ÒWE
1 Òwe Sólómọ́nì,+ ọmọ Dáfídì,+ ọba Ísírẹ́lì:+
2 Láti kọ́* ọgbọ́n+ àti ìbáwí;
Láti lóye àwọn ọ̀rọ̀ ọgbọ́n;
3 Láti gba ìbáwí+ tó ń fúnni ní ìjìnlẹ̀ òye,
Òdodo,+ ìdájọ́ òdodo*+ àti ìdúróṣinṣin;*
4 Láti mú kí àwọn aláìmọ̀kan ní àròjinlẹ̀;+
Láti mú kí ọ̀dọ́kùnrin ní ìmọ̀ àti làákàyè.+
5 Ọlọ́gbọ́n máa ń fetí sílẹ̀, á sì kọ́ ẹ̀kọ́ sí i;+
Olóye máa ń gba ìtọ́sọ́nà ọlọgbọ́n+
6 Láti lóye òwe àti ọ̀rọ̀ tó díjú,*
Ọ̀rọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n àti àlọ́ wọn.+
7 Ìbẹ̀rù* Jèhófà ni ìbẹ̀rẹ̀ ìmọ̀.+
Àwọn òmùgọ̀ ni kì í ka ọgbọ́n àti ìbáwí sí.+
10 Ọmọ mi, tí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ bá fẹ́ fa ojú rẹ mọ́ra, má gbà.+
11 Tí wọ́n bá sọ pé: “Jẹ́ ká lọ.
Ká lọ lúgọ láti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀.
Àá fara pa mọ́, àá sì dúró de àwọn aláìṣẹ̀ tó máa kó sọ́wọ́ wa.
13 Jẹ́ ká gba gbogbo ìṣúra wọn tó ṣeyebíye;
Àá fi ẹrù tí a bá gbà kún ilé wa.
15 Ọmọ mi, má tẹ̀ lé wọn.
Jẹ́ kí ẹsẹ̀ rẹ jìnnà sí ọ̀nà wọn,+
16 Nítorí ẹsẹ̀ wọn yá nílẹ̀ láti ṣe ibi;
Wọ́n yára láti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀.+
17 Asán ni téèyàn bá ta àwọ̀n sílẹ̀ níṣojú ẹyẹ.
20 Ọgbọ́n tòótọ́+ ń ké jáde ní ojú ọ̀nà.+
Ó ń gbé ohùn rẹ̀ sókè ní àwọn ojúde ìlú.+
21 Ó ké jáde ní igun* ọ̀nà tí ọ̀pọ̀ èèyàn ń gbà.
Ní àtiwọ àwọn ẹnubodè ìlú, ó ń sọ pé:+
22 “Ìgbà wo ni ẹ̀yin aláìmọ̀kan máa jáwọ́ nínú àìmọ̀kan yín?
Ìgbà wo ni ẹ̀yin afiniṣẹ̀sín máa gbádùn fífini ṣẹ̀sín dà?
Ìgbà wo sì ni ẹ̀yin òmùgọ̀ máa kórìíra ìmọ̀ dà?+
Nígbà náà, màá tú ẹ̀mí mi jáde fún yín;
Màá jẹ́ kí ẹ mọ àwọn ọ̀rọ̀ mi.+
24 Nítorí mò ń pè, àmọ́ ẹ ò dáhùn,
Mo na ọwọ́ mi jáde, àmọ́ kò sẹ́ni tó fiyè sí i,+
25 Ẹ kì í ka gbogbo ìmọ̀ràn mi sí
Ẹ kì í sì í gba ìbáwí mi,
26 Èmi náà á rẹ́rìn-ín nígbà tí àjálù bá dé bá yín;
Màá fi yín ṣe yẹ̀yẹ́ nígbà tí ohun tí ẹ̀ ń bẹ̀rù bá dé,+
27 Nígbà tí ohun tí ẹ̀ ń bẹ̀rù bá dé bí ìjì,
Tí àjálù yín sì dé bí ìjì líle,
Nígbà tí ìdààmú àti wàhálà bá dé bá yín.
28 Ní àkókò yẹn, wọ́n á máa pè mí, àmọ́ mi ò ní dáhùn;
Wọ́n á máa fi ìtara wá mi, àmọ́ wọn ò ní rí mi,+
29 Torí wọ́n kórìíra ìmọ̀,+
Wọn ò sì bẹ̀rù Jèhófà.+
30 Wọn ò gba ìmọ̀ràn mi;
Wọn ò ka gbogbo ìbáwí mi sí.
32 Nítorí ìwà àìníjàánu àwọn aláìmọ̀kan ni yóò pa wọ́n,
Àìka-nǹkan-sí àwọn òmùgọ̀ ni yóò sì pa wọ́n run.
2 Ọmọ mi, tí o bá gba àwọn ọ̀rọ̀ mi
Tí o sì fi àwọn àṣẹ mi ṣe ìṣúra rẹ,+
Àti fífi ọkàn sí ìfòyemọ̀;+
3 Bákan náà, tí o bá ké pe òye+
Tí o sì nahùn pe ìfòyemọ̀;+
Tí o sì ń wá a kiri bí àwọn ìṣúra tó fara sin;+
5 Nígbà náà, wàá lóye ìbẹ̀rù Jèhófà,+
Wàá sì rí ìmọ̀ Ọlọ́run.+
7 Ó ń to ọgbọ́n tó gbéṣẹ́ jọ fún àwọn adúróṣinṣin;
Ó jẹ́ apata fún àwọn tó ń rìn nínú ìwà títọ́.+
8 Ó ń pa ọ̀nà àwọn olódodo mọ́,
Ó sì ń ṣọ́ ọ̀nà àwọn adúróṣinṣin rẹ̀.+
10 Nígbà tí ọgbọ́n bá wọnú ọkàn rẹ+
11 Làákàyè yóò máa ṣọ́ ọ,+
Ìfòyemọ̀ yóò sì máa dáàbò bò ọ́,
12 Láti gbà ọ́ kúrò ní ọ̀nà búburú,
Kúrò lọ́wọ́ ẹni tó ń sọ ọ̀rọ̀ àyídáyidà,+
13 Kúrò lọ́wọ́ àwọn tó ń fi ọ̀nà òdodo* sílẹ̀
Kí wọ́n lè máa rìn ní ọ̀nà òkùnkùn,+
14 Kúrò lọ́wọ́ àwọn tó ń fi ìwà àìtọ́ ṣayọ̀,
Àwọn tí ìwà tó burú jáì ń múnú wọn dùn,
15 Àwọn tí ọ̀nà wọn wọ́
Tí gbogbo ọ̀nà wọn sì jẹ́ békebèke.
16 Yóò dáàbò bò ọ́ kúrò lọ́wọ́ obìnrin oníwàkiwà,*
Kúrò lọ́wọ́ ọ̀rọ̀ dídùn* obìnrin oníṣekúṣe,*+
17 Ẹni tó fi ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́* ìgbà èwe rẹ̀ sílẹ̀+
Tó sì gbàgbé májẹ̀mú Ọlọ́run rẹ̀;
18 Nítorí ilé rẹ̀ ń rini sínú ikú,
19 Kò sí ìkankan lára àwọn tó ní ohunkóhun ṣe pẹ̀lú rẹ̀* tó máa pa dà,
Bẹ́ẹ̀ ni wọn ò ní pa dà sí ọ̀nà ìyè.+
20 Torí náà, máa gba ọ̀nà àwọn ẹni rere
Má sì kúrò ní ọ̀nà àwọn olódodo,+
21 Nítorí àwọn adúróṣinṣin ló máa gbé ní ayé,
22 Ní ti àwọn ẹni burúkú, a ó pa wọ́n run kúrò ní ayé,+
Ní ti àwọn oníbékebèke, a ó fà wọ́n tu kúrò nínú rẹ̀.+
3 Ọmọ mi, má gbàgbé ẹ̀kọ́* mi,
Sì jẹ́ kí ọkàn rẹ máa pa àwọn àṣẹ mi mọ́,
2 Nítorí wọ́n á fi ọ̀pọ̀ ọjọ́
Àti ẹ̀mí gígùn pẹ̀lú àlàáfíà kún un fún ọ.+
3 Má ṣe jẹ́ kí ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ àti ìṣòtítọ́* fi ọ́ sílẹ̀.+
So wọ́n mọ́ ọrùn rẹ;
Kọ wọ́n sí wàláà ọkàn rẹ;+
4 Nígbà náà, wàá rí ojú rere àti òye tó jinlẹ̀ gan-an
Lójú Ọlọ́run àti èèyàn.+
7 Má ṣe jẹ́ ọlọ́gbọ́n lójú ara rẹ.+
Bẹ̀rù Jèhófà kí o sì yẹra fún ibi.
9 Fi àwọn ohun ìní rẹ tó níye lórí bọlá fún Jèhófà,+
Pẹ̀lú àkọ́so* gbogbo irè oko rẹ;*+
10 Nígbà náà, àwọn ilé ìkẹ́rùsí rẹ á kún fọ́fọ́,+
Wáìnì tuntun á sì kún àwọn ẹkù* rẹ ní àkúnwọ́sílẹ̀.
11 Ọmọ mi, má ṣe kọ ìbáwí Jèhófà,+
Má sì kórìíra ìtọ́sọ́nà rẹ̀,+
12 Torí pé àwọn tí Jèhófà nífẹ̀ẹ́ ló máa ń bá wí,+
Bí bàbá ṣe máa ń fún ọmọ tí inú rẹ̀ dùn sí ní ìbáwí.+
13 Aláyọ̀ ni ẹni tó wá ọgbọ́n rí+
Àti ẹni tó ní òye;
14 Kéèyàn ní in sàn ju kéèyàn ní fàdákà,
Kéèyàn jèrè rẹ̀ sì sàn ju kéèyàn jèrè wúrà.+
16 Ẹ̀mí gígùn wà ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀;
Ọrọ̀ àti ògo sì wà ní ọwọ́ òsì rẹ̀.
17 Àwọn ọ̀nà rẹ̀ gbádùn mọ́ni,
Àlàáfíà sì wà ní gbogbo ipa ọ̀nà rẹ̀.+
18 Igi ìyè ni fún àwọn tó dì í mú,
Aláyọ̀ ni a ó sì máa pe àwọn tó dì í mú ṣinṣin.+
19 Ọgbọ́n ni Jèhófà fi dá ayé.+
Òye ni ó fi fìdí ọ̀run múlẹ̀ gbọn-in.+
20 Nípa ìmọ̀ rẹ̀ ni àwọn ibú omi fi pínyà
Tí ìkùukùu ojú sánmà sì ń mú kí ìrì sẹ̀.+
21 Ọmọ mi, máa fi wọ́n* sọ́kàn.
Má ṣe jẹ́ kí ọgbọ́n tó gbéṣẹ́ àti làákàyè bọ́ mọ́ ọ lọ́wọ́;
22 Wọ́n á fún ọ* ní ìyè
Wọ́n á sì jẹ́ ọ̀ṣọ́ fún ọrùn rẹ;
23 Nígbà náà, wàá máa rìn láìséwu ní ọ̀nà rẹ,
28 Má sọ fún ọmọnìkejì rẹ pé, “Máa lọ ná, tó bá dọ̀la kí o pa dà wá, màá fún ọ,”
Nígbà tí o lè fún un lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀.
29 Má gbèrò ibi sí ọmọnìkejì rẹ+
Nígbà tí ọkàn rẹ̀ balẹ̀ lọ́dọ̀ rẹ pé kò séwu.
31 Má ṣe jowú ẹni tó ń hùwà ipá+
Má sì yan èyíkéyìí nínú àwọn ọ̀nà rẹ̀,
32 Nítorí Jèhófà kórìíra oníbékebèke,+
Ṣùgbọ́n àwọn adúróṣinṣin ni ọ̀rẹ́ Rẹ̀ tímọ́tímọ́.+
35 Àwọn ọlọ́gbọ́n á jogún ọlá,
Àmọ́, ẹ̀tẹ́ ni àwọn òmùgọ̀ fi ń ṣayọ̀.+
4 Ẹ̀yin ọmọ mi, ẹ fetí sí ìbáwí bàbá;+
Ẹ fiyè sílẹ̀, kí ẹ lè ní òye,
2 Nítorí màá fún yín ní ìtọ́ni rere;
4 Bàbá mi kọ́ mi, ó sì sọ pé: “Kí àwọn ọ̀rọ̀ mi wà lọ́kàn rẹ digbí.+
Pa àwọn àṣẹ mi mọ́ kí o sì máa wà láàyè.+
Má gbàgbé, má sì kúrò nínú ohun tí mo sọ.
6 Má pa á tì, yóò dáàbò bò ọ́.
Nífẹ̀ẹ́ rẹ̀, yóò sì pa ọ́ mọ́.
8 Jẹ́ kó níyì gan-an lójú rẹ, yóò sì gbé ọ ga.+
Yóò bọlá fún ọ nítorí pé o gbá a mọ́ra.+
9 Yóò fi òdòdó ẹ̀yẹ tó fani mọ́ra sí ọ lórí;
Yóò sì dé ọ ní adé ẹwà.”
12 Nígbà tí o bá ń rìn, ẹsẹ̀ rẹ kò ní kọ́lẹ̀;
Tí o bá sì ń sáré, o ò ní kọsẹ̀.
13 Di ìbáwí mú; má ṣe jẹ́ kó lọ.+
Pa á mọ́, nítorí òun ni ẹ̀mí rẹ.+
16 Torí wọn ò lè sùn àfi tí wọ́n bá ṣe ohun tí kò dáa.
Wọn kì í rí oorun sùn àfi tí wọ́n bá mú kí ẹnì kan ṣubú.
17 Oúnjẹ ìwà burúkú ni wọ́n fi ń bọ́ ara wọn,
Wáìnì ìwà ipá ni wọ́n sì ń mu.
19 Ọ̀nà àwọn ẹni burúkú dà bí òkùnkùn;
Wọn ò mọ ohun tó ń mú wọn kọsẹ̀.
20 Ọmọ mi, fetí sí àwọn ọ̀rọ̀ mi;
Fetí sílẹ̀ dáadáa* sí àwọn ọ̀rọ̀ mi.
21 Máa fi wọ́n sọ́kàn;
Jẹ́ kí wọ́n jinlẹ̀ lọ́kàn rẹ,+
22 Nítorí ìyè ni wọ́n jẹ́ fún àwọn tó wá wọn rí+
Wọ́n sì jẹ́ ìlera fún gbogbo ara* wọn.
23 Ju gbogbo ohun mìíràn tí ò ń dáàbò bò, dáàbò bo ọkàn rẹ,+
Nítorí inú rẹ̀ ni àwọn ohun tó ń fúnni ní ìyè ti ń wá.
27 Má yà sí ọ̀tún tàbí sí òsì.+
Má fi ẹsẹ̀ rẹ lé ọ̀nà búburú.
5 Ọmọ mi, fiyè sí ọgbọ́n mi.
