ ọkàn wọn sílẹ̀;+

Wọ́n kọsẹ̀, kò sì sí ẹni tó máa ràn wọ́n lọ́wọ́.

13 Wọ́n ké pe Jèhófà fún ìrànlọ́wọ́ nítorí wàhálà tó bá wọn,

Ó sì gbà wọ́n nínú ìnira wọn.

14 Ó mú wọn jáde nínú òkùnkùn biribiri,

Ó sì fa ìdè wọn já.+

15 Kí àwọn èèyàn máa dúpẹ́ lọ́wọ́ Jèhófà nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀+

Àti nítorí àwọn iṣẹ́ àgbàyanu rẹ̀ lórí àwọn ọmọ èèyàn.

16 Nítorí ó ti fọ́ àwọn ilẹ̀kùn bàbà,

Ó sì ti gé àwọn ọ̀pá ìdábùú onírin.+

17 Wọ́n ya òmùgọ̀, wọ́n sì jìyà+

Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn àti àṣìṣe wọn.+

18 Oúnjẹ kankan ò lọ lẹ́nu wọn;*

Wọ́n sún mọ́ àwọn ẹnubodè ikú.

19 Wọ́n á ké pe Jèhófà fún ìrànlọ́wọ́ nítorí wàhálà tó bá wọn;

Á sì gbà wọ́n nínú ìnira wọn.

20 Á fi ọ̀rọ̀ rẹ̀ ránṣẹ́ sí wọn, á mú wọn lára dá,+

Á sì yọ wọ́n nínú kòtò tí wọ́n há sí.

21 Kí àwọn èèyàn máa dúpẹ́ lọ́wọ́ Jèhófà nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀

Àti nítorí àwọn iṣẹ́ àgbàyanu rẹ̀ lórí àwọn ọmọ èèyàn.

22 Kí wọ́n rú ẹbọ ọpẹ́,+

Kí wọ́n sì máa fi igbe ayọ̀ kéde àwọn iṣẹ́ rẹ̀.

23 Àwọn tó ń fi ọkọ̀ rìnrìn àjò lórí òkun,

Tí wọ́n ń ṣòwò lórí agbami òkun,+

 24 Wọ́n ti rí àwọn iṣẹ́ Jèhófà

Àti àwọn iṣẹ́ àgbàyanu rẹ̀ nínú ibú;+

 25 Bó ṣe fi ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú kí ìjì máa jà,+

Tó sì ń ru ìgbì òkun sókè.

26 Wọ́n gòkè lọ sí ojú ọ̀run;

Wọ́n já wálẹ̀ ṣòòròṣò sínú ibú.

Ọkàn wọn domi nítorí àjálù tó rọ̀ dẹ̀dẹ̀.

27 Wọ́n ń rìn tàgétàgé, wọ́n sì ń ta gọ̀ọ́gọ̀ọ́ bí ọ̀mùtí,

Gbogbo ọgbọ́n tí wọ́n ní já sí pàbó.+

28 Ni wọ́n bá ké pe Jèhófà nínú wàhálà tó bá wọn,+

Ó sì gbà wọ́n nínú ìnira wọn.

29 Ó mú kí ìjì náà rọlẹ̀,

Ìgbì òkun sì pa rọ́rọ́.+

30 Inú wọn dùn nígbà tí gbogbo rẹ̀ pa rọ́rọ́,

Ó sì ṣamọ̀nà wọn dé èbúté tí wọ́n fẹ́.

31 Kí àwọn èèyàn máa dúpẹ́ lọ́wọ́ Jèhófà nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀

Àti nítorí àwọn iṣẹ́ àgbàyanu rẹ̀ lórí àwọn ọmọ èèyàn.+

32 Kí wọ́n máa gbé e ga nínú ìjọ àwọn èèyàn,+

Kí wọ́n sì máa yìn ín nínú ìgbìmọ̀* àwọn àgbààgbà.

33 Ó ń sọ àwọn odò di aṣálẹ̀,

Ó sì ń sọ ìṣàn omi di ilẹ̀ tó gbẹ táútáú,+

 34 Ó ń sọ ilẹ̀ eléso di aṣálẹ̀,+

Nítorí ìwà burúkú àwọn tó ń gbé orí rẹ̀.

35 Ó ń sọ aṣálẹ̀ di adágún omi tí esùsú* kún inú rẹ̀,

Ó sì ń sọ ilẹ̀ gbígbẹ di ìṣàn omi.+

36 Ó ń mú kí àwọn tí ebi ń pa máa gbé ibẹ̀,+

Kí wọ́n lè tẹ ìlú dó láti máa gbé.+

37 Wọ́n dáko, wọ́n sì gbin ọgbà àjàrà+

Tí irè oko rẹ̀ pọ̀ dáadáa.+

38 Ó bù kún wọn, wọ́n sì pọ̀ gidigidi;

Kò jẹ́ kí ẹran ọ̀sìn wọn pẹ̀dín.+

39 Àmọ́ wọ́n tún dín kù, ẹ̀tẹ́ sì bá wọn

Nítorí ìnilára, àjálù àti ẹ̀dùn ọkàn.

40 Ó rọ̀jò àbùkù sórí àwọn èèyàn pàtàkì,

Ó sì mú kí wọ́n rìn kiri ní ilẹ̀ tó ti di ahoro, tí kò sì lójú ọ̀nà.+

41 Àmọ́ ó dáàbò bo àwọn aláìní* lọ́wọ́ ìnilára,+

Ó sì mú kí ìdílé wọn pọ̀ bí agbo ẹran.

42 Àwọn adúróṣinṣin rí èyí, wọ́n sì yọ̀;+

Àmọ́ gbogbo àwọn aláìṣòdodo pa ẹnu wọn mọ́.+

43 Ẹni tó bá gbọ́n yóò kíyè sí àwọn nǹkan yìí,+

Yóò sì fara balẹ̀ kíyè sí àwọn ohun tí Jèhófà ṣe nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́