5 Àwọn ẹsẹ̀ rẹ̀ lọ sí ikú.
Àwọn ìṣísẹ̀ rẹ̀ lọ tààrà sí Isà Òkú.*
6 Kì í ronú nípa ọ̀nà ìyè.
Ó ti ṣìnà, kò mọ ibi tí ọ̀nà rẹ̀ máa já sí.
7 Ní báyìí, ẹ̀yin ọmọ mi, ẹ fetí sí mi
Ẹ má sì kúrò nínú ohun tí mò ń sọ.
8 Jìnnà réré sí i;
Má sì sún mọ́ ẹnu ọ̀nà ilé rẹ̀,+
9 Kí o má bàa fi iyì rẹ fún àwọn ẹlòmíì+
Tàbí kí o fi ọ̀pọ̀ ọdún kórè ohun tó burú;+
10 Kí àwọn àjèjì má bàa fa ọrọ̀* rẹ gbẹ,+
Kí àwọn ohun tí o ṣiṣẹ́ kára fún sì lọ sí ilé àjèjì.
11 Àìjẹ́ bẹ́ẹ̀, wàá kérora nígbẹ̀yìn ayé rẹ
Nígbà tí okun rẹ bá tán, tí ẹran ara rẹ sì gbẹ+
12 Tí o sì sọ pé: “Ẹ wo bí mo ṣe kórìíra ẹ̀kọ́ tó!
Ẹ wo bí ọkàn mi ti ṣàìka ìbáwí sí!
13 Mi ò fetí sí ohùn àwọn tó ń kọ́ mi
Mi ò sì tẹ́tí sí àwọn olùkọ́ mi.
17 Jẹ́ kí wọ́n wà fún ìwọ nìkan,
Kì í ṣe fún ìwọ àti àwọn àjèjì.+
Jẹ́ kí ọmú rẹ̀ máa dá ọ lọ́rùn* nígbà gbogbo.
Kí ìfẹ́ rẹ̀ máa gbà ọ́ lọ́kàn ní gbogbo ìgbà.+
22 Àwọn àṣìṣe ẹni burúkú ló ń dẹkùn mú un,
Àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ á sì wé mọ́ ọn bí okùn.+
23 Ó máa kú nítorí kò gba ìbáwí
Á sì ṣìnà nítorí ìwà òmùgọ̀ rẹ̀ tó pọ̀ lápọ̀jù.
6 Ọmọ mi, tí o bá ti ṣe onídùúró* fún ọmọnìkejì rẹ,+
2 Tí ìlérí rẹ bá ti dẹkùn mú ọ,
Tí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ bá ti mú ọ,+
3 Ohun tí wàá ṣe nìyí, ọmọ mi, kí o lè gba ara rẹ sílẹ̀,
Nítorí o ti kó sọ́wọ́ ọmọnìkejì rẹ:
Lọ rẹ ara rẹ sílẹ̀, kí o sì tètè bẹ ọmọnìkejì rẹ.+
4 Má ṣe jẹ́ kí oorun kun ojú rẹ,
Má sì jẹ́ kí ìpéǹpéjú rẹ tòògbé.
5 Gba ara rẹ sílẹ̀ bí àgbọ̀nrín tó bọ́ lọ́wọ́ ọdẹ,
Àti bí ẹyẹ tó bọ́ lọ́wọ́ pẹyẹpẹyẹ.
7 Bó tilẹ̀ jẹ́ pé kò ní olùdarí, aláṣẹ tàbí alákòóso,
8 Ó ń ṣètò oúnjẹ rẹ̀ sílẹ̀ nígbà ẹ̀ẹ̀rùn,+
Ó sì ń kó oúnjẹ rẹ̀ jọ nígbà ìkórè.
9 Ìgbà wo ni ìwọ ọ̀lẹ máa dùbúlẹ̀ dà?
Ìgbà wo lo máa dìde lójú oorun rẹ?
10 Oorun díẹ̀, ìtòògbé díẹ̀,
Kíkáwọ́ gbera díẹ̀ láti sinmi,+
11 Ipò òṣì rẹ yóò sì dé bí olè,
Àti àìní rẹ bí ọkùnrin tó dìhámọ́ra.+
17 Ojú ìgbéraga,+ ahọ́n èké+ àti ọwọ́ tó ń ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀,+
18 Ọkàn tó ń gbèrò ìkà+ àti ẹsẹ̀ tó ń sáré tete láti ṣe ibi,
19 Ẹlẹ́rìí èké tí kò lè ṣe kó má parọ́+
Àti ẹni tó ń dá awuyewuye sílẹ̀ láàárín àwọn arákùnrin.+
21 So wọ́n mọ́ ọkàn rẹ nígbà gbogbo;
Dè wọ́n mọ́ ọrùn rẹ.
22 Nígbà tí o bá ń rìn, á máa darí rẹ;
Nígbà tí o bá dùbúlẹ̀, á máa ṣọ́ ẹ;
Nígbà tí o bá sì jí, á máa bá ẹ sọ̀rọ̀.*
24 Wọ́n máa dáàbò bò ọ́ lọ́wọ́ obìnrin burúkú,+
Lọ́wọ́ ahọ́n obìnrin oníṣekúṣe* tó ń sọ ọ̀rọ̀ tó fani mọ́ra.+
25 Má ṣe jẹ́ kí ẹwà rẹ̀ wù ọ́+
Tàbí kí o jẹ́ kó fi ojú rẹ̀ tó ń fani mọ́ra mú ọ,
26 Ní tìtorí aṣẹ́wó, èèyàn á di ẹni tí kò ní ju búrẹ́dì kan ṣoṣo lọ,+
Ní ti obìnrin alágbèrè, ẹ̀mí* tó ṣeyebíye ló fi ń ṣe ìjẹ.
27 Ṣé ọkùnrin kan lè wa iná jọ sí àyà rẹ̀, kí ẹ̀wù rẹ̀ má sì jó?+
28 Tàbí ṣé ọkùnrin kan lè rìn lórí ẹyin iná, kó má sì jó o lẹ́sẹ̀?
29 Bẹ́ẹ̀ náà ló rí fún ẹni tó bá ń ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú aya ọmọnìkejì rẹ̀;
Kò sí ẹni tó fọwọ́ kàn án tó máa lọ láìjìyà.+
31 Síbẹ̀, tí wọ́n bá rí i, á san án pa dà ní ìlọ́po méje;
Gbogbo ohun tó níye lórí nínú ilé rẹ̀ ló máa kó sílẹ̀.+
4 Sọ fún ọgbọ́n pé, “Arábìnrin mi ni ọ́,”
Kí o sì pe òye ní “ìbátan mi,”
Mo bojú wolẹ̀ látojú fèrèsé,*
7 Bí mo ṣe ń wo àwọn aláìmọ̀kan,*
Mo kíyè sí ọ̀dọ́kùnrin kan tí kò ní làákàyè* láàárín àwọn ọ̀dọ́.+
8 Ó gba ojú ọ̀nà tó wà nítòsí ìyànà ilé obìnrin náà kọjá,
Ó sì rìn lọ sí ọ̀nà ilé obìnrin náà
Nígbà tí ilẹ̀ ń ṣú, tí òkùnkùn sì ń kùn.
11 Ó jẹ́ aláriwo àti aláfojúdi.+
Kì í* dúró sílé.
13 Obìnrin náà gbá a mú, ó sì fi ẹnu kò ó lẹ́nu;
Ó fi ọ̀dájú sọ fún un pé:
14 “Mo ti rú àwọn ẹbọ ìrẹ́pọ̀.+
Òní ni mo san àwọn ẹ̀jẹ́ mi.
15 Ìdí nìyẹn tí mo fi jáde wá pàdé rẹ,
Láti wá ọ, mo sì ti rí ọ!
17 Mo ti fi òjíá, álóè àti sínámónì wọ́n ibùsùn mi.+
18 Wá, jẹ́ ká jọ ṣeré ìfẹ́ títí di àárọ̀;
Jẹ́ ká gbádùn ìfẹ́ láàárín ara wa,
19 Nítorí ọkọ mi ò sí nílé;
Ó ti rin ìrìn àjò lọ sí ọ̀nà jíjìn.
20 Ó gbé àpò owó dání,
Kò sì ní pa dà títí di ọjọ́ òṣùpá àrànmọ́jú.”
21 Ó fi ọ̀rọ̀ tó ń yíni lérò pa dà ṣì í lọ́nà.+
Ó fi ọ̀rọ̀ dídùn fa ojú rẹ̀ mọ́ra.
22 Lójijì, ó tẹ̀ lé obìnrin náà, bí akọ màlúù tí wọ́n ń mú lọ síbi tí wọ́n ti fẹ́ pa á,
Bí òmùgọ̀ tí wọ́n fẹ́ fìyà jẹ nínú àbà,*+
23 Títí ọfà fi gún ẹ̀dọ̀ rẹ̀ ní àgúnyọ;
Bí ẹyẹ tó kó sínú pańpẹ́, kò mọ̀ pé ẹ̀mí òun máa lọ sí i.+
24 Ní báyìí, ẹ fetí sí mi, ẹ̀yin ọmọ mi;
Ẹ fiyè sí àwọn ọ̀rọ̀ tí mò ń sọ.
25 Má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ lọ sí àwọn ọ̀nà rẹ̀.
Má rìn gbéregbère wọ àwọn ipa ọ̀nà rẹ̀,+
26 Nítorí ọ̀pọ̀ èèyàn ló ti ṣekú pa,+
Àwọn tó ti pa sì pọ̀ gan-an.+
27 Ilé rẹ̀ lọ sí Isà Òkú;*
Ó sọ̀ kalẹ̀ sínú yàrá ikú.
8 Ǹjẹ́ ọgbọ́n ò máa ké jáde?
Ṣé òye ò máa gbé ohùn rẹ̀ sókè?+
6 Ẹ fetí sílẹ̀, torí ohun tí mò ń sọ ṣe pàtàkì,
Ètè mi ń sọ ohun tí ó tọ́;
7 Nítorí ẹnu mi ń sọ òtítọ́ ní ohùn jẹ́ẹ́jẹ́ẹ́,
Ètè mi sì kórìíra ohun tó burú.
8 Òdodo ni gbogbo ọ̀rọ̀ ẹnu mi.
Kò sí ẹ̀tàn kankan tàbí màgòmágó nínú wọn.
9 Gbogbo wọn tọ̀nà lójú ẹni tó lóye
Wọ́n sì tọ́ lójú àwọn tó ti wá ìmọ̀ rí.
10 Ẹ gba ìbáwí mi dípò fàdákà,
Àti ìmọ̀ dípò wúrà tó dára jù lọ,+
11 Nítorí ọgbọ́n sàn ju iyùn* lọ;
Kò sí ohun ṣíṣeyebíye míì tí a lè fi wé e.
13 Ìbẹ̀rù Jèhófà ni ìkórìíra ohun búburú.+
Mo kórìíra ìṣefọ́nńté àti ìgbéraga+ àti ọ̀nà ibi àti ọ̀rọ̀ àyídáyidà.+
16 Ipasẹ̀ mi ni àwọn olórí ń ṣàkóso,
Tí àwọn èèyàn pàtàkì sì ń fi òdodo ṣèdájọ́.
19 Èso mi sàn ju wúrà lọ, àní wúrà tí a yọ́ mọ́,
Ohun tí mo sì ń mú jáde sàn ju fàdákà tó dára jù lọ.+
20 Mò ń rìn ní ọ̀nà òdodo,
Ní àárín àwọn ipa ọ̀nà ìdájọ́ òdodo;
21 Mo fún àwọn tó nífẹ̀ẹ́ mi ní ogún tó ṣeyebíye,
Mo sì mú kí ilé ìkẹ́rùsí wọn kún.
25 Kí a tó fìdí àwọn òkè ńlá kalẹ̀,
Ṣáájú àwọn òkè kéékèèké, a ti mú mi jáde,
26 Nígbà tí kò tíì dá ayé àti àwọn pápá rẹ̀
Tàbí erùpẹ̀ ilẹ̀ tó kọ́kọ́ wà.
27 Nígbà tó dá ọ̀run,+ mo wà níbẹ̀;
Nígbà tó fi ààlà* sí orí omi,+
28 Nígbà tó ṣe àwọsánmà sókè,*
Nígbà tó dá àwọn ìsun ibú omi,
29 Nígbà tó pàṣẹ fún òkun
Pé kí omi rẹ̀ má kọjá àṣẹ tó pa fún un,+
Nígbà tó fi àwọn ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀,*
Èmi ni àrídunnú rẹ̀+ lójoojúmọ́;
Inú mi sì ń dùn níwájú rẹ̀ ní gbogbo ìgbà;+
31 Inú mi ń dùn nítorí ayé tí ó dá fún èèyàn láti máa gbé,
Mo sì fẹ́ràn àwọn ọmọ èèyàn* lọ́nà àrà ọ̀tọ̀.
32 Ní báyìí, ẹ̀yin ọmọ mi, ẹ fetí sí mi;
Bẹ́ẹ̀ ni, aláyọ̀ ni àwọn tó ń pa àwọn ọ̀nà mi mọ́.
34 Aláyọ̀ ni ẹni tó ń fetí sí mi
Tó ń jí wá sẹ́nu* ọ̀nà mi lójoojúmọ́,
Tó ń dúró lẹ́gbẹ̀ẹ́ òpó ilẹ̀kùn mi;
35 Nítorí ẹni tó bá rí mi yóò rí ìyè,+
Yóò sì rí ìtẹ́wọ́gbà Jèhófà.
9 Ọgbọ́n tòótọ́ ti kọ́ ilé rẹ̀;
Ó ti gbẹ́ òpó rẹ̀ méjèèje.
4 “Kí ẹni tó bá jẹ́ aláìmọ̀kan wọlé síbí.”
Ó sọ fún àwọn tí kò ní làákàyè* pé:
5 “Ẹ wá, ẹ jẹ oúnjẹ mi
Kí ẹ sì mu nínú wáìnì tí mo ti pò.
8 Má ṣe bá afiniṣẹ̀sín wí, torí á kórìíra rẹ.+
Bá ọlọ́gbọ́n wí, yóò sì nífẹ̀ẹ́ rẹ.+
9 Kọ́ ọlọ́gbọ́n, yóò sì gbọ́n sí i. +
Kọ́ olódodo, yóò sì kọ́ ẹ̀kọ́ sí i.
12 Tí o bá gbọ́n, o gbọ́n fún àǹfààní ara rẹ,
Àmọ́ tí o bá ya afiniṣẹ̀sín, ìwọ nìkan lo máa jìyà rẹ̀.
13 Òmùgọ̀ obìnrin jẹ́ aláriwo.+
Òpè ni, kò sì mọ nǹkan kan rárá.
14 Ó máa ń jókòó sí ẹnu ọ̀nà ilé rẹ̀
Lórí ìjókòó ní àwọn ibi gíga ìlú,+
15 Ó ń pe àwọn tó ń kọjá lọ,
Àwọn tó ń lọ tààrà ní ọ̀nà wọn, pé:
16 “Kí ẹni tó bá jẹ́ aláìmọ̀kan wọlé síbí.”
Ó sọ fún àwọn tí kò ní làákàyè* pé:+
Ọlọ́gbọ́n ọmọ ń mú inú bàbá rẹ̀ dùn,+
Àmọ́ òmùgọ̀ ọmọ ń kó ẹ̀dùn ọkàn bá ìyá rẹ̀.
3 Jèhófà ò ní jẹ́ kí ebi pa olódodo,*+
Bẹ́ẹ̀ sì ni kò ní jẹ́ kí ọwọ́ àwọn ẹni burúkú tẹ ohun tí wọ́n ń fẹ́.
5 Ọmọ tó ní ìjìnlẹ̀ òye ń kó irè oko jọ ní ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn,
Àmọ́ ọmọ tó ń dójú tini ń sùn fọnfọn nígbà ìkórè.+
9 Ẹni tó ń rìn nínú ìwà títọ́ yóò máa rìn nínú ààbò,+
Àmọ́ àṣírí ẹni tó ń sọ ọ̀nà ara rẹ̀ di wíwọ́ yóò tú.+
15 Ohun ìní* ọlọ́rọ̀ ni ìlú olódi rẹ̀.
Ipò òṣì àwọn aláìní ni ìparun wọn.+
31 Ẹnu olódodo ń mú* ọgbọ́n jáde,
Àmọ́, ahọ́n àyídáyidà ni a ó gé kúrò.
32 Ètè olódodo mọ ohun tó tọ́ láti sọ,
Àmọ́ ẹnu ẹni burúkú jẹ́ ẹ̀tàn.
7 Nígbà tí ẹni burúkú bá kú, ìrètí rẹ̀ á ṣègbé;
Ohun tó sì ń retí pé òun á fi agbára òun ṣe yóò ṣègbé pẹ̀lú.+
14 Nígbà tí kò bá sí ìtọ́sọ́nà ọlọgbọ́n, àwọn èèyàn á ṣubú,
15 Ẹni tó bá ṣe onídùúró* fún àjèjì yóò rí láburú,+
Àmọ́ ẹni tó bá yẹra fún* bíbọ ọwọ́ nínú ẹ̀jẹ́ yóò rí ààbò.
19 Ẹni tó dúró gbọn-in lórí òdodo máa rí ìyè,+
Àmọ́ ẹni tó ń lépa ohun búburú á rí ikú he.
22 Bí òrùka wúrà ní imú ẹlẹ́dẹ̀
Ni obìnrin tó rẹwà àmọ́ tí kì í lo làákàyè.
23 Ìfẹ́ ọkàn àwọn olódodo ń yọrí sí ire,+
Àmọ́ ohun tí àwọn ẹni burúkú ń retí máa ń yọrí sí ìbínú ńlá.
24 Ẹnì kan wà tó ń fúnni lọ́pọ̀lọpọ̀,* ó sì ń ní sí i;+
Ẹnì kan sì wà tó ń fawọ́ ohun tó yẹ kó fúnni sẹ́yìn, àmọ́ ó di aláìní.+
26 Àwọn èèyàn á gégùn-ún fún ẹni tó bá kó oúnjẹ pa mọ́,
Àmọ́ wọ́n á súre fún ẹni tó bá ń tà á.
27 Ẹni tó ń wá bó ṣe máa ṣe rere lójú méjèèjì ń wá ojú rere,+
Àmọ́ ẹni tó bá ń wá ibi, ó dájú pé ibi ló máa wá sórí rẹ̀.+
29 Ẹni tó bá ń fa wàhálà* bá agbo ilé rẹ̀ á jogún òfo,*+
Òmùgọ̀ èèyàn ló sì máa jẹ́ ìránṣẹ́ ọlọ́gbọ́n.
5 Ìrònú àwọn olódodo máa ń tọ́,
Àmọ́ ẹ̀tàn ni ìmọ̀ràn àwọn ẹni burúkú.
11 Ẹni tó ń ro ilẹ̀ rẹ̀ yóò jẹun tẹ́rùn,+
Àmọ́ ẹni tó ń lépa àwọn ohun tí kò ní láárí kò ní làákàyè.*
12 Ẹni burúkú ń jowú ohun tí àwọn ẹni burúkú míì dẹkùn mú,
Àmọ́ àwọn olódodo dà bí igi tí gbòǹgbò rẹ̀ jinlẹ̀ tó ń méso jáde.
16 Òmùgọ̀ máa ń fi ìbínú rẹ̀ hàn lójú ẹsẹ̀,*+
Àmọ́ aláròjinlẹ̀ máa ń gbójú fo* àbùkù tí wọ́n fi kàn án.
22 Ètè tó ń parọ́ jẹ́ ohun ìríra lójú Jèhófà,+
Àmọ́ àwọn tó ń fi òtítọ́ hùwà ń mú inú rẹ̀ dùn.
26 Olódodo ń ṣàyẹ̀wò ibi ìjẹko rẹ̀,
Àmọ́ ọ̀nà àwọn ẹni burúkú ń kó wọn ṣìnà.
28 Ipa ọ̀nà òdodo ń yọrí sí ìyè;+
Kò sí ikú ní ipa ọ̀nà rẹ̀.
2 Ọ̀rọ̀ ẹnu èèyàn máa jẹ́ kó rí ohun rere gbà,+
Àmọ́ ìfẹ́ ọkàn àwọn oníbékebèke máa ń jẹ́ kí wọ́n hùwà ipá.
7 Ẹnì kan wà tó ń ṣe bíi pé òun jẹ́ ọlọ́rọ̀, síbẹ̀ kò ní nǹkan kan;+
Ẹlòmíì sì wà tó ń ṣe bíi pé aláìní lòun, síbẹ̀ ó ní ọrọ̀ rẹpẹtẹ.
11 Ọrọ̀ tí èèyàn fi ìkánjú kó jọ* kì í pẹ́ tán,+
Àmọ́ ọrọ̀ tí èèyàn ń kó jọ díẹ̀díẹ̀* á máa pọ̀ sí i.
15 Ìjìnlẹ̀ òye ń mú kéèyàn jèrè ojú rere,
Àmọ́ ọ̀nà àwọn oníbékebèke korò.
18 Ẹni tí kò bá ka ìbáwí sí á di òtòṣì, á sì kan àbùkù,
22 Ẹni rere máa ń fi ogún sílẹ̀ fún àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀,
Àmọ́ ọrọ̀ àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni a ó kó jọ fún àwọn olódodo.+
3 Pàṣán ìgbéraga wà ní ẹnu òmùgọ̀,
Àmọ́ ètè àwọn ọlọ́gbọ́n yóò dáàbò bò wọ́n.
8 Ọgbọ́n ni aláròjinlẹ̀ fi ń lóye ibi tí ọ̀nà rẹ̀ máa já sí,
13 Èèyàn lè máa rẹ́rìn-ín, síbẹ̀ kí ọkàn rẹ̀ máa jẹ̀rora,
Ìdùnnú sì lè di ìbànújẹ́.
16 Ọlọ́gbọ́n máa ń ṣọ́ra, ó sì ń yẹra fún ìwà burúkú,
Àmọ́ òmùgọ̀ kì í kíyè sára,* ó sì máa ń dá ara rẹ̀ lójú jù.
19 Àwọn èèyàn búburú yóò tẹrí ba níwájú àwọn ẹni rere,
Àwọn èèyàn burúkú yóò sì tẹrí ba ní ẹnubodè àwọn olódodo.
22 Àwọn tó ń gbèrò ibi máa ṣìnà.
Àmọ́ àwọn tó ti pinnu láti máa ṣe rere máa rí ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ àti òtítọ́.+
27 Ìbẹ̀rù Jèhófà jẹ́ orísun ìyè,
Kì í jẹ́ kéèyàn kó sínú ìdẹkùn ikú.
11 Isà Òkú* àti ibi ìparun* ṣí sílẹ̀ gbayawu lójú Jèhófà.+
Ká má ṣẹ̀ṣẹ̀ wá sọ ọkàn èèyàn!+
12 Ẹlẹ́gàn kì í fẹ́ràn ẹni tó ń tọ́ ọ sọ́nà.*+
Kì í fi ọ̀rọ̀ lọ àwọn ọlọ́gbọ́n.+
27 Ẹni tó ń jẹ èrè tí kò tọ́ ń fa wàhálà* bá agbo ilé rẹ̀,+
Àmọ́ ẹni tó kórìíra àbẹ̀tẹ́lẹ̀ yóò máa wà láàyè.+
5 Jèhófà kórìíra gbogbo ẹni tó ń gbéra ga.+
Ó dájú* pé wọn ò ní lọ láìjìyà.
6 Ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ àti òtítọ́ máa ń mú ẹ̀ṣẹ̀ kúrò,+
Ìbẹ̀rù Jèhófà sì máa ń mú kéèyàn yẹra fún ohun búburú.+
11 Ọ̀dọ̀ Jèhófà ni ìwọ̀n àti òṣùwọ̀n pípé ti wá;
Gbogbo òkúta ìwọ̀n tó wà nínú àpò jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.+
13 Ọ̀rọ̀ òdodo jẹ́ ìdùnnú àwọn ọba.
Wọ́n fẹ́ràn ẹni tó bá ń sọ òótọ́.+
16 Ó mà sàn kéèyàn ní ọgbọ́n ju kó ní wúrà o!+
Ó sì dára kéèyàn ní òye ju kó ní fàdákà.+
17 Láti yẹra fún ohun búburú ni ọ̀nà àwọn adúróṣinṣin.
Ẹni tó bá ń ṣọ́ ọ̀nà rẹ̀ ń dáàbò bo ẹ̀mí* rẹ̀.+
22 Ìjìnlẹ̀ òye jẹ́ kànga ìyè fún àwọn tó ni ín,
Àmọ́ ìwà ẹ̀gọ̀ àwọn òmùgọ̀ ló ń bá wọn wí.
29 Oníwà ipá máa ń tan ọmọnìkejì rẹ̀
Á sì kó o ṣìnà.
30 Bó ṣe ń ṣẹ́jú ló ń gbèrò ibi.
Ó fún ètè rẹ̀ pọ̀ bó ṣe ń ṣe iṣẹ́ ibi.
2 Ìránṣẹ́ tó ní ìjìnlẹ̀ òye yóò di ọ̀gá lórí ọmọ tó ń hùwà ìtìjú,
Yóò sì pín nínú ogún bí ọ̀kan lára àwọn ọmọ.
3 Ìkòkò tí wọ́n fi ń yọ́ nǹkan mọ́ wà fún fàdákà, iná ìléru sì wà fún wúrà,+
Àmọ́ Jèhófà ni olùṣàyẹ̀wò ọkàn.+
4 Ẹni burúkú máa ń fetí sí ọ̀rọ̀ tó ń dunni,
Ẹlẹ́tàn sì ń fetí sí ahọ́n tó ń bani jẹ́.+
5 Ẹni tó bá ń fi aláìní ṣẹ̀sín ń gan Ẹni tó dá a,+
Ẹni tó bá sì ń yọ̀ nítorí àjálù tó bá ẹlòmíì kò ní lọ láìjìyà.+
7 Ọ̀rọ̀ tí ó tọ́* kò yẹ òmùgọ̀.+
Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rọ̀ èké kò yẹ alákòóso!*+
8 Ẹ̀bùn dà bí òkúta iyebíye* lójú ẹni tó ni ín;+
Ibi gbogbo tí ẹni náà bá yíjú sí ni yóò ti mú kó máa ṣàṣeyọrí.+
9 Ẹni tó bá ń dárí ẹ̀ṣẹ̀ jini* ń wá ìfẹ́,+
Àmọ́ ẹni tó bá ń tẹnu mọ́ ọ̀rọ̀ ṣáá ń tú ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́ ká.+
11 Kìkì ọ̀tẹ̀ ni ẹni búburú máa ń wá,
Àmọ́ òjíṣẹ́ tó jẹ́ ìkà ni wọn yóò rán sí i láti fìyà jẹ ẹ́.+
12 Ó sàn kéèyàn pàdé bíárì tó ṣòfò ọmọ
Ju kéèyàn pàdé ẹni tó jẹ́ òmùgọ̀ nínú ìwà ẹ̀gọ̀ rẹ̀. +
13 Tí ẹnikẹ́ni bá ń fi búburú san rere,
Ohun búburú kò ní kúrò ní ilé rẹ̀.+
15 Ẹni tó bá dá ẹni burúkú láre àti ẹni tó dá olódodo lẹ́bi+
Àwọn méjèèjì jẹ́ ẹni ìkórìíra lójú Jèhófà.
18 Ẹni tí kò ní làákàyè* ló máa ń bọ ọwọ́, tí á sì tún gbà tọkàntọkàn
19 Ẹni tó bá fẹ́ràn ìjà fẹ́ràn ẹ̀ṣẹ̀.+
Ẹni tó bá mú kí àbáwọlé rẹ̀ ga sókè ń wá ìparun.+
21 Ẹni tó bá bí òmùgọ̀ ọmọ yóò ní ẹ̀dùn ọkàn;
Bàbá ọmọ tí kò nírònú kì í sì í láyọ̀.+
26 Kò dára láti fìyà jẹ* olódodo,
Kò sì tọ́ láti na àwọn èèyàn pàtàkì.
28 Kódà òmùgọ̀ tó bá dákẹ́, a ó kà á sí ọlọ́gbọ́n,
Ẹni tó bá sì pa ètè rẹ̀ dé, a ó kà á sí olóye.
2 Inú òmùgọ̀ kì í dùn sí òye;
Dípò bẹ́ẹ̀, ṣe ló máa ń tú ohun tó wà lọ́kàn rẹ̀ jáde.+
3 Nígbà tí ẹni burúkú bá dé, ìkórìíra náà á dé,
Ìtìjú ló sì máa ń bá àbùkù rìn.+
4 Ọ̀rọ̀ ẹnu èèyàn dà bí odò tó jìn.+
Orísun ọgbọ́n dà bí odò tó ń ṣàn.
10 Orúkọ Jèhófà jẹ́ ilé gogoro tó lágbára.+
Olódodo sá wọ inú rẹ̀, ó sì rí ààbò.*+
16 Ẹ̀bùn máa ń ṣí ọ̀nà sílẹ̀ fún ẹni tó fúnni;+
Ó ń jẹ́ kó dé ọ̀dọ̀ àwọn ẹni ńlá.
19 Ọmọ ìyá tí a ṣẹ̀, ó le ju ìlú olódi lọ,+
Àwọn ìjà kan sì wà tó dà bí ọ̀pá ìdábùú ẹnubodè ilé gogoro tó láàbò.+
20 Ọ̀rọ̀ ẹnu èèyàn máa ń fi ohun rere tẹ́ ikùn rẹ̀ lọ́rùn;+
Yóò rí ìtẹ́lọ́rùn nínú ohun tí ẹnu rẹ̀ sọ.
23 Aláìní máa ń bẹ̀bẹ̀ tó bá ń sọ̀rọ̀,
Àmọ́ ọlọ́rọ̀ máa ń dáhùn lọ́nà líle.
24 Àwọn ọ̀rẹ́ kan wà tí wọ́n ṣe tán láti ṣe ara wọn níkà,+
Àmọ́ ọ̀rẹ́ kan wà tó ń fà mọ́ni ju ọmọ ìyá lọ.+
3 Ìwà òmùgọ̀ èèyàn ló ń lọ́ ọ̀nà rẹ̀ po,
Tí ọkàn rẹ̀ fi ń bínú gidigidi sí Jèhófà.
4 Ọrọ̀ ń mú kéèyàn ní ọ̀rẹ́ púpọ̀,
Àmọ́ ọ̀rẹ́ tálákà pàápàá yóò fi í sílẹ̀.+
6 Ọ̀pọ̀ èèyàn ló ń wá ojú rere èèyàn pàtàkì,*
Gbogbo èèyàn ló sì ń bá ẹni tó ń fúnni lẹ́bùn ṣọ̀rẹ́.
Ó ń béèrè nǹkan lọ́wọ́ wọn ṣáá, àmọ́ kò sẹ́ni tó dá a lóhùn.
8 Ẹni tó ní làákàyè* fẹ́ràn ara* rẹ̀.+
Ẹni tó fi òye ṣe ìṣúra yóò ṣàṣeyọrí.*+
9 Ẹlẹ́rìí èké kò ní lọ láìjìyà,
Ẹni tí kò sì lè ṣe kó má parọ́ yóò ṣègbé.+
10 Kò yẹ kí òmùgọ̀ máa gbé ìgbé ayé gbẹdẹmukẹ;
Ká má ṣẹ̀ṣẹ̀ wá sọ pé kí ìránṣẹ́ máa ṣe olórí àwọn ìjòyè!+
14 Ọ̀dọ̀ àwọn baba ni a ti ń jogún ilé àti ọrọ̀,
Àmọ́ ọ̀dọ̀ Jèhófà ni aya olóye ti ń wá.+
19 Onínúfùfù yóò jìyà ìwà rẹ̀;
Tí o bá gbà á sílẹ̀, wàá tún ní láti ṣe bẹ́ẹ̀ léraléra.+
22 Ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ ni ẹwà èèyàn;+
Ó sì sàn kéèyàn jẹ́ aláìní ju kí ó jẹ́ òpùrọ́.
24 Ọ̀lẹ ki ọwọ́ rẹ̀ bọ inú abọ́ oúnjẹ,
Àmọ́ kò wulẹ̀ janpata láti gbé e pa dà sí ẹnu.+
26 Ẹni tó ṣe àìdáa sí bàbá rẹ̀ tó sì lé ìyá rẹ̀ lọ
Jẹ́ ọmọ tó ń fa ìtìjú àti àbùkù.+
27 Ọmọ mi, tí o bá ṣíwọ́ fífi etí sí ìbáwí,
Wàá yà kúrò ní ọ̀nà ìmọ̀.
2 Ẹ̀rù* tó wà lára ọba dà bí ìgbà tí kìnnìún* bá ń kùn;+
Ẹnikẹ́ni tó bá mú un bínú ń fi ẹ̀mí ara rẹ̀ wewu.+
6 Ọ̀pọ̀ èèyàn ló ń sọ pé àwọn ní ìfẹ́ tí kì í yẹ̀,
Àmọ́ ibo la ti lè rí olóòótọ́ èèyàn?
7 Olódodo ń rìn nínú ìwà títọ́ rẹ̀.+
Aláyọ̀ ni àwọn ọmọ* tó ń bọ̀ lẹ́yìn rẹ̀.+
8 Nígbà tí ọba bá jókòó sórí ìtẹ́ láti dájọ́,+
Ó máa ń fi ojú rẹ̀ yẹ ọ̀ràn wò kí ó lè mú gbogbo ìwà ibi kúrò.+
12 Etí tí a fi ń gbọ́ràn àti ojú tí a fi ń ríran
Jèhófà ló dá àwọn méjèèjì.+
13 Má ṣe nífẹ̀ẹ́ oorun, torí wàá di aláìní.+
La ojú rẹ, wàá sì máa jẹ àjẹtẹ́rùn.+
14 “Èyí ò dáa, tọ̀hún ò dáa!” ni ẹni tó ń rajà ń sọ;
Lẹ́yìn náà, ó bá tirẹ̀ lọ, ó sì ń yangàn.+
16 Gba ẹ̀wù ẹni tó bá ṣe onídùúró fún àjèjì;+
Tó bá sì jẹ́ pé obìnrin àjèjì* ló ṣe é fún, gba ohun tó fi ṣe ìdúró lọ́wọ́ rẹ̀.+
17 Oúnjẹ tí a fi èrú kó jọ máa ń dùn lẹ́nu èèyàn,
Àmọ́ tó bá yá, òkúta ni yóò kún ẹnu rẹ̀.+
18 Ìmọ̀ràn* máa ń jẹ́ kí ohun téèyàn fẹ́ ṣe yọrí sí rere,*+
Ìtọ́sọ́nà ọlọgbọ́n sì ni kí o fi ja ogun rẹ.+
20 Ẹni tó bá bú bàbá àti ìyá rẹ̀,
Fìtílà rẹ̀ yóò kú nígbà tí òkùnkùn bá ṣú.+
21 Ogún téèyàn bá fi ojúkòkòrò gbà níbẹ̀rẹ̀
Kì í ní ìbùkún lẹ́yìn-ọ̀-rẹyìn.+
22 Má ṣe sọ pé: “Màá fi búburú san búburú!”+
Ní ìrètí nínú Jèhófà,+ yóò sì gbà ọ́ là.+
23 Jèhófà kórìíra ìwọ̀n èké,*
Òṣùwọ̀n èké kò sì dára.
25 Ìdẹkùn ni téèyàn bá sọ láìronú pé, “Mímọ́!”+
Lẹ́yìn náà, kó ṣẹ̀ṣẹ̀ máa ronú lórí ẹ̀jẹ́ tó jẹ́.+
27 Èémí èèyàn jẹ́ fìtílà Jèhófà,
Ó ń ṣàyẹ̀wò inú rẹ̀ lọ́hùn-ún.
21 Ọkàn ọba dà bí odò ní ọwọ́ Jèhófà.+
Ibi tí Ó bá fẹ́ ló ń darí rẹ̀ sí.+
3 Kí èèyàn ṣe ohun tó dára tí ó sì tọ́
Máa ń mú inú Jèhófà dùn ju ẹbọ lọ.+
4 Ojú ìgbéraga àti ọkàn gíga
Ni fìtílà tó ń darí àwọn ẹni burúkú, ẹ̀ṣẹ̀ sì ni.+
5 Àwọn ohun tí òṣìṣẹ́ kára gbèrò láti ṣe máa ń yọrí sí rere,*+
Àmọ́ ó dájú pé gbogbo àwọn tó bá ń kánjú yóò di aláìní.+
7 Ìwà ipá àwọn ẹni burúkú yóò gbá wọn dà nù,+
Torí wọ́n kọ̀ láti ṣe ohun tí ó tọ́.
8 Ọ̀nà ẹlẹ́bi kì í gún,
Àmọ́ iṣẹ́ aláìlẹ́bi máa ń tọ́.+
11 Nígbà tí wọ́n bá fìyà jẹ afiniṣẹ̀sín, aláìmọ̀kan á kọ́gbọ́n,
12 Ọlọ́run Olódodo máa ń kíyè sí ilé ẹni burúkú;
Ó ń dojú àwọn ẹni burúkú dé kí wọ́n lè pa run.+
14 Ẹ̀bùn tí a fúnni ní ìkọ̀kọ̀ ń mú ìbínú rọlẹ̀,+
Àbẹ̀tẹ́lẹ̀ tí a sì fúnni ní bòókẹ́lẹ́* ń mú ìbínú gbígbóná rọlẹ̀.
15 Inú olódodo máa ń dùn láti ṣe ohun tó bá ẹ̀tọ́ mu,+
Àmọ́ ó ṣòro gan-an fún àwọn tó ń hùwà burúkú.
18 Ẹni burúkú ni ìràpadà fún olódodo,
A ó sì mú oníbékebèke dípò adúróṣinṣin.+
20 Ìṣúra tó ṣeyebíye àti òróró máa ń wà ní ilé ọlọ́gbọ́n,+
24 Agbéraga tó ń fọ́nnu tó sì ń kọjá àyè rẹ̀
Là ń pe ẹni tó ń fi wàdùwàdù ṣe nǹkan láìbìkítà.+
25 Ohun tó ń wu ọ̀lẹ ló máa pa á,
Nítorí pé ọwọ́ rẹ̀ kọ̀ láti ṣiṣẹ́.+
26 Àtàárọ̀ ṣúlẹ̀ ló ń ṣojúkòkòrò,
Àmọ́ olódodo ń fúnni láìfawọ́ nǹkan kan sẹ́yìn.+
27 Ẹbọ ẹni burúkú jẹ́ ohun ìríra.+
Ká má ṣẹ̀ṣẹ̀ wá sọ pé kó mú un wá pẹ̀lú èrò ibi!*
30 Kò sí ọgbọ́n tàbí òye tàbí ìmọ̀ràn tó lòdì sí Jèhófà tó lè dúró.+
2 Ohun tí ọlọ́rọ̀ àti aláìní fi jọra* ni pé:
Jèhófà ló dá àwọn méjèèjì.+
4 Èrè ìrẹ̀lẹ̀ àti ìbẹ̀rù Jèhófà
Ni ọrọ̀ àti ògo àti ìyè.+
12 Ojú Jèhófà ń ṣọ́ ìmọ̀,
Àmọ́ Ó ń dojú ọ̀rọ̀ oníbékebèke dé.+
13 Ọ̀lẹ ń sọ pé: “Kìnnìún wà níta!
Àárín gbàgede ìlú ló máa pa mí sí!”+
14 Kòtò jíjìn ni ẹnu obìnrin oníwàkiwà.*+
Ẹni tí Jèhófà dá lẹ́bi yóò já sínú rẹ̀.
17 Fetí sílẹ̀ kí o sì gbọ́ àwọn ọ̀rọ̀ ọlọgbọ́n,+
Kí o lè fi ọkàn rẹ sí ìmọ̀ mi,+
18 Nítorí ó dára pé kí o pa wọ́n mọ́ sínú ọkàn rẹ,+
Kí gbogbo wọn lè máa wà ní ètè rẹ nígbà gbogbo.+
19 Kí o lè gbẹ́kẹ̀ lé Jèhófà
Ni mo ṣe ń fún ọ ní ìmọ̀ lónìí.
20 Ǹjẹ́ mi ò ti kọ̀wé sí ọ,
Láti fún ọ ní ìmọ̀ràn àti ìmọ̀,
21 Láti kọ́ ọ ní ọ̀rọ̀ tó jẹ́ òótọ́ tó sì ṣe é gbára lé,
Kí o lè pa dà lọ jẹ́ iṣẹ́ tó péye fún ẹni tó rán ọ?
22 Má ja tálákà lólè torí pé kò ní lọ́wọ́,+
Má sì fojú aláìní gbolẹ̀ ní ẹnubodè,+
23 Nítorí Jèhófà fúnra rẹ̀ yóò gba ẹjọ́ wọn rò+
Yóò sì gba ẹ̀mí* àwọn tó lù wọ́n ní jìbìtì.
24 Má ṣe bá onínúfùfù kẹ́gbẹ́,
Má sì bá ẹni tó máa ń tètè bínú da nǹkan pọ̀,
25 Kí o má bàa kọ́ àwọn ọ̀nà rẹ̀,
26 Má ṣe wà lára àwọn tó ń bọ ọwọ́ nínú ẹ̀jẹ́,
Tí wọ́n ń ṣe onídùúró fún ẹni tó ń yá owó.+
27 Tí o kò bá rí i san,
Wọ́n á gba ibùsùn rẹ kúrò lábẹ́ rẹ!
28 Má ṣe sún ààlà àtọjọ́mọ́jọ́ sẹ́yìn
Èyí tí àwọn baba ńlá rẹ pa.+
29 Ǹjẹ́ o ti rí ọkùnrin tó já fáfá lẹ́nu iṣẹ́ rẹ̀?
Yóò dúró níwájú àwọn ọba;+
Kò ní dúró níwájú àwọn èèyàn yẹpẹrẹ.
23 Nígbà tí o bá jókòó láti bá ọba jẹun,
Fara balẹ̀ kíyè sí ohun tó wà níwájú rẹ;
2 Fi ọ̀bẹ sí ara rẹ lọ́fun*
Tó bá jẹ́ pé oúnjẹ púpọ̀ lo máa ń jẹ.*
3 Má ṣe jẹ́ kí oúnjẹ aládùn rẹ̀ wọ̀ ọ́ lójú,
Torí oúnjẹ ẹ̀tàn ni.
4 Má fi wàhálà pa ara rẹ torí kí o lè kó ọrọ̀ jọ.+
Fara balẹ̀ kí o sì lo òye.*
5 Nígbà tí o bá bojú wò ó, kò ní sí níbẹ̀,+
Torí ó dájú pé ó máa hu ìyẹ́ bí ẹyẹ idì, á sì fò lọ sójú ọ̀run.+
6 Má ṣe jẹ oúnjẹ ẹni tó ń ṣahun;*
Má ṣe jẹ́ kí oúnjẹ aládùn rẹ̀ wọ̀ ọ́ lójú.
7 Nítorí ó dà bí ẹni tó ń ṣe àkọsílẹ̀.*
Ó ń sọ fún ọ pé, “máa jẹ, máa mu,” àmọ́ kò dénú rẹ̀.*
8 Wàá pọ àwọn òkèlè tí o ti gbé mì
Àwọn ọ̀rọ̀ ti o fi yìn ín á sì di àsọdànù.
10 Má ṣe sún ààlà àtọjọ́mọ́jọ́ sẹ́yìn,+
Má sì wọnú ilẹ̀ àwọn aláìníbaba.
12 Fi ọkàn sí ìbáwí
Kí o sì fetí sí àwọn ọ̀rọ̀ ìmọ̀.
13 Má fawọ́ ìbáwí sẹ́yìn fún ọmọdé.*+
Tí o bá fi ọ̀pá nà án, kò ní kú.
17 Kí ọkàn rẹ má ṣe jowú àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀,+
Àmọ́ kí o máa bẹ̀rù Jèhófà láti àárọ̀ ṣúlẹ̀,+
18 Ìgbà náà ni ọjọ́ ọ̀la rẹ á dára+
Ìrètí rẹ kò sì ní pa rẹ́.
19 Fetí sílẹ̀, ọmọ mi, kí o sì gbọ́n,
Darí ọkàn rẹ lọ́nà tí ó tọ́.
20 Má ṣe wà lára àwọn tó ń mu wáìnì lámujù,+
Tàbí àwọn tó ń jẹ ẹran ní àjẹkì,+
21 Nítorí ọ̀mùtí àti alájẹkì yóò di òtòṣì,+
Ìtòògbé yóò sì sọni di alákìísà.
24 Bàbá olódodo yóò máa láyọ̀;
Ẹni tó bá sì bí ọlọ́gbọ́n ọmọ yóò yọ̀.
25 Bàbá rẹ àti ìyá rẹ yóò máa yọ̀,
Inú ìyá tó bí ọ yóò sì máa dùn.
26 Ọmọ mi, fi ọkàn rẹ fún mi,
Kí ojú rẹ sì fẹ́ràn àwọn ọ̀nà mi.+
28 Ó máa ń lúgọ deni bí ọlọ́ṣà;+
Ó ń mú kí àwọn ọkùnrin aláìṣòótọ́ pọ̀ sí i.
29 Ta ló ni ìyà? Ta ló ni àìnírọ̀rùn?
Ta ló ni ìjà? Ta ló ni àròyé?
Ta ló ni ọgbẹ́ láìnídìí? Ta ló ni ojú tó ń ṣe bàìbàì?*
31 Má ṣe wo àwọ̀ pupa wáìnì
Bó ṣe ń ta wíríwírí nínú ife, tó sì ń lọ tìnrín,
32 Torí níkẹyìn, á buni ṣán bí ejò,
Á sì tu oró jáde bíi paramọ́lẹ̀.
34 Wàá dà bí ẹni tó dùbúlẹ̀ sí àárín òkun,
Bí ẹni tó dùbúlẹ̀ sí orí òpó ọkọ̀ òkun.
35 Wàá sọ pé: “Wọ́n lù mí, àmọ́ mi ò mọ̀ ọ́n lára.*
Wọ́n nà mí, àmọ́ mi ò mọ̀.
Ìgbà wo ni màá jí?+
Ẹ fún mi lọ́tí sí i.”*
24 Má ṣe jowú àwọn ẹni ibi,
Má sì jẹ́ kó máa wù ọ́ láti bá wọn kẹ́gbẹ́,+
2 Nítorí ìwà ipá ni ọkàn wọn ń rò,
Ètè wọn sì ń sọ̀rọ̀ ìjàngbọ̀n.
5 Ẹni tó gbọ́n jẹ́ alágbára,+
Ìmọ̀ sì ni èèyàn fi ń mú kí agbára rẹ̀ pọ̀ sí i.
8 Ẹnikẹ́ni tó bá ń gbèrò ibi,
Ọ̀gá elétekéte la ó máa pè é.+
11 Gba àwọn tí wọ́n fẹ́ lọ pa sílẹ̀,
Sì fa àwọn tó ń ta gọ̀ọ́gọ̀ọ́ lọ sí ibi pípa sẹ́yìn.+
13 Ọmọ mi, jẹ oyin, nítorí ó dára;
Oyin inú afárá sì ń dùn lẹ́nu.
14 Lọ́nà kan náà, mọ̀ pé ọgbọ́n dára fún ọ.*+
Tí o bá wá a rí, ọjọ́ ọ̀la rẹ á dára
Ìrètí rẹ kò sì ní pa rẹ́.+
15 Má ṣe lúgọ sí tòsí ilé olódodo láti ṣe é níbi;
Má ṣe ba ibi ìsinmi rẹ̀ jẹ́.
16 Nítorí olódodo lè ṣubú ní ìgbà méje, á sì tún dìde,+
Àmọ́ àjálù yóò mú kí ẹni burúkú ṣubú pátápátá.+
17 Tí ọ̀tá rẹ bá ṣubú, má ṣe dunnú,
Tó bá sì kọsẹ̀, má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ yọ̀;+
18 Nítorí Jèhófà yóò rí i, á sì bí i nínú,
19 Má ṣe kanra* nítorí àwọn aṣebi;
Má ṣe jowú àwọn ẹni ibi.
21 Ọmọ mi, bẹ̀rù Jèhófà àti ọba.+
Má sì bá àwọn oníyapa* kẹ́gbẹ́.+
22 Nítorí àjálù wọn yóò dé lójijì.+
Ta ló mọ ìparun tí àwọn méjèèjì* máa mú bá wọn?+
23 Ọ̀rọ̀ wọ̀nyí tún jẹ́ ti àwọn ọlọ́gbọ́n:
Kò dára láti máa ṣe ojúsàájú nínú ìdájọ́.+
24 Ẹni tó bá ń sọ fún ẹni burúkú pé, “Olódodo ni ọ́,”+
Àwọn èèyàn yóò gégùn-ún fún un, àwọn orílẹ̀-èdè yóò sì dá a lẹ́bi.
26 Àwọn èèyàn yóò fi ẹnu ko ètè ẹni tó ń fi òótọ́ inú fèsì.*+
27 Múra iṣẹ́ tí o máa ṣe lóde sílẹ̀, kí o sì wá gbogbo nǹkan sílẹ̀ ní pápá;
Lẹ́yìn náà, kọ́ ilé* rẹ.
28 Má ṣe ta ko ọmọnìkejì rẹ láìnídìí.+
Má ṣe fi ètè rẹ tanni jẹ.+
32 Mo kíyè sí i, mo sì fi í sọ́kàn;
Mo rí i, mo sì kọ́ ẹ̀kọ́* yìí:
33 Oorun díẹ̀, ìtòògbé díẹ̀,
Kíkáwọ́ gbera díẹ̀ láti sinmi,
34 Ipò òṣì rẹ yóò sì dé bí olè,
Àti àìní rẹ bí ọkùnrin tó dìhámọ́ra.+
25 Àwọn òwe míì tí Sólómọ́nì pa,+ èyí tí àwọn ọkùnrin Hẹsikáyà+ ọba Júdà dà kọ* nìyí:
3 Bí ọ̀run ṣe ga, tí ilẹ̀ sì jìn,
Bẹ́ẹ̀ ni ọkàn àwọn ọba jẹ́ ohun àwámáridìí.
4 Yọ́ ìdàrọ́ kúrò lára fàdákà,
Á sì mọ́ pátápátá.+
5 Mú ẹni burúkú kúrò níwájú ọba,
Ìtẹ́ rẹ̀ yóò sì fìdí múlẹ̀ gbọn-in nínú òdodo.+
6 Má bọlá fún ara rẹ níwájú ọba,+
Má sì jókòó ní àyè àwọn ẹni ńlá,+
7 Nítorí ó sàn kó sọ fún ọ pé, “Máa bọ̀ níbí,”
Ju pé kó kàn ọ́ lábùkù níwájú àwọn èèyàn pàtàkì.+
8 Má fi ìkánjú gbé ọ̀rọ̀ lọ sílé ẹjọ́,
Àbí kí lo máa ṣe tí ọmọnìkejì rẹ bá kàn ọ́ lábùkù?+
9 Ro ẹjọ́ rẹ pẹ̀lú ọmọnìkejì rẹ,+
Àmọ́ má sọ ọ̀rọ̀ àṣírí tí o gbọ́,*+
10 Kí ẹni tó ń fetí sílẹ̀ má bàa kó ìtìjú bá ọ,
Ọ̀rọ̀ burúkú* tí o tàn kálẹ̀ kò sì ní ṣeé kó pa dà.
12 Bíi yẹtí wúrà àti ohun ọ̀ṣọ́ tí wọ́n fi wúrà tó dára ṣe
Ni ọlọ́gbọ́n tó ń báni wí jẹ́ ní etí ẹni tó ń gbọ́ràn.+
13 Bí ìtutù yìnyín ní ọjọ́ ìkórè
Ni òjíṣẹ́ olóòótọ́ jẹ́ fún àwọn tó rán an,
14 Bí òjò tó ṣú, tó sì ń fẹ́ atẹ́gùn àmọ́ tí kò rọ̀
16 Tí o bá rí oyin, èyí tí o nílò nìkan ni kí o jẹ,
Torí tí o bá jẹ ẹ́ ní àjẹjù, o lè bì í.+
17 Má ṣe jẹ́ kí ẹsẹ̀ rẹ ṣe lemọ́lemọ́ ní ilé ọmọnìkejì rẹ,
Kí ọ̀rọ̀ rẹ má bàa sú u, kó sì kórìíra rẹ.
18 Bíi kùmọ̀ ogun àti idà àti ọfà tó mú
Ni ẹni tó ń jẹ́rìí èké sí ọmọnìkejì rẹ̀.+
19 Bí eyín tó ká tàbí ẹsẹ̀ tó ń gbò yèpéyèpé
Ni ìgbọ́kànlé téèyàn ní nínú ẹni tí kò ṣe é fọkàn tán* lásìkò wàhálà.
20 Bí ẹni tó bọ́ aṣọ lọ́jọ́ òtútù
Àti bí ọtí kíkan tí wọ́n dà sórí sódà*
Ni ẹni tó ń kọrin fún ọkàn tí ìbànújẹ́ bá.+
21 Tí ebi bá ń pa ọ̀tá rẹ,* fún un ní oúnjẹ jẹ;
Tí òùngbẹ bá sì ń gbẹ ẹ́, fún un ní omi mu,+
22 Torí ṣe ni wàá máa kó ẹyin iná jọ lé e lórí,*+
Jèhófà yóò sì san èrè fún ọ.
23 Ẹ̀fúùfù láti àríwá ń mú kí òjò rọ̀,
Ahọ́n tó ń ṣòfófó sì ń mú kí ojú fà ro.+
26 Bí ìsun omi tó rú àti kànga tó ti bà jẹ́
Ni olódodo tó gbà fún* ẹni burúkú.
26 Bíi yìnyín nígbà ẹ̀ẹ̀rùn àti òjò nígbà ìkórè,
Bẹ́ẹ̀ ni ògo kò yẹ òmùgọ̀.+
2 Bí ẹyẹ kì í ṣeé fò láìnídìí, tí alápàáǹdẹ̀dẹ̀ kì í sì í ṣàdédé fò,
Bẹ́ẹ̀ ni ègún kì í dédé wá láìsí ìdí kan pàtó.*
4 Má ṣe fún òmùgọ̀ lésì gẹ́gẹ́ bí ìwà ẹ̀gọ̀ rẹ̀,
Kí o má bàa fi ara rẹ sí ipò rẹ̀.*
5 Fún òmùgọ̀ lésì gẹ́gẹ́ bí ìwà òmùgọ̀ rẹ̀,
Kó má bàa rò pé òun gbọ́n.+
6 Bí ẹni tó dá ara rẹ̀ lẹ́sẹ̀, tó sì ṣe ara rẹ̀ léṣe*
Ni ẹni tó fa ọ̀ràn lé òmùgọ̀ lọ́wọ́.
8 Bí ẹni ń so òkúta mọ́ kànnàkànnà
Ni téèyàn bá ń fi ògo fún òmùgọ̀.+
9 Bíi koríko ẹlẹ́gùn-ún tó dé ọwọ́ ọ̀mùtí,
Bẹ́ẹ̀ ni òwe rí lẹ́nu àwọn òmùgọ̀.
10 Bíi tafàtafà tó ń ṣe ohun tó bá ṣáà ti rí léṣe,*
Ni ẹni tó gbéṣẹ́ fún òmùgọ̀ tàbí àwọn tó ń kọjá lọ.
11 Bí ajá tó pa dà sídìí èébì rẹ̀,
Bẹ́ẹ̀ ni òmùgọ̀ ṣe ń tún ìwà ẹ̀gọ̀ rẹ̀ hù.+
12 Ṣe o ti rí ẹni tó rò pé òun gbọ́n?+
Ìrètí wà fún òmùgọ̀ jù ú lọ.
13 Ọ̀lẹ ń sọ pé: “Ọmọ kìnnìún wà lójú ọ̀nà,
Kìnnìún wà ní gbàgede ìlú!”+
16 Ọ̀lẹ rò pé òun gbọ́n
Ju àwọn méje tó lè fèsì tó mọ́gbọ́n dání.
18 Bíi wèrè tó ń ta ohun ọṣẹ́ oníná, ọfà àti ikú*
19 Ni ẹni tó tan ọmọnìkejì rẹ̀ jẹ, tó wá sọ pé, “Eré ni mò ń ṣe!”+
20 Níbi tí kò bá sí igi, iná á kú,
Níbi tí kò bá sì sí abanijẹ́, ìjà á tán.+
21 Bí èédú ṣe wà fún ẹyin iná, tí igi sì wà fún iná,
Bẹ́ẹ̀ ni alárìíyànjiyàn ṣe máa ń dá ìjà sílẹ̀.+
24 Ẹni tó kórìíra ẹlòmíì máa ń fi ọ̀rọ̀ ẹnu bò ó mọ́lẹ̀,
Àmọ́ ẹ̀tàn ló fi sínú.
25 Bó tilẹ̀ ń sọ ohun rere, má gbà á gbọ́,
Nítorí ohun ìríra méje ló wà lọ́kàn rẹ̀.*
26 Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ó fi ẹ̀tàn bo ìkórìíra rẹ̀ mọ́lẹ̀,
A ó tú ìwà burúkú rẹ̀ síta nínú ìjọ.
27 Ẹni tó gbẹ́ kòtò yóò já sínú rẹ̀,
Ẹni tó bá sì yí òkúta kúrò, òkúta náà yóò pa dà sórí rẹ̀.+
28 Ẹni tó ní ahọ́n èké kórìíra àwọn tó fi ń bà jẹ́,
Ẹnu tó ń pọ́nni sì ń fa ìparun.+
3 Òkúta wúwo, iyanrìn sì tẹ̀wọ̀n,
Àmọ́ ìbínú tí òmùgọ̀ máa ń fà wúwo ju àwọn méjèèjì lọ.+
4 Ìrunú jẹ́ ìwà ìkà, ìbínú sì dà bí àkúnya omi,
Àmọ́ ta ló lè dúró níwájú owú?+
5 Ìbáwí tí a fúnni níta sàn ju ìfẹ́ tí a fi pa mọ́ lọ.+
7 Ẹni* tó bá ti yó kì í ka oyin inú afárá sí,*
Àmọ́ ní ti ẹni* tí ebi ń pa, ohun tó korò pàápàá á dùn lẹ́nu rẹ̀.
8 Bí ẹyẹ tó ṣìnà* ìtẹ́ rẹ̀
Ni ẹni tó ṣìnà ilé rẹ̀ rí.
9 Òróró àti tùràrí máa ń mú ọkàn yọ̀;
Bẹ́ẹ̀ ni adùn ọ̀rẹ́ máa ń wá látinú ìmọ̀ràn àtọkànwá.+
10 Má fi ọ̀rẹ́ rẹ tàbí ọ̀rẹ́ bàbá rẹ sílẹ̀,
Má sì wọ ilé ọmọ ìyá rẹ ní ọjọ́ àjálù rẹ;
Aládùúgbò tó wà nítòsí sàn ju ọmọ ìyá tó jìnnà réré.+
13 Gba ẹ̀wù ẹni tó bá ṣe onídùúró fún àjèjì;
Tó bá sì jẹ́ pé obìnrin àjèjì* ló ṣe é fún, gba ohun tó fi ṣe ìdúró lọ́wọ́ rẹ̀.+
14 Tí ẹnì kan bá ń fi ohùn tó ròkè súre fún ọmọnìkejì rẹ̀ láàárọ̀ kùtù,
Ńṣe ni àwọn èèyàn máa sọ pé ó ń gégùn-ún.
15 Aya tó jẹ́ oníjà* dà bí òrùlé tó ń jò ṣùrùṣùrù lọ́jọ́ tí òjò ń rọ̀.+
16 Ẹni tó bá lè kápá rẹ̀ lè kápá ẹ̀fúùfù,
Á sì lè fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ di òróró mú.
19 Bí omi ṣe ń fi ìrísí ojú hàn,
Bẹ́ẹ̀ ni ọkàn èèyàn ń fi ti ẹlòmíì hàn.
21 Bí ìkòkò tí wọ́n fi ń yọ́ nǹkan mọ́ ṣe wà fún fàdákà, tí iná ìléru sì wà fún wúrà,+
Bẹ́ẹ̀ ni ìyìn tí ẹnì kan gbà ṣe ń dán an wò.*
22 Kódà tí o bá fi ọmọ odó gún òmùgọ̀
Bí ọkà tí a ti pa nínú odó,
Ìwà ẹ̀gọ̀ rẹ̀ kò ní fi í sílẹ̀.
23 Ó yẹ kí o mọ bí agbo ẹran rẹ ṣe rí ní àmọ̀dunjú.
Tọ́jú* àwọn àgùntàn rẹ dáadáa,+
24 Nítorí ọrọ̀ kì í wà títí láé,+
Bẹ́ẹ̀ ni adé* kì í wà jálẹ̀ gbogbo ìran.
25 Bí koríko tútù ṣe ń pa rẹ́, tí koríko tuntun ń fara hàn,
Bẹ́ẹ̀ ni à ń kó àwọn ewéko orí òkè wálé.
26 Àwọn ọmọ àgbò ń pèsè aṣọ rẹ,
Àwọn òbúkọ sì ń pèsè owó pápá.
27 Wàrà ewúrẹ́ tí ó pọ̀ tó yóò sì wà láti bọ́ ìwọ
Àti agbo ilé rẹ àti láti gbé ẹ̀mí àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ ró.
2 Tí ẹ̀ṣẹ̀* bá wà ní ilẹ̀ kan, olórí ibẹ̀ kì í pẹ́ kí òmíì tó jẹ,+
Àmọ́ nípasẹ̀ ẹnì kan tó ní òye àti ìmọ̀, olórí* yóò pẹ́ lórí ìtẹ́.+
3 Tálákà tó ń lu aláìní ní jìbìtì,+
Ó dà bí òjò tó ń gbá gbogbo oúnjẹ lọ.
4 Àwọn tó ń pa òfin tì máa ń yin àwọn ẹni burúkú,
Àmọ́ àwọn tó ń pa òfin mọ́ máa ń bínú sí wọn.+
6 Aláìní tó ń rìn nínú ìwà títọ́
Sàn ju olówó tí ọ̀nà rẹ̀ wọ́ lọ.+
7 Ọmọ tó lóye máa ń pa òfin mọ́,
Àmọ́ ẹni tó ń bá àwọn alájẹkì kẹ́gbẹ́ ń dójú ti bàbá rẹ̀.+
10 Ẹni tó bá ń ṣi adúróṣinṣin lọ́nà láti ṣe búburú máa já sínú kòtò òun fúnra rẹ̀,+
Àmọ́ àwọn aláìlẹ́bi máa jogún ohun rere.+
12 Nígbà tí olódodo bá borí, ìdùnnú á ṣubú layọ̀,
Àmọ́ nígbà tí agbára bá dọ́wọ́ ẹni burúkú, àwọn èèyàn á lọ fara pa mọ́.+
13 Ẹni tó bá ń bo àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ kò ní ṣàṣeyọrí,+
Àmọ́ ẹni tó bá jẹ́wọ́, tó sì fi wọ́n sílẹ̀ la ó fi àánú hàn sí.+
14 Aláyọ̀ ni ẹni tó bá ń kíyè sára* nígbà gbogbo,
Àmọ́ ẹni tó bá ń sé ọkàn rẹ̀ le yóò ṣubú sínú ìyọnu.+
15 Bíi kìnnìún tó ń kùn àti bíárì tó ń kù gììrì mọ́ nǹkan
Ni ìkà èèyàn tó ń ṣàkóso àwọn tí kò ní olùrànlọ́wọ́.+
16 Aṣáájú tí kò lóye máa ń ṣi agbára lò,+
Àmọ́ ẹni tó kórìíra èrè tí kò tọ́ yóò mú ẹ̀mí ara rẹ̀ gùn.+
17 Ẹni tí ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ bá wọ̀ lọ́rùn torí pé ó gba ẹ̀mí èèyàn* yóò máa sá títí á fi wọnú sàréè.*+
Kí ẹnì kankan má ṣe dì í mú.
19 Ẹni tó bá ń ro ilẹ̀ rẹ̀ yóò ní oúnjẹ tó pọ̀,
Àmọ́ ẹni tó ń lé àwọn ohun tí kò ní láárí yóò di òtòṣì paraku.+
21 Kò dáa kéèyàn máa ṣe ojúsàájú;+
Àmọ́ èèyàn lè ṣe ohun tí kò tọ́ nítorí búrẹ́dì tí kò tó nǹkan.
22 Onílara* èèyàn ń wá bó ṣe máa di olówó,
Kò mọ̀ pé òṣì máa ta òun.
24 Ẹni tó bá ja bàbá àti ìyá rẹ̀ lólè tó sì ń sọ pé, “Kò sóhun tó burú níbẹ̀,”+
Ẹlẹgbẹ́ ẹni tó ń fa ìparun ni.+
27 Ẹni tó bá ń fún aláìní ní nǹkan kò ní ṣaláìní,+
Àmọ́ ẹni tó bá ń gbójú kúrò lára wọn yóò gba ọ̀pọ̀ ègún.
28 Nígbà tí agbára bá dọ́wọ́ àwọn ẹni burúkú, àwọn èèyàn á fara pa mọ́,
Àmọ́ nígbà tí wọ́n bá ṣègbé, olódodo á pọ̀ sí i.+
2 Nígbà tí olódodo bá pọ̀, àwọn èèyàn á máa yọ̀,
Àmọ́ tí ẹni burúkú bá ń ṣàkóso, àwọn èèyàn á máa kérora.+
4 Ìdájọ́ òdodo ni ọba fi ń mú kí ilẹ̀ rẹ̀ tòrò,+
Àmọ́ ẹni tó ń gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ yóò da ibẹ̀ rú.
5 Ẹni tó ń pọ́n ọmọnìkejì rẹ̀
Ń ta àwọ̀n fún ẹsẹ̀ rẹ̀.+
9 Nígbà tí ọlọ́gbọ́n bá ń bá òmùgọ̀ fa ọ̀rọ̀,
Ariwo àti yẹ̀yẹ́ á gbòde kan, síbẹ̀ kò ní sí ìsinmi.+
12 Tí alákòóso bá ti ń fetí sí irọ́,
Gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò di ẹni burúkú.+
13 Ohun tí aláìní àti aninilára fi jọra* ni pé:
Jèhófà ń tan ìmọ́lẹ̀ sí ojú àwọn méjèèjì.*
16 Tí àwọn ẹni burúkú bá ti ń pọ̀ sí i, ẹ̀ṣẹ̀ á máa pọ̀ sí i,
Àmọ́ àwọn olódodo yóò rí ìṣubú wọn.+
18 Níbi tí kò bá ti sí ìran,* àwọn èèyàn á máa ṣe bó ṣe wù wọ́n,+
Àmọ́ aláyọ̀ ni àwọn tó ń pa òfin mọ́.+
19 Ìránṣẹ́ kì í jẹ́ kí wọ́n fi ọ̀rọ̀ ẹnu tọ́ òun sọ́nà,
Bó tiẹ̀ yé e, kò ní ṣègbọràn.+
20 Ṣé o ti rí ẹni tí kì í ronú kó tó sọ̀rọ̀?+
Ìrètí wà fún òmùgọ̀ ju fún irú ẹni bẹ́ẹ̀ lọ.+
21 Tí a bá kẹ́ ìránṣẹ́ kan ní àkẹ́jù látìgbà èwe rẹ̀,
Tó bá yá, kò ní mọ ọpẹ́ dá.
24 Ẹni tó ń bá olè kẹ́gbẹ́ kórìíra ara rẹ̀.*
Ó lè gbọ́ pé kí àwọn èèyàn wá jẹ́rìí,* àmọ́ kò ní sọ nǹkan kan.+
27 Aláìṣòótọ́ jẹ́ ẹni ìkórìíra lójú olódodo,+
Ẹni tí ọ̀nà rẹ̀ tọ́ sì jẹ́ ẹni ìkórìíra lójú èèyàn burúkú.+
30 Àwọn ohun pàtàkì tó wà nínú ọ̀rọ̀ tí Ágúrì ọmọ Jákè sọ fún Ítíélì, ìyẹn fún Ítíélì àti Úkálì.
2 Mo jẹ́ aláìmọ̀kan ju ẹnikẹ́ni lọ,+
Mi ò sì ní òye tó yẹ kí èèyàn ní.
3 Mi ò tíì kọ́ ọgbọ́n,
Mi ò sì tíì ní ìmọ̀ Ẹni Mímọ́ Jù Lọ.
4 Ta ló ti gòkè lọ sí ọ̀run tó sì sọ̀ kalẹ̀ wá?+
Ta ló ti kó ẹ̀fúùfù jọ sí àtẹ́lẹwọ́ rẹ̀ méjèèjì?
Ta ló ti di omi sínú aṣọ rẹ̀?+
Ta ló ti fi ìdí gbogbo ìkángun ayé sọlẹ̀?*+
Kí ni orúkọ rẹ̀, kí sì ni orúkọ ọmọ rẹ̀, tí o bá mọ̀ ọ́n?
5 Gbogbo ọ̀rọ̀ Ọlọ́run mọ́.+
Ó* jẹ́ apata fún àwọn tó ń wá ààbò lọ́dọ̀ rẹ̀.+
7 Ohun méjì ni mo béèrè lọ́wọ́ rẹ.
Má ṣàì fún mi kí n tó kú.
8 Mú kí àìṣòótọ́ àti irọ́ jìnnà sí mi.+
Má ṣe fún mi ní òṣì tàbí ọrọ̀.
Ṣáà jẹ́ kí n jẹ ìwọ̀nba oúnjẹ tí ó tó mi,+
9 Kí n má bàa yó tán, kí n sì sẹ́ ọ, kí n sọ pé, “Ta ni Jèhófà?”+
Má sì jẹ́ kí n tòṣì, kí n wá jalè, kí n sì kó ìtìjú bá* orúkọ Ọlọ́run mi.
10 Má ṣe ba ìránṣẹ́ jẹ́ lójú ọ̀gá rẹ̀,
Nítorí ó lè gégùn-ún fún ọ, wàá sì jẹ̀bi.+
11 Ìran kan wà tó ń gégùn-ún fún bàbá rẹ̀,
Kì í sì í súre fún ìyá rẹ̀.+
13 Ìran kan wà tó ní ojú ìgbéraga
Ó sì jọ ara rẹ̀ lójú gan-an!+
14 Ìran kan wà tí eyín rẹ̀ jẹ́ idà,
Egungun páárì ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀ sì jẹ́ ọ̀bẹ ìpẹran;
Wọ́n ń jẹ àwọn aláìní inú ayé run
Wọ́n sì ń jẹ àwọn òtòṣì run láàárín aráyé.+
15 Àwọn eṣúṣú* ní ọmọbìnrin méjì tó ń ké pé, “Mú wá! Mú wá!”
Ohun mẹ́ta wà tí kì í ní ìtẹ́lọ́rùn,
Àní ohun mẹ́rin tí kì í sọ pé, “Ó tó!”
17 Ojú tó ń fi bàbá ṣẹ̀sín, tí kì í sì í ṣègbọràn sí ìyá,+
Àwọn ẹyẹ ìwò tó wà ní àfonífojì yóò yọ ọ́ jáde,
Àwọn ọmọ ẹyẹ idì yóò sì mú un jẹ.+
19 Ọ̀nà ẹyẹ idì lójú ọ̀run,
Ọ̀nà ejò lórí àpáta,
Ọ̀nà ọkọ̀ òkun lójú agbami,
Àti ọ̀nà ọkùnrin pẹ̀lú ọ̀dọ́bìnrin.
20 Ọ̀nà obìnrin alágbèrè nìyí:
Ó jẹun, ó nu ẹnu rẹ̀;
Ó sì sọ pé, “Mi ò ṣe nǹkan kan tó burú.”+
21 Ohun mẹ́ta wà tó ń mú kí ayé mì jìgìjìgì,
Àní ohun mẹ́rin tí ayé kò lè fara dà:
29 Àwọn ohun mẹ́ta wà tí ìṣísẹ̀ wọn jọni lójú,
Àní ohun mẹ́rin tí ìrìn wọn dùn-ún wò:
30 Kìnnìún, tó jẹ́ pé òun ló lágbára jù nínú àwọn ẹranko,
Tí kì í sì í yíjú pa dà níwájú ẹnikẹ́ni;+
31 Ajá ọdẹ; òbúkọ;
Àti ọba tí àwọn ọmọ ogun rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀.
32 Tí o bá ti jẹ́ kí ìwà òmùgọ̀ mú kí o gbéra ga+
Tàbí tí o bá ti gbèrò láti ṣe bẹ́ẹ̀,
Fi ọwọ́ bo ẹnu rẹ.+
33 Nítorí bí pípo wàrà pọ̀ ṣe ń mú bọ́tà jáde,
Tí fífún imú pọ̀ sì ń mú ẹ̀jẹ̀ jáde,
Bẹ́ẹ̀ ni mímú inú bíni máa ń dá ìjà sílẹ̀.+
31 Àwọn ọ̀rọ̀ Ọba Lémúẹ́lì, ọ̀rọ̀ pàtàkì tí ìyá rẹ̀ fi dá a lẹ́kọ̀ọ́:+
4 Lémúẹ́lì, kò tọ́ sí àwọn ọba,
Kò tọ́ kí àwọn ọba máa mu wáìnì
Tàbí kí àwọn alákòóso máa sọ pé, “Ọtí mi dà?”+
5 Kí wọ́n má bàa mutí tán, kí wọ́n wá gbàgbé àṣẹ tó wà nílẹ̀,
Kí wọ́n sì fi ẹ̀tọ́ àwọn aláìní dù wọ́n.
7 Kí wọ́n mu, kí wọ́n gbàgbé ipò òṣì wọn;
Kí wọ́n má sì rántí ìdààmú wọn mọ́.
8 Gba ọ̀rọ̀ sọ fún ẹni tí kò lè sọ̀rọ̀;
Gbèjà ẹ̀tọ́ gbogbo àwọn tó ń kú lọ.+
א [Áléfì]
10 Ta ló ti rí aya tó dáńgájíá?*+
Ó níye lórí lọ́pọ̀lọpọ̀ ju iyùn.*
ב [Bétì]
ג [Gímélì]
12 Ohun rere ni obìnrin náà fi ń san án lẹ́san, kì í ṣe búburú,
Ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.*
ד [Dálétì]
ה [Híì]
ו [Wọ́ọ̀]
15 Bákan náà, ó máa ń dìde nígbà tí ilẹ̀ kò tíì mọ́,
Láti wá oúnjẹ sílẹ̀ fún agbo ilé rẹ̀
Àti èyí tó máa fún àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀.+
ז [Sáyìn]
ח [Hétì]
ט [Tétì]
18 Ó rí i pé òwò òun ń mérè wọlé;
Fìtílà rẹ̀ kì í kú ní òru.
י [Yódì]
כ [Káfì]
20 Ó la àtẹ́lẹwọ́ rẹ̀ sí aláìní,
Ó sì la ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn tálákà.+
ל [Lámédì]
21 Kò dààmú nípa agbo ilé rẹ̀ pé yìnyín ń já bọ́,
Nítorí pé gbogbo agbo ilé rẹ̀ ti wọ ẹ̀wù òtútù.*
מ [Mémì]
22 Ó ṣe àwọn aṣọ ìtẹ́lébùsùn rẹ̀.
Aṣọ rẹ̀ jẹ́ aṣọ ọ̀gbọ̀* àti olówùú pọ́pù.
נ [Núnì]
23 Àwọn èèyàn mọ ọkọ rẹ̀ dáadáa ní àwọn ẹnubodè ìlú,+
Níbi tó máa ń jókòó sí láàárín àwọn àgbààgbà ilẹ̀ náà.
ס [Sámékì]
ע [Áyìn]
25 Ó fi agbára àti ògo ṣe aṣọ wọ̀,
Ọkàn rẹ̀ sì balẹ̀* bó ṣe ń wo ọjọ́ iwájú.
פ [Péè]
צ [Sádì]
ק [Kófì]
28 Àwọn ọmọ rẹ̀ dìde, wọ́n sì pè é ní aláyọ̀;
Ọkọ rẹ̀ dìde, ó sì yìn ín.
ר [Réṣì]
ש [Ṣínì]
ת [Tọ́ọ̀]
31 Ẹ fún un ní èrè ohun tó ṣe,*+
Kí àwọn iṣẹ́ rẹ̀ sì máa yìn ín ní àwọn ẹnubodè ìlú.+
Ní Héb., “mọ.”
Tàbí “ohun tó tọ́.”
Tàbí “àìṣègbè.”
Tàbí “àkàwé.”
Tàbí “Ọ̀wọ̀ fún.”
Tàbí “òfin.”
Tàbí “Ṣìọ́ọ̀lù,” ìyẹn ibojì aráyé. Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.
Tàbí “Da ìpín rẹ pọ̀ mọ́ tiwa.”
Tàbí “jọ lo àpò (pọ́ọ̀sì) kan náà.”
Tàbí “ọkàn.”
Tàbí “ọkàn.”
Ní Héb., “orí.”
Tàbí “Yí pa dà tí mo bá bá ọ wí.”
Ní Héb., “jẹ nínú èso.”
Tàbí “Ètekéte; èrò.”
Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀, “Ọkàn.”
Tàbí “ìdúróṣinṣin.”
Ní Héb., “àjèjì obìnrin.” Ó ṣe kedere pé èyí tí ìwà rẹ̀ kò bá ti Ọlọ́run mu mọ́ ni.
Tàbí “fífanimọ́ra.”
Ní Héb., “obìnrin ilẹ̀ òkèèrè.” Ó ṣe kedere pé èyí tí ìwà rẹ̀ jìnnà sí ti Ọlọ́run ni.
Tàbí “ọkọ.”
Ní Héb., “Àwọn ipa ọ̀nà.”
Tàbí “ti sọ di aláìlágbára.”
Ní Héb., “wọlé sọ́dọ̀ rẹ̀.”
Tàbí “Àwọn tó ń pa ìwà títọ́ mọ́.”
Tàbí “òfin.”
Tàbí “òtítọ́.”
Ní Héb., “ìdodo.”
Tàbí “èyí tó dára jù lọ nínú.”
Tàbí “owó tó ń wọlé fún ọ.”
Tàbí “àwọn ibi tí wọ́n ti ń fún wáìnì.”
Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.
Ó ṣe kedere pé àwọn ànímọ́ Ọlọ́run tí àwọn ẹsẹ tó ṣáájú mẹ́nu bà ló ń tọ́ka sí.
Tàbí “ọkàn rẹ.”
Tàbí “gbá.”
Tàbí “àwọn tí ó tọ́ sí.”
Tàbí “Tí o bá lágbára.”
Tàbí “òfin.”
Tàbí “ṣe kókó.”
Tàbí “ìdúróṣinṣin.”
Ní Héb., “Dẹ etí rẹ.”
Ní Héb., “ẹran ara.”
Tàbí “ranjú.”
Tàbí kó jẹ́, “Fara balẹ̀ kíyè sí ọ̀nà tí ẹsẹ̀ rẹ ń gbà.”
Ní Héb., “Dẹ etí rẹ.”
Ní Héb., “àjèjì obìnrin.” Wo Owe 2:16.
Ní Héb., “Ẹnu.”
Ìyẹn, igi kan tó korò gan-an.
Tàbí “Ṣìọ́ọ̀lù,” ìyẹn ibojì aráyé. Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.
Tàbí “agbára.”
Ní Héb., “Ní àárín àpéjọ àti ìjọ.”
Tàbí “omi tó mọ́ lóló.”
Tàbí “ìsun omi.”
Tàbí “pa ọ́ bí ọtí.”
Ní Héb., “àjèjì obìnrin.” Wo Owe 2:16.
Ní Héb., “obìnrin ilẹ̀ òkèèrè.” Wo Owe 2:16.
Tàbí “onígbọ̀wọ́.”
Ìyẹn, nínú ẹ̀jẹ́.
Tàbí “ọkàn rẹ̀.”
Tàbí “òfin.”
Tàbí “kọ́ ẹ lẹ́kọ̀ọ́.”
Ní Héb., “ilẹ̀ òkèèrè.” Wo Owe 2:16.
Tàbí “ọkàn.”
Tàbí “ara.”
Ní Héb., “jẹ́ ẹni tí ọkàn kù fún.”
Tàbí “ọkàn.”
Tàbí “ìràpadà.”
Tàbí “òfin.”
Ní Héb., “àjèjì obìnrin.” Wo Owe 2:16.
Ní Héb., “ilẹ̀ òkèèrè.” Wo Owe 2:16.
Tàbí “fífanimọ́ra.”
Tàbí “wíńdò.”
Ìyẹn, fèrèsé tó ní asẹ́ onígi.
Tàbí “aláìní ìrírí.”
Ní Héb., “tí ọkàn kù fún.”
Tàbí “wọṣọ.”
Ní Héb., “Ẹsẹ̀ rẹ̀ kì í.”
Tàbí “Aṣọ àtàtà.”
Tàbí “ṣẹkẹ́ṣẹkẹ̀.”
Tàbí “Ṣìọ́ọ̀lù,” ìyẹn ibojì aráyé. Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.
Ní Héb., “Ẹ̀yin ọmọ èèyàn.”
Ní Héb., “lóye ọkàn.”
Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.
Tàbí “Ohun àjogúnbá tó ṣeyebíye.”
Tàbí “Láti ayérayé.”
Tàbí “a bí mi nínú ìrora ìbímọ.”
Ní Héb., “àmì òbìrìkìtì.”
Ní Héb., “tó mú kí àwọsánmà lágbára lókè.”
Tàbí “tó fi àṣẹ gbé àwọn ìpìlẹ̀ ayé kalẹ̀.”
Tàbí “aráyé.”
Tàbí “Tó ń wà lójúfò lẹ́nu.”
Tàbí “ọkàn.”
Ní Héb., “Ó ti pa ohun pípa rẹ̀.”
Ní Héb., “tí ọkàn kù fún.”
Tàbí “àwọn aláìmọ̀kan.”
Ní Héb., “tí ọkàn kù fún.”
Tàbí “ti sọ di aláìlágbára.”
Tàbí “Ṣìọ́ọ̀lù,” ìyẹn ibojì aráyé. Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.
Tàbí “ọkàn olódodo.”
Tàbí “Orúkọ.”
Ní Héb., “àṣẹ.”
Ní Héb., “tí ọkàn kù fún.”
Tàbí “Ohun iyebíye.”
Tàbí kó jẹ́, “wà ní.”
Tàbí “àhesọ ọ̀rọ̀.”
Tàbí “tọ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ èèyàn sọ́nà.”
Tàbí “ìbànújẹ́; ìṣòro.”
Tàbí “ẹni tó gbà á síṣẹ́.”
Tàbí “Ìrètí.”
Tàbí “so èso.”
Tàbí “ìrẹ́nijẹ.”
Tàbí “òkúta ìwọ̀n.”
Tàbí “Àwọn ohun iyebíye.”
Tàbí “ẹni tí kò gba Ọlọ́run gbọ́.”
Ní Héb., “tí ọkàn kù fún.”
Tàbí “pẹ̀gàn.”
Ní Héb., “olóòótọ́ ní ẹ̀mí.”
Ní Héb., “bo ọ̀rọ̀ mọ́lẹ̀.”
Tàbí “olùdámọ̀ràn.”
Tàbí “ìgbàlà.”
Tàbí “onígbọ̀wọ́.”
Ní Héb., “kórìíra.”
Tàbí “tó rẹwà.”
Tàbí “Ẹni tó ní ìfẹ́ tí kì í yẹ̀.”
Tàbí “ń ṣe ọkàn rẹ̀ lóore.”
Tàbí “ìtìjú.”
Ní Héb., “Ọwọ́ sí ọwọ́.”
Ní Héb., “tó ń fọ́n ká.”
Tàbí “Ọkàn.”
Ní Héb., “ni a ó mú sanra.”
Ní Héb., “bomi rin àwọn míì fàlàlà.”
Tàbí “kó ìtìjú.”
Ní Héb., “ẹ̀fúùfù.”
Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.
Tàbí “kò ní ọgbọ́n.”
Ní Héb., “lílúgọ deni fún ẹ̀jẹ̀.”
Ní Héb., “búrẹ́dì.”
Tàbí “ọkàn ẹran.”
Ní Héb., “jẹ́ ẹni tí ọkàn kù fún.”
Tàbí “àmọ̀ràn.”
Tàbí “lọ́jọ́ kan náà.”
Ní Héb., “ń bo.”
Ní Héb., “ohun tó jẹ́ òdodo.”
Ní Héb., “àwọn agbani-nímọ̀ràn àlàáfíà.”
Tàbí “banú jẹ́.”
Tàbí “ìtọ́sọ́nà.”
Tàbí “ohun tó ń sọ.”
Tàbí “ọkàn.”
Tàbí “ọkàn rẹ̀ kò.”
Tàbí “ọkàn.”
Ní Héb., “ni a ó mú sanra.”
Tàbí “ọkàn.”
Ní Héb., “aláìní kì í gbọ́ ìbáwí.”
Ní Héb., “ń yọ̀.”
Tàbí “fèrò wérò.”
Tàbí “Ọrọ̀ tó wá látinú asán.”
Ní Héb., “ń fi ọwọ́ kó jọ.”
Tàbí “Ìfojúsọ́nà.”
Tàbí “ọ̀rọ̀.”
Tàbí “Òfin.”
Tàbí “ìbáwí.”
Tàbí “mọ́ ọkàn.”
Tàbí “aláìní.”
Tàbí “ìbáwí; ìfìyàjẹni.”
Tàbí kó jẹ́, “kánmọ́kánmọ́.”
Tàbí “Olódodo ń jẹ, ó sì tẹ́ ọkàn rẹ̀ lọ́rùn.”
Tàbí “tí ọ̀nà rẹ̀ wọ́.”
Tàbí “màlúù.”
Tàbí kó jẹ́, “ni wọ́n fi ń ṣi àwọn míì lọ́nà.”
Tàbí “ṣíṣe àtúnṣe.”
Tàbí “máa ń wá ire.”
Tàbí “ìkorò ọkàn rẹ̀.”
Tàbí “Aláìní ìrírí.”
Tàbí “máa ń bínú fùfù.”
Tàbí “aláròjinlẹ̀.”
Tàbí “aláìní ìrírí.”
Tàbí “ọkàn.”
Tàbí “ní ìlera.”
Tàbí “Ọ̀rọ̀ tútù.”
Tàbí “ọ̀rọ̀ tó ń dunni.”
Tàbí “Ahọ́n tó ń woni sàn.”
Ní Héb., “ń wó ẹ̀mí palẹ̀.”
Tàbí “ìtọ́sọ́nà.”
Tàbí “owó tó ń wọlé fún.”
Tàbí “ohun tó le jù.”
Tàbí “Ṣìọ́ọ̀lù,” ìyẹn ibojì aráyé. Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.
Tàbí “àti Ábádónì.”
Tàbí “tó ń bá a wí.”
Tàbí “ń wá.”
Tàbí “ọkàn rẹ̀ ń yọ̀.”
Tàbí “ìdàrúdàpọ̀.”
Ní Héb.,“tí wọ́n bọ́ ní ibùjẹ ẹran.”
Ní Héb., “tí ọkàn kù fún.”
Tàbí “pé àwọn èèyàn bára wọn sọ òótọ́ ọ̀rọ̀.”
Tàbí “olùdámọ̀ràn.”
Ní Héb., “nínú ìdáhùn ẹnu rẹ̀.”
Tàbí “Ṣìọ́ọ̀lù,” ìyẹn ibojì aráyé. Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.
Tàbí “ń kó ìtìjú.”
Tàbí “ń fara balẹ̀ ro bó ṣe máa dáhùn; máa ń ronú kí ó tó sọ̀rọ̀.”
Tàbí “Ẹ̀rín músẹ́.”
Ní Héb., “sanra.”
Tàbí “ọkàn.”
Ní Héb., “ọkàn.”
Ní Héb., “Èèyàn ló máa ń ṣètò ọkàn.”
Tàbí “ìdáhùn tí ó tọ́.” Ní Héb., “ìdáhùn ahọ́n.”
Ní Héb., “mọ́.”
Ní Héb., “ẹ̀mí.”
Ní Héb., “Yí àwọn iṣẹ́ rẹ sọ́dọ̀ Jèhófà.”
Ní Héb., “Ọwọ́ sí ọwọ́.”
Tàbí “Ìpinnu àtọ̀runwá.”
Tàbí “ń yẹra fún un.”
Tàbí “ọkàn.”
Ní Héb., “ẹni tó rẹlẹ̀ ní ẹ̀mí.”
Ní Héb., “rí ire.”
Tàbí “tó ń tuni lára.” Ní Héb., “tó sì ní ètè dídùn.”
Tàbí “Ó dùn lẹ́nu.” Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀, “Ọkàn.”
Tàbí “Ọkàn.”
Ní Héb., “Ẹnu rẹ̀.”
Tàbí “Elétekéte.”
Tàbí “ògo.”
Ní Héb., “ṣàkóso ẹ̀mí rẹ̀.”
Ní Héb., “Búrẹ́dì.”
Tàbí “tí kò sí ìyọlẹ́nu.”
Ní Héb., “ẹbọ.”
Tàbí “ọmọ.”
Tàbí “òbí.”
Tàbí “rere.”
Tàbí “èèyàn pàtàkì.”
Tàbí “òkúta tó ń mú kéèyàn rójú rere.”
Ní Héb., “bo ẹ̀ṣẹ̀ mọ́lẹ̀.”
Tàbí “àgbájọ omi.” Ní Héb., “jẹ́ kí omi tú jáde.”
Ní Héb., “Nígbà tí kò ní ọkàn láti ní in.”
Ní Héb., “tí ọkàn kù fún.”
Tàbí “onígbọ̀wọ́.”
Ní Héb., “rí ire.”
Tàbí “tó ń woni sàn.”
Tàbí “ń mú kí egungun gbẹ.”
Ní Héb., “àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti oókan àyà.”
Ní Héb., “ìkorò.”
Tàbí “bu owó ìtanràn lé.”
Ní Héb., “máa ń tutù ní ẹ̀mí.”
Tàbí “yóò kórìíra.”
Tàbí “ọkàn.”
Tàbí “ohun téèyàn fẹ́ fi ojú kòkòrò gbé mì.”
Ní Héb., “a sì gbé e ga sókè,” ìyẹn ni pé, ọwọ́ kò lè tó o, kò sí ohun tó máa ṣe é.
Tàbí “ta ló lè fara dà á tí nǹkan bá tojú súni pátápátá?”
Tàbí “wádìí rẹ̀ wò látòkèdélẹ̀.”
Ní Héb., “ṣe ìyàsọ́tọ̀.”
Tàbí “ìtẹ́wọ́gbà.”
Tàbí “ọkàn.”
Ní Héb., “kí ẹsẹ̀ èèyàn yá.”
Tàbí “ẹni tó lawọ́.”
Ní Héb., “ọkàn.”
Tàbí “ọkàn.”
Ní Héb., “rí ire.”
Ní Héb., “mójú kúrò nínú.”
Tàbí “ìṣìnà.”
Tàbí “ọmọ kìnnìún tó tó ọdẹ ṣe (onígọ̀gọ̀).”
Tàbí “Ẹlẹ́jọ́ wẹ́wẹ́.”
Tàbí “ọkàn.”
Tàbí “ọkàn.”
Tàbí “èrè.”
Tàbí “fẹ́.” Ní Héb., “gbé ọkàn rẹ sí.”
Tàbí “ìpinnu.”
Tàbí “Ìpayà.”
Tàbí “ọmọ kìnnìún tó tó ọdẹ ṣe (onígọ̀gọ̀).”
Tàbí kó jẹ́, “Á máa wá nǹkan nígbà ìkórè, àmọ́ kò ní rí nǹkan kan.”
Ní Héb., “Ìmọ̀ràn.”
Ní Héb., “àwọn ọmọkùnrin.”
Tàbí “Òkúta ìwọ̀n oríṣi méjì àti ohun èèlò ìdíwọ̀n oríṣi méjì.”
Tàbí “ọmọdékùnrin.”
Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.
Tàbí “àjèjì kan.”
Tàbí “Àmọ̀ràn.”
Tàbí “fẹsẹ̀ múlẹ̀.”
Tàbí “ẹni tó máa ń fi ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ fajú èèyàn mọ́ra.”
Tàbí “òkúta ìwọ̀n oríṣi méjì.”
Tàbí “ọ̀nà tó yẹ kó gbà?”
Tàbí “nu.”
Tàbí “èrò ọkàn.”
Tàbí “àǹfààní.”
Tàbí kó jẹ́, “fún àwọn tó ń wá ikú.”
Tàbí “ẹlẹ́jọ́ wẹ́wẹ́.”
Tàbí “ọkàn ẹni.”
Tàbí “mọ ohun tó yẹ kó ṣe.”
Ní Héb., “ní àyà.”
Tàbí “ti sọ di aláìlágbára.”
Tàbí “ìgbádùn.”
Tàbí “ẹlẹ́jọ́ wẹ́wẹ́.”
Ní Héb., “gbé ohun tó ní mì.”
Tàbí “borí.”
Tàbí “ọkàn.”
Tàbí “pẹ̀lú ìwà tó ń tini lójú.”
Ní Héb., “ẹni tó ń fetí sílẹ̀ yóò máa sọ̀rọ̀ títí láé.”
Tàbí “ló ń mú kí ọ̀nà rẹ̀ dájú.”
Ní Héb., “Orúkọ.”
Ní Héb., “Ojú rere.”
Ní Héb., “bára pàdé.”
Tàbí “Aláròjinlẹ̀.”
Tàbí “jìyà àbájáde rẹ̀.”
Tàbí “ọkàn.”
Tàbí “ọ̀dọ́.” Ní Héb., “ọmọdékùnrin.”
Ní Héb., “Ẹni tó ní ojú tó dára.”
Tàbí “Ẹjọ́.”
Ní Héb., “àjèjì obìnrin.” Wo Owe 2:16.
Tàbí “ọ̀dọ́.” Ní Héb., “ọmọdékùnrin.”
Tàbí “ọkàn.”
Tàbí “ọkàn.”
Tàbí “Kó ara rẹ níjàánu.”
Tàbí “pé ọkàn rẹ ń fẹ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan.”
Tàbí kó jẹ́, “Jáwọ́ nínú lílo òye tìrẹ.”
Tàbí “ẹni tó ń fojú burúkú wo èèyàn.”
Tàbí “tó ń ṣe ìṣírò nínú ọkàn rẹ̀.”
Ní Héb., “ọkàn rẹ̀ kò wà pẹ̀lú rẹ.”
Ní Héb., “Olùràpadà.”
Tàbí “ọ̀dọ́.” Ní Héb., “ọmọdékùnrin.”
Tàbí “ọkàn rẹ̀.”
Tàbí “Ṣìọ́ọ̀lù,” ìyẹn ibojì aráyé. Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.
Ní Héb., “kíndìnrín mi.”
Tàbí “Ní.”
Ní Héb., “àjèjì obìnrin.” Wo Owe 2:16.
Tàbí “tó tín-ín-rín.”
Tàbí “Àwọn tó ń kóra jọ láti wo bí àdàlù wáìnì ṣe ń rí lára.”
Tàbí “kò dùn mí.”
Tàbí “Màá wá a lẹ́ẹ̀kan sí i.”
Tàbí “agbo ilé.”
Tàbí “olùdámọ̀ràn.”
Tàbí “àṣeyọrí; ìgbàlà.”
Ìyẹn, òmùgọ̀.
Tàbí “Ohun tí òmùgọ̀ ń gbèrò.”
Tàbí “lásìkò ìdààmú.”
Tàbí “èrò.”
Tàbí “wo ọkàn rẹ.”
Tàbí “dùn mọ́ ọkàn rẹ.”
Ìyẹn, ọ̀tá náà.
Tàbí “gbaná jẹ.”
Tàbí “àwọn tó ń wá ìyípadà.”
Ìyẹn, Jèhófà àti ọba.
Tàbí kó jẹ́, “Fífèsì lọ́nà tó tọ́ dà bí fífi ẹnu koni lẹ́nu.”
Tàbí “agbo ilé.”
Tàbí “Màá ṣe bákan náà sí i.”
Ní Héb., “tí ọkàn kù fún.”
Ní Héb., “gba ìbáwí.”
Tàbí “dà kọ, tí wọ́n sì kó jọ.”
Tàbí “àṣírí ẹlòmíì.”
Tàbí “Àhesọ ọ̀rọ̀ tó ń bani lórúkọ jẹ́.”
Tàbí “férémù.”
Tàbí “ó ń tu ọkàn ọ̀gá rẹ̀ lára.”
Ní Héb., “ẹ̀bùn èké.”
Tàbí “Ọ̀rọ̀ tútù.”
Tàbí kó jẹ́, “oníbékebèke.”
Tàbí “ákáláì.”
Ní Héb., “ẹni tó kórìíra rẹ.”
Ìyẹn, láti mú kí ọkàn ẹni náà rọ̀, kí inú rẹ̀ sì yọ́.
Tàbí “ẹlẹ́jọ́ wẹ́wẹ́.”
Ní Héb., “ọkàn.” Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.
Tàbí “tó fohùn ṣọ̀kan pẹ̀lú.” Ní Héb., “ta gọ̀ọ́gọ̀ọ́ níwájú.”
Tàbí “ẹ̀mí.”
Tàbí kó jẹ́, “ègún tí kò tọ́ síni kì í mọ́ni.”
Tàbí “Kí o má bàa mú ara rẹ bá a dọ́gba.”
Ní Héb., “tó sì ń mu ìwà ipá.”
Tàbí “dirodiro.”
Tàbí “tó ń ṣe gbogbo èèyàn léṣe.”
Tàbí “ìkọ́ aláyìípo.”
Tàbí kó jẹ́, “tó sì ń dá sí.”
Tàbí “ọfà tó ń ṣekú pani.”
Tàbí “ohun téèyàn fẹ́ fi ojú kòkòrò gbé mì.”
Ní Héb., “ètè tó ń jó belebele pẹ̀lú.”
Tàbí “ọkàn rẹ̀ jẹ́ ohun ìríra látòkèdélẹ̀.”
Ní Héb., “ohun tí ọ̀la máa bí.”
Ní Héb., “Àjèjì.”
Ní Héb., “Ọmọ ilẹ̀ òkèèrè.”
Tàbí kó jẹ́, “kò dénú; jẹ́ tipátipá.”
Tàbí “Ọkàn.”
Ní Héb., “ló ń tẹ oyin inú afárá mọ́lẹ̀.”
Tàbí “ọkàn.”
Tàbí “tó sá kúrò ní.”
Tàbí “Aláròjinlẹ̀.”
Tàbí “jìyà àbájáde rẹ̀.”
Tàbí “àjèjì kan.”
Tàbí “ẹlẹ́jọ́ wẹ́wẹ́.”
Ní Héb., “pọ́n ojú.”
Tàbí “Ṣìọ́ọ̀lù àti Ábádónì.”
Tàbí “Bẹ́ẹ̀ ni èèyàn ṣe rí ní ti ìyìn tó gbà.”
Tàbí “Fi ọkàn rẹ sí; Kíyè sí.”
Tàbí “dáyádémà.”
Tàbí “ọmọ kìnnìún.”
Tàbí “ọ̀tẹ̀.”
Ní Héb., “òun.”
Tàbí “ẹni tó bá ń bẹ̀rù.”
Tàbí “tí ẹ̀jẹ̀ ọkàn kan bá wọ̀ lọ́rùn.”
Tàbí “kòtò.”
Tàbí “Olójúkòkòrò.”
Tàbí kó jẹ́, “Agbéraga ẹ̀dá.”
Ní Héb., “ni a ó mú sanra.”
Tàbí “tó ń ṣorí kunkun.”
Tàbí “aláìlẹ́bi.”
Tàbí “ọkàn.”
Tàbí kó jẹ́, “Àmọ́ adúróṣinṣin máa ń wá ọ̀nà láti dáàbò bo ẹ̀mí rẹ̀. ”
Ní Héb., “Gbogbo ẹ̀mí.”
Ní Héb., “bára pàdé.”
Ìyẹn ni pé, Òun ló fún wọn ní ẹ̀mí.
Tàbí “Ìbáwí; Ìfìyàjẹni.”
Tàbí “mú ọkàn rẹ yọ̀.”
Tàbí “ìran alásọtẹ́lẹ̀; ìfihàn.”
Tàbí “ọkàn òun fúnra rẹ̀.”
Tàbí “gbọ́ ìbúra kan tó ní ègún nínú.”
Ní Héb., “Wíwárìrì nítorí.”
Tàbí “ń dẹ.”
Tàbí kó jẹ́, “ń wá ojú rere alákòóso.” Ní Héb., “ń wá ojú alákòóso.”
Ní Héb., “gbé gbogbo ìkángun ayé dìde.”
Ìyẹn, Ọlọ́run.
Tàbí “dojú ìjà kọ.”
Ní Héb., “ìgbọ̀nsẹ̀.”
Tàbí “kòkòrò mùjẹ̀mùjẹ̀.”
Tàbí “Ṣìọ́ọ̀lù,” ìyẹn ibojì aráyé. Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.
Tàbí “ilé ọmọ tí kò lè gba oyún dúró.”
Tàbí “tó jẹ́ àgbàyanu fún mi.”
Tàbí “tí wọn ò fẹ́ràn.”
Tàbí “bá lé ọ̀gá rẹ̀ obìnrin jáde.”
Tàbí “ọgbọ́n tó ga gan-an.”
Ní Héb., “èèyàn.”
Ìyẹn, ẹranko kan tó jọ ehoro tó máa ń gbé níbi tí àpáta wà.
Ní Héb., “èèyàn.”
Tàbí “ní àwùjọ-àwùjọ.”
Tàbí “tí ọkàn wọn gbọgbẹ́.”
Tàbí “Gba ẹjọ́ àwọn aláìní àti ti tálákà rò.”
Tàbí “aya àtàtà.”
Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.
Ìyẹn, ọkọ rẹ̀.
Ìyẹn, obìnrin náà.
Tàbí “aṣọ àtàtà.”
Tàbí “owó ara rẹ̀.” Ní Héb., “èso iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.”
Ní Héb., “Ó fi agbára di ìbàdí rẹ̀ lámùrè.”
Ọ̀pá ìrànwú àti ìrànwú ni igi tí wọ́n fi ń yí òwú àti fọ́nrán pọ̀ tàbí kí wọ́n fi ṣe é.
Ní Héb., “ẹ̀wù oníṣẹ̀ẹ́po.”
Tàbí “aṣọ àtàtà.”
Tàbí “aṣọ àtàtà.”
Tàbí “àwọ̀tẹ́lẹ̀.”
Tàbí “Ó sì ń rẹ́rìn-ín.”
Tàbí “Ẹ̀kọ́ onífẹ̀ẹ́; Òfin ìfẹ́ tí kì í yẹ̀.”
Tàbí “obìnrin àtàtà.”
Tàbí “lè jẹ́ òfo; asán.”
Ní Héb., “Ẹ fún un látinú èso ọwọ́ rẹ̀.